< Nehemiah 13 >

1 Ní ọjọ́ náà ni a ka ìwé Mose sókè sí etí ìgbọ́ àwọn ènìyàn, nínú rẹ̀ ni a ti rí i tí a kọ ọ́ sílẹ̀ pé a kò gbọdọ̀ gba àwọn ará a Ammoni tàbí àwọn ará a Moabu sí àárín ìjọ ènìyàn Ọlọ́run láéláé.
V ten den čteno jest v knize Mojžíšově, tak že lid slyšeti mohl. I nalezeno v ní napsáno, že nemá vjíti Ammonitský a Moábský do shromáždění Božího až na věky,
2 Nítorí wọn kò mú oúnjẹ àti omi wá pàdé àwọn ọmọ Israẹli lọ́nà, dípò bẹ́ẹ̀, wọ́n bẹ Balaamu ní ọ̀wẹ̀ láti gégùn ún lé wọn lórí. (Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa yí ègún náà padà sí ìbùkún.)
Proto že nevyšli proti synům Izraelským s chlebem a s vodou, ale najali ze mzdy proti nim Baláma, aby jim zlořečil, ačkoli obrátil Bůh náš to zlořečení v požehnání.
3 Nígbà tí àwọn ènìyàn gbọ́ òfin yìí, wọ́n yọ gbogbo àwọn àjèjì ènìyàn tí ó darapọ̀ mọ́ wọn kúrò láàrín àwọn Israẹli.
Stalo se pak, když slyšeli zákon, že odmísili všecky přimíšené od Izraele.
4 Ṣáájú èyí a ti fi Eliaṣibu àlùfáà ṣe alákòóso yàrá ìkó nǹkan ilé Ọlọ́run wa sí. Ó súnmọ́ Tobiah pẹ́kípẹ́kí.
Ale před tím Eliasib kněz, správce komory domu Boha našeho, spříznil se s Tobiášem.
5 Ó sì ti pèsè yàrá ńlá kan fún un, èyí tí a ń lò tẹ́lẹ̀ fún ìtọ́jú ọrẹ ọkà, tùràrí àti àwọn ohun èlò tẹmpili àti ìdámẹ́wàá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró ti a fi lélẹ̀ bí ìlànà fún àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà àti pẹ̀lú gbogbo ọrẹ fún àwọn àlùfáà.
Kterémuž udělal pokoj veliký, kdež prvé skládali dary, kadidlo a nádoby, a desátky z obilé, mstu a oleje nového, nařízené Levítům a zpěvákům i vrátným, též i obět kněžím.
6 Ṣùgbọ́n nígbà tí gbogbo èyí ń lọ lọ́wọ́, èmi kò sí ní Jerusalẹmu, nítorí pé ní ọdún kejìlélọ́gbọ̀n Artasasta ọba Babeli ni mo padà tọ ọba lọ. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó ṣe díẹ̀, mo gba ààyè lọ́dọ̀ọ rẹ̀.
Ale když se to vše dálo, nebyl jsem v Jeruzalémě. Nebo léta třidcátého druhého Artaxerxa krále Babylonského přišel jsem k králi, a po přeběhnutí let, vyžádán jsem na králi.
7 Mo sì padà sí Jerusalẹmu. Níhìn-ín ni mo ti mọ̀ nípa onírúurú ohun búburú tí Eliaṣibu ti ṣe ní ti pípèsè yàrá fún Tobiah nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run.
Když jsem pak přišel do Jeruzaléma, srozuměl jsem tomu zlému, co učinil Eliasib pro Tobiáše, udělav mu pokoj v síních domu Božího.
8 Kò tẹ́ mi lọ́rùn rárá, mo kó gbogbo ohun èlò ìdílé e Tobiah dà síta láti inú iyàrá náà.
Což mi se velmi nelíbilo. Protož vyházel jsem všecko nádobí domu Tobiášova ven z toho pokoje.
9 Mo pàṣẹ kí wọn ya àwọn iyàrá náà sí mímọ́, mo sì kó àwọn ohun èlò ilé Ọlọ́run padà síbẹ̀ pẹ̀lú ọrẹ ọkà àti tùràrí.
A rozkázal jsem očistiti ty pokoje. I vnesl jsem tam zase nádoby domu Božího, dary a kadidlo.
10 Mo sì tún gbọ́ pé, kò fi àwọn ìpín tí a yà sọ́tọ̀ fún àwọn Lefi, àwọn akọrin tí ń ṣe àkóso ìsìn sì ti padà sí ẹnu onírúurú iṣẹ́ wọn.
Potom dověděv se, že dílové Levítům nebyli dáváni, a že rozběhli se jeden každý na svou rolí, Levítové i zpěváci vedoucí práci,
11 Nígbà náà ni mo bá àwọn ìjòyè wí, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí a fi kọ ilé Ọlọ́run sílẹ̀?” Nígbà náà ni mo pè wọ́n jọ pọ̀, mo sì fi olúkúlùkù sí ẹnu iṣẹ́ rẹ̀.
Protož domlouval jsem se na starší, řka: Proč jest opuštěn dům Boží? A shromáždiv je, postavil jsem je na místě jejich.
12 Gbogbo Juda mú ìdámẹ́wàá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró wá sínú yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí.
A všecken Juda přinášeli desátky obilé, mstu a oleje nového do skladů.
13 Mo sì fi àlùfáà Ṣelemiah, Sadoku akọ̀wé àti ọmọ Lefi kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Pedaiah ṣe alákòóso àwọn yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí. Mo sì yan Hanani ọmọ Sakkuri, ọmọ Mattaniah bí olùrànlọ́wọ́ ọ wọn. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ni a kà sí àwọn tó ṣé e gbẹ́kẹ̀lé. Àwọn ni a yàn láti máa pín ohun èlò fún àwọn arákùnrin wọn.
A ustanovil jsem úředníky nad sklady: Selemiáše kněze, a Sádocha učitele, a Pedaiáše z Levítů, přidav k nim Chanana syna Zakurova, syna Mattaniášova; nebo za věrné jmíni byli. A ti měli rozdělovati bratřím svým.
14 Rántí ì mi fún èyí, Ọlọ́run mi, kí o má sì ṣe gbàgbé ohun tí mo fi òtítọ́ ṣe fún ilé Ọlọ́run mi yìí àti fún iṣẹ́ ẹ rẹ̀ gbogbo.
Budiž pamětliv na mne, Bože můj, pro to, a nevyhlazuj dobrodiní mých, kteráž jsem prokázal k domu Boha svého i k službám jeho.
15 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, mo rí àwọn ènìyàn ní Juda tí wọ́n ń fúntí ní ọjọ́ ìsinmi, tí wọ́n sì ń gbé ọkà wọlé, tí wọn ń di ẹrù lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ pẹ̀lú wáìnì, èso àjàrà, ọ̀pọ̀tọ́ àti onírúurú ẹrù. Wọ́n sì ń kó gbogbo èyí wá sí Jerusalẹmu ní ọjọ́ ìsinmi. Nítorí náà, mo kìlọ̀ fún wọn nípa títa oúnjẹ ní ọjọ́ náà.
V těch dnech viděl jsem v Judstvu, ani tlačí presem v sobotu, a přinášejí snopy, kteréž nakládali na osly, též víno, hrozny, fíky i všeliká břemena, a snášejí v den sobotní do Jeruzaléma. I domlouval jsem jim v ten den, když prodávali potravu.
16 Àwọn ará Tire ti ń gbé nínú Jerusalẹmu ń gbé ẹja àti onírúurú ọjà wá fún títà ní ọjọ́ ìsinmi fún àwọn ènìyàn Jerusalẹmu àti fún àwọn ọmọ Juda.
Tyrští také, kteříž bydlili v něm, nosili ryby i všelijaké koupě, a prodávali v sobotu synům Juda, a to v Jeruzalémě.
17 Mo bá àwọn ọlọ́lá Juda wí, mo wí fún wọn pé, “Èwo ni ohun búburú tí ẹ ń ṣe yìí ti ẹ ń ba ọjọ́ ìsinmi jẹ́.
Protož jsem domlouval starším Judským, a řekl jsem jim: Jaká jest to nepravost, kterouž činíte, poškvrňujíce dne sobotního?
18 Ṣé àwọn baba ńlá yín kò ha ti ṣe nǹkan kan náà tí Ọlọ́run wa fi mú gbogbo àjálù yìí wá orí wa, àti sórí ìlú yìí? Báyìí, ẹ̀yin tún ń ru ìbínú sókè sí i sórí Israẹli nípa bíba ọjọ́ ìsinmi jẹ́.”
Zdaliž jsou tak nečinili otcové vaši? Pročež Bůh náš přivedl na nás všecko toto zlé, i na toto město, a vy přidáváte hněvivosti na Izraele, poškvrňujíce soboty.
19 Nígbà tí ojú ọjọ́ ń bora ní ẹnu ibodè Jerusalẹmu, ṣáájú ọjọ́ ìsinmi, mo pàṣẹ pé kí a ti àwọn ìlẹ̀kùn, kí wọn má sì ṣí i títí tí ọjọ́ ìsinmi yóò fi kọjá. Mo yan àwọn ìránṣẹ́ mi láti ṣọ́ ẹnu ibodè, kí a má ba à lè gbé ẹrù kankan wọlé ní ọjọ́ ìsinmi.
Když tedy byly v stínu brány Jeruzalémské před sobotou, rozkázal jsem zavříti brány, a rozkázal jsem, aby jich neotvírali až po sobotě. K tomu i z služebníků svých některé postavil jsem v bráně, aby náklad nebyl vezen do města v sobotu.
20 Síbẹ̀, àwọn tí ń tà àti àwọn tí ń rà sùn ẹ̀yìn odi Jerusalẹmu ní ẹ̀ẹ̀kan tàbí ẹ̀ẹ̀mejì.
Protož zůstali kupci a prodavači všelijakých věcí prodajných vně před Jeruzalémem, jednou i podruhé.
21 Ṣùgbọ́n mo kìlọ̀ fún wọn pé, “Èétijẹ́ ti ẹ̀yin fi ń sùn ní ẹ̀yin odi ní òru? Bí ẹ̀yìn bá tún dánwò mọ́, èmi yóò fi ọwọ́ líle mú yín.” Láti ọjọ́ náà lọ, wọn kò sì wá ní ọjọ́ ìsinmi mọ́.
I osvědčil jsem se jim, řka jim: Proč zůstáváte přes noc naproti zdi? Učiníte-li to více, vztáhnu ruku na vás. Od té chvíle nepřicházeli v sobotu.
22 Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún àwọn ọmọ Lefi pé kí wọn ya ara wọn sí mímọ́, kí wọn sì ṣọ́ ẹnu ibodè kí a lè pa ọjọ́ ìsinmi mọ́. Tún rántí mi fún èyí, Ọlọ́run mi, kí o sì fi àánú un rẹ hàn fún mi gẹ́gẹ́ bí i títóbi ìfẹ́ ẹ̀ rẹ.
Rozkázal jsem pak Levítům, aby se očistili, a přijdouce, ostříhali bran, a světili den sobotní. Také i v tom pamatuj na mne, Bože můj, a buď mi milostiv podlé množství milosrdenství svého.
23 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, mo rí àwọn ọkùnrin Juda tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin láti Aṣdodu, Ammoni àti Moabu.
V těch dnech spatřil jsem také Židy, kteříž byli pojali ženy Azotské, Ammonitské a Moábské,
24 Ìdajì àwọn ọmọ wọn ń sọ èdè Aṣdodu tàbí èdè ọ̀kan lára àwọn ènìyàn mìíràn tókù, wọn kò sì mọ bí a ṣe ń sọ èdè Juda.
An synové jejich mluvili od polu Azotsky, a neuměli mluviti Židovsky, ale podlé jazyku každého toho lidu.
25 Mo bá wọn wí mo sì gégùn ún lé wọn lórí. Mo lu àwọn ènìyàn díẹ̀ nínú wọn mo sì fa irun orí wọn tu. Mo mú kí wọn búra ní orúkọ Ọlọ́run, kí wọn wí pé, “Ẹ̀yin kì yóò fi àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin yín ní ìyàwó tàbí fún ẹ̀yin tìkára yín.
Protož domlouval jsem jim, a zlořečil jsem jim, a některé z nich bil jsem a rval, přísahou je zavazuje skrze Boha, řka: Budete-li dávati dcery své synům jejich, aneb bráti dcery jejich synům svým neb sobě, zlořečení budete.
26 Kì í ha á ṣe àwọn ìgbéyàwó bí irú èyí ni ọba Solomoni fi dá ẹ̀ṣẹ̀? Láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, kò sí ọba kan bí i tirẹ̀. Ọlọ́run rẹ̀ fẹ́ràn rẹ̀, Ọlọ́run sì fi jẹ ọba lórí i gbogbo Israẹli, ṣùgbọ́n àwọn obìnrin àjèjì ti sọ ọ́ sínú òfin ẹ̀ṣẹ̀.
Zdaliž tím nezhřešil Šalomoun král Izraelský? Ješto ve mnohých národech nebylo krále jemu podobného, kterýž byl milý Bohu svému, tak že ustanovil jej Bůh králem nade vším Izraelem, však i toho k hříchu přivedly ženy cizozemky.
27 Ǹjẹ́ ó ha yẹ kí àwa tún gbọ́ báyìí pé ẹ̀yin náà tún ń ṣe àwọn nǹkan tí ó burú jọjọ wọ̀nyí tí ẹ sì ń ṣe aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì?”
A vám zdali povolíme, abyste se dopouštěli všeho toho zlého velikého, a přestupovali proti Bohu svému, pojímajíce ženy cizozemky?
28 Ọ̀kan lára àwọn ọmọ Joiada, ọmọ Eliaṣibu olórí àlùfáà jẹ́ àna Sanballati ará a Horoni. Mo sì lé e jáde kúrò lọ́dọ̀ mi.
Z synů pak Joiady syna Eliasiba, kněze nejvyššího, jeden byl zeť Sanballata Choronského, kteréhož jsem zahnal od sebe.
29 Rántí wọn, Ọlọ́run mi, nítorí wọ́n ti ba iṣẹ́ àlùfáà jẹ́ pẹ̀lú májẹ̀mú iṣẹ́ àlùfáà àti ti àwọn Lefi.
Budiž pamětliv na to, Bože můj, proti těm, kteříž poškvrňují kněžství, a smlouvy kněžské i Levítské.
30 Nítorí náà, mo ya àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi sí mímọ́ kúrò nínú gbogbo ohun àjèjì, mo sì yan iṣẹ́ fún wọn, olúkúlùkù sí ẹnu iṣẹ́ rẹ̀.
Protož jsem je vyčistil od všelikého cizozemce, a ustanovil jsem zase třídy kněžím a Levítům, jednomu každému v práci jeho,
31 Mo sì tún pèsè fún ọrẹ, igi—pákó ní àkókò tí a yàn àti fún àwọn èso àkọ́so. Rántí mi fún rere, Ọlọ́run mi.
I nošení dříví k obětem časy uloženými, též i prvotin. Budiž pamětliv na mne, Bože můj, k mému dobrému.

< Nehemiah 13 >