< Nehemiah 3 >

1 Eliaṣibu olórí àlùfáà àti àwọn àlùfáà arákùnrin rẹ̀ lọ ṣiṣẹ́, wọ́n sì tún ibodè Àgùntàn mọ. Wọ́n yà á sí mímọ́, wọ́n sì gbé ìlẹ̀kùn dúró sí ibi tí ó yẹ, wọ́n mọ ọ́n títí dé ilé ìṣọ́ ọgọ́rùn-ún, èyí tí wọ́n yà sí mímọ́ títí dé ilé ìṣọ́ gíga Hananeli.
Eliasib donc, le grand Sacrificateur se leva, avec ses frères les sacrificateurs, et ils rebâtirent la porte du bercail, laquelle ils sanctifièrent, et ils y posèrent ses portes, et ils la sanctifièrent jusqu'à la tour de Méah, jusqu'à la tour de Hananéël.
2 Àwọn ọkùnrin Jeriko sì mọ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, Sakkuri ọmọ Imri sì mọ ní ẹ̀gbẹ́ àwọn ọkùnrin Jeriko.
Et à son côté rebâtirent les gens de Jérico; et à côté d'eux Zaccur, fils d'Imri, rebâtit.
3 Àwọn ọkùnrin Senaa ni wọ́n mọ ibodè ẹja. Wọ́n kún ọ̀pọ̀ ìgbéró rẹ̀, wọ́n sì gbé ìlẹ̀kùn rẹ̀, ìdábùú ìlẹ̀kùn àti àwọn ìdè e rẹ̀ sí ààyè e wọn.
Et les enfants de Sénaa rebâtirent la porte des poissons, laquelle ils planchéièrent, et y mirent ses portes, ses serrures et ses barres.
4 Meremoti ọmọ Uriah, ọmọ Hakosi tún èyí tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ẹ wọn mọ. Ẹni tí ó tún wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni Meṣullamu ọmọ Berekiah, ọmọ Meṣesabeli tún èyí ti ó wà ní ẹ̀gbẹ́ wọn mọ. Bákan náà ni ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, Sadoku ọmọ Baanah náà tún odi mọ.
Et à leur côté répara Mérémoth, fils d'Urija, fils de Kots; et à leur côté répara Mésullam, fils de Bérecia, fils de Mésézabéël, et à leur côté répara Tsadok, fils de Bahana.
5 Èyí tí ó tún wà ní ẹ̀gbẹ́ wọn ni àwọn ọkùnrin Tekoa tún mọ, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́lá kò ṣe àtìlẹ́yìn fún iṣẹ́ náà lábẹ́ àwọn olórí wọn.
Et à leur côté réparèrent les Tékohites; mais les plus considérables d'entre eux ne se rangèrent point à l'œuvre de leur Seigneur.
6 Jehoida ọmọ Pasea àti Meṣullamu ọmọ Besodeiah ni wọ́n tún ẹnu ibodè àtijọ́ ṣe. Wọ́n kún bíìmù rẹ̀, wọ́n ri àwọn ìlẹ̀kùn rẹ̀, àwọn ìdábùú ìlẹ̀kùn àti àwọn ìdè rẹ̀ sí ààyè wọn.
Et Jéhojadah, fils de Paséah, et Mésullam, fils de Bésodia, réparèrent la porte vieille, laquelle ils planchéièrent, et ils y mirent ses portes, ses serrures et ses barres.
7 Lẹ́yìn in wọn ni àtúnṣe tún wà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọkùnrin Gibeoni àti Mispa; Melatiah ti Gibeoni àti Jadoni ti Meronoti; àwọn ibi tí ó wà lábẹ́ àṣẹ baálẹ̀ agbègbè Eufurate.
Et à leur côté réparèrent Mélatia Gabaonite, et Jadon Méronothite, de Gabaon et de Mitspa, vers le siège du Gouverneur de deçà le fleuve.
8 Usieli ọmọ Harhiah, ọ̀kan lára àwọn alágbẹ̀dẹ wúrà, túnṣe àtúnṣe èyí tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀; àti Hananiah, ọ̀kan lára àwọn tí ó ń ṣe tùràrí, túnṣe àtúnṣe èyí tí ó tún tẹ̀lé e. Wọ́n mú Jerusalẹmu padà bọ̀ sípò títí dé Odi gbígbòòrò.
Et à côté de ce [siège] répara Huziël, fils de Harhaja, d'[entre] les orfèvres; et à son côté répara Hanania fils de Harakkahim; et ainsi ils relevèrent Jérusalem jusqu'à la muraille large.
9 Refaiah ọmọ Huri, alákòóso ìdajì agbègbè Jerusalẹmu, tún èyí tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀ ṣe.
Et à leur côté répara Réphaja, fils de Hur, capitaine d'un demi-quartier de Jérusalem;
10 Ní ẹ̀gbẹ́ èyí Jedaiah ọmọ Haramafu tún èyí tí ó wà ní ọ̀ọ́kán ilé rẹ̀ mọ, Hattusi ọmọ Haṣbneiah sì tún tí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ mọ.
Et à leur côté répara Jédaja, fils de Harumaph, même à l'endroit de sa maison; et à son côté répara Hattus, fils de Hasabnéja.
11 Malkiah ọmọ Harimu àti Haṣubu ọmọ Pahati-Moabu tún ẹ̀gbẹ́ kejì ṣe àti ilé ìṣọ́ ìléru.
Et Malkija, fils de Harim, et Hasub, fils de Pahath-Moab, en réparèrent autant, et même la tour des fours.
12 Ṣallumu ọmọ Halloheṣi, alákòóso ìdajì agbègbè Jerusalẹmu tún ti ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ mọ pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn ọmọbìnrin rẹ̀.
Et à leur côté Sallum, fils de Lobès, capitaine de [l'autre] demi-quartier de Jérusalem, répara, lui et ses filles.
13 Ibodè àfonífojì ni Hanuni àti àwọn ará Sanoa tún mọ. Wọ́n tún un kọ́, wọ́n ri àwọn ìlẹ̀kùn àti àwọn ìdè rẹ̀ sí ààyè rẹ̀. Wọ́n sì tún tún ẹgbẹ̀rún kan ìgbọ̀nwọ́ odi mọ títí dé ẹnu ibodè ààtàn.
Et Hanun et les habitants de Zanoah réparèrent la porte de la vallée, ils la rebâtirent, et mirent ses portes, ses serrures, et ses barres, et [ils bâtirent] mille coudées de muraille, jusqu'à la porte de la fiente,
14 Ẹnu ibodè Ààtàn ni Malkiah ọmọ Rekabu, alákòóso agbègbè Beti-Hakeremu tún mọ. Ó tún un mọ, ó sì gbé àwọn ìlẹ̀kùn rẹ̀, àwọn ìdábùú ìlẹ̀kùn àti àwọn ìdè rẹ̀ sí ààyè wọn.
Et Malkija, fils de Réchab, capitaine du quartier de Beth-Kérem, répara la porte de la fiente; il la rebâtit, et mit ses portes, ses serrures et ses barres.
15 Ẹnu ibodè orísun ni Ṣalluni Koli-Hose, alákòóso agbègbè Mispa tún mọ. Ó tún ún mọ, ó kan òrùlé e rẹ̀ yíká, ó gbé àwọn ìlẹ̀kùn rẹ̀ àwọn ìdábùú ìlẹ̀kùn àti àwọn idẹ rẹ̀ ró sí ààyè wọn. Ó tún tún odi adágún Siloamu mọ, ní ẹ̀gbẹ́ ọgbà ọba, títí dé àwọn àtẹ̀gùn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ láti ìlú Dafidi.
Et Sallum, fils de Col-Hoze, capitaine du quartier de Mitspa, répara la porte de la fontaine; il la rebâtit, et la couvrit, et mit ses portes, ses serrures, et ses barres; et [il répara aussi] la muraille de l'étang de Sélah, tirant vers le jardin du Roi, et jusqu'aux degrés qui descendent de la Cité de David.
16 Lẹ́yìn in rẹ̀ ni, Nehemiah ọmọ Asbuku, alákòóso ìdajì agbègbè Beti-Suri ṣe àtúnmọ dé ibi ọ̀ọ́kán òdìkejì ibojì Dafidi, títí dé adágún omi àtọwọ́dá àti títí dé ilé àwọn alágbára.
Après lui répara Néhémie, fils d'Hazbuk, capitaine du demi-quartier de Beth-Tsur, jusqu'à l'endroit des sépulcres de David, et jusqu'à l'étang qui avait été refait, et jusqu'à la maison des forts.
17 Lẹ́yìn rẹ̀ ni àwọn ará a Lefi, ní abẹ́ ẹ Rehumu ọmọ Bani. Lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀ ni Haṣabiah, alákòóso ìdajì agbègbè Keila ṣe àtúnṣe fún agbègbè tirẹ̀.
Après lui réparèrent les Lévites, Néhum, fils de Bani; et à son côté répara Hasabja, capitaine du demi-quartier de Kéhila, pour ceux de son quartier.
18 Lẹ́yìn rẹ̀ ni àwọn Lefi arákùnrin wọn ní abẹ́ àkóso Binnui ṣe àtúnṣe, Bafai ọmọ Henadadi, ìjòyè àwọn ìdajì agbègbè Keila.
Après lui réparèrent leurs frères, [savoir], Bavvaï, fils de Hénadad, capitaine de [l'autre] demi-quartier de Kéhila.
19 Lẹ́yìn rẹ̀ ni Eseri ọmọ Jeṣua, alákòóso Mispa, tún ìbò mìíràn ṣe, láti ibìkan tí ó kojú sí ibi gíga sí ilé-ìhámọ́ra títí dé orígun.
Et à son côté Héser, fils de Jésuah, capitaine de Mitspa, en répara autant, à l'endroit par où l'on monte à l'arsenal de l'encoignûre.
20 Lẹ́yìn rẹ̀ ni Baruku ọmọ Sakkai fi ìtara tún apá mìíràn ṣe, láti orígun dé ẹnu-ọ̀nà ilé Eliaṣibu olórí àlùfáà.
Après lui Baruch, fils de Zaccaï, prit courage, et en répara autant, depuis l'encoignûre jusqu'à l'entrée de la maison d'Eliasib, grand Sacrificateur.
21 Lẹ́yìn rẹ̀ ni, Meremoti ọmọ Uriah, ọmọ Hakosi tún apá mìíràn ṣe, láti ẹnu-ọ̀nà ilé Eliaṣibu títí dé òpin rẹ̀.
Après lui Mérémoth, fils d'Urija, fils de Kots, en répara autant, depuis l'entrée de la maison d'Eliasib, jusqu'au bout de la maison d'Eliasib.
22 Àtúnṣe tí a tún túnṣe lẹ́yìn rẹ̀ ní àwọn àlùfáà ní àyíká agbègbè túnṣe.
Et après lui réparèrent les Sacrificateurs, habitants de la campagne.
23 Lẹ́yìn wọn ni Benjamini àti Haṣubu tún èyí ti iwájú ilé wọn ṣe; lẹ́yìn wọn ni, Asariah ọmọ Maaseiah ọmọ Ananiah tún ti ẹ̀gbẹ́ ilé rẹ̀ ṣe.
Après eux, Benjamin et Hasub réparèrent à l'endroit de leur maison. Après lesquels, Hazaria, fils de Mahaséja, fils d'Hanania, répara auprès de sa maison.
24 Lẹ́yìn rẹ̀ ni Binnui ọmọ Henadadi tún apá mìíràn ṣe, láti ilé Asariah dé orígun àti kọ̀rọ̀,
Après lui, Binnuï, fils de Henadad, en répara autant, depuis la maison d'Hazaria, jusqu'à l'encoignûre, même jusqu'au coin.
25 àti Palali ọmọ Usai tún òdìkejì orígun ṣe àti ilé ìṣọ́ tí ó yọ sóde láti ibi gíga ní ẹ̀gbẹ́ ààfin ọba ti òkè lẹ́gbẹ̀ẹ́ agbègbè àwọn olùṣọ́. Lẹ́yìn rẹ̀ ni, Pedaiah ọmọ Paroṣi
[Et] Palal, fils d'Uzaï, depuis l'endroit de l'encoignûre, et de la tour, qui sort de la haute maison du Roi, qui est auprès du parvis de la prison. Après lui Pédaja, fils de Parhos.
26 àti àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili tí ó ń gbé ní òkè Ofeli ṣe àtúnṣe títí dé ibi ọ̀kánkán òdìkejì ibodè omi sí ìhà ìlà-oòrùn àti ilé ìṣọ́ tí ó yọ sóde.
Et les Néthiniens, qui demeuraient en Hophel, [réparèrent] vers l'Orient, jusqu'à l'endroit de la porte des eaux, et vers la tour qui sort en dehors.
27 Lẹ́yìn wọn ni àwọn ènìyàn Tekoa tún apá mìíràn ṣe, láti ilé ìṣọ́ ńlá tí ó yọ sóde títí dé ògiri Ofeli.
Après eux, les Tékohites en réparèrent autant, depuis l'endroit de la grande tour qui sort en dehors, jusqu'à la muraille d'Hophel.
28 Àwọn àlùfáà ni ó ṣe àtúnṣe òkè ibodè ẹṣin ṣe, ẹnìkọ̀ọ̀kan ní iwájú ilé e rẹ̀.
Et les Sacrificateurs réparèrent depuis le dessus de la porte des chevaux, chacun à l'endroit de sa maison.
29 Lẹ́yìn wọn, Sadoku ọmọ Immeri tún ọ̀kánkán òdìkejì ilé rẹ̀ ṣe. Lẹ́yìn rẹ̀ ni Ṣemaiah ọmọ Ṣekaniah, olùṣọ́ ibodè ìhà ìlà-oòrùn ṣe àtúnṣe.
Après eux Tsadok, fils d'Immer, répara à l'endroit de sa maison. Et après lui répara Sémahia, fils de Sécania, garde de la porte Orientale.
30 Lẹ́yìn rẹ̀ ni, Hananiah ọmọ Ṣelemiah, àti Hanuni ọmọ ẹ̀kẹfà Salafi, tún apá ibòmíràn ṣe. Lẹ́yìn wọn ni, Meṣullamu ọmọ Berekiah tún ọ̀kánkán òdìkejì ibùgbé ẹ̀ ṣe.
Après lui Hanania, fils de Sélemia, et Hanun le sixième fils de Tsalaph, en réparèrent autant. Après eux, Mésullam, fils de Bérécia, répara à l'endroit de sa chambre.
31 Lẹ́yìn in rẹ̀ ni Malkiah, ọ̀kan nínú àwọn alágbẹ̀dẹ wúrà ṣe àtúnṣe títí dé ilé àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn oníṣòwò, ní ọ̀kánkán òdìkejì ibodè àyẹ̀wò títí dé yàrá òkè kọ̀rọ̀;
Après lui Malkija, fils de Tsoreph, répara jusqu'à la maison des Néthiniens, et des revendeurs, et l'endroit de la porte de Miphkad, et jusqu'à la montée du coin.
32 àti láàrín yàrá òkè kọ̀rọ̀ àti ibodè àgùntàn ni àwọn alágbẹ̀dẹ wúrà àti àwọn oníṣòwò túnṣe.
Et les orfèvres et les revendeurs réparèrent entre la montée du coin et la porte du bercail.

< Nehemiah 3 >