< Nehemiah 2 >

1 Ní oṣù Nisani, ní ogún ọdún ìjọba ọba Artasasta, nígbà tí a gbé wáìnì wá fún un, mo gbé wáìnì náà, mo fi fún ọba, ìbànújẹ́ kò hàn ní ojú mi rí ní iwájú rẹ̀.
We shundaq boldiki, padishah Artaxshashtaning yigirminchi yili Nisan éyi, padishahning aldigha sharab keltürülgenidi; men sharabni élip padishahqa sundum. Buningdin ilgiri men padishahning aldida héchqachan ghemkin körün’gen emes idim.
2 Nítorí náà ni ọba béèrè lọ́wọ́ mi pé, “Èéṣe tí ojú rẹ fi fàro nígbà tí kò rẹ̀ ọ́? Èyí kì í ṣe ohun mìíràn bí kò ṣe ìbànújẹ́ ọkàn.” Ẹ̀rù bà mí gidigidi,
Shuning bilen padishah méningdin: — Birer késiling bolmisa, chiraying némishqa shunche ghemkin körünidu? Könglüngde choqum bir derd bar, déwidi, men intayin qorqup kettim.
3 ṣùgbọ́n mo wí fún ọba pé, “Kí ọba kí ó pẹ́! Èéṣe tí ojú mi ko ṣe ní fàro, nígbà tí ìlú tí a sin àwọn baba mi sí wà ní ahoro, tí a sì ti fi iná run àwọn ibodè rẹ̀?”
Men padishahqa: — Padishahim menggü yashighayla! Ata-bowilirimning qebriliri jaylashqan sheher xarabilikke aylan’ghan, derwaza-qowuqliri köydürüwétilgen tursa, men qandaqmu ghemkin körünmey? — dédim.
4 Ọba wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?” Nígbà náà, ni mo gbàdúrà sí Ọlọ́run ọ̀run,
Padishah méningdin: — Séning néme teliping bar? — dep soriwidi, men asmandiki Xudagha dua qilip,
5 mo sì dá ọba lóhùn pé, “Ti ó bá wu ọba, tí ìránṣẹ́ rẹ bá sì rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí ó rán mi lọ sí ìlú náà ní Juda níbi tí a sin àwọn baba mi nítorí kí èmi lè tún un kọ́.”
andin padishahqa: — Eger padishahimning könglige muwapiq körünse, qulliri özlirining aldida iltipatqa érishken bolsa, méni Yehudiyege ewetken bolsila, ata-bowilirimning qebriliri jaylashqan sheherge bérip, uni yéngiwashtin qurup chiqsam, dédim.
6 Nígbà náà ni ọba, pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀ tí ó jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, bi mí pé, “Báwo ni ìrìnàjò náà yóò ṣe pẹ́ ọ tó, nígbà wo sì ni ìwọ yóò padà?” Ó dùn mọ́ ọba láti rán mi lọ, bẹ́ẹ̀ ni mo dá àkókò kan.
Padishah (shu chaghda xanish padishahning yénida olturatti) mendin: — Sepiringge qanchilik waqit kétidu? Qachan qaytip kélisen? — dep soridi. Shuning bilen padishah méni ewetishni muwapiq kördi; menmu uninggha qaytip kélidighan bir waqitni békittim.
7 Mo sì tún wí fún ọba pé, “Bí ó bá wu ọba, kí ó fún mi ní lẹ́tà sí àwọn baálẹ̀ òkè odò Eufurate kí wọ́n le mú mi kọjá títí èmi yóò fi dé Juda láìléwu.
Men yene padishahtin: — Aliylirigha muwapiq körünse, manga [Efrat] deryasining u qétidiki waliylargha méni taki Yehudiyege barghuche ötkili qoyush toghruluq yarliq xetlirini pütüp bergen bolsila;
8 Kí èmi sì gba lẹ́tà kan lọ́wọ́ fún Asafu, olùṣọ́ igbó ọba, nítorí kí ó lè fún mi ní igi láti fi ṣe àtẹ́rígbà fún ibodè ilé ìṣọ́ tẹmpili àti fún odi ìlú náà àti fún ilé tí èmi yóò gbé?” Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi wà lórí mi, ọba fi ìbéèrè mi fún mi.
We yene padishahliq ormanliqigha qaraydighan Asafqa muqeddes öyge tewe bolghan qel’ening derwaziliri, shuningdek sheherning sépili we özüm turidighan öyge kétidighan limlarni yasashqa kéreklik yaghachlarni manga bérish toghruluqmu bir yarliqni pütüp bergen bolsila, dédim. Xudayimning shepqetlik qoli üstümde bolghachqa, padishah iltipat qilip bularning hemmisini manga berdi.
9 Bẹ́ẹ̀ ni mo lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, mo sì fún wọn ní àwọn lẹ́tà ọba. Ọba sì ti rán àwọn ológun àti àwọn ẹlẹ́ṣin ogun pẹ̀lú mi.
Shuning bilen men deryaning u qétidiki waliylarning yénigha bérip padishahning yarliqlirini tapshurdum. Padishah yene birnechche qoshun serdarliri bilen atliq leshkerlernimu manga hemrah bolushqa orunlashturghanidi.
10 Nígbà tí Sanballati ará Horoni àti Tobiah ará a Ammoni tí wọ́n jẹ́ ìjòyè gbọ́ nípa èyí pé, ẹnìkan wá láti mú ìtẹ̀síwájú bá àlàáfíà àwọn ará Israẹli inú bí wọn gidigidi.
Horonluq Sanballat bilen Ammoniy Tobiya dégen emeldar Israillarning menpeetini izdep adem keptu, dégen xewerni anglap intayin narazi boldi.
11 Mo sì lọ sí Jerusalẹmu, lẹ́yìn ìgbà tí mo dúró níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta.
Men Yérusalémgha kélip üch kün turdum.
12 Mo jáde ní òru pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀. Èmi kò sì sọ fún ẹnìkankan ohun tí Ọlọ́run mi ti fi sí ọkàn mi láti ṣe fún Jerusalẹmu. Kò sí ẹranko kankan pẹ̀lú mi, bí kò ṣe ọ̀kan ṣoṣo tí mo gùn.
Andin kéchisi men we manga hemrah bolghan birnechche adem ornimizdin turduq (men Xudayimning könglümge Yérusalém üchün néme ishlarni qilishni salghanliqi toghrisida héchkimge birer néme démigenidim). Özüm min’gen ulaghdin bashqa héchqandaq ulaghmu almay,
13 Ní òru, mo jáde lọ sí àfonífojì ibodè sí ìhà kànga Jakali àti sí ẹnu ibodè Ààtàn àti ẹnu ibodè rẹ̀ èyí tí ó ti wó odi Jerusalẹmu tí ó lulẹ̀, tí a ti fi iná sun.
kéchisi «Jilgha qowuqi»din chiqip «Ejdiha buliqi»gha qarap méngip, «Tézek qowuqi»gha kélip, Yérusalémning buzuwétilgen sépillirini we köydürüwétilgen qowuq-derwazilirini közdin kechürdum.
14 Nígbà náà ni mo lọ sí ẹnu ibodè orísun àti sí adágún omi ọba, ṣùgbọ́n kò sí ààyè tó fún ẹranko mi láti kọjá;
Yene aldigha méngip «Bulaq qowuqi» bilen «Shahane köl»ge keldim; lékin shu yerde men min’gen ulaghning ötüshike yol bek tar kelgechke,
15 bẹ́ẹ̀ ni mo gòkè àfonífojì ní òru, mo ń wo odi. Ní ìparí, mo padà sẹ́yìn, mo sì tún wọlé láti ibodè àfonífojì.
kéchide men jilgha bilen chiqip sépilni közdin kechürüp chiqtim. Andin yénip «Jilgha qowuqi»din sheherge kirip, öyge qayttim.
16 Àwọn olórí kò mọ ibi tí mo lọ tàbí mọ ohun tí mo ń ṣe, nítorí èmi kò tí ì sọ fún àwọn ará Júù tàbí àwọn àlùfáà tàbí àwọn ọlọ́lá tàbí àwọn ìjòyè tàbí ẹnikẹ́ni mìíràn tí yóò máa ṣe iṣẹ́ náà.
Emeldarlarning héchqaysisi méning nege barghanliqimni we néme qilghanliqimni bilmey qélishti, chünki men ya Yehudiylargha, kahinlargha, ya emir-hakimlargha we yaki bashqa xizmet qilidighanlargha héchnéme éytmighanidim.
17 Nígbà náà ni mo sọ fún wọn pé, “Ṣé ẹ rí wàhálà tí a ni: Jerusalẹmu wà nínú ìparun, ibodè rẹ̀ ni a sì ti fi iná jó. Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tún odi Jerusalẹmu mọ, àwa kò sì ní jẹ́ ẹni ẹ̀gàn mọ́”.
Kéyin men ulargha: — Siler béshimizgha kelgen balayi’apetni, Yérusalémning xarabige aylan’ghanliqini, sépil qowuqlirining köydürüwétilgenlikini kördünglar; kélinglar, hemmimiz haqaretke qéliwermeslikimiz üchün Yérusalémning sépilini qaytidin yasap chiqayli, — dédim.
18 Èmi sì tún sọ fún wọn nípa bí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi ṣe wà lára mi àti ohun tí ọba ti sọ fún mi. Wọ́n dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a bẹ̀rẹ̀ àtúnmọ rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rere yìí.
Men yene ulargha Xudayimning shepqetlik qolining méning üstümde bolghanliqini we padishahning manga qilghan geplirini éytiwidim, ular: — Ornumizdin turup uni yasayli! — déyiship, bu yaxshi ishni qilishqa öz qollirini quwwetlendürdi.
19 Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati ará a Horoni, Tobiah ara olóyè Ammoni àti Geṣemu ará a Arabia gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n fi wá ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n sì fi wá ṣe ẹ̀sín. Wọ́n béèrè pé, “Kí ni èyí tí ẹ ń ṣe yìí? Ṣé ẹ ń ṣọ̀tẹ̀ sí ọba ni?”
Lékin Horonluq Sanballat, xizmetkar Ammoniy Tobiya hem ereb bolghan Geshem bu ishni anglap bizni zangliq qilip mensitmey: — Silerning bu qilghininglar néme ish? Siler padishahqa asiyliq qilmaqchimusiler? — déyishti.
20 Mo dá wọn lóhùn, mo wí fún wọn pé, “Ọlọ́run ọ̀run yóò fún wa ní àṣeyọrí. Àwa ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò bẹ̀rẹ̀ láti tún un mọ, ṣùgbọ́n fún un yin, ẹ̀yin kò ní ìpín tàbí ipa tàbí ẹ̀tọ́ ohunkóhun tí ó jẹ mọ́ ìtàn ní Jerusalẹmu.”
Men ulargha jawab bérip: — Asmanlardiki Xuda bolsa bizni ghelibige érishtüridu we Uning qulliri bolghan bizler qopup qurimiz. Lékin silerning Yérusalémda héchqandaq nésiwenglar, hoququnglar yaki yadnamenglar yoq, — dédim.

< Nehemiah 2 >