< Nehemiah 4 >
1 Nígbà tí Sanballati gbọ́ pé àwa ń tún odi náà mọ, ó bínú, ó sì bínú púpọ̀. Ó fi àwọn ará Júù ṣe ẹlẹ́yà,
Og det skete, der Sanballat hørte, at vi byggede Muren, da optændtes hans Vrede, og han blev meget fortørnet, og han bespottede Jøderne.
2 ó sọ níwájú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ àti níwájú àwọn ọmọ-ogun Samaria pé, “Kí ni àwọn aláìlera Júù wọ̀nyí ń ṣe yìí? Ṣé wọn yóò mú odi wọn padà ni? Ṣé wọn yóò rú ẹbọ ni? Ṣé wọn yóò parí i rẹ̀ lóòjọ́ ni bí? Ṣé wọ́n lè mú òkúta tí a ti sun láti inú òkìtì padà bọ̀ sípò tí ó jóná bí wọ́n ṣe wà?”
Og han sagde i Paahør af sine Brødre og af Hæren i Samaria, han sagde: Hvad gøre de afmægtige Jøder? skulde man lade dem være? skulde de ofre? skulde de fuldende det paa denne Dag? skulde de lade Stenene leve op af Grusdyngerne, da de ere forbrændte?
3 Tobiah ará Ammoni, ẹni tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, wí pé, “Ohun tí wọ́n ń mọ—bí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ lásán bá gùn ún sókè, yóò fọ́ odi òkúta wọn lulẹ̀!”
Og Ammoniten Tobia var Jios ham, og han sagde: Om de end bygge, vil dog en Ræv, om den sprang op, nedrive deres Stenmur.
4 Gbọ́ ti wa, Ọlọ́run wa, nítorí àwa di ẹni ẹ̀gàn. Dá ẹ̀gàn wọn padà sórí ara wọn. Kí o sì fi wọ́n fún ìkógun ní ilẹ̀ ìgbèkùn.
Hør, vor Gud! at vi ere foragtede, og lad deres Forsmædelse vende tilbage paa deres Hoved, og giv dem hen til Bytte i Fangenskabs Land;
5 Má ṣe bo ẹ̀bi wọn tàbí wẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wọn nù kúrò níwájú rẹ, nítorí wọ́n mú ọ bínú níwájú àwọn ọ̀mọ̀lé.
og skjul ikke deres Misgerning, og lad deres Synd ikke udslettes fra dit Ansigt; thi de have opirret dig lige over for dem, som byggede.
6 Bẹ́ẹ̀ ni àwa mọ odi náà títí gbogbo rẹ̀ fi dé ìdajì gíga rẹ̀, nítorí àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an wọn.
Men vi byggede Muren, saa at den ganske Mur blev sammenføjet indtil dens halvs Højde; thi Folket havde Hjerte til at gøre det.
7 Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati, Tobiah, àwọn ará Arabia, ará Ammoni, àti àwọn ènìyàn Aṣdodu gbọ́ pé àtúnṣe odi Jerusalẹmu ti ga dé òkè àti pé a ti mọ àwọn ibi tí ó yá dí, inú bí wọn gidigidi.
Og det skete, der Sanballat og Tobia og Araberne og Ammoniterne og Asdoditerne hørte, at Udbedringen havde taget til paa Murene i Jerusalem, og at Revnerne begyndte at lukkes til, da optændtes deres Vrede saare.
8 Gbogbo wọn jọ gbìmọ̀ pọ̀ láti wá bá Jerusalẹmu jà àti láti dìde wàhálà sí í.
Og de gjorde alle et Forbund med hverandre om at komme at stride imod Jerusalem og at gøre en Forstyrrelse deri.
9 Ṣùgbọ́n àwa gbàdúrà sí Ọlọ́run wa, a sì yan olùṣọ́ ọ̀sán àti ti òru láti kojú ìhàlẹ̀ yìí.
Men vi bade til vor Gud; og vi stillede Vagt imod dem Dag og Nat over for dem.
10 Lákòókò yìí, àwọn ènìyàn Juda wí pé, “Agbára àwọn òṣìṣẹ́ ti dínkù, àlàpà púpọ̀ ni ó wà tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi le è mọ odi náà.”
Da sagde Juda: Lastdragernes Kraft er skrøbelig, og Gruset er meget, og vi kunne ikke bygge paa Muren.
11 Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ọ̀tá wa wí pé, “Kí wọn tó mọ̀ tàbí kí wọn tó rí wa, àwa yóò ti dé àárín wọn, a ó sì pa wọ́n, a ó sì dá iṣẹ́ náà dúró.”
Og vore Modstandere sagde: De skulle ikke vide og ikke se det, førend vi komme midt iblandt dem og slaa dem ihjel; og vi ville gøre, at Gerningen skal holde op.
12 Nígbà náà ni àwọn Júù tí ó ń gbé ní ẹ̀gbẹ́ wọn wá sọ fún wa ní ìgbà mẹ́wàá pé, “Ibikíbi tí ẹ̀yin bá padà sí, wọn yóò kọlù wá.”
Og det skete, der Jøderne, som boede hos dem, kom og sagde vel ti Gange til os: I, som ere komne fra alle Steder, vender tilbage til os!
13 Nítorí náà mo dá ènìyàn díẹ̀ dúró níbi tí ó rẹlẹ̀ jù lẹ́yìn odi ní ibi gbangba, mo fi wọ́n síbẹ̀ nípa àwọn ìdílé wọn, pẹ̀lú àwọn idà wọn, àwọn ọ̀kọ̀ wọn àti àwọn ọrun wọn.
da stillede jeg Folket neden for Stedet, bag om Muren, paa de frie Pladser; og jeg stillede Folket efter Slægter med deres Sværd, deres Spyd og deres Buer.
14 Lẹ́yìn ìgbà tí mo wo àwọn nǹkan yíká, mo dìde mo sì wí fún àwọn ọlọ́lá àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù u wọn. Ẹ rántí Olúwa, ẹni tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, kí ẹ sì jà fún àwọn arákùnrin yín, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, àwọn ìyàwó yín àti àwọn ilé yín.”
Og jeg saa til og rejste mig og sagde til de ypperste og til Forstanderne og til det øvrige Folk: Frygter ikke for deres Ansigt, tænker paa den store og forfærdelige Herre og strider før eders Brødre, eders Sønner og eders Døtre, eders Hustruer og eders Huse!
15 Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ pé àwa ti mọ èrò wọn àti wí pé Ọlọ́run ti bà á jẹ́, gbogbo wa padà sí ibi odi, ẹnìkọ̀ọ̀kan sí ibi iṣẹ́ tirẹ̀.
Og det skete, der vore Fjender hørte, at det var os tilkendegivet, og at Gud havde gjort deres Raad til intet, da vendte vi os alle til Muren igen, hver til sin Gerning.
16 Láti ọjọ́ náà lọ, ìdajì àwọn ènìyàn ń ṣe iṣẹ́ náà, nígbà tí àwọn ìdajì tókù múra pẹ̀lú ọ̀kọ̀, asà, ọrun àti ìhámọ́ra. Àwọn ìjòyè sì pín ara wọn sẹ́yìn gbogbo ènìyàn Juda.
Og det skete fra den samme Dag af, at Halvdelen af mine unge Karle udførte Arbejdet, og den anden halve Del af dem holdt baade Spydene, Skjoldene og Buerne og Panserne, og Øversterne stode bag det ganske Judas Hus.
17 Àwọn ẹni tí ó ń mọ odi. Àwọn tí ń ru àwọn ohun èlò ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú ọwọ́ kan, wọ́n sì fi ọwọ́ kejì di ohun ìjà mú,
De, som byggede paa Muren, og Lastdragerne og de, som læssede paa, udførte med, deres ene Haand Arbejdet, og med den anden holdt de Vaabnet.
18 olúkúlùkù àwọn ọ̀mọ̀lé fi idà wọn sí ẹ̀gbẹ́ wọn bí wọ́n ṣe ń ṣiṣẹ́. Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí ń fọn ìpè dúró pẹ̀lú mi.
Og de, som byggede, havde hver sit Sværd bundet ved sine Lænder og byggede saa; og den, som blæste i Trompeten, var hos mig.
19 Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Iṣẹ́ náà fẹ̀ ó sì pọ̀, a sì ti jìnnà sí ara wa púpọ̀ lórí odi.
Og jeg sagde til de ypperste og til Forstanderne og til det øvrige Folk: Arbejdet er stort og vidtløftigt; men vi ere adspredte paa Murene, den ene langt fra den anden.
20 Níbikíbi tí ẹ bá ti gbọ́ ohùn ìpè, ẹ da ara pọ̀ mọ́ wa níbẹ̀. Ọlọ́run wa yóò jà fún wa!”
Paa hvilket Sted I høre Trompetens Lyd, samler eder derhen til os; vor Gud skal stride for os.
21 Bẹ́ẹ̀ ni àwa ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú àwọn ìdajì ènìyàn tí ó di ọ̀kọ̀ mú, láti òwúrọ̀ kùtùkùtù títí di ìgbà tí ìràwọ̀ yóò fi yọ.
Saa udførte vi Arbejdet, medens Halvdelen af dem holdt paa Spydene, fra Morgenrøden gik op, indtil Stjernerne kom frem.
22 Ní ìgbà náà mo tún sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Jẹ́ kí olúkúlùkù ènìyàn àti olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ dúró ní Jerusalẹmu ní òru, nítorí kí wọn le jẹ́ ẹ̀ṣọ́ fún wa ní òru, kí wọn sì le ṣe iṣẹ́ ní ọ̀sán.”
Ogsaa sagde jeg paa samme Tid til Folket: Hver blive med sin Tjener Natten over midt i Jerusalem, at vi maa have dem om Natten til Vagt og om Dagen til Gerningen.
23 Bẹ́ẹ̀ ni èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi àti àwọn ẹ̀ṣọ́ tí ó wà pẹ̀lú mi kò bọ́ aṣọ wa, olúkúlùkù wa ní ohun ìjà tirẹ̀, kódà nígbà tí wọ́n bá ń lọ pọn omi.
Men hverken jeg eller mine Brødre eller mine Tjenere eller de Mænd paa Vagten, som vare bag mig, førte os af vore Klæder; hver havde sit Vaaben hos sig og Vand.