< Nehemiah 13 >

1 Ní ọjọ́ náà ni a ka ìwé Mose sókè sí etí ìgbọ́ àwọn ènìyàn, nínú rẹ̀ ni a ti rí i tí a kọ ọ́ sílẹ̀ pé a kò gbọdọ̀ gba àwọn ará a Ammoni tàbí àwọn ará a Moabu sí àárín ìjọ ènìyàn Ọlọ́run láéláé.
Le même jour on lut dans le Livre de Moïse aux oreilles du peuple, et l'on y trouva écrit: Aucun Ammonite ou Moabite n'aura entrée dans l'Assemblée de Dieu, jamais,
2 Nítorí wọn kò mú oúnjẹ àti omi wá pàdé àwọn ọmọ Israẹli lọ́nà, dípò bẹ́ẹ̀, wọ́n bẹ Balaamu ní ọ̀wẹ̀ láti gégùn ún lé wọn lórí. (Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa yí ègún náà padà sí ìbùkún.)
parce qu'ils ne prévinrent pas les enfants d'Israël avec le pain et l'eau, et qu'ils soudoyèrent contre eux Balaam pour les maudire; mais notre Dieu fit tourner la malédiction en bénédiction.
3 Nígbà tí àwọn ènìyàn gbọ́ òfin yìí, wọ́n yọ gbogbo àwọn àjèjì ènìyàn tí ó darapọ̀ mọ́ wọn kúrò láàrín àwọn Israẹli.
Et lorsqu'ils eurent entendu cette loi, ils séparèrent d'Israël tous les étrangers.
4 Ṣáájú èyí a ti fi Eliaṣibu àlùfáà ṣe alákòóso yàrá ìkó nǹkan ilé Ọlọ́run wa sí. Ó súnmọ́ Tobiah pẹ́kípẹ́kí.
Cependant avec cela le Prêtre Eliasib, préposé sur une cellule dans la maison de Dieu, parent de Tobie,
5 Ó sì ti pèsè yàrá ńlá kan fún un, èyí tí a ń lò tẹ́lẹ̀ fún ìtọ́jú ọrẹ ọkà, tùràrí àti àwọn ohun èlò tẹmpili àti ìdámẹ́wàá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró ti a fi lélẹ̀ bí ìlànà fún àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà àti pẹ̀lú gbogbo ọrẹ fún àwọn àlùfáà.
lui avait arrangé une grande cellule où l'on déposait auparavant les offrandes, l'encens et la vaisselle et la dîme du blé, du moût et de l'huile, les redevances dues aux Lévites, aux Chantres et aux Portiers, et ce qui était prélevé pour les Prêtres.
6 Ṣùgbọ́n nígbà tí gbogbo èyí ń lọ lọ́wọ́, èmi kò sí ní Jerusalẹmu, nítorí pé ní ọdún kejìlélọ́gbọ̀n Artasasta ọba Babeli ni mo padà tọ ọba lọ. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó ṣe díẹ̀, mo gba ààyè lọ́dọ̀ọ rẹ̀.
Et quand cela se fit, je n'étais point à Jérusalem, car c'est la trente-deuxième année d'Arthachsastha, roi de Babel, que je me présentai au roi et à la fin de l'année que j'obtins l'agrément du roi.
7 Mo sì padà sí Jerusalẹmu. Níhìn-ín ni mo ti mọ̀ nípa onírúurú ohun búburú tí Eliaṣibu ti ṣe ní ti pípèsè yàrá fún Tobiah nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run.
Étant ainsi arrivé à Jérusalem, je m'aperçus de l'abus qu'avait commis Eliasib en faveur de Tobie en lui laissant l'usage d'une cellule dans les Parvis de la Maison de Dieu,
8 Kò tẹ́ mi lọ́rùn rárá, mo kó gbogbo ohun èlò ìdílé e Tobiah dà síta láti inú iyàrá náà.
et je fus fort mécontent, et je jetai tous les meubles de la demeure de Tobie dehors, hors de la cellule.
9 Mo pàṣẹ kí wọn ya àwọn iyàrá náà sí mímọ́, mo sì kó àwọn ohun èlò ilé Ọlọ́run padà síbẹ̀ pẹ̀lú ọrẹ ọkà àti tùràrí.
Et j'ordonnai qu'on purifiât les cellules, et j'y fis rentrer les meubles de la Maison de Dieu, l'offrande et l'encens.
10 Mo sì tún gbọ́ pé, kò fi àwọn ìpín tí a yà sọ́tọ̀ fún àwọn Lefi, àwọn akọrin tí ń ṣe àkóso ìsìn sì ti padà sí ẹnu onírúurú iṣẹ́ wọn.
Et j'appris que les redevances dues aux Lévites n'avaient point été payées, et qu'avaient fui, chacun vers son champ, les Lévites et Chantres qui exerçaient les fonctions.
11 Nígbà náà ni mo bá àwọn ìjòyè wí, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí a fi kọ ilé Ọlọ́run sílẹ̀?” Nígbà náà ni mo pè wọ́n jọ pọ̀, mo sì fi olúkúlùkù sí ẹnu iṣẹ́ rẹ̀.
Alors je pris à partie les chefs et je dis: Pourquoi la Maison de Dieu est-elle délaissée? Et je les rassemblai et les mis à leur poste.
12 Gbogbo Juda mú ìdámẹ́wàá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró wá sínú yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí.
Et tout Juda apporta la dîme de blé, moût et huile au trésor.
13 Mo sì fi àlùfáà Ṣelemiah, Sadoku akọ̀wé àti ọmọ Lefi kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Pedaiah ṣe alákòóso àwọn yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí. Mo sì yan Hanani ọmọ Sakkuri, ọmọ Mattaniah bí olùrànlọ́wọ́ ọ wọn. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ni a kà sí àwọn tó ṣé e gbẹ́kẹ̀lé. Àwọn ni a yàn láti máa pín ohun èlò fún àwọn arákùnrin wọn.
Et j'établis comme préposés sur le trésor, Sélémia, le Prêtre, et Tsadoc, le Scribe, et Pedaïa d'entre les Lévites, et comme leurs adjoints, Hanan, fils de Zaccur, fils de Matthania, car ils étaient réputés hommes sûrs, et c'était à eux à faire les répartitions à leurs frères. —
14 Rántí ì mi fún èyí, Ọlọ́run mi, kí o má sì ṣe gbàgbé ohun tí mo fi òtítọ́ ṣe fún ilé Ọlọ́run mi yìí àti fún iṣẹ́ ẹ rẹ̀ gbogbo.
Souviens-toi de moi, ô mon Dieu, à cause de cela, et ne raie pas les actes pieux que j'ai accomplis dans la Maison de Dieu et dans son administration!
15 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, mo rí àwọn ènìyàn ní Juda tí wọ́n ń fúntí ní ọjọ́ ìsinmi, tí wọ́n sì ń gbé ọkà wọlé, tí wọn ń di ẹrù lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ pẹ̀lú wáìnì, èso àjàrà, ọ̀pọ̀tọ́ àti onírúurú ẹrù. Wọ́n sì ń kó gbogbo èyí wá sí Jerusalẹmu ní ọjọ́ ìsinmi. Nítorí náà, mo kìlọ̀ fún wọn nípa títa oúnjẹ ní ọjọ́ náà.
Dans le même temps, je vis en Juda des pressureurs aux pressoirs le jour du Sabbat et des gens rentrer des gerbes et les charger sur des ânes, ainsi que du vin, des raisins et des figues et toutes sortes de fardeaux, et les amener à Jérusalem le jour du Sabbat. Et je leur fis une remontrance le jour où ils vendaient les denrées.
16 Àwọn ará Tire ti ń gbé nínú Jerusalẹmu ń gbé ẹja àti onírúurú ọjà wá fún títà ní ọjọ́ ìsinmi fún àwọn ènìyàn Jerusalẹmu àti fún àwọn ọmọ Juda.
Il s'y trouvait aussi des Tyriens qui apportaient du poisson et toutes sortes de marchandises qu'ils vendaient le jour du Sabbat aux enfants de Juda et de Jérusalem.
17 Mo bá àwọn ọlọ́lá Juda wí, mo wí fún wọn pé, “Èwo ni ohun búburú tí ẹ ń ṣe yìí ti ẹ ń ba ọjọ́ ìsinmi jẹ́.
Alors je pris à partie les notables de Juda et leur dis: Qu'est-ce que ce mal que vous faites là, profanant ainsi le jour du Sabbat?
18 Ṣé àwọn baba ńlá yín kò ha ti ṣe nǹkan kan náà tí Ọlọ́run wa fi mú gbogbo àjálù yìí wá orí wa, àti sórí ìlú yìí? Báyìí, ẹ̀yin tún ń ru ìbínú sókè sí i sórí Israẹli nípa bíba ọjọ́ ìsinmi jẹ́.”
N'est-ce pas ainsi qu'ont agi vos pères, ensuite de quoi notre Dieu a fait tomber sur nous et sur cette ville tous ces malheurs? Et vous accumulez la colère divine sur Israël par la profanation du Sabbat!
19 Nígbà tí ojú ọjọ́ ń bora ní ẹnu ibodè Jerusalẹmu, ṣáájú ọjọ́ ìsinmi, mo pàṣẹ pé kí a ti àwọn ìlẹ̀kùn, kí wọn má sì ṣí i títí tí ọjọ́ ìsinmi yóò fi kọjá. Mo yan àwọn ìránṣẹ́ mi láti ṣọ́ ẹnu ibodè, kí a má ba à lè gbé ẹrù kankan wọlé ní ọjọ́ ìsinmi.
Et lorsqu'il fit sombre dans les Portes de Jérusalem avant le Sabbat, j'ordonnai que les portes fussent fermées, et ordonnai de ne les rouvrir qu'après le Sabbat passé. Et je postai de mes écuyers aux portes, afin qu'il n'entrât aucune charge le jour du Sabbat.
20 Síbẹ̀, àwọn tí ń tà àti àwọn tí ń rà sùn ẹ̀yìn odi Jerusalẹmu ní ẹ̀ẹ̀kan tàbí ẹ̀ẹ̀mejì.
Et les marchands et vendeurs de toutes sortes de marchandises durent passer la nuit en dehors de Jérusalem, une et deux fois.
21 Ṣùgbọ́n mo kìlọ̀ fún wọn pé, “Èétijẹ́ ti ẹ̀yin fi ń sùn ní ẹ̀yin odi ní òru? Bí ẹ̀yìn bá tún dánwò mọ́, èmi yóò fi ọwọ́ líle mú yín.” Láti ọjọ́ náà lọ, wọn kò sì wá ní ọjọ́ ìsinmi mọ́.
Et je les tançai et leur dis: Pourquoi passez-vous la nuit devant le mur? Si vous réitérez, je mettrai la main sur vous. Dès ce moment ils ne vinrent plus le jour du Sabbat.
22 Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún àwọn ọmọ Lefi pé kí wọn ya ara wọn sí mímọ́, kí wọn sì ṣọ́ ẹnu ibodè kí a lè pa ọjọ́ ìsinmi mọ́. Tún rántí mi fún èyí, Ọlọ́run mi, kí o sì fi àánú un rẹ hàn fún mi gẹ́gẹ́ bí i títóbi ìfẹ́ ẹ̀ rẹ.
Et je dis aux Lévites de se purifier et de venir garder les portes pour sanctifier le jour du Sabbat. — De cela aussi conserve-moi le souvenir, ô mon Dieu, et use de clémence envers moi selon ta grande miséricorde!
23 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, mo rí àwọn ọkùnrin Juda tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin láti Aṣdodu, Ammoni àti Moabu.
Dans ce temps aussi je vis des Juifs qui avaient épousé des femmes Asdodites, Ammonites, Moabites.
24 Ìdajì àwọn ọmọ wọn ń sọ èdè Aṣdodu tàbí èdè ọ̀kan lára àwọn ènìyàn mìíràn tókù, wọn kò sì mọ bí a ṣe ń sọ èdè Juda.
Et la moitié de leurs fils parlaient asdodite, et ne savaient pas parler le juif, mais bien la langue de tel ou tel de ces peuples-là.
25 Mo bá wọn wí mo sì gégùn ún lé wọn lórí. Mo lu àwọn ènìyàn díẹ̀ nínú wọn mo sì fa irun orí wọn tu. Mo mú kí wọn búra ní orúkọ Ọlọ́run, kí wọn wí pé, “Ẹ̀yin kì yóò fi àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin yín ní ìyàwó tàbí fún ẹ̀yin tìkára yín.
Et je les pris à partie, et les maudis et en battis quelques-uns, et leur arrachai les cheveux, et je leur fis jurer ceci par le Nom de Dieu: Vous ne donnerez point vos filles à leurs fils et ne prendrez point de leurs filles pour vos fils, ni pour vous-mêmes.
26 Kì í ha á ṣe àwọn ìgbéyàwó bí irú èyí ni ọba Solomoni fi dá ẹ̀ṣẹ̀? Láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, kò sí ọba kan bí i tirẹ̀. Ọlọ́run rẹ̀ fẹ́ràn rẹ̀, Ọlọ́run sì fi jẹ ọba lórí i gbogbo Israẹli, ṣùgbọ́n àwọn obìnrin àjèjì ti sọ ọ́ sínú òfin ẹ̀ṣẹ̀.
N'est-ce pas en ce point qu'a péché Salomon, le roi d'Israël? et dans le nombre des peuples il n'y eut pas de roi comme lui, et il était aimé de son Dieu, et Dieu l'établit roi de tout Israël; néanmoins c'est lui qu'entraînèrent au péché des femmes étrangères!
27 Ǹjẹ́ ó ha yẹ kí àwa tún gbọ́ báyìí pé ẹ̀yin náà tún ń ṣe àwọn nǹkan tí ó burú jọjọ wọ̀nyí tí ẹ sì ń ṣe aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì?”
Nous faudrait-il vous faire la concession de commettre un si grand crime que de nous révolter contre notre Dieu par des mariages avec des femmes étrangères?
28 Ọ̀kan lára àwọn ọmọ Joiada, ọmọ Eliaṣibu olórí àlùfáà jẹ́ àna Sanballati ará a Horoni. Mo sì lé e jáde kúrò lọ́dọ̀ mi.
Et l'un des fils de Joïada, fils d'Eliasib, le Grand-Prêtre, était devenu gendre de Saneballat, l'Horonite, et je le chassai loin de moi.
29 Rántí wọn, Ọlọ́run mi, nítorí wọ́n ti ba iṣẹ́ àlùfáà jẹ́ pẹ̀lú májẹ̀mú iṣẹ́ àlùfáà àti ti àwọn Lefi.
Souviens-toi d'eux, ô mon Dieu, à cause de la souillure du Sacerdoce, et de la constitution Sacerdotale et Lévitique!
30 Nítorí náà, mo ya àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi sí mímọ́ kúrò nínú gbogbo ohun àjèjì, mo sì yan iṣẹ́ fún wọn, olúkúlùkù sí ẹnu iṣẹ́ rẹ̀.
Et ainsi, je les purifiai de tout étranger, et je fixai les fonctions pour les Prêtres et pour les Lévites, pour chacun dans son office,
31 Mo sì tún pèsè fún ọrẹ, igi—pákó ní àkókò tí a yàn àti fún àwọn èso àkọ́so. Rántí mi fún rere, Ọlọ́run mi.
et les prestations en bois à fournir par époques déterminées, et en prémices. — Garde de moi, ô mon Dieu, un favorable souvenir!

< Nehemiah 13 >