< Nehemiah 2 >
1 Ní oṣù Nisani, ní ogún ọdún ìjọba ọba Artasasta, nígbà tí a gbé wáìnì wá fún un, mo gbé wáìnì náà, mo fi fún ọba, ìbànújẹ́ kò hàn ní ojú mi rí ní iwájú rẹ̀.
Og det skete i Nisan Maaned i Kong Artakserkses's tyvende Aar, da stod der Vin for hans Ansigt, og jeg tog Vinen og gav Kongen, og jeg havde ikke vist mig sørgmodig for hans Ansigt.
2 Nítorí náà ni ọba béèrè lọ́wọ́ mi pé, “Èéṣe tí ojú rẹ fi fàro nígbà tí kò rẹ̀ ọ́? Èyí kì í ṣe ohun mìíràn bí kò ṣe ìbànújẹ́ ọkàn.” Ẹ̀rù bà mí gidigidi,
Da sagde Kongen til mig: Hvorfor er du sørgmodig? og du er ikke syg, det er ikke dette, men dit Hjerte er sørgmodigt; da frygtede jeg saare meget.
3 ṣùgbọ́n mo wí fún ọba pé, “Kí ọba kí ó pẹ́! Èéṣe tí ojú mi ko ṣe ní fàro, nígbà tí ìlú tí a sin àwọn baba mi sí wà ní ahoro, tí a sì ti fi iná run àwọn ibodè rẹ̀?”
Og jeg sagde til Kongen: Kongen leve evindelig! hvorfor skulde jeg ikke være sørgmodig, da den Stad, i hvilken mine Fædres Begravelsers Hus er, ligger øde, og dens Porte ere fortærede af Ild?
4 Ọba wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?” Nígbà náà, ni mo gbàdúrà sí Ọlọ́run ọ̀run,
Da sagde Kongen til mig: Hvad er det, du søger om? da bad jeg til Gud i Himmelen.
5 mo sì dá ọba lóhùn pé, “Ti ó bá wu ọba, tí ìránṣẹ́ rẹ bá sì rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí ó rán mi lọ sí ìlú náà ní Juda níbi tí a sin àwọn baba mi nítorí kí èmi lè tún un kọ́.”
Da sagde jeg til Kongen: Dersom det synes Kongen godt, og dersom din Tjener synes god for dit Ansigt, da sende du mig til Juda, til mine Fædres Begravelsers Stad, at jeg maa bygge den op.
6 Nígbà náà ni ọba, pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀ tí ó jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, bi mí pé, “Báwo ni ìrìnàjò náà yóò ṣe pẹ́ ọ tó, nígbà wo sì ni ìwọ yóò padà?” Ó dùn mọ́ ọba láti rán mi lọ, bẹ́ẹ̀ ni mo dá àkókò kan.
Da sagde Kongen og Dronningen, som sad hos ham, til mig: Hvor længe skal din Rejse vare, og naar vil du komme igen? Og det syntes Kongen godt, og han sendte mig hen, og jeg satte ham en bestemt Tid.
7 Mo sì tún wí fún ọba pé, “Bí ó bá wu ọba, kí ó fún mi ní lẹ́tà sí àwọn baálẹ̀ òkè odò Eufurate kí wọ́n le mú mi kọjá títí èmi yóò fi dé Juda láìléwu.
Og jeg sagde til Kongen: Dersom det synes Kongen godt, da lad dem give mig Breve til Landshøvdingerne paa hin Side Floden, at de lade mig komme frem, indtil jeg kommer til Juda,
8 Kí èmi sì gba lẹ́tà kan lọ́wọ́ fún Asafu, olùṣọ́ igbó ọba, nítorí kí ó lè fún mi ní igi láti fi ṣe àtẹ́rígbà fún ibodè ilé ìṣọ́ tẹmpili àti fún odi ìlú náà àti fún ilé tí èmi yóò gbé?” Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi wà lórí mi, ọba fi ìbéèrè mi fún mi.
og Brev til Asaf, som har Opsyn over Kongens Lysthave, at han maa give mig Træ til at sammentømre Porten paa Borgen, som hører til Huset, og ligeledes til Stadsmurene og til det Hus, som jeg skal drage ind udi; og Kongen gav mig det, efterdi min Guds gode Haand var over mig.
9 Bẹ́ẹ̀ ni mo lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, mo sì fún wọn ní àwọn lẹ́tà ọba. Ọba sì ti rán àwọn ológun àti àwọn ẹlẹ́ṣin ogun pẹ̀lú mi.
Da kom jeg til Landshøvdingerne paa hin Side Floden og gav dem Kongens Breve, og Kongen sendte Stridshøvedsmænd og Ryttere med mig.
10 Nígbà tí Sanballati ará Horoni àti Tobiah ará a Ammoni tí wọ́n jẹ́ ìjòyè gbọ́ nípa èyí pé, ẹnìkan wá láti mú ìtẹ̀síwájú bá àlàáfíà àwọn ará Israẹli inú bí wọn gidigidi.
Men der Sanballat, Horoniten, og Tobia, den ammonitiske Tjener, hørte det, da gjorde det dem saare ondt, at der var kommet et Menneske til at søge Israels Børns Bedste.
11 Mo sì lọ sí Jerusalẹmu, lẹ́yìn ìgbà tí mo dúró níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta.
Og der jeg kom til Jerusalem og havde været der i tre Dage,
12 Mo jáde ní òru pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀. Èmi kò sì sọ fún ẹnìkankan ohun tí Ọlọ́run mi ti fi sí ọkàn mi láti ṣe fún Jerusalẹmu. Kò sí ẹranko kankan pẹ̀lú mi, bí kò ṣe ọ̀kan ṣoṣo tí mo gùn.
da gjorde jeg mig rede om Natten, jeg og faa Mænd med mig, og jeg gav ikke til Kende for noget Menneske, hvad min Gud indgav mit Hjerte at gøre for Jerusalem, og der var intet Dyr med mig uden det Dyr, som jeg red paa.
13 Ní òru, mo jáde lọ sí àfonífojì ibodè sí ìhà kànga Jakali àti sí ẹnu ibodè Ààtàn àti ẹnu ibodè rẹ̀ èyí tí ó ti wó odi Jerusalẹmu tí ó lulẹ̀, tí a ti fi iná sun.
Og jeg drog ud ad Dalporten om Natten og hen imod Dragekilden og hen til Møgporten, og jeg undersøgte Jerusalems Mure, som vare nedrevne, og dens Porte, som vare fortærede af Ild.
14 Nígbà náà ni mo lọ sí ẹnu ibodè orísun àti sí adágún omi ọba, ṣùgbọ́n kò sí ààyè tó fún ẹranko mi láti kọjá;
Og jeg drog over til Kildeporten og til Kongens Dam, og der var ikke Rum for Dyret til at komme frem under mig.
15 bẹ́ẹ̀ ni mo gòkè àfonífojì ní òru, mo ń wo odi. Ní ìparí, mo padà sẹ́yìn, mo sì tún wọlé láti ibodè àfonífojì.
Og jeg drog om Natten op i Dalen, og jeg undersøgte Muren, og jeg vendte om og kom ind ad Dalporten og vendte tilbage.
16 Àwọn olórí kò mọ ibi tí mo lọ tàbí mọ ohun tí mo ń ṣe, nítorí èmi kò tí ì sọ fún àwọn ará Júù tàbí àwọn àlùfáà tàbí àwọn ọlọ́lá tàbí àwọn ìjòyè tàbí ẹnikẹ́ni mìíràn tí yóò máa ṣe iṣẹ́ náà.
Og Forstanderne vidste ikke, hvor jeg var gaaet hen, eller hvad jeg gjorde, og for Jøderne og Præsterne og de ypperste og Forstanderne og de øvrige, som skulde have med Gerningen at gøre, havde jeg ikke hidindtil tilkendegivet det.
17 Nígbà náà ni mo sọ fún wọn pé, “Ṣé ẹ rí wàhálà tí a ni: Jerusalẹmu wà nínú ìparun, ibodè rẹ̀ ni a sì ti fi iná jó. Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tún odi Jerusalẹmu mọ, àwa kò sì ní jẹ́ ẹni ẹ̀gàn mọ́”.
Da sagde jeg til dem: I se den Ulykke, i hvilken vi ere, at Jerusalem er øde, og dens Porte ere opbrændte af Ild: Kommer og lader os opbygge Jerusalems Mure, at vi ikke ydermere skulle være til Spot.
18 Èmi sì tún sọ fún wọn nípa bí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi ṣe wà lára mi àti ohun tí ọba ti sọ fún mi. Wọ́n dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a bẹ̀rẹ̀ àtúnmọ rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rere yìí.
Og jeg fortalte dem om min Guds Haand, som var god over mig, tilmed om Kongens Ord, som han havde sagt mig; og de sagde: Lader os gøre os rede og bygge, og de styrkede deres Hænder til det gode Værk.
19 Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati ará a Horoni, Tobiah ara olóyè Ammoni àti Geṣemu ará a Arabia gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n fi wá ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n sì fi wá ṣe ẹ̀sín. Wọ́n béèrè pé, “Kí ni èyí tí ẹ ń ṣe yìí? Ṣé ẹ ń ṣọ̀tẹ̀ sí ọba ni?”
Men der Sanballat, Horoniten, og Tobia, den ammonitiske Tjener, og Gesem, Araberen, hørte det, da bespottede de os og foragtede os, og de sagde: Hvad er dette for en Ting, som I gøre? ville I være genstridige imod Kongen?
20 Mo dá wọn lóhùn, mo wí fún wọn pé, “Ọlọ́run ọ̀run yóò fún wa ní àṣeyọrí. Àwa ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò bẹ̀rẹ̀ láti tún un mọ, ṣùgbọ́n fún un yin, ẹ̀yin kò ní ìpín tàbí ipa tàbí ẹ̀tọ́ ohunkóhun tí ó jẹ mọ́ ìtàn ní Jerusalẹmu.”
Da svarede jeg dem og sagde til dem: Gud i Himmelen, han skal lade det lykkes for os, og vi hans Tjenere, vi ville gøre os rede og bygge; men I have ikke Del eller Ret eller Ihukommelse i Jerusalem.