< Nehemiah 3 >

1 Eliaṣibu olórí àlùfáà àti àwọn àlùfáà arákùnrin rẹ̀ lọ ṣiṣẹ́, wọ́n sì tún ibodè Àgùntàn mọ. Wọ́n yà á sí mímọ́, wọ́n sì gbé ìlẹ̀kùn dúró sí ibi tí ó yẹ, wọ́n mọ ọ́n títí dé ilé ìṣọ́ ọgọ́rùn-ún, èyí tí wọ́n yà sí mímọ́ títí dé ilé ìṣọ́ gíga Hananeli.
Niongak’ amy zao t’i Eliasibe rekets’ o rahalahi’e mpisoroñeo, le niranjie’ iareo i lalambein’ Añondriy; navahe’ iereo naho natroa’ iareo o lala’eo; navahe’ iareo pak’am-pitala­kesañ’ abo’ i Meà eo, sikal’ amy fita­lakesañabo’ i Kanàneley.
2 Àwọn ọkùnrin Jeriko sì mọ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, Sakkuri ọmọ Imri sì mọ ní ẹ̀gbẹ́ àwọn ọkùnrin Jeriko.
Nifañefetse am’ iereo o nte-Ierikoo t’ie namboatse; le nioza am’ iereo ty namboare’ i Zakore, ana’ Imrý.
3 Àwọn ọkùnrin Senaa ni wọ́n mọ ibodè ẹja. Wọ́n kún ọ̀pọ̀ ìgbéró rẹ̀, wọ́n sì gbé ìlẹ̀kùn rẹ̀, ìdábùú ìlẹ̀kùn àti àwọn ìdè e rẹ̀ sí ààyè e wọn.
Nandranjy i lalam­beim-piañey o ana’ i Hasenào, le hene namboare’ iereo o faha’eo naho nampitroatse o lala’eo naho o tolà’eo vaho o sikada’eo.
4 Meremoti ọmọ Uriah, ọmọ Hakosi tún èyí tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ẹ wọn mọ. Ẹni tí ó tún wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni Meṣullamu ọmọ Berekiah, ọmọ Meṣesabeli tún èyí ti ó wà ní ẹ̀gbẹ́ wọn mọ. Bákan náà ni ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, Sadoku ọmọ Baanah náà tún odi mọ.
Nanonjohy iareo ty namboare’ i Meremote, ana’ i Oriià, ana’ i Hakotse. Le nifanoiñe am’ iereo ty namboare’ i Mesolame, ana’ i Bere­kià, ana’ i Mesezabele. Le nifanoiñ’ am’ iareo ty namboare’ i Tsadoke, ana’ i Baanà.
5 Èyí tí ó tún wà ní ẹ̀gbẹ́ wọn ni àwọn ọkùnrin Tekoa tún mọ, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́lá kò ṣe àtìlẹ́yìn fún iṣẹ́ náà lábẹ́ àwọn olórí wọn.
Nañorike iereo o nte-Tekoào, le namboatse, fe tsy najò’ o roandria’ iareoo amy tolon-draha’ i Talèy ty fititia’ iareo.
6 Jehoida ọmọ Pasea àti Meṣullamu ọmọ Besodeiah ni wọ́n tún ẹnu ibodè àtijọ́ ṣe. Wọ́n kún bíìmù rẹ̀, wọ́n ri àwọn ìlẹ̀kùn rẹ̀, àwọn ìdábùú ìlẹ̀kùn àti àwọn ìdè rẹ̀ sí ààyè wọn.
Le namboare’ Ioiadà, ana’ i Paseà naho i Mesolàme, ana’ i Besodeià i lalambei’ i rova haehaey; napeta’ iareo o faha’eo, le natroa’ iareo o lala’eo naho o tolà’eo vaho o sikada’eo.
7 Lẹ́yìn in wọn ni àtúnṣe tún wà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọkùnrin Gibeoni àti Mispa; Melatiah ti Gibeoni àti Jadoni ti Meronoti; àwọn ibi tí ó wà lábẹ́ àṣẹ baálẹ̀ agbègbè Eufurate.
Nifanoiñ’ am’ iereo ty namboare’ i Melatià nte-Gibone naho Iadone nte-Merenote naho o nte-Giboneo vaho o nte-Mitspào, nimpitoroñe o mpiami’ bein-tanañe alafe’ i sakay atoio.
8 Usieli ọmọ Harhiah, ọ̀kan lára àwọn alágbẹ̀dẹ wúrà, túnṣe àtúnṣe èyí tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀; àti Hananiah, ọ̀kan lára àwọn tí ó ń ṣe tùràrí, túnṣe àtúnṣe èyí tí ó tún tẹ̀lé e. Wọ́n mú Jerusalẹmu padà bọ̀ sípò títí dé Odi gbígbòòrò.
Nifanoiñ’ ama’e ty namboare’ i Oziele, ana’ i Karhaià, amo mpanefe volamenao, le nanonjohy aze ty namboare’ i Kananià, ana’ o mpanao rano-mañitseo, le nihafatrare’ iereo t’Ierosalaime pak’ amy kijoly mangada­gadañey.
9 Refaiah ọmọ Huri, alákòóso ìdajì agbègbè Jerusalẹmu, tún èyí tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀ ṣe.
Nanonjohy aze namboatse t’i Refaià ana’ i Kore, ty mpifele’ ty vakim-pifehea’ Ierosalaime.
10 Ní ẹ̀gbẹ́ èyí Jedaiah ọmọ Haramafu tún èyí tí ó wà ní ọ̀ọ́kán ilé rẹ̀ mọ, Hattusi ọmọ Haṣbneiah sì tún tí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ mọ.
Nanonjohy aze namboatse t’Iedaià ana’ i Karomafe, tandrife’ i anjomba’ey. Le nanonjohy aze namboatse t’i Katose ana’ i Kasab­neà.
11 Malkiah ọmọ Harimu àti Haṣubu ọmọ Pahati-Moabu tún ẹ̀gbẹ́ kejì ṣe àti ilé ìṣọ́ ìléru.
Le namboare’ i Malkià, ana’ i Karime naho i Kasobe, ana’ i Pakate-moabe, ty fange’e raike vaho i fitalakesañ’ abon-toñakey.
12 Ṣallumu ọmọ Halloheṣi, alákòóso ìdajì agbègbè Jerusalẹmu tún ti ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ mọ pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn ọmọbìnrin rẹ̀.
Nanonjohy aze namboatse t’i Salome, ana’ i Halokese, mpifehe’ ty vakim-pifehea’ Ierosalaime, ie naho o anak’ ampela’eo.
13 Ibodè àfonífojì ni Hanuni àti àwọn ará Sanoa tún mọ. Wọ́n tún un kọ́, wọ́n ri àwọn ìlẹ̀kùn àti àwọn ìdè rẹ̀ sí ààyè rẹ̀. Wọ́n sì tún tún ẹgbẹ̀rún kan ìgbọ̀nwọ́ odi mọ títí dé ẹnu ibodè ààtàn.
Namboatse i lalambeim-bavataney t’i Kanone naho o nte-Zanoakeo; niranjie’ iereo naho natroa’ iareo o lala’eo, o tolà’eo, o sikada’eo, reketse ty kiho arivo amy kijoliy pak’ an-dalambeim-porompotse eo.
14 Ẹnu ibodè Ààtàn ni Malkiah ọmọ Rekabu, alákòóso agbègbè Beti-Hakeremu tún mọ. Ó tún un mọ, ó sì gbé àwọn ìlẹ̀kùn rẹ̀, àwọn ìdábùú ìlẹ̀kùn àti àwọn ìdè rẹ̀ sí ààyè wọn.
Le namboare’ i Malkià ana’ i Rekabe, mpifehe am-paripari’ i Betehakereme i lalambeim-porompotsey; niranjie’e le najado’e o lala’eo, o tolà’eo vaho o sikada’eo.
15 Ẹnu ibodè orísun ni Ṣalluni Koli-Hose, alákòóso agbègbè Mispa tún mọ. Ó tún ún mọ, ó kan òrùlé e rẹ̀ yíká, ó gbé àwọn ìlẹ̀kùn rẹ̀ àwọn ìdábùú ìlẹ̀kùn àti àwọn idẹ rẹ̀ ró sí ààyè wọn. Ó tún tún odi adágún Siloamu mọ, ní ẹ̀gbẹ́ ọgbà ọba, títí dé àwọn àtẹ̀gùn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ láti ìlú Dafidi.
Le namboare’ i Salome, ana’ i Kolkozè, mpifehe’ ty fifehea’ i Mitspà i lalambein-drano migoangoañey; rinanji’e naho nitafoe’e naho najado’e o lala’eo, o tolà’eo vaho o sikada’eo; naho ty kijolin’ antara’ i Siloake an-golobo’ i mpanjakay, pak’ amy fanongàñe mizotso boak’ an-drova’ i Davidey.
16 Lẹ́yìn in rẹ̀ ni, Nehemiah ọmọ Asbuku, alákòóso ìdajì agbègbè Beti-Suri ṣe àtúnmọ dé ibi ọ̀ọ́kán òdìkejì ibojì Dafidi, títí dé adágún omi àtọwọ́dá àti títí dé ilé àwọn alágbára.
Nanonjohy aze t’i Nekemià, ana’ i Azboke, mpifehe ty vakim-pifehea’ i Bete-tsore, namboatse ampara’ t’ie nifanandrife amo kibori’ i Davideo, pak’ amy antara namboareñey vaho mb’ amy anjombam-panalolahiy.
17 Lẹ́yìn rẹ̀ ni àwọn ará a Lefi, ní abẹ́ ẹ Rehumu ọmọ Bani. Lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀ ni Haṣabiah, alákòóso ìdajì agbègbè Keila ṣe àtúnṣe fún agbègbè tirẹ̀.
Nanonjohy aze namboatse o nte-Levio, i Rekome ana’ i Baný. Nanonjohy aze t’i Kasbià, mpifehe’ ty vakim-pifehea’ i Keilà, namboatse ho a i fifehea’ey.
18 Lẹ́yìn rẹ̀ ni àwọn Lefi arákùnrin wọn ní abẹ́ àkóso Binnui ṣe àtúnṣe, Bafai ọmọ Henadadi, ìjòyè àwọn ìdajì agbègbè Keila.
Nanonjohy aze namboatse o rahalahi’ iareoo, i Bavaý ana’ i Kenadade, ty mpifehe’ ty vakim-pifehea’ i Keilà.
19 Lẹ́yìn rẹ̀ ni Eseri ọmọ Jeṣua, alákòóso Mispa, tún ìbò mìíràn ṣe, láti ibìkan tí ó kojú sí ibi gíga sí ilé-ìhámọ́ra títí dé orígun.
Nanonjohy aze ty namboare’ i Ezere, ana’ Iesòa, mpifehe’ i Mitspà: ty fange’e tandrife’ i fitroarañe mb’ amy fañajam-pialiañey amy fiolahañey mb’eo.
20 Lẹ́yìn rẹ̀ ni Baruku ọmọ Sakkai fi ìtara tún apá mìíràn ṣe, láti orígun dé ẹnu-ọ̀nà ilé Eliaṣibu olórí àlùfáà.
Nanonjohy aze an-kahimbañañe t’i Baroke, ana’ i Zabày: namboatse ty ila’ i fiolahañey pak’ amy lala’ ty anjomba’ i Eliasibe mpisorombeiy.
21 Lẹ́yìn rẹ̀ ni, Meremoti ọmọ Uriah, ọmọ Hakosi tún apá mìíràn ṣe, láti ẹnu-ọ̀nà ilé Eliaṣibu títí dé òpin rẹ̀.
Nanonjohy aze t’i Meremote, ana’ i Oriià, ana’ i Hakotse, namboatse ty fange tovo’e boak’ an-dala’ i Eliasibey pak’ am-para’ i anjomba’ i Eliasibey.
22 Àtúnṣe tí a tún túnṣe lẹ́yìn rẹ̀ ní àwọn àlùfáà ní àyíká agbègbè túnṣe.
Nanonjohy aze namboatse o mpisoroñeo, ondaty nte-montoñeo.
23 Lẹ́yìn wọn ni Benjamini àti Haṣubu tún èyí ti iwájú ilé wọn ṣe; lẹ́yìn wọn ni, Asariah ọmọ Maaseiah ọmọ Ananiah tún ti ẹ̀gbẹ́ ilé rẹ̀ ṣe.
Nanonjohy aze t’i Beniamine naho i Kasobe namboatse tandrife ty anjomba’ iareo eo. Nanonjohy iareo t’i Azarià ana’ i Maaseià ana’ i Ananià namboatse añ’ ila’ i anjomba’ey.
24 Lẹ́yìn rẹ̀ ni Binnui ọmọ Henadadi tún apá mìíràn ṣe, láti ilé Asariah dé orígun àti kọ̀rọ̀,
Nanonjohy aze t’i Binoý ana’ i Kenadade, namboatse ty fange tovo’e boak’ añ’ anjomba’ i Aza­rià ampara’ i fiolahañey pak’ an-kotso’e eo.
25 àti Palali ọmọ Usai tún òdìkejì orígun ṣe àti ilé ìṣọ́ tí ó yọ sóde láti ibi gíga ní ẹ̀gbẹ́ ààfin ọba ti òkè lẹ́gbẹ̀ẹ́ agbègbè àwọn olùṣọ́. Lẹ́yìn rẹ̀ ni, Pedaiah ọmọ Paroṣi
Le i Palale ana’ i Ozay, tandrife i fiolahañey naho i fitalakesañ’ abo miboak’ ami’ty anjomba ambone’ i mpanjakaiy, añ’ila’ ty kiririsam-porozò eo. Nanonjohy aze t’i Pedaià ana’ i Parose.
26 àti àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili tí ó ń gbé ní òkè Ofeli ṣe àtúnṣe títí dé ibi ọ̀kánkán òdìkejì ibodè omi sí ìhà ìlà-oòrùn àti ilé ìṣọ́ tí ó yọ sóde.
O mpitoroñ’ anjomban’ Añahare nimoneñe e Ofeleo, ty namboatse tandrife ty lalambein-drano maniñana naho i fitalakesañ’ abo maningìy.
27 Lẹ́yìn wọn ni àwọn ènìyàn Tekoa tún apá mìíràn ṣe, láti ilé ìṣọ́ ńlá tí ó yọ sóde títí dé ògiri Ofeli.
Nanonjohy iareo, namboare’ o nte-Tekoao ty fange’e tandrife i fitalakesañ’ abo jabajaba maningìy, pak’ amy kijoli’ i Ofeley.
28 Àwọn àlùfáà ni ó ṣe àtúnṣe òkè ibodè ẹṣin ṣe, ẹnìkọ̀ọ̀kan ní iwájú ilé e rẹ̀.
Ambone’ i lalam-bein-tsoavalay ty namboare’ o mpisoroñeo, songa tandrife ty anjomba’e.
29 Lẹ́yìn wọn, Sadoku ọmọ Immeri tún ọ̀kánkán òdìkejì ilé rẹ̀ ṣe. Lẹ́yìn rẹ̀ ni Ṣemaiah ọmọ Ṣekaniah, olùṣọ́ ibodè ìhà ìlà-oòrùn ṣe àtúnṣe.
Le nañorike iareo namboatse tandrife i anjomba’ey t’i Tsadoke ana’ Imere. Nanonjohy aze ty namboare’ i Semaià ana’ i Sekanià, mpañambeñe i lalam-bey atiñanañey.
30 Lẹ́yìn rẹ̀ ni, Hananiah ọmọ Ṣelemiah, àti Hanuni ọmọ ẹ̀kẹfà Salafi, tún apá ibòmíràn ṣe. Lẹ́yìn wọn ni, Meṣullamu ọmọ Berekiah tún ọ̀kánkán òdìkejì ibùgbé ẹ̀ ṣe.
Nanonjohy aze namboatse ty fange tovo’e t’i Kananià ana’ i Selemià naho i Kanone ty ana-dahy fah’ene’ i Tsalafe. Nanonjohy eo t’i Mesola­me, ana’ i Bere­kià namboatse tandrife i akiba’ey.
31 Lẹ́yìn in rẹ̀ ni Malkiah, ọ̀kan nínú àwọn alágbẹ̀dẹ wúrà ṣe àtúnṣe títí dé ilé àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn oníṣòwò, ní ọ̀kánkán òdìkejì ibodè àyẹ̀wò títí dé yàrá òkè kọ̀rọ̀;
Nanonjohy aze t’i Malakià, raik’ amo mpanefe volamenao, namboatse pak’amy fange’ o mpitoroñ’ anjombao naho o mpanao balikeoy, aolo’ i lalam-beim-pisavañe eo pak’ amy efetse ambone’ i kotsokeiy.
32 àti láàrín yàrá òkè kọ̀rọ̀ àti ibodè àgùntàn ni àwọn alágbẹ̀dẹ wúrà àti àwọn oníṣòwò túnṣe.
Le namboare’ o mpanefe volamenao naho o mpanao balikeo ty añivo’ i efetse ambone’ i kotsokeiy pak’ amy lalambein’ añondriy.

< Nehemiah 3 >