< Nehemiah 2 >

1 Ní oṣù Nisani, ní ogún ọdún ìjọba ọba Artasasta, nígbà tí a gbé wáìnì wá fún un, mo gbé wáìnì náà, mo fi fún ọba, ìbànújẹ́ kò hàn ní ojú mi rí ní iwájú rẹ̀.
I månaden Nisan, i Artasastas tjugonde regeringsår, vid ett tillfälle då vin stod framsatt för konungen, tog jag vinet och gav det åt honom. Och jag hade icke förr visat mig sorgsen inför honom;
2 Nítorí náà ni ọba béèrè lọ́wọ́ mi pé, “Èéṣe tí ojú rẹ fi fàro nígbà tí kò rẹ̀ ọ́? Èyí kì í ṣe ohun mìíràn bí kò ṣe ìbànújẹ́ ọkàn.” Ẹ̀rù bà mí gidigidi,
men nu sade konungen till mig: "Varför ser du så sorgsen ut? Du är ju icke sjuk; du måste hava någon hjärtesorg." Då blev jag övermåttan häpen.
3 ṣùgbọ́n mo wí fún ọba pé, “Kí ọba kí ó pẹ́! Èéṣe tí ojú mi ko ṣe ní fàro, nígbà tí ìlú tí a sin àwọn baba mi sí wà ní ahoro, tí a sì ti fi iná run àwọn ibodè rẹ̀?”
Och jag sade till konungen: "Må konungen leva evinnerligen! Skulle jag icke se sorgsen ut, då den stad där mina fäders gravar äro ligger öde och dess portar äro förtärda av eld?"
4 Ọba wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?” Nígbà náà, ni mo gbàdúrà sí Ọlọ́run ọ̀run,
Konungen sade till mig: "Vad är det då du begär?" Då bad jag en bön till himmelens Gud
5 mo sì dá ọba lóhùn pé, “Ti ó bá wu ọba, tí ìránṣẹ́ rẹ bá sì rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí ó rán mi lọ sí ìlú náà ní Juda níbi tí a sin àwọn baba mi nítorí kí èmi lè tún un kọ́.”
och sade till konungen: "Om det så täckes konungen, och om du finner behag i din tjänare, så beder jag att du ville låta mig fara till Juda, till den stad där mina fäders gravar äro, på det att jag åter må bygga upp den."
6 Nígbà náà ni ọba, pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀ tí ó jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, bi mí pé, “Báwo ni ìrìnàjò náà yóò ṣe pẹ́ ọ tó, nígbà wo sì ni ìwọ yóò padà?” Ó dùn mọ́ ọba láti rán mi lọ, bẹ́ẹ̀ ni mo dá àkókò kan.
Då frågade konungen mig, allt under det att drottningen satt vid hans sida: "Huru länge kan din resa räcka, och när kan du komma tillbaka?" Då det nu alltså täcktes konungen att låta mig fara, uppgav jag för honom en bestämd tid.
7 Mo sì tún wí fún ọba pé, “Bí ó bá wu ọba, kí ó fún mi ní lẹ́tà sí àwọn baálẹ̀ òkè odò Eufurate kí wọ́n le mú mi kọjá títí èmi yóò fi dé Juda láìléwu.
Och jag sade till konungen: "Om det så täckes konungen, så må brev givas mig till ståthållarna i landet på andra sidan floden, att de låta mig fara därigenom, till dess jag kommer till Juda,
8 Kí èmi sì gba lẹ́tà kan lọ́wọ́ fún Asafu, olùṣọ́ igbó ọba, nítorí kí ó lè fún mi ní igi láti fi ṣe àtẹ́rígbà fún ibodè ilé ìṣọ́ tẹmpili àti fún odi ìlú náà àti fún ilé tí èmi yóò gbé?” Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi wà lórí mi, ọba fi ìbéèrè mi fún mi.
så ock ett brev till Asaf, uppsyningsmannen över den kungliga skogsparken, att han låter mig få virke för att därmed timra upp portarna till borgen som hör till templet, ävensom virke till stadsmuren, så ock till det hus där jag själv skall hava min bostad." Och konungen beviljade mig detta, eftersom min Guds goda hand var över mig.
9 Bẹ́ẹ̀ ni mo lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, mo sì fún wọn ní àwọn lẹ́tà ọba. Ọba sì ti rán àwọn ológun àti àwọn ẹlẹ́ṣin ogun pẹ̀lú mi.
När jag så kom till ståthållarna i landet på andra sidan floden, gav jag dem konungens brev. Och konungen hade sänt med mig härhövitsmän och ryttare.
10 Nígbà tí Sanballati ará Horoni àti Tobiah ará a Ammoni tí wọ́n jẹ́ ìjòyè gbọ́ nípa èyí pé, ẹnìkan wá láti mú ìtẹ̀síwájú bá àlàáfíà àwọn ará Israẹli inú bí wọn gidigidi.
Men då horoniten Sanballat och Tobia, den ammonitiske tjänstemannen, hörde detta, förtröt det dem högeligen att någon hade kommit för att se Israels barn till godo.
11 Mo sì lọ sí Jerusalẹmu, lẹ́yìn ìgbà tí mo dúró níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta.
När jag sedan hade kommit till Jerusalem och varit där i tre dagar,
12 Mo jáde ní òru pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀. Èmi kò sì sọ fún ẹnìkankan ohun tí Ọlọ́run mi ti fi sí ọkàn mi láti ṣe fún Jerusalẹmu. Kò sí ẹranko kankan pẹ̀lú mi, bí kò ṣe ọ̀kan ṣoṣo tí mo gùn.
stod jag upp om natten jämte några få män, utan att hava omtalat för någon människa vad min Gud ingav mig i hjärtat att göra för Jerusalem; och det djur som jag red på var det enda jag hade med mig.
13 Ní òru, mo jáde lọ sí àfonífojì ibodè sí ìhà kànga Jakali àti sí ẹnu ibodè Ààtàn àti ẹnu ibodè rẹ̀ èyí tí ó ti wó odi Jerusalẹmu tí ó lulẹ̀, tí a ti fi iná sun.
Och jag drog om natten ut genom Dalporten fram emot Drakkällan och Dyngporten och besåg Jerusalems murar, huru de voro nedbrutna, och huru dess portar voro förtärda av eld.
14 Nígbà náà ni mo lọ sí ẹnu ibodè orísun àti sí adágún omi ọba, ṣùgbọ́n kò sí ààyè tó fún ẹranko mi láti kọjá;
Och jag drog vidare till Källporten och till Konungsdammen, men där var det icke möjligt för djuret att komma fram med mig.
15 bẹ́ẹ̀ ni mo gòkè àfonífojì ní òru, mo ń wo odi. Ní ìparí, mo padà sẹ́yìn, mo sì tún wọlé láti ibodè àfonífojì.
Då begav jag mig uppför dalen om natten och besåg muren och vände sedan åter in genom Dalporten och kom så tillbaka.
16 Àwọn olórí kò mọ ibi tí mo lọ tàbí mọ ohun tí mo ń ṣe, nítorí èmi kò tí ì sọ fún àwọn ará Júù tàbí àwọn àlùfáà tàbí àwọn ọlọ́lá tàbí àwọn ìjòyè tàbí ẹnikẹ́ni mìíràn tí yóò máa ṣe iṣẹ́ náà.
Och föreståndarna hade icke fått veta vart jag hade gått, och vad jag ville göra, ty jag hade ännu icke omtalat något för judarna, prästerna, ädlingarna, föreståndarna och de övriga, som skulle få med arbetet att göra.
17 Nígbà náà ni mo sọ fún wọn pé, “Ṣé ẹ rí wàhálà tí a ni: Jerusalẹmu wà nínú ìparun, ibodè rẹ̀ ni a sì ti fi iná jó. Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tún odi Jerusalẹmu mọ, àwa kò sì ní jẹ́ ẹni ẹ̀gàn mọ́”.
Men nu sade jag till dem: "I sen själva i vilken nöd vi äro, huru Jerusalem ligger öde, och huru dess portar äro uppbrända i eld. Välan då, låt oss bygga upp Jerusalems mur, för att vi icke längre må vara till smälek."
18 Èmi sì tún sọ fún wọn nípa bí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi ṣe wà lára mi àti ohun tí ọba ti sọ fún mi. Wọ́n dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a bẹ̀rẹ̀ àtúnmọ rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rere yìí.
Och jag omtalade för dem huru min Guds hand hade varit mig nådig, så ock vad konungen hade lovat mig. Då sade de: "Vi vilja stå upp och bygga." Och de togo mod till sig för det goda verket.
19 Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati ará a Horoni, Tobiah ara olóyè Ammoni àti Geṣemu ará a Arabia gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n fi wá ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n sì fi wá ṣe ẹ̀sín. Wọ́n béèrè pé, “Kí ni èyí tí ẹ ń ṣe yìí? Ṣé ẹ ń ṣọ̀tẹ̀ sí ọba ni?”
Men när horoniten Sanballat och Tobia, den ammonitiske tjänstemannen, och araben Gesem hörde detta, bespottade de oss och visade förakt för oss; och de sade: "Vad är det I gören? Viljen I sätta eder upp mot konungen?"
20 Mo dá wọn lóhùn, mo wí fún wọn pé, “Ọlọ́run ọ̀run yóò fún wa ní àṣeyọrí. Àwa ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò bẹ̀rẹ̀ láti tún un mọ, ṣùgbọ́n fún un yin, ẹ̀yin kò ní ìpín tàbí ipa tàbí ẹ̀tọ́ ohunkóhun tí ó jẹ mọ́ ìtàn ní Jerusalẹmu.”
Då gav jag dem detta svar: "Himmelens Gud skall låta det gå oss väl, och vi, hans tjänare, vilja stå upp och bygga; men I haven ingen del eller rätt eller åminnelse i Jerusalem."

< Nehemiah 2 >