< Nehemiah 4 >

1 Nígbà tí Sanballati gbọ́ pé àwa ń tún odi náà mọ, ó bínú, ó sì bínú púpọ̀. Ó fi àwọn ará Júù ṣe ẹlẹ́yà,
Sa: naba: la: de da ninia Yu dunu da moilai gagosu gagobe amo nababeba: le, e da ninima ougili bagadewane lasogole oufesega: su.
2 ó sọ níwájú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ àti níwájú àwọn ọmọ-ogun Samaria pé, “Kí ni àwọn aláìlera Júù wọ̀nyí ń ṣe yìí? Ṣé wọn yóò mú odi wọn padà ni? Ṣé wọn yóò rú ẹbọ ni? Ṣé wọn yóò parí i rẹ̀ lóòjọ́ ni bí? Ṣé wọ́n lè mú òkúta tí a ti sun láti inú òkìtì padà bọ̀ sípò tí ó jóná bí wọ́n ṣe wà?”
E da ea dogolegei dunu odagiaba, amola Samelia dadi gagui dunu odagiaba, amane sia: i, “Goe Yu hahaninisi dunu da adi hamosala: ? Ilia da moilai bu hahamomusa: dawa: bela: ? Ilia Godema gobele salasu hamobeba: le, eso afae amoga hawa: hamosu dagomusa: dawa: bela: ? Amola, ilia da isu laluga nei amoga diasu gagusu gele noga: i hamomusa: dawa: bela: ?”
3 Tobiah ará Ammoni, ẹni tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, wí pé, “Ohun tí wọ́n ń mọ—bí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ lásán bá gùn ún sókè, yóò fọ́ odi òkúta wọn lulẹ̀!”
Doubaia amola da Sa: naba: la: de dafulili lelu. E amane sia: i, “Mae dawa: ma! Ilia gagoi noga: i gagomu da hamedei! Fogisi fonobahadi da ilia gagoi amo fuli fasimusa: defele ba: mu,” e oufesega: ne amane sia: i.
4 Gbọ́ ti wa, Ọlọ́run wa, nítorí àwa di ẹni ẹ̀gàn. Dá ẹ̀gàn wọn padà sórí ara wọn. Kí o sì fi wọ́n fún ìkógun ní ilẹ̀ ìgbèkùn.
Amo sia: nababeba: le, na da Godema sia: ne gadoi amane, “Gode! Dia ilia oufesega: su nabima! Ilia oufesega: su amo ilima sinidigima! Di da eno dunu ilia liligi wamolama: ne yolesima. Amola ha lai dunu da ili se dabe hamoma: ne, sedaga sogega oule masa: ma.
5 Má ṣe bo ẹ̀bi wọn tàbí wẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wọn nù kúrò níwájú rẹ, nítorí wọ́n mú ọ bínú níwájú àwọn ọ̀mọ̀lé.
Ilia wadela: i hou mae gogolema: ne olofoma. Bai ilia da ninia moilai gagosu hawa: hamonanoba, ilia da ninima lasogole oufesega: lala.”
6 Bẹ́ẹ̀ ni àwa mọ odi náà títí gbogbo rẹ̀ fi dé ìdajì gíga rẹ̀, nítorí àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an wọn.
Amalalu, ninia da gagoi amo bu gagolalu. Fonobahadi hedolowane ninia da gagolalu damana yolei defei amoga doaga: i. Bai dunu ilia da hawa: hamomu hanai galu.
7 Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati, Tobiah, àwọn ará Arabia, ará Ammoni, àti àwọn ènìyàn Aṣdodu gbọ́ pé àtúnṣe odi Jerusalẹmu ti ga dé òkè àti pé a ti mọ àwọn ibi tí ó yá dí, inú bí wọn gidigidi.
Sa: naba: la: de, Doubaia, A:la: be soge dunu, A:mone soge dunu amola A: siedode soge dunu da ninia hehenane Yelusaleme gagoi gagolalebe amola dibi amo gagoi ganodini nini ga: simusa: ahoanebe amo nababeba: le, ilia da ougi bagade ba: i.
8 Gbogbo wọn jọ gbìmọ̀ pọ̀ láti wá bá Jerusalẹmu jà àti láti dìde wàhálà sí í.
Amaiba: le, ilia da Yelusaleme amoga doagala: musa: amola ninia hawa: hamoi wadela: musa: sia: dasu.
9 Ṣùgbọ́n àwa gbàdúrà sí Ọlọ́run wa, a sì yan olùṣọ́ ọ̀sán àti ti òru láti kojú ìhàlẹ̀ yìí.
Be ninia da ninia Godema sia: ne gadosu. Amola ninia da eso amola gasi ganodini, sosodo aligisu dunu ili liligi noga: le ouligima: ne, ilegei dagoi.
10 Lákòókò yìí, àwọn ènìyàn Juda wí pé, “Agbára àwọn òṣìṣẹ́ ti dínkù, àlàpà púpọ̀ ni ó wà tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi le è mọ odi náà.”
Yuda dunu da agoane gesami hea: su, “Ninia gisasu liligi da dioi bagade, amola gisabeba: le ninia da gasa hamedesa. Wadela: i isu ninia gisawene, gaguli ahoa da gilisidafa. Amaiba: le, ninia da moilai gagoi wali eso habodane gaguma: bela: ?”
11 Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ọ̀tá wa wí pé, “Kí wọn tó mọ̀ tàbí kí wọn tó rí wa, àwa yóò ti dé àárín wọn, a ó sì pa wọ́n, a ó sì dá iṣẹ́ náà dúró.”
Ninima ha lai dunu da sia: dasu amo ninia Yu dunu da ilia hamobe da hame dawa: iyale ilia dawa: i. Ilia da ninima hedolo doagala: loba, nini huluane medole legele amola ninia hawa: hamosu hedofamusa: dawa: i.
12 Nígbà náà ni àwọn Júù tí ó ń gbé ní ẹ̀gbẹ́ wọn wá sọ fún wa ní ìgbà mẹ́wàá pé, “Ibikíbi tí ẹ̀yin bá padà sí, wọn yóò kọlù wá.”
Be eso bagohame amoga, Yu dunu amo da ninia ha lai dunu gilisisu ganodini esalu, amo da ninima misini, amo ha lai sia: dasu ninima sisasu olelei.
13 Nítorí náà mo dá ènìyàn díẹ̀ dúró níbi tí ó rẹlẹ̀ jù lẹ́yìn odi ní ibi gbangba, mo fi wọ́n síbẹ̀ nípa àwọn ìdílé wọn, pẹ̀lú àwọn idà wọn, àwọn ọ̀kọ̀ wọn àti àwọn ọrun wọn.
Amaiba: le na da dunu ilima gegesu gobihei, goge agei amola dadi, amo gegesu liligi ilima i. Amola ilia fi afae afae amo gagoi hame gagoi dagoi sogebi amoga sosodo aligima: ne sia: i.
14 Lẹ́yìn ìgbà tí mo wo àwọn nǹkan yíká, mo dìde mo sì wí fún àwọn ọlọ́lá àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù u wọn. Ẹ rántí Olúwa, ẹni tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, kí ẹ sì jà fún àwọn arákùnrin yín, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, àwọn ìyàwó yín àti àwọn ilé yín.”
Na ba: loba da dunu da bagadewane da: i dioi. Amaiba: le, na da ilia ouligisu dunu amola ouligisu hina dunu ilima amane sia: i, “Dilia ha lai dunu amoba: le mae beda: ma. Hina Gode da gasa bagadedafa amola osobo bagade dunu huluane da ema beda: sa. Amo dawa: sea, dilia fi dunu, dilia mano, dilia uda amola dilia diasu amo gaga: ma: ne gegema.”
15 Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ pé àwa ti mọ èrò wọn àti wí pé Ọlọ́run ti bà á jẹ́, gbogbo wa padà sí ibi odi, ẹnìkọ̀ọ̀kan sí ibi iṣẹ́ tirẹ̀.
Fa: no, ninia ha lai dunu da ninia da ilia doagala: musa: sia: dasu nabi dagoi, amo ilia da nabi. Gode da ilia wadela: i logo ga: i dagoi, amo ilia da dawa: i. Amalalu, ninia huluane da gagoi bu gagomusa: , amoga buhagi.
16 Láti ọjọ́ náà lọ, ìdajì àwọn ènìyàn ń ṣe iṣẹ́ náà, nígbà tí àwọn ìdajì tókù múra pẹ̀lú ọ̀kọ̀, asà, ọrun àti ìhámọ́ra. Àwọn ìjòyè sì pín ara wọn sẹ́yìn gbogbo ènìyàn Juda.
Amo esoga amola fa: no, na hawa: hamosu dunu eno dogoa mogili da gegesu liligi gaguli amola da: igene ga: ne, ninia ha lai dunu mabeale sosodo ouligili oulelu, amola eno mogili da gagoi gagomusa: hawa: hamosu. Amola ouligisu dunu da dunu huluane bagadewane fuligala: su.
17 Àwọn ẹni tí ó ń mọ odi. Àwọn tí ń ru àwọn ohun èlò ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú ọwọ́ kan, wọ́n sì fi ọwọ́ kejì di ohun ìjà mú,
Be hawa: hamonanu dunu amola liligi gaguli ahoasu dunu da agoane hamosu. Ilia da lobo la: idi amoga dadi gagui amola lobo eno la: idi amoga hawa: hamosu.
18 olúkúlùkù àwọn ọ̀mọ̀lé fi idà wọn sí ẹ̀gbẹ́ wọn bí wọ́n ṣe ń ṣiṣẹ́. Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí ń fọn ìpè dúró pẹ̀lú mi.
Amola dunu da gagosu hawa: hamonoba, ilia huluane gegesu gobihei bagade bulua salawane hawa: hamonanu. Amola dunu amo da “biugale” wele sia: su liligi ouligisu da ani dafulili aligi.
19 Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Iṣẹ́ náà fẹ̀ ó sì pọ̀, a sì ti jìnnà sí ara wa púpọ̀ lórí odi.
Na da dunu amola ilia ouligisu dunu ilima amane sia: i, “Dilia hawa: hamosu sogebi da bagadedafa amola dilia hisu hisuya hawa: hamonana.
20 Níbikíbi tí ẹ bá ti gbọ́ ohùn ìpè, ẹ da ara pọ̀ mọ́ wa níbẹ̀. Ọlọ́run wa yóò jà fún wa!”
Dilia ‘biugale’ wele sia: su nabasea, nama gilisila misa. Amola ninia Gode da nini fidili gegemu,” na amane sia: i.
21 Bẹ́ẹ̀ ni àwa ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú àwọn ìdajì ènìyàn tí ó di ọ̀kọ̀ mú, láti òwúrọ̀ kùtùkùtù títí di ìgbà tí ìràwọ̀ yóò fi yọ.
Amaiba: le, eso huluane hadigibi galu, dunu mogili da hawa: hamonanea, mogili da gegemusa: oulelu. Amalalu, daeya gasili gasumuni aligibiba: le fisi.
22 Ní ìgbà náà mo tún sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Jẹ́ kí olúkúlùkù ènìyàn àti olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ dúró ní Jerusalẹmu ní òru, nítorí kí wọn le jẹ́ ẹ̀ṣọ́ fún wa ní òru, kí wọn sì le ṣe iṣẹ́ ní ọ̀sán.”
Amo esoga, ouligisu dunu amo da Yelusaleme moilai amo ganodini ouligilaleawane hadigima: ne na da sia: i dagoi. Bai ninia da gilisili esoga hawa: hamomu amola gasia moilai amo sosodo aligimusa: dawa: i.
23 Bẹ́ẹ̀ ni èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi àti àwọn ẹ̀ṣọ́ tí ó wà pẹ̀lú mi kò bọ́ aṣọ wa, olúkúlùkù wa ní ohun ìjà tirẹ̀, kódà nígbà tí wọ́n bá ń lọ pọn omi.
Na, na ouligisu dunu, dadi gagui dunu amola hawa: hamosu dunu, ninia golaloba, abula sali mae gisa: le amowane golasu amola ninia dadi amola gegesu liligi loboga gaguiwane golasu.

< Nehemiah 4 >