< Nehemiah 13 >

1 Ní ọjọ́ náà ni a ka ìwé Mose sókè sí etí ìgbọ́ àwọn ènìyàn, nínú rẹ̀ ni a ti rí i tí a kọ ọ́ sílẹ̀ pé a kò gbọdọ̀ gba àwọn ará a Ammoni tàbí àwọn ará a Moabu sí àárín ìjọ ènìyàn Ọlọ́run láéláé.
En ce jour-là, on lut à haute voix au peuple le livre de Moïse, et on y trouva écrit: Que les Ammonites et les Moabites ne devaient jamais entrer dans l'Église de Dieu.
2 Nítorí wọn kò mú oúnjẹ àti omi wá pàdé àwọn ọmọ Israẹli lọ́nà, dípò bẹ́ẹ̀, wọ́n bẹ Balaamu ní ọ̀wẹ̀ láti gégùn ún lé wọn lórí. (Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa yí ègún náà padà sí ìbùkún.)
Parce qu'ils n'étaient point venus au-devant d'Israël avec du pain et de l'eau, et qu'ils avaient salarié Balaam pour le maudire; mais, notre Dieu changea la malédiction en bénédiction.
3 Nígbà tí àwọn ènìyàn gbọ́ òfin yìí, wọ́n yọ gbogbo àwọn àjèjì ènìyàn tí ó darapọ̀ mọ́ wọn kúrò láàrín àwọn Israẹli.
Et lorsqu'ils eurent ouï la loi, tous ceux qui s'étaient mêlés à Israël en furent séparés.
4 Ṣáájú èyí a ti fi Eliaṣibu àlùfáà ṣe alákòóso yàrá ìkó nǹkan ilé Ọlọ́run wa sí. Ó súnmọ́ Tobiah pẹ́kípẹ́kí.
Or, avant cela, Eliasib, le prêtre, très-proche allié de Tobias, demeurait dans le trésor du temple de notre Dieu.
5 Ó sì ti pèsè yàrá ńlá kan fún un, èyí tí a ń lò tẹ́lẹ̀ fún ìtọ́jú ọrẹ ọkà, tùràrí àti àwọn ohun èlò tẹmpili àti ìdámẹ́wàá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró ti a fi lélẹ̀ bí ìlànà fún àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà àti pẹ̀lú gbogbo ọrẹ fún àwọn àlùfáà.
Et il s'était fait faire un vaste magasin dans le lieu où l'on déposait jadis les offrandes, l'encens, les vases, la dîme du blé, du vin et de l'huile, ce qui était dû aux lévites, aux chantres et aux portiers, et les prémices destinées aux prêtres.
6 Ṣùgbọ́n nígbà tí gbogbo èyí ń lọ lọ́wọ́, èmi kò sí ní Jerusalẹmu, nítorí pé ní ọdún kejìlélọ́gbọ̀n Artasasta ọba Babeli ni mo padà tọ ọba lọ. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó ṣe díẹ̀, mo gba ààyè lọ́dọ̀ọ rẹ̀.
Et, en ce temps-là, je n'étais pas à Jérusalem. Car, dans la trente- deuxième année du règne d'Arthasastha, roi de Babylone, j'étais allé auprès du roi. Et, un certain nombre de jours étant accompli, je demandai au roi la permission de partir.
7 Mo sì padà sí Jerusalẹmu. Níhìn-ín ni mo ti mọ̀ nípa onírúurú ohun búburú tí Eliaṣibu ti ṣe ní ti pípèsè yàrá fún Tobiah nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run.
Et je revins à Jérusalem, et je reconnus le mal qu'avait fait Eliasib avec Tobias en lui faisant un magasin dans le parvis du temple de Dieu.
8 Kò tẹ́ mi lọ́rùn rárá, mo kó gbogbo ohun èlò ìdílé e Tobiah dà síta láti inú iyàrá náà.
Et cela me parut très-mal; et je jetai hors du magasin tous les meubles de la maison de Tobias.
9 Mo pàṣẹ kí wọn ya àwọn iyàrá náà sí mímọ́, mo sì kó àwọn ohun èlò ilé Ọlọ́run padà síbẹ̀ pẹ̀lú ọrẹ ọkà àti tùràrí.
Et je parlai, et on purifia le magasin, et j'y fis replacer les vases du temple, les offrandes et l'encens.
10 Mo sì tún gbọ́ pé, kò fi àwọn ìpín tí a yà sọ́tọ̀ fún àwọn Lefi, àwọn akọrin tí ń ṣe àkóso ìsìn sì ti padà sí ẹnu onírúurú iṣẹ́ wọn.
Et je reconnus qu'on n'avait plus donné la part des lévites, de sorte que les lévites et les chantres faisant œuvre au temple s'étaient enfuis chacun en sa terre.
11 Nígbà náà ni mo bá àwọn ìjòyè wí, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí a fi kọ ilé Ọlọ́run sílẹ̀?” Nígbà náà ni mo pè wọ́n jọ pọ̀, mo sì fi olúkúlùkù sí ẹnu iṣẹ́ rẹ̀.
Et je fis des reproches aux officiers, et je leur dis: D'où vient que le temple du Seigneur est abandonné? Puis, je rassemblai les lévites et les Chantres, et je les rétablis dans leurs fonctions.
12 Gbogbo Juda mú ìdámẹ́wàá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró wá sínú yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí.
Alors, tout Juda apporta dans les trésors la dîme du froment; de l'huile et du vin,
13 Mo sì fi àlùfáà Ṣelemiah, Sadoku akọ̀wé àti ọmọ Lefi kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Pedaiah ṣe alákòóso àwọn yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí. Mo sì yan Hanani ọmọ Sakkuri, ọmọ Mattaniah bí olùrànlọ́wọ́ ọ wọn. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ni a kà sí àwọn tó ṣé e gbẹ́kẹ̀lé. Àwọn ni a yàn láti máa pín ohun èlò fún àwọn arákùnrin wọn.
Entre les mains de Sélémias le prêtre, de Sadoc le scribe, et de Phadaïa, l'un des lévites. Et ils avaient auprès d'eux Anan, fils de Zacchur, fils de Matthanias; car ils étaient réputés fidèles, et ils furent chargés de faire les distributions à leurs frères.
14 Rántí ì mi fún èyí, Ọlọ́run mi, kí o má sì ṣe gbàgbé ohun tí mo fi òtítọ́ ṣe fún ilé Ọlọ́run mi yìí àti fún iṣẹ́ ẹ rẹ̀ gbogbo.
Souvenez-vous de moi, ô mon Dieu, à cause de cela; que mes bonnes œuvres dans le temple du Seigneur Dieu ne soient point effacées.
15 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, mo rí àwọn ènìyàn ní Juda tí wọ́n ń fúntí ní ọjọ́ ìsinmi, tí wọ́n sì ń gbé ọkà wọlé, tí wọn ń di ẹrù lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ pẹ̀lú wáìnì, èso àjàrà, ọ̀pọ̀tọ́ àti onírúurú ẹrù. Wọ́n sì ń kó gbogbo èyí wá sí Jerusalẹmu ní ọjọ́ ìsinmi. Nítorí náà, mo kìlọ̀ fún wọn nípa títa oúnjẹ ní ọjọ́ náà.
En ces jours-là, je vis que dans Juda quelques-uns pressuraient le vin le jour du sabbat; je vis que d'autres transportaient des gerbes, que d'autres encore chargeaient leurs ânes de vin, de grappes, de figues, de toutes sortes de fardeaux, et qu'ils les conduisaient à Jérusalem le jour du sabbat. Et je les avertis des jours où ils pouvaient trafiquer.
16 Àwọn ará Tire ti ń gbé nínú Jerusalẹmu ń gbé ẹja àti onírúurú ọjà wá fún títà ní ọjọ́ ìsinmi fún àwọn ènìyàn Jerusalẹmu àti fún àwọn ọmọ Juda.
Et des gens s'étaient établis à Jérusalem, apportant du poisson, vendant toutes sortes de marchandises aux Juifs, le jour du sabbat.
17 Mo bá àwọn ọlọ́lá Juda wí, mo wí fún wọn pé, “Èwo ni ohun búburú tí ẹ ń ṣe yìí ti ẹ ń ba ọjọ́ ìsinmi jẹ́.
Et je réprimandai les fils de Juda de condition libre, et je leur dis: Quelle est cette mauvaise action que vous faites, en profanant le jour du sabbat?
18 Ṣé àwọn baba ńlá yín kò ha ti ṣe nǹkan kan náà tí Ọlọ́run wa fi mú gbogbo àjálù yìí wá orí wa, àti sórí ìlú yìí? Báyìí, ẹ̀yin tún ń ru ìbínú sókè sí i sórí Israẹli nípa bíba ọjọ́ ìsinmi jẹ́.”
N'est-ce point là ce que faisaient vos pères? n'est-ce point la cause de tous les malheurs dont notre Dieu les à frappés, eux et notre ville? Et vous, n'attirerez-vous pas un surcroît de colère sur Israël en profanant le sabbat?
19 Nígbà tí ojú ọjọ́ ń bora ní ẹnu ibodè Jerusalẹmu, ṣáájú ọjọ́ ìsinmi, mo pàṣẹ pé kí a ti àwọn ìlẹ̀kùn, kí wọn má sì ṣí i títí tí ọjọ́ ìsinmi yóò fi kọjá. Mo yan àwọn ìránṣẹ́ mi láti ṣọ́ ẹnu ibodè, kí a má ba à lè gbé ẹrù kankan wọlé ní ọjọ́ ìsinmi.
Or, quand les portes de Jérusalem furent rétablie, la veille d'un sabbat, je parlai, et on ferma les portes; je parlai, et on ne les ouvrit qu'après le sabbat, et je mis de mes serviteurs à chaque porte pour qu'on ne pût introduire des fardeaux le jour du sabbat.
20 Síbẹ̀, àwọn tí ń tà àti àwọn tí ń rà sùn ẹ̀yìn odi Jerusalẹmu ní ẹ̀ẹ̀kan tàbí ẹ̀ẹ̀mejì.
Et tous les marchands passèrent la nuit en plein air, et ils vendirent une ou deux fois hors de Jérusalem.
21 Ṣùgbọ́n mo kìlọ̀ fún wọn pé, “Èétijẹ́ ti ẹ̀yin fi ń sùn ní ẹ̀yin odi ní òru? Bí ẹ̀yìn bá tún dánwò mọ́, èmi yóò fi ọwọ́ líle mú yín.” Láti ọjọ́ náà lọ, wọn kò sì wá ní ọjọ́ ìsinmi mọ́.
Et je les avertis, et je leur dis: Pourquoi passez-vous la nuit devant les remparts? Si vous recommencez, j'étendrai la main sur vous. Depuis lors, ils ne vinrent plus le jour du sabbat.
22 Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún àwọn ọmọ Lefi pé kí wọn ya ara wọn sí mímọ́, kí wọn sì ṣọ́ ẹnu ibodè kí a lè pa ọjọ́ ìsinmi mọ́. Tún rántí mi fún èyí, Ọlọ́run mi, kí o sì fi àánú un rẹ hàn fún mi gẹ́gẹ́ bí i títóbi ìfẹ́ ẹ̀ rẹ.
Et je dis aux lévites qui s'étaient purifiés, et qui étaient venus garder les portes, de sanctifier le jour du sabbat: à cause de cela, souvenez-vous de moi, mon Dieu, et épargnez-moi, selon la plénitude de votre miséricorde.
23 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, mo rí àwọn ọkùnrin Juda tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin láti Aṣdodu, Ammoni àti Moabu.
Or, en ces jours-là, je vis que des Juifs avaient épousé des femmes d'Azot, et des Ammonites et des Moabites.
24 Ìdajì àwọn ọmọ wọn ń sọ èdè Aṣdodu tàbí èdè ọ̀kan lára àwọn ènìyàn mìíràn tókù, wọn kò sì mọ bí a ṣe ń sọ èdè Juda.
Et leurs fils parlaient à demi la langue d'Azot, et ils ne savaient point parler juif.
25 Mo bá wọn wí mo sì gégùn ún lé wọn lórí. Mo lu àwọn ènìyàn díẹ̀ nínú wọn mo sì fa irun orí wọn tu. Mo mú kí wọn búra ní orúkọ Ọlọ́run, kí wọn wí pé, “Ẹ̀yin kì yóò fi àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin yín ní ìyàwó tàbí fún ẹ̀yin tìkára yín.
Et je les réprimandai, et je les maudis, et j'en frappai quelques-uns, et je leur rasai la tête, et je leur fis jurer devant Dieu de ne point donner leurs filles aux fils des étrangers, et de ne point faire épouser par leurs fils des filles étrangères, disant:
26 Kì í ha á ṣe àwọn ìgbéyàwó bí irú èyí ni ọba Solomoni fi dá ẹ̀ṣẹ̀? Láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, kò sí ọba kan bí i tirẹ̀. Ọlọ́run rẹ̀ fẹ́ràn rẹ̀, Ọlọ́run sì fi jẹ ọba lórí i gbogbo Israẹli, ṣùgbọ́n àwọn obìnrin àjèjì ti sọ ọ́ sínú òfin ẹ̀ṣẹ̀.
N'est-ce pas là le péché de Salomon, roi d'Israël? Il n'y avait point son pareil parmi les rois des nations: il aimait Dieu, Dieu lui avait donné le royaume entier d'Israël, et les femmes étrangères le pervertirent.
27 Ǹjẹ́ ó ha yẹ kí àwa tún gbọ́ báyìí pé ẹ̀yin náà tún ń ṣe àwọn nǹkan tí ó burú jọjọ wọ̀nyí tí ẹ sì ń ṣe aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì?”
Que nous n'apprenions plus que vous faites ce péché; que vous violez l'alliance avec notre Dieu; que vous épousez des femmes étrangères.
28 Ọ̀kan lára àwọn ọmọ Joiada, ọmọ Eliaṣibu olórí àlùfáà jẹ́ àna Sanballati ará a Horoni. Mo sì lé e jáde kúrò lọ́dọ̀ mi.
Or, l'un des fils de Joad, le grand prêtre Elisab, était gendre de Sanaballat l'Horonite; je le chassai loin de moi.
29 Rántí wọn, Ọlọ́run mi, nítorí wọ́n ti ba iṣẹ́ àlùfáà jẹ́ pẹ̀lú májẹ̀mú iṣẹ́ àlùfáà àti ti àwọn Lefi.
Souvenez-vous d'eux, ô Seigneur, à cause de la violation du sacerdoce, et de votre alliance, touchant les prêtres et les lévites.
30 Nítorí náà, mo ya àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi sí mímọ́ kúrò nínú gbogbo ohun àjèjì, mo sì yan iṣẹ́ fún wọn, olúkúlùkù sí ẹnu iṣẹ́ rẹ̀.
Et je les purifiai de leur contact avec des étrangères, et je réglai les services journaliers des prêtres et des lévites,
31 Mo sì tún pèsè fún ọrẹ, igi—pákó ní àkókò tí a yàn àti fún àwọn èso àkọ́so. Rántí mi fún rere, Ọlọ́run mi.
Et l'offrande du bois des holocaustes au temps prescrit, lorsque l'on taille la vigne. Souvenez-vous de moi, ô mon Dieu, dans votre mansuétude.

< Nehemiah 13 >