< Nehemiah 2 >

1 Ní oṣù Nisani, ní ogún ọdún ìjọba ọba Artasasta, nígbà tí a gbé wáìnì wá fún un, mo gbé wáìnì náà, mo fi fún ọba, ìbànújẹ́ kò hàn ní ojú mi rí ní iwájú rẹ̀.
I oto zdarzyło się w miesiącu Nisan, w dwudziestym roku króla Artakserksesa, gdy [stało] przed nim wino, że wziąłem [je] i podałem królowi, a nigdy [przedtem] nie byłem taki smutny w jego obecności.
2 Nítorí náà ni ọba béèrè lọ́wọ́ mi pé, “Èéṣe tí ojú rẹ fi fàro nígbà tí kò rẹ̀ ọ́? Èyí kì í ṣe ohun mìíràn bí kò ṣe ìbànújẹ́ ọkàn.” Ẹ̀rù bà mí gidigidi,
Król więc zapytał mnie: Czemu [tak] smutno wyglądasz, skoro nie jesteś chory? Nic innego to jak smutek serca. I bardzo się przeraziłem.
3 ṣùgbọ́n mo wí fún ọba pé, “Kí ọba kí ó pẹ́! Èéṣe tí ojú mi ko ṣe ní fàro, nígbà tí ìlú tí a sin àwọn baba mi sí wà ní ahoro, tí a sì ti fi iná run àwọn ibodè rẹ̀?”
I powiedziałem do króla: Niech król żyje na wieki. Jakże nie mam wyglądać smutno, gdy miasto, dom grobów moich ojców, jest zburzone, a jego bramy pochłonął ogień?
4 Ọba wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?” Nígbà náà, ni mo gbàdúrà sí Ọlọ́run ọ̀run,
Król ponownie zapytał mnie: O co chciałbyś prosić? Modliłem się więc do Boga niebios.
5 mo sì dá ọba lóhùn pé, “Ti ó bá wu ọba, tí ìránṣẹ́ rẹ bá sì rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí ó rán mi lọ sí ìlú náà ní Juda níbi tí a sin àwọn baba mi nítorí kí èmi lè tún un kọ́.”
Potem powiedziałem do króla: Jeśli król uważa [to] za dobre i jeśli twój sługa znalazł łaskę w twoich oczach, [proszę], abyś mnie posłał do Judy, do miasta grobów moich ojców, abym je odbudował.
6 Nígbà náà ni ọba, pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀ tí ó jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, bi mí pé, “Báwo ni ìrìnàjò náà yóò ṣe pẹ́ ọ tó, nígbà wo sì ni ìwọ yóò padà?” Ó dùn mọ́ ọba láti rán mi lọ, bẹ́ẹ̀ ni mo dá àkókò kan.
Król – obok którego siedziała królowa – zapytał mnie: Jak długo potrwa twoja podróż i kiedy powrócisz? Gdy podałem mu termin, spodobało się to królowi i posłał mnie.
7 Mo sì tún wí fún ọba pé, “Bí ó bá wu ọba, kí ó fún mi ní lẹ́tà sí àwọn baálẹ̀ òkè odò Eufurate kí wọ́n le mú mi kọjá títí èmi yóò fi dé Juda láìléwu.
Potem powiedziałem królowi: Jeśli król uważa to za dobre, niech mi dadzą listy do namiestników zarzecza, aby mnie przeprowadzili, aż przyjdę do Judy;
8 Kí èmi sì gba lẹ́tà kan lọ́wọ́ fún Asafu, olùṣọ́ igbó ọba, nítorí kí ó lè fún mi ní igi láti fi ṣe àtẹ́rígbà fún ibodè ilé ìṣọ́ tẹmpili àti fún odi ìlú náà àti fún ilé tí èmi yóò gbé?” Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi wà lórí mi, ọba fi ìbéèrè mi fún mi.
Także list do Asafa, dozorcy lasu królewskiego, aby mi dał drewno na belki do bram pałacu przy domu, na mur miejski i na dom, do którego się wprowadzę. Król więc dał mi [listy], gdyż była nade mną łaskawa ręka mego Boga.
9 Bẹ́ẹ̀ ni mo lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, mo sì fún wọn ní àwọn lẹ́tà ọba. Ọba sì ti rán àwọn ológun àti àwọn ẹlẹ́ṣin ogun pẹ̀lú mi.
A gdy przyszedłem do namiestników zarzecza, oddałem im listy króla. A król wyprawił ze mną dowódców wojskowych i jeźdźców.
10 Nígbà tí Sanballati ará Horoni àti Tobiah ará a Ammoni tí wọ́n jẹ́ ìjòyè gbọ́ nípa èyí pé, ẹnìkan wá láti mú ìtẹ̀síwájú bá àlàáfíà àwọn ará Israẹli inú bí wọn gidigidi.
Kiedy Sanballat Choronita i Tobiasz, sługa ammonicki, usłyszeli o tym, bardzo im się nie spodobało to, że przyszedł człowiek, który będzie zabiegał o dobro synów Izraela.
11 Mo sì lọ sí Jerusalẹmu, lẹ́yìn ìgbà tí mo dúró níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta.
Gdy więc przyszedłem do Jerozolimy, spędziłem tam trzy dni.
12 Mo jáde ní òru pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀. Èmi kò sì sọ fún ẹnìkankan ohun tí Ọlọ́run mi ti fi sí ọkàn mi láti ṣe fún Jerusalẹmu. Kò sí ẹranko kankan pẹ̀lú mi, bí kò ṣe ọ̀kan ṣoṣo tí mo gùn.
Potem wstałem w nocy, ja i kilku mężczyzn ze mną – a nikomu nie wyjawiłem, co mój Bóg położył mi na sercu, abym uczynił w Jerozolimie, nie miałem też ze sobą żadnego zwierzęcia oprócz tego, na którym jechałem;
13 Ní òru, mo jáde lọ sí àfonífojì ibodè sí ìhà kànga Jakali àti sí ẹnu ibodè Ààtàn àti ẹnu ibodè rẹ̀ èyí tí ó ti wó odi Jerusalẹmu tí ó lulẹ̀, tí a ti fi iná sun.
I wyjechałem nocą przez Bramę nad Doliną w kierunku Źródła Smoczego do Bramy Gnojnej, i oglądałem mury jerozolimskie, które były zburzone, a [których] bramy były strawione ogniem.
14 Nígbà náà ni mo lọ sí ẹnu ibodè orísun àti sí adágún omi ọba, ṣùgbọ́n kò sí ààyè tó fún ẹranko mi láti kọjá;
Potem dotarłem do Bramy Źródlanej i do Stawu Królewskiego, gdzie dla zwierzęcia, na którym jechałem, nie było już przejścia.
15 bẹ́ẹ̀ ni mo gòkè àfonífojì ní òru, mo ń wo odi. Ní ìparí, mo padà sẹ́yìn, mo sì tún wọlé láti ibodè àfonífojì.
Jechałem więc nocą przez potok i oglądałem mur, po czym zawróciłem i przejechałem przez Bramę nad Doliną, i tak powróciłem.
16 Àwọn olórí kò mọ ibi tí mo lọ tàbí mọ ohun tí mo ń ṣe, nítorí èmi kò tí ì sọ fún àwọn ará Júù tàbí àwọn àlùfáà tàbí àwọn ọlọ́lá tàbí àwọn ìjòyè tàbí ẹnikẹ́ni mìíràn tí yóò máa ṣe iṣẹ́ náà.
Ale przełożeni nie wiedzieli, dokąd się udałem ani co uczyniłem. Dotychczas bowiem nie oznajmiłem [tego] ani Żydom, ani kapłanom, ani dostojnikom, ani przełożonym, ani żadnemu z budowniczych.
17 Nígbà náà ni mo sọ fún wọn pé, “Ṣé ẹ rí wàhálà tí a ni: Jerusalẹmu wà nínú ìparun, ibodè rẹ̀ ni a sì ti fi iná jó. Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tún odi Jerusalẹmu mọ, àwa kò sì ní jẹ́ ẹni ẹ̀gàn mọ́”.
Wtedy powiedziałem do nich: Widzicie, w jakiej niedoli się znajdujemy, Jerozolima jest spustoszona i jej bramy spalone są ogniem. Chodźcie i odbudujmy mur Jerozolimy, abyśmy już nie byli zhańbieni.
18 Èmi sì tún sọ fún wọn nípa bí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi ṣe wà lára mi àti ohun tí ọba ti sọ fún mi. Wọ́n dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a bẹ̀rẹ̀ àtúnmọ rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rere yìí.
A gdy opowiedziałem im [o tym], jak łaskawa ręka mego Boga była nade mną, także o słowach, które wypowiedział do mnie król, powiedzieli: Wstańmy i budujmy. I zachęcali się do tego dobrego dzieła.
19 Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati ará a Horoni, Tobiah ara olóyè Ammoni àti Geṣemu ará a Arabia gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n fi wá ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n sì fi wá ṣe ẹ̀sín. Wọ́n béèrè pé, “Kí ni èyí tí ẹ ń ṣe yìí? Ṣé ẹ ń ṣọ̀tẹ̀ sí ọba ni?”
Kiedy usłyszeli o tym Sanballat Choronita i Tobiasz, sługa ammonicki, oraz Geszem Arab, szydzili z nas i wzgardzili nami, mówiąc: Co to za rzecz, którą robicie? Czy buntujecie się przeciw królowi?
20 Mo dá wọn lóhùn, mo wí fún wọn pé, “Ọlọ́run ọ̀run yóò fún wa ní àṣeyọrí. Àwa ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò bẹ̀rẹ̀ láti tún un mọ, ṣùgbọ́n fún un yin, ẹ̀yin kò ní ìpín tàbí ipa tàbí ẹ̀tọ́ ohunkóhun tí ó jẹ mọ́ ìtàn ní Jerusalẹmu.”
Odpowiedziałem im: Bóg niebios poszczęści nam; my więc, jego słudzy, powstaniemy i odbudujemy. Wy zaś nie macie ani działu, ani prawa, ani pamiątki w Jerozolimie.

< Nehemiah 2 >