< Nehemiah 13 >

1 Ní ọjọ́ náà ni a ka ìwé Mose sókè sí etí ìgbọ́ àwọn ènìyàn, nínú rẹ̀ ni a ti rí i tí a kọ ọ́ sílẹ̀ pé a kò gbọdọ̀ gba àwọn ará a Ammoni tàbí àwọn ará a Moabu sí àárín ìjọ ènìyàn Ọlọ́run láéláé.
Ce jour-là, on lut dans le livre de Moïse, à l'oreille du peuple, et l'on trouva écrit qu'un Ammonite et un Moabite ne devaient pas entrer à jamais dans l'assemblée de Dieu,
2 Nítorí wọn kò mú oúnjẹ àti omi wá pàdé àwọn ọmọ Israẹli lọ́nà, dípò bẹ́ẹ̀, wọ́n bẹ Balaamu ní ọ̀wẹ̀ láti gégùn ún lé wọn lórí. (Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa yí ègún náà padà sí ìbùkún.)
parce qu'ils n'allaient pas au-devant des enfants d'Israël avec du pain et de l'eau, mais qu'ils engageaient contre eux Balaam pour les maudire; cependant, notre Dieu changea la malédiction en bénédiction.
3 Nígbà tí àwọn ènìyàn gbọ́ òfin yìí, wọ́n yọ gbogbo àwọn àjèjì ènìyàn tí ó darapọ̀ mọ́ wọn kúrò láàrín àwọn Israẹli.
Lorsqu'ils eurent entendu la loi, ils séparèrent d'Israël toute la multitude mélangée.
4 Ṣáájú èyí a ti fi Eliaṣibu àlùfáà ṣe alákòóso yàrá ìkó nǹkan ilé Ọlọ́run wa sí. Ó súnmọ́ Tobiah pẹ́kípẹ́kí.
Avant cela, le prêtre Éliaschib, qui était préposé aux chambres de la maison de notre Dieu, étant allié à Tobija,
5 Ó sì ti pèsè yàrá ńlá kan fún un, èyí tí a ń lò tẹ́lẹ̀ fún ìtọ́jú ọrẹ ọkà, tùràrí àti àwọn ohun èlò tẹmpili àti ìdámẹ́wàá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró ti a fi lélẹ̀ bí ìlànà fún àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà àti pẹ̀lú gbogbo ọrẹ fún àwọn àlùfáà.
avait préparé pour lui une grande salle, où l'on déposait les offrandes, l'encens, les vases, les dîmes du blé, du vin nouveau et de l'huile, qui étaient donnés par ordre aux Lévites, aux chantres et aux portiers, et les offrandes d'ondulations pour les prêtres.
6 Ṣùgbọ́n nígbà tí gbogbo èyí ń lọ lọ́wọ́, èmi kò sí ní Jerusalẹmu, nítorí pé ní ọdún kejìlélọ́gbọ̀n Artasasta ọba Babeli ni mo padà tọ ọba lọ. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó ṣe díẹ̀, mo gba ààyè lọ́dọ̀ọ rẹ̀.
Mais en tout cela, je n'étais pas à Jérusalem; car la trente-deuxième année d'Artaxerxès, roi de Babylone, je me rendis auprès du roi; quelques jours après, je demandai congé au roi,
7 Mo sì padà sí Jerusalẹmu. Níhìn-ín ni mo ti mọ̀ nípa onírúurú ohun búburú tí Eliaṣibu ti ṣe ní ti pípèsè yàrá fún Tobiah nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run.
et j'arrivai à Jérusalem, où je compris le mal qu'Eliashib avait fait à Tobija, en lui préparant une chambre dans les parvis de la maison de Dieu.
8 Kò tẹ́ mi lọ́rùn rárá, mo kó gbogbo ohun èlò ìdílé e Tobiah dà síta láti inú iyàrá náà.
Cela m'a beaucoup peiné. C'est pourquoi j'ai jeté hors de la chambre tous les effets personnels de Tobija.
9 Mo pàṣẹ kí wọn ya àwọn iyàrá náà sí mímọ́, mo sì kó àwọn ohun èlò ilé Ọlọ́run padà síbẹ̀ pẹ̀lú ọrẹ ọkà àti tùràrí.
Puis j'ai donné des ordres, et on a nettoyé les chambres. J'y apportai les vases de la maison de Dieu, avec les offrandes de repas et l'encens de nouveau.
10 Mo sì tún gbọ́ pé, kò fi àwọn ìpín tí a yà sọ́tọ̀ fún àwọn Lefi, àwọn akọrin tí ń ṣe àkóso ìsìn sì ti padà sí ẹnu onírúurú iṣẹ́ wọn.
Je m'aperçus que les parts des Lévites ne leur avaient pas été données, de sorte que les Lévites et les chantres, qui faisaient le travail, s'étaient enfuis chacun dans son champ.
11 Nígbà náà ni mo bá àwọn ìjòyè wí, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí a fi kọ ilé Ọlọ́run sílẹ̀?” Nígbà náà ni mo pè wọ́n jọ pọ̀, mo sì fi olúkúlùkù sí ẹnu iṣẹ́ rẹ̀.
Alors je contestai avec les chefs, et je dis: « Pourquoi la maison de Dieu est-elle abandonnée? » Je les rassemblai et les remis à leur place.
12 Gbogbo Juda mú ìdámẹ́wàá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró wá sínú yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí.
Alors tout Juda apporta aux trésors la dîme du blé, du vin nouveau et de l'huile.
13 Mo sì fi àlùfáà Ṣelemiah, Sadoku akọ̀wé àti ọmọ Lefi kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Pedaiah ṣe alákòóso àwọn yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí. Mo sì yan Hanani ọmọ Sakkuri, ọmọ Mattaniah bí olùrànlọ́wọ́ ọ wọn. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ni a kà sí àwọn tó ṣé e gbẹ́kẹ̀lé. Àwọn ni a yàn láti máa pín ohun èlò fún àwọn arákùnrin wọn.
J'établis comme trésoriers des trésors le sacrificateur Schélémia, le scribe Tsadok, et Pedaja, l'un des Lévites; Hanan, fils de Zaccur, fils de Matthania, était à côté d'eux, car ils étaient considérés comme fidèles, et leur tâche était de distribuer à leurs frères.
14 Rántí ì mi fún èyí, Ọlọ́run mi, kí o má sì ṣe gbàgbé ohun tí mo fi òtítọ́ ṣe fún ilé Ọlọ́run mi yìí àti fún iṣẹ́ ẹ rẹ̀ gbogbo.
Souviens-toi de moi, mon Dieu, à propos de ceci, et n'efface pas mes bonnes actions que j'ai faites pour la maison de mon Dieu et pour ses observances.
15 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, mo rí àwọn ènìyàn ní Juda tí wọ́n ń fúntí ní ọjọ́ ìsinmi, tí wọ́n sì ń gbé ọkà wọlé, tí wọn ń di ẹrù lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ pẹ̀lú wáìnì, èso àjàrà, ọ̀pọ̀tọ́ àti onírúurú ẹrù. Wọ́n sì ń kó gbogbo èyí wá sí Jerusalẹmu ní ọjọ́ ìsinmi. Nítorí náà, mo kìlọ̀ fún wọn nípa títa oúnjẹ ní ọjọ́ náà.
En ce temps-là, j'ai vu en Juda des hommes qui foulaient des pressoirs le jour du sabbat, qui apportaient des gerbes et chargeaient des ânes de vin, de raisins, de figues et de toutes sortes de fardeaux qu'ils apportaient à Jérusalem le jour du sabbat; et j'ai rendu témoignage contre eux le jour où ils vendaient des aliments.
16 Àwọn ará Tire ti ń gbé nínú Jerusalẹmu ń gbé ẹja àti onírúurú ọjà wá fún títà ní ọjọ́ ìsinmi fún àwọn ènìyàn Jerusalẹmu àti fún àwọn ọmọ Juda.
Il y avait là aussi des hommes de Tyr, qui apportaient du poisson et toutes sortes de marchandises, et vendaient le jour du sabbat aux enfants de Juda et à Jérusalem.
17 Mo bá àwọn ọlọ́lá Juda wí, mo wí fún wọn pé, “Èwo ni ohun búburú tí ẹ ń ṣe yìí ti ẹ ń ba ọjọ́ ìsinmi jẹ́.
Alors je contestai avec les nobles de Juda, et je leur dis: « Quelle est cette mauvaise action que vous faites, et qui consiste à profaner le jour du sabbat?
18 Ṣé àwọn baba ńlá yín kò ha ti ṣe nǹkan kan náà tí Ọlọ́run wa fi mú gbogbo àjálù yìí wá orí wa, àti sórí ìlú yìí? Báyìí, ẹ̀yin tún ń ru ìbínú sókè sí i sórí Israẹli nípa bíba ọjọ́ ìsinmi jẹ́.”
Vos pères n'ont-ils pas fait cela, et notre Dieu n'a-t-il pas fait venir tout ce mal sur nous et sur cette ville? Mais vous attirez encore plus de colère sur Israël en profanant le sabbat. »
19 Nígbà tí ojú ọjọ́ ń bora ní ẹnu ibodè Jerusalẹmu, ṣáájú ọjọ́ ìsinmi, mo pàṣẹ pé kí a ti àwọn ìlẹ̀kùn, kí wọn má sì ṣí i títí tí ọjọ́ ìsinmi yóò fi kọjá. Mo yan àwọn ìránṣẹ́ mi láti ṣọ́ ẹnu ibodè, kí a má ba à lè gbé ẹrù kankan wọlé ní ọjọ́ ìsinmi.
Lorsque les portes de Jérusalem commencèrent à s'obscurcir avant le sabbat, j'ordonnai de fermer les portes et de ne les ouvrir qu'après le sabbat. Je confiai la surveillance des portes à quelques-uns de mes serviteurs, afin qu'aucun fardeau ne soit introduit le jour du sabbat.
20 Síbẹ̀, àwọn tí ń tà àti àwọn tí ń rà sùn ẹ̀yìn odi Jerusalẹmu ní ẹ̀ẹ̀kan tàbí ẹ̀ẹ̀mejì.
Les marchands et les vendeurs de toutes sortes de marchandises campaient donc une ou deux fois devant Jérusalem.
21 Ṣùgbọ́n mo kìlọ̀ fún wọn pé, “Èétijẹ́ ti ẹ̀yin fi ń sùn ní ẹ̀yin odi ní òru? Bí ẹ̀yìn bá tún dánwò mọ́, èmi yóò fi ọwọ́ líle mú yín.” Láti ọjọ́ náà lọ, wọn kò sì wá ní ọjọ́ ìsinmi mọ́.
Je leur rendis alors témoignage et leur dis: « Pourquoi restez-vous autour de la muraille? Si vous le faites encore, je mettrai la main sur vous. » À partir de ce moment-là, ils ne vinrent plus le jour du sabbat.
22 Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún àwọn ọmọ Lefi pé kí wọn ya ara wọn sí mímọ́, kí wọn sì ṣọ́ ẹnu ibodè kí a lè pa ọjọ́ ìsinmi mọ́. Tún rántí mi fún èyí, Ọlọ́run mi, kí o sì fi àánú un rẹ hàn fún mi gẹ́gẹ́ bí i títóbi ìfẹ́ ẹ̀ rẹ.
J'ai ordonné aux Lévites de se purifier et de venir garder les portes, afin de sanctifier le jour du sabbat. Souviens-toi de moi pour cela aussi, mon Dieu, et épargne-moi selon la grandeur de ta bonté.
23 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, mo rí àwọn ọkùnrin Juda tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin láti Aṣdodu, Ammoni àti Moabu.
En ce temps-là, je vis aussi des Juifs qui avaient épousé des femmes d'Asdod, d'Ammon et de Moab;
24 Ìdajì àwọn ọmọ wọn ń sọ èdè Aṣdodu tàbí èdè ọ̀kan lára àwọn ènìyàn mìíràn tókù, wọn kò sì mọ bí a ṣe ń sọ èdè Juda.
et leurs enfants parlaient à demi dans la langue d'Asdod, et ne pouvaient parler dans la langue des Juifs, mais selon la langue de chaque peuple.
25 Mo bá wọn wí mo sì gégùn ún lé wọn lórí. Mo lu àwọn ènìyàn díẹ̀ nínú wọn mo sì fa irun orí wọn tu. Mo mú kí wọn búra ní orúkọ Ọlọ́run, kí wọn wí pé, “Ẹ̀yin kì yóò fi àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin yín ní ìyàwó tàbí fún ẹ̀yin tìkára yín.
Je les disputai, je les maudis, je frappai quelques-uns d'entre eux, j'arrachai leurs cheveux, et je leur fis jurer par Dieu: Vous ne donnerez pas vos filles à leurs fils, et vous ne prendrez pas leurs filles pour vos fils ou pour vous-mêmes.
26 Kì í ha á ṣe àwọn ìgbéyàwó bí irú èyí ni ọba Solomoni fi dá ẹ̀ṣẹ̀? Láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, kò sí ọba kan bí i tirẹ̀. Ọlọ́run rẹ̀ fẹ́ràn rẹ̀, Ọlọ́run sì fi jẹ ọba lórí i gbogbo Israẹli, ṣùgbọ́n àwọn obìnrin àjèjì ti sọ ọ́ sínú òfin ẹ̀ṣẹ̀.
Salomon, roi d'Israël, n'a-t-il pas péché par ces choses? Pourtant, parmi les nombreuses nations, il n'y avait pas de roi comme lui, et il était aimé de son Dieu, et Dieu l'a établi roi sur tout Israël. Mais les femmes étrangères l'ont fait pécher, lui aussi.
27 Ǹjẹ́ ó ha yẹ kí àwa tún gbọ́ báyìí pé ẹ̀yin náà tún ń ṣe àwọn nǹkan tí ó burú jọjọ wọ̀nyí tí ẹ sì ń ṣe aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì?”
Allons-nous donc vous écouter pour faire tout ce grand mal, pour transgresser notre Dieu en épousant des femmes étrangères? ".
28 Ọ̀kan lára àwọn ọmọ Joiada, ọmọ Eliaṣibu olórí àlùfáà jẹ́ àna Sanballati ará a Horoni. Mo sì lé e jáde kúrò lọ́dọ̀ mi.
L'un des fils de Jojada, fils d'Eliashib, le grand prêtre, était gendre de Sanballat, le Horonite; c'est pourquoi je l'ai chassé de moi.
29 Rántí wọn, Ọlọ́run mi, nítorí wọ́n ti ba iṣẹ́ àlùfáà jẹ́ pẹ̀lú májẹ̀mú iṣẹ́ àlùfáà àti ti àwọn Lefi.
Souviens-toi d'eux, mon Dieu, car ils ont souillé le sacerdoce et l'alliance du sacerdoce et des Lévites.
30 Nítorí náà, mo ya àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi sí mímọ́ kúrò nínú gbogbo ohun àjèjì, mo sì yan iṣẹ́ fún wọn, olúkúlùkù sí ẹnu iṣẹ́ rẹ̀.
C'est ainsi que je les ai purifiés de tout étranger et que j'ai établi des fonctions pour les prêtres et les lévites, chacun dans son travail;
31 Mo sì tún pèsè fún ọrẹ, igi—pákó ní àkókò tí a yàn àti fún àwọn èso àkọ́so. Rántí mi fún rere, Ọlọ́run mi.
ainsi que pour l'offrande de bois, aux temps fixés, et pour les prémices. Souviens-toi de moi, mon Dieu, pour le bien.

< Nehemiah 13 >