< Nehemiah 2 >
1 Ní oṣù Nisani, ní ogún ọdún ìjọba ọba Artasasta, nígbà tí a gbé wáìnì wá fún un, mo gbé wáìnì náà, mo fi fún ọba, ìbànújẹ́ kò hàn ní ojú mi rí ní iwájú rẹ̀.
I KA malama o Nisana, i ka iwakalua o ka makahiki o ke alii o Aretasaseta, imua ona ka waina, a ua lawe au i ka waina, a haawi aku i ke alii; aohe o'u kaumaha mamua imua o kona alo.
2 Nítorí náà ni ọba béèrè lọ́wọ́ mi pé, “Èéṣe tí ojú rẹ fi fàro nígbà tí kò rẹ̀ ọ́? Èyí kì í ṣe ohun mìíràn bí kò ṣe ìbànújẹ́ ọkàn.” Ẹ̀rù bà mí gidigidi,
A i mai la ke alii ia'u, No ke aha la i inoino ai kou maka, aole hoi ou mai? aohe mea e ae keia, o ke kaumaha no ia o ka naau. Alaila makau nui loa iho la au,
3 ṣùgbọ́n mo wí fún ọba pé, “Kí ọba kí ó pẹ́! Èéṣe tí ojú mi ko ṣe ní fàro, nígbà tí ìlú tí a sin àwọn baba mi sí wà ní ahoro, tí a sì ti fi iná run àwọn ibodè rẹ̀?”
A i aku la i ke alii, I ola mau loa ke alii; heaha ka mea e ole ai e inoino ko'u maka i ka wa e waiho neoneo ana ke kulanakauhale, kahi o ua ilina a ko'u mau makuakane, a o na panipuka no hoi ona ua hoopauia i ke ahi.
4 Ọba wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?” Nígbà náà, ni mo gbàdúrà sí Ọlọ́run ọ̀run,
A olelo mai la ke alii ia'u, Heaha kau e imi nei? Alaila pule aku la au i ke Akua o ka lani.
5 mo sì dá ọba lóhùn pé, “Ti ó bá wu ọba, tí ìránṣẹ́ rẹ bá sì rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí ó rán mi lọ sí ìlú náà ní Juda níbi tí a sin àwọn baba mi nítorí kí èmi lè tún un kọ́.”
A i aku la au i ke alii, Ina he mea oluolu ia i ke alii, a i loaa hoi ke aloha i kau kauwa imua o kou alo, alaila e hoonua oe ia'u ma Iuda, ma ke kulanakauhale o na ilina o ko'u mau makuakane, i kukulu au ia.
6 Nígbà náà ni ọba, pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀ tí ó jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, bi mí pé, “Báwo ni ìrìnàjò náà yóò ṣe pẹ́ ọ tó, nígbà wo sì ni ìwọ yóò padà?” Ó dùn mọ́ ọba láti rán mi lọ, bẹ́ẹ̀ ni mo dá àkókò kan.
A i mai la ke alii ia'u, (o ke alii wahine kekahi o noho pu ana me ia, ) Pehea ka loihi o kou manawa e hele ai? Ahea la oe e hoi mai ai? A he mea oluolu ia i ke alii e hoouna ia'u; a hai aku au ia ia i manawa.
7 Mo sì tún wí fún ọba pé, “Bí ó bá wu ọba, kí ó fún mi ní lẹ́tà sí àwọn baálẹ̀ òkè odò Eufurate kí wọ́n le mú mi kọjá títí èmi yóò fi dé Juda láìléwu.
A olelo aku no hoi au i ke alii, Ina he mea pono ia i ke alii, e haawiia mai ia'u kekahi mau palapala na na kiaaina ma kela aoao o ka muliwai, i lawe lakou ia'u a hiki au ma Iuda;
8 Kí èmi sì gba lẹ́tà kan lọ́wọ́ fún Asafu, olùṣọ́ igbó ọba, nítorí kí ó lè fún mi ní igi láti fi ṣe àtẹ́rígbà fún ibodè ilé ìṣọ́ tẹmpili àti fún odi ìlú náà àti fún ilé tí èmi yóò gbé?” Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi wà lórí mi, ọba fi ìbéèrè mi fún mi.
A i palapala na Asapa ka mea malama i ko ke alii ululaau, i haawi mai ia ia'u i mau laau e kapili ai i na puka o ka pakiai o ka hale, a no ka pa o ke kulanakauhale, a no ka hale hoi a'u e komo ai. A haawi mai no ke alii ia'u, mamuli o ka lima lokomaikai o ko'u Akua maluna o'u.
9 Bẹ́ẹ̀ ni mo lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, mo sì fún wọn ní àwọn lẹ́tà ọba. Ọba sì ti rán àwọn ológun àti àwọn ẹlẹ́ṣin ogun pẹ̀lú mi.
A hiki mai la au i na kiaaina ma keia aoao o ka muliwai, haawi aku au ia lakou i na palapala a ke alii. A ua hoouna mai no hoi ke alii me au i mau luna koa a i poe hoohololio.
10 Nígbà tí Sanballati ará Horoni àti Tobiah ará a Ammoni tí wọ́n jẹ́ ìjòyè gbọ́ nípa èyí pé, ẹnìkan wá láti mú ìtẹ̀síwájú bá àlàáfíà àwọn ará Israẹli inú bí wọn gidigidi.
A lohe o Sonebalata ka Horona, a me Tobia ke kauwa, ka Amono, ho mea kaumaha loa no ia laua ka hiki ana mai o kekahi kanaka e imi i ka mea e pono ai na mamo a Iseraela.
11 Mo sì lọ sí Jerusalẹmu, lẹ́yìn ìgbà tí mo dúró níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta.
A hiki aku au ma Ierusalema, a malaila no au i na la ekolu.
12 Mo jáde ní òru pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀. Èmi kò sì sọ fún ẹnìkankan ohun tí Ọlọ́run mi ti fi sí ọkàn mi láti ṣe fún Jerusalẹmu. Kò sí ẹranko kankan pẹ̀lú mi, bí kò ṣe ọ̀kan ṣoṣo tí mo gùn.
Alaila ala ae la au iluna i ka po, owau a me kekahi poe kanaka uuku me au; aka, aole au i hai aku i kekahi kanaka i ka mea a ko'u Akua i hookomo mai ai iloko o ko'u naau e hana no Ierusalema. A aohe holoholona me au, o ka holoholona wale no a'u i hooholo ai.
13 Ní òru, mo jáde lọ sí àfonífojì ibodè sí ìhà kànga Jakali àti sí ẹnu ibodè Ààtàn àti ẹnu ibodè rẹ̀ èyí tí ó ti wó odi Jerusalẹmu tí ó lulẹ̀, tí a ti fi iná sun.
A hele aku au ma ka puka awawa i ka po, ma ke alo o ka punawai, a ka puka lepo, a nana aku la au i na pa o Ierusalema i hoohioloia a me na panipuka ona i hoopauia i ke ahi.
14 Nígbà náà ni mo lọ sí ẹnu ibodè orísun àti sí adágún omi ọba, ṣùgbọ́n kò sí ààyè tó fún ẹranko mi láti kọjá;
A hele aku au a i ka puka waipuna, a i ka loko hoi o ke alii: a aohe wahi no ka holoholona malalo o'u e hiki aku ai.
15 bẹ́ẹ̀ ni mo gòkè àfonífojì ní òru, mo ń wo odi. Ní ìparí, mo padà sẹ́yìn, mo sì tún wọlé láti ibodè àfonífojì.
Alaila pii aku la au i ka po ma ke kahawai, a nana aku la au i ka pa, a huli ae la hoi au, a komo ma ka puka awawa, a hoi mai la.
16 Àwọn olórí kò mọ ibi tí mo lọ tàbí mọ ohun tí mo ń ṣe, nítorí èmi kò tí ì sọ fún àwọn ará Júù tàbí àwọn àlùfáà tàbí àwọn ọlọ́lá tàbí àwọn ìjòyè tàbí ẹnikẹ́ni mìíràn tí yóò máa ṣe iṣẹ́ náà.
A o na luna, aole lakou i ike i kahi a'u i hele ai, a me ka mea a'u i hana'i; aole hoi au i hoike aku ia i ka Iuda, aole no hoi i na kahuna, a me ka poe kaukaualii, a me ka poe luna, a me ka poe i koe nana ka hana.
17 Nígbà náà ni mo sọ fún wọn pé, “Ṣé ẹ rí wàhálà tí a ni: Jerusalẹmu wà nínú ìparun, ibodè rẹ̀ ni a sì ti fi iná jó. Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tún odi Jerusalẹmu mọ, àwa kò sì ní jẹ́ ẹni ẹ̀gàn mọ́”.
Alaila, olelo aku la au ia lakou, Ke ike nei oukou i ka popilikia i loaa ia kakou, ua neoneo o Ierusalema, a o na puka ona ua pau i ke ahi: auhea oukou; ea, e kukulu kakou i ka pa o Ierusalema, i ole e hoino hou ia kakou.
18 Èmi sì tún sọ fún wọn nípa bí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi ṣe wà lára mi àti ohun tí ọba ti sọ fún mi. Wọ́n dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a bẹ̀rẹ̀ àtúnmọ rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rere yìí.
A hai aku la au ia lakou i ka lima o ko'u Akua, he lokomaikai maluna o'u, a me na olelo no hoi a ke alii, ana i olelo mai ai ia'u. A i ae la lakou, E ku ae kakou a e kukulu. A hooikaika iho la ko lakou mau lima ma keia mea e pono ai.
19 Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati ará a Horoni, Tobiah ara olóyè Ammoni àti Geṣemu ará a Arabia gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n fi wá ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n sì fi wá ṣe ẹ̀sín. Wọ́n béèrè pé, “Kí ni èyí tí ẹ ń ṣe yìí? Ṣé ẹ ń ṣọ̀tẹ̀ sí ọba ni?”
A lohe o Sanebalata ka Horona, a me Tobia ke kauwa, ka Amona, a me Gesema, ka Arabia, ua akahenehene mai lakou ia makou, o ua hoowahawaha mai no hoi ia makou, i mai la, Heaha keia mea a oukou e hana nei? e kipi aku anei oukou i ke alii?
20 Mo dá wọn lóhùn, mo wí fún wọn pé, “Ọlọ́run ọ̀run yóò fún wa ní àṣeyọrí. Àwa ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò bẹ̀rẹ̀ láti tún un mọ, ṣùgbọ́n fún un yin, ẹ̀yin kò ní ìpín tàbí ipa tàbí ẹ̀tọ́ ohunkóhun tí ó jẹ mọ́ ìtàn ní Jerusalẹmu.”
A pane aku la au ia lakou, a i aku la au ia lakou, o ke Akua o ka lani, oia ka mea nana makou e kokua mai; a o makou, kana poe kauwa, e ku iluua no makou a e kukulu: aka, aole o oukou kuleana, aole no he pono, aole hoi he mea e hoomanao ai iloko o Ierusalema.