< Nehemiah 12 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tí ó bá Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti Jeṣua padà: Seraiah, Jeremiah, Esra,
A cić są kapłani i Lewitowie, którzy przyszli z Zorobabelem, synem Sealtyjelowym, i z Jesuą: Serejasz, Jeremijasz, Ezdrasz.
2 Amariah, Malluki, Hattusi,
Amaryjasz, Malluch, Hattus,
3 Ṣekaniah, Rehumu, Meremoti,
Sechanijasz, Rehum, Meremot,
4 Iddo, Ginetoni, Abijah,
Iddo, Ginnetoj, Abijasz;
5 Mijamini, Moadiah, Bilgah,
Mijamin, Maadyjasz, Bilgal,
6 Ṣemaiah, Joiaribu, Jedaiah,
Semejasz, i Jojaryb, Jedajasz,
7 Sallu, Amoki, Hilkiah, àti Jedaiah. Wọ̀nyí ni olórí àwọn àlùfáà àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn ní ìgbà ayé e Jeṣua.
Sallu, Amok, Helkijasz, Jedajasz. Cić byli przedniejsi z kapłanów i z braci swych, za dni Jesuego.
8 Àwọn ọmọ Lefi ni Jeṣua, Binnui, Kadmieli, Ṣerebiah, Juda àti Mattaniah ẹni tí òun pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, ni wọn ṣe àkóso orin ìdúpẹ́.
A Lewitowie: Jesua, Binnui, Kadmiel, Serebijasz, Juda; Matanijasz nad pieśniami, sam i bracia jego.
9 Bakbukiah àti Unni, àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn dúró sí òdìkejì wọn nínú ìsìn.
A Bakbukijasz i Hunni, bracia ich, byli przeciwko nim w porządku swoim.
10 Jeṣua ni baba Joiakimu, Joiakimu ni baba Eliaṣibu, Eliaṣibu ni baba Joiada,
A Jesua spłodził Joakima, a Joakim spłodził Elijasyba, a Elijasyb spłodził Jojadę:
11 Joiada ni baba Jonatani, Jonatani sì ni baba Jaddua.
A Jojada spłodził Jonatana, a Jonatan spłodził Jadduę.
12 Ní ìgbé ayé Joiakimu, wọ̀nyí ni àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn àlùfáà: ti ìdílé Seraiah, Meraiah; ti ìdílé Jeremiah, Hananiah;
A za dni Joakima byli kapłani przedniejsi z domów ojcowskich: z Serajaszowego Merajasz, z Jeremijaszowego Chananijasz;
13 ti ìdílé Esra, Meṣullamu; ti ìdílé Amariah, Jehohanani;
Z Ezdraszowego Mesullam, z Amaryjaszowego Jochanan;
14 ti ìdílé Malluki, Jonatani; ti ìdílé Ṣekaniah, Josẹfu;
Z Melchowego Jonatan, z Sechanijaszowego Józef;
15 ti ìdílé Harimu, Adna; ti ìdílé Meraioti Helikai;
Z Harymowego Adna, z Merajotowego Helkaj;
16 ti ìdílé Iddo, Sekariah; ti ìdílé Ginetoni, Meṣullamu;
Z Iddowego Zacharyjasz, z Ginnetowego Mesullam;
17 ti ìdílé Abijah, Sikri; ti ìdílé Miniamini àti ti ìdílé Moadiah, Piltai;
Z Abijaszowego Zychry, z Miniaminowego i z Maadyjaszowego Piltaj;
18 ti ìdílé Bilgah, Ṣammua; ti ìdílé Ṣemaiah, Jehonatani;
Z Bilgowego Sammua, z Semejaszowego Jonatan;
19 ti ìdílé Joiaribu, Mattenai; ti ìdílé Jedaiah, Ussi;
A z Jojarybowego Mattenaj, z Jedajaszowego Uzy;
20 ti ìdílé Sallu, Kallai; ti ìdílé Amoki, Eberi;
Z Sallajowego Kalaj, z Amokowego Heber;
21 ti ìdílé Hilkiah, Haṣabiah; ti ìdílé Jedaiah, Netaneli.
Z Helkijaszowego Hasabijasz, z Jedajaszowego Natanael.
22 Àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi ní ìgbà ayé Eliaṣibu, Joiada, Johanani àti Jaddua, àti pẹ̀lú ti àwọn àlùfáà ni a kọ sílẹ̀ ní ìgbà ìjọba Dariusi ará Persia.
A Lewitowie za dni Elijasyba, Jojady, i Jochanana, i Jadduego popisani są, którzy byli przedniejszymi z domów ojcowskich; także i kapłani aż do królestwa Daryjusza, króla Perskiego.
23 Àwọn olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Lefi títí di àkókò Johanani ọmọ Eliaṣibu ni a kọ sílẹ̀ nínú ìwé ìtàn.
Synowie mówię Lewiego, przedniejsi z domów ojcowskich, zapisani są w księgach kroniki aż do dni Jochanana, syna Elijasybowego.
24 Àti àwọn olórí àwọn ọmọ Lefi ni Haṣabiah, Ṣerebiah, Jeṣua ọmọ Kadmieli, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n dúró ní ìdojúkojú wọn láti fi ìyìn àti láti dúpẹ́, apá kan ń dá èkejì lóhùn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run.
Przedniejsi mówię z Lewitów byli Hasabijasz, Serebijasz, i Jesua, syn Kadmielowy, i bracia ich przeciwko nim, ku chwaleniu i wysławianiu Boga według rozkazania Dawida, męża Bożego, straż przeciwko straży.
25 Mattaniah, Bakbukiah, Obadiah, Meṣullamu, Talmoni àti Akkubu ni aṣọ́nà tí wọ́n ń sọ yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ní ẹnu-ọ̀nà.
Matanijasz, i Bakbukijasz, Obadyjasz, Mesullam, Talmon, Akkub, byli stróżami odźwiernymi przy domu skarbu u bram.
26 Wọ́n ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ìgbà ayé e Joiakimu ọmọ Jeṣua, ọmọ Josadaki, àti ní ọjọ́ ọ Nehemiah baálẹ̀ àti ní ọjọ́ Esra àlùfáà àti akọ̀wé.
Cić byli za dni Joakima, syna Jesuego, syna Jozedekowego, i za dni Nehemijasza wodza, i Ezdrasza kapłana, nauczonego w Piśmie.
27 Nígbà ìyàsímímọ́ odi Jerusalẹmu a mú àwọn ọmọ Lefi jáde wá láti ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú wọn wá sí Jerusalẹmu láti fi ayọ̀ ṣe ayẹyẹ ìyàsímímọ́ pẹ̀lú orin ìdúpẹ́ àti pẹ̀lú ohun èlò orin kimbali, haapu àti ohun èlò orin olókùn.
A przy poświęcaniu muru Jeruzalemskiego szukano Lewitów ze wszystkich miejsc ich, aby ich przywiedziono do Jeruzalemu, żeby wykonali poświęcania i wesela, a to z wysławianiem i z śpiewaniem, z cymbałami, z lutniami, i z cytrami.
28 A kó àwọn akọrin náà jọ papọ̀ láti àwọn ìletò tí ó yí Jerusalẹmu náà ká—láti àwọn abúlé Netofa,
Przetoż zgromadzeni są synowie śpiewaków, i z równin około Jeruzalemu, i ze wsi Netofatyckich.
29 láti Beti-Gilgali, àti láti àwọn agbègbè Geba àti Asmafeti, nítorí àwọn akọrin ti kọ́ àwọn ìletò fúnra wọn ní agbègbè Jerusalẹmu.
Także z domu Gilgal, i z pól Gieba, i z Azmawet; bo sobie śpiewacy budowali wsi około Jeruzalemu.
30 Nígbà tí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n ya àwọn ènìyàn sí mímọ́, àti ẹnu ibodè àti odi pẹ̀lú.
A oczyściwszy się kapłani i Lewitowie, oczyścili też lud, i bramy, i mur.
31 Mo sì tún yan àwọn olórí Juda láti gun orí odi náà. Mo sì tún yan àwọn ẹgbẹ́ akọrin ńlá méjì láti dúpẹ́. Àwọn kan yóò gòkè odi lọ sí apá ọ̀tún sí ọ̀nà ibodè Ààtàn.
Zatemem rozkazał wstąpić książętom Judzkim na mur, i postawiłem dwa hufy wielkie chwalących, z których jedni szli na prawo od wyższej strony muru ku bramie gnojowej.
32 Hoṣaiah àti ìdajì àwọn olórí Juda tẹ̀lé wọn,
A za nimi szedł Hozajasz, i połowa książąt Judzkich;
33 àwọn wọ̀nyí náà sì lọ pẹ̀lú wọn, Asariah, Esra, Meṣullamu,
Także Azaryjasz, Ezdrasz, i Mesullam,
34 Juda, Benjamini, Ṣemaiah, Jeremiah,
Juda, i Benjamin, i Semejasz, i Jeremijasz.
35 pẹ̀lú àwọn àlùfáà díẹ̀ pẹ̀lú ìpè, pẹ̀lú u Sekariah ọmọ Jonatani, ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Mattaniah, ọmọ Mikaiah, ọmọ Sakkuri, ọmọ Asafu,
Potem niektórzy z synów kapłańskich z trąbami, mianowicie Zacharyjasz, syn Jonatana, syna Semejaszowego, syna Matanijaszowego, syna Michajaszowego, syna Zachurowego, syna Asafowego;
36 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, Ṣemaiah, Asareeli, Milalai, Gilalai, Maai, Netaneli, Juda àti Hanani—pẹ̀lú ohun èlò orin bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run. Esra akọ̀wé ni ó ṣáájú wọn bí wọ́n ti ń tò lọ lọ́wọ̀ọ̀wọ́.
A bracia jego Semejasz, i Asarel, Milalaj, Gilalaj, Maaj, Netaneel, i Juda, Chanani, z instrumentami muzycznemi Dawida, męża Bożego, a Ezdrasz, nauczony w Piśmie, przed nimi.
37 Ní ẹnu ibodè orísun wọ́n ti ń lọ tààrà sí ọ̀nà ní orí àtẹ̀gùn ìlú Dafidi ní orí òkè tí ó kángun sí odi, wọ́n sì gba ẹ̀gbẹ́ ilé Dafidi kọjá títí dé ẹnu ibodè omi ní ìhà ìlà-oòrùn.
Potem ku bramie źródła, która przeciwko nim była, wstępowali po schodach miasta Dawidowego, którędy chodzą na mur, a od muru przy domu Dawidowym aż do bramy wodnej na wschód słońca.
38 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin kejì gba ọ̀nà òdìkejì lọ. Mo tẹ̀lé wọn ní orí odi, pẹ̀lú ìdajì àwọn ènìyàn, kọjá ilé ìṣọ́ ìléru lọ sí odi fífẹ̀,
A drugi huf chwalących szedł przeciwko nim, a ja za nim, a połowa ludu po murze od wieży Tannurym aż do muru szerokiego;
39 kọjá ẹnu ibodè Efraimu ibodè Jeṣana, ẹnu ibodè ẹja, ilé ìṣọ́ Hananeli àti ilé ìṣọ́ ọgọ́rùn-ún, títí dé ẹnu ibodè àgùntàn. Wọ́n sì dúró ní ibodè ìṣọ́.
A od bramy Efraim ku bramie starej, i ku bramie rybnej, i wieży Chananeel, i wieży Mea, aż do bramy owczej. I stanął u bramy straży.
40 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin méjèèjì tí wọ́n dúpẹ́ wà ní ààyè nínú ilé Ọlọ́run, èmi náà sì dúró ní ààyè mi pẹ̀lú ìdajì àwọn ìjòyè,
Potem stanęły one dwa hufy chwalących w domu Bożym, i ja i połowa przełożonych ze mną.
41 àti àwọn àlùfáà Eliakimu, Maaseiah, Miniamini, Mikaiah, Elioenai, Sekariah àti Hananiah pẹ̀lú àwọn ìpè wọn.
Także kapłani: Elijakim, Maasejasz, Minijamin, Michajasz, Elijenaj, Zacharyjasz, Chananijasz, z trąbami;
42 Àti pẹ̀lú Maaseiah, Ṣemaiah, Eleasari àti Ussi, àti Jehohanani, àti Malkiah, àti Elamu, àti Eseri. Àwọn akọrin kọrin sókè ní abẹ́ alábojútó Jesrahiah.
I Maazyjasz, i Semejasz, i Eleazar, i Uzy, i Jochanan, i Malchyjasz, i Elam, i Ezer; a śpiewacy głośno śpiewali, i Izrachyjasz, przełożony ich.
43 Ní ọjọ́ náà wọ́n rú ẹbọ ńlá, wọ́n ṣe àjọyọ̀ nítorí Ọlọ́run ti fún wọn ní ayọ̀ ńlá. Àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé sì yọ̀ pẹ̀lú. A lè gbọ́ ariwo ayọ̀ tí ó jáde láti Jerusalẹmu ní jìnnà réré.
Sprawowali także onegoż dnia ofiary wielkie, i weselili się; albowiem Bóg rozweselił ich był weselem wielkiem, tak, iż się i niewiasty i dziatki weseliły; i było słyszeć wesele Jeruzalemskie daleko.
44 Ní àkókò náà, a yan àwọn ènìyàn láti jẹ́ alábojútó yàrá ìṣúra fún àwọn ọrẹ àkọ́so èso àti àwọn ìdámẹ́wàá. Láti inú àwọn oko tí ó wà ní àyíká ìlú ni wọ́n ti ní láti mú wá sínú yàrá ìṣúra, ìpín tí òfin sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, nítorí inú àwọn ará a Juda yọ́ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tó ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́.
Obrani też są dnia onego mężowie nad komorami skarbów, i ofiar, pierwocin, i dziesięcin, aby zgromadzali do nich z pól miejskich działy, zakonem warowane kapłanom i Lewitom; bo się weselił Juda z kapłanów i z Lewitów tam stojących;
45 Wọ́n ń ṣiṣẹ́ Ọlọ́run wọn àti iṣẹ́ ìyàsímímọ́, bẹ́ẹ̀ náà ni fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà, wọ́n ń ṣe gẹ́gẹ́ bí Dafidi àti Solomoni ọmọ rẹ̀ ti pàṣẹ fún wọn.
Którzy strzegli straży Boga swego, i straży oczyszczania, i śpiewaków, i odźwiernych, według rozkazania Dawida i Salomona, syna jego.
46 Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn ní ìgbà Dafidi àti Asafu, ni àwọn atọ́nisọ́nà ti wà fún àwọn akọrin àti fún orin ìyìn àti orin ọpẹ́ sí Ọlọ́run.
Bo za dni Dawida i Asafa byli postanowieni z starodawna przełożeni nad śpiewakami dla śpiewania, wychwalania i dziękczynienia Bogu.
47 Nítorí náà ní ìgbà ayé Serubbabeli àti Nehemiah, gbogbo Israẹli ni ó ń dá ìpín lójoojúmọ́ fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà. Wọ́n sì tún yan ìpín mìíràn sọ́tọ̀ fún àwọn ọmọ Lefi tókù, àwọn ọmọ Lefi náà tún ya ìpín ti àwọn ọmọ Aaroni sọ́tọ̀ fún wọn.
Przetoż wszystek Izrael za dni Zorobabela, i za dni Nehemijasza, dawali działy dla śpiewaków i odźwiernych, każdodzienny wymiar, a oddawali to, co poświęcili, Lewitom; Lewitowie zaś oddawali synom Aaronowym.

< Nehemiah 12 >