< Nehemiah 12 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tí ó bá Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti Jeṣua padà: Seraiah, Jeremiah, Esra,
Lalaba ngabapristi lamaLevi abenyuka loZerubhabheli indodana kaSalatiyeli, loJeshuwa: OSeraya, uJeremiya, uEzra,
2 Amariah, Malluki, Hattusi,
uAmariya, uMaluki, uHathushi,
3 Ṣekaniah, Rehumu, Meremoti,
uShekaniya, uRehuma, uMeremothi,
4 Iddo, Ginetoni, Abijah,
uIdo, uGinethoyi, uAbhiya,
5 Mijamini, Moadiah, Bilgah,
uMijamini, uMahadiya, uBiliga,
6 Ṣemaiah, Joiaribu, Jedaiah,
uShemaya, loJoyaribi, uJedaya,
7 Sallu, Amoki, Hilkiah, àti Jedaiah. Wọ̀nyí ni olórí àwọn àlùfáà àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn ní ìgbà ayé e Jeṣua.
uSalu, uAmoki, uHilikhiya, uJedaya. Laba babezinhloko zabapristi labafowabo ensukwini zikaJeshuwa.
8 Àwọn ọmọ Lefi ni Jeṣua, Binnui, Kadmieli, Ṣerebiah, Juda àti Mattaniah ẹni tí òun pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, ni wọn ṣe àkóso orin ìdúpẹ́.
LamaLevi: OJeshuwa, uBinuwi, uKadimiyeli, uSherebiya, uJuda, uMathaniya, babephezu kokubonga, yena labafowabo.
9 Bakbukiah àti Unni, àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn dúró sí òdìkejì wọn nínú ìsìn.
LoBakibukiya loUni, abafowabo, babeqondene labo emilindweni.
10 Jeṣua ni baba Joiakimu, Joiakimu ni baba Eliaṣibu, Eliaṣibu ni baba Joiada,
UJeshuwa wasezala uJoyakimi, uJoyakimi wasezala uEliyashibi, uEliyashibi wasezala uJoyada,
11 Joiada ni baba Jonatani, Jonatani sì ni baba Jaddua.
uJoyada wasezala uJonathani, uJonathani wasezala uJaduwa.
12 Ní ìgbé ayé Joiakimu, wọ̀nyí ni àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn àlùfáà: ti ìdílé Seraiah, Meraiah; ti ìdílé Jeremiah, Hananiah;
Lensukwini zikaJoyakimi abapristi, inhloko zaboyise, babengo: OkaSeraya nguMeraya; okaJeremiya nguHananiya;
13 ti ìdílé Esra, Meṣullamu; ti ìdílé Amariah, Jehohanani;
okaEzra nguMeshulamu; okaAmariya nguJehohanani;
14 ti ìdílé Malluki, Jonatani; ti ìdílé Ṣekaniah, Josẹfu;
okaMeliku nguJonathani; okaShebaniya nguJosefa;
15 ti ìdílé Harimu, Adna; ti ìdílé Meraioti Helikai;
okaHarimi nguAdina; okaMerayothi nguHelikayi;
16 ti ìdílé Iddo, Sekariah; ti ìdílé Ginetoni, Meṣullamu;
okaIdo nguZekhariya; okaGinethoni nguMeshulamu;
17 ti ìdílé Abijah, Sikri; ti ìdílé Miniamini àti ti ìdílé Moadiah, Piltai;
okaAbhiya nguZikiri; okaMiniyamini, okaMowadiya nguPilitayi;
18 ti ìdílé Bilgah, Ṣammua; ti ìdílé Ṣemaiah, Jehonatani;
okaBiliga nguShamuwa; okaShemaya nguJehonathani;
19 ti ìdílé Joiaribu, Mattenai; ti ìdílé Jedaiah, Ussi;
lokaJoyaribi nguMathenayi; okaJedaya nguUzi;
20 ti ìdílé Sallu, Kallai; ti ìdílé Amoki, Eberi;
okaSalayi nguKalayi; okaAmoki nguEberi;
21 ti ìdílé Hilkiah, Haṣabiah; ti ìdílé Jedaiah, Netaneli.
okaHilikhiya nguHashabhiya; okaJedaya nguNethaneli.
22 Àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi ní ìgbà ayé Eliaṣibu, Joiada, Johanani àti Jaddua, àti pẹ̀lú ti àwọn àlùfáà ni a kọ sílẹ̀ ní ìgbà ìjọba Dariusi ará Persia.
AmaLevi ensukwini zikaEliyashibi, oJoyada loJohanani loJaduwa, babhalwa baba zinhloko zaboyise, labapristi kwaze kwaba ngumbuso kaDariyusi umPerisiya.
23 Àwọn olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Lefi títí di àkókò Johanani ọmọ Eliaṣibu ni a kọ sílẹ̀ nínú ìwé ìtàn.
Amadodana kaLevi, inhloko zaboyise, abhalwa egwalweni lwemilando, kwaze kwaba sensukwini zikaJohanani indodana kaEliyashibi.
24 Àti àwọn olórí àwọn ọmọ Lefi ni Haṣabiah, Ṣerebiah, Jeṣua ọmọ Kadmieli, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n dúró ní ìdojúkojú wọn láti fi ìyìn àti láti dúpẹ́, apá kan ń dá èkejì lóhùn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run.
Lenhloko zamaLevi: OHashabhiya, uSherebiya, loJeshuwa indodana kaKadimiyeli, labafowabo maqondana labo, ukudumisa lokubonga, njengomlayo kaDavida umuntu kaNkulunkulu, umlindo maqondana lomlindo.
25 Mattaniah, Bakbukiah, Obadiah, Meṣullamu, Talmoni àti Akkubu ni aṣọ́nà tí wọ́n ń sọ yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ní ẹnu-ọ̀nà.
OMathaniya, loBakibukiya, uObhadiya, uMeshulamu, uTalimoni, uAkubi, babengabalindimasango belinda umlindo eziphaleni zamasango.
26 Wọ́n ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ìgbà ayé e Joiakimu ọmọ Jeṣua, ọmọ Josadaki, àti ní ọjọ́ ọ Nehemiah baálẹ̀ àti ní ọjọ́ Esra àlùfáà àti akọ̀wé.
Labo babekhona ensukwini zikaJoyakimi indodana kaJeshuwa indodana kaJozadaki, lensukwini zikaNehemiya umbusi, loEzra umpristi, umbhali.
27 Nígbà ìyàsímímọ́ odi Jerusalẹmu a mú àwọn ọmọ Lefi jáde wá láti ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú wọn wá sí Jerusalẹmu láti fi ayọ̀ ṣe ayẹyẹ ìyàsímímọ́ pẹ̀lú orin ìdúpẹ́ àti pẹ̀lú ohun èlò orin kimbali, haapu àti ohun èlò orin olókùn.
Lekwehlukaniselweni komduli weJerusalema badinga amaLevi evela ezindaweni zawo zonke ukuwaletha eJerusalema ukwenza ukwehlukaniswa, langentokozo, langokubonga, langokuhlabela, ngensimbi ezincencethayo, izigubhu zezintambo, langamachacho.
28 A kó àwọn akọrin náà jọ papọ̀ láti àwọn ìletò tí ó yí Jerusalẹmu náà ká—láti àwọn abúlé Netofa,
Amadodana abahlabeleli asebuthana, njalo evela emagcekeni azingelezele iJerusalema, lemizini yamaNetofa,
29 láti Beti-Gilgali, àti láti àwọn agbègbè Geba àti Asmafeti, nítorí àwọn akọrin ti kọ́ àwọn ìletò fúnra wọn ní agbègbè Jerusalẹmu.
leBeti-Giligali, lelizweni leGeba leAzimavethi, ngoba abahlabeleli babezakhele imizi ezingelezele iJerusalema.
30 Nígbà tí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n ya àwọn ènìyàn sí mímọ́, àti ẹnu ibodè àti odi pẹ̀lú.
Labapristi lamaLevi bazihlambulula, bahlambulula labantu lamasango lomduli.
31 Mo sì tún yan àwọn olórí Juda láti gun orí odi náà. Mo sì tún yan àwọn ẹgbẹ́ akọrin ńlá méjì láti dúpẹ́. Àwọn kan yóò gòkè odi lọ sí apá ọ̀tún sí ọ̀nà ibodè Ààtàn.
Ngasengisenza iziphathamandla zakoJuda zenyukele emdulini, ngamisa amaxuku amakhulu amabili okubonga lezindwendwe, elinye kwesokunene phezu komduli kusiya esangweni lomquba.
32 Hoṣaiah àti ìdajì àwọn olórí Juda tẹ̀lé wọn,
Lemva kwawo kwahamba oHoshaya, lengxenye yeziphathamandla zakoJuda,
33 àwọn wọ̀nyí náà sì lọ pẹ̀lú wọn, Asariah, Esra, Meṣullamu,
loAzariya, uEzra, loMeshulamu,
34 Juda, Benjamini, Ṣemaiah, Jeremiah,
uJuda, loBhenjamini, loShemaya, loJeremiya.
35 pẹ̀lú àwọn àlùfáà díẹ̀ pẹ̀lú ìpè, pẹ̀lú u Sekariah ọmọ Jonatani, ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Mattaniah, ọmọ Mikaiah, ọmọ Sakkuri, ọmọ Asafu,
Lakumadodana abapristi elezimpondo: OZekhariya indodana kaJonathani indodana kaShemaya indodana kaMathaniya indodana kaMikhaya indodana kaZakuri indodana kaAsafi,
36 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, Ṣemaiah, Asareeli, Milalai, Gilalai, Maai, Netaneli, Juda àti Hanani—pẹ̀lú ohun èlò orin bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run. Esra akọ̀wé ni ó ṣáájú wọn bí wọ́n ti ń tò lọ lọ́wọ̀ọ̀wọ́.
labafowabo, oShemaya, loAzareli, uMilalayi, uGilalayi, uMahayi, uNethaneli, loJuda, uHanani, belezinto zokuhlabelela zikaDavida umuntu kaNkulunkulu, loEzra umbhali ephambi kwabo.
37 Ní ẹnu ibodè orísun wọ́n ti ń lọ tààrà sí ọ̀nà ní orí àtẹ̀gùn ìlú Dafidi ní orí òkè tí ó kángun sí odi, wọ́n sì gba ẹ̀gbẹ́ ilé Dafidi kọjá títí dé ẹnu ibodè omi ní ìhà ìlà-oòrùn.
Langasesangweni lomthombo, njalo maqondana labo, benyuka ngezinyathelo zomuzi kaDavida, emqansweni womduli, ngaphezu kwendlu kaDavida, kusiya esangweni lamanzi ngempumalanga.
38 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin kejì gba ọ̀nà òdìkejì lọ. Mo tẹ̀lé wọn ní orí odi, pẹ̀lú ìdajì àwọn ènìyàn, kọjá ilé ìṣọ́ ìléru lọ sí odi fífẹ̀,
Lexuku lesibili lokubonga lahamba maqondana lalo, lami ngililandela, lengxenye yabantu phezu komduli, kusukela ngaphezu komphotshongo wesithando kusiya emdulini obanzi,
39 kọjá ẹnu ibodè Efraimu ibodè Jeṣana, ẹnu ibodè ẹja, ilé ìṣọ́ Hananeli àti ilé ìṣọ́ ọgọ́rùn-ún, títí dé ẹnu ibodè àgùntàn. Wọ́n sì dúró ní ibodè ìṣọ́.
njalo kusukela ngaphezu kwesango lakoEfrayimi, langaphezu kwesango elidala, langaphezu kwesango lenhlanzi, lomphotshongo kaHananeli, lomphotshongo kaHameha, kusiya esangweni lezimvu; bema-ke esangweni labalindi.
40 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin méjèèjì tí wọ́n dúpẹ́ wà ní ààyè nínú ilé Ọlọ́run, èmi náà sì dúró ní ààyè mi pẹ̀lú ìdajì àwọn ìjòyè,
Womabili amaxuku okubonga asesima endlini kaNkulunkulu, lami, lengxenye yababusi ilami.
41 àti àwọn àlùfáà Eliakimu, Maaseiah, Miniamini, Mikaiah, Elioenai, Sekariah àti Hananiah pẹ̀lú àwọn ìpè wọn.
Labapristi: OEliyakhimi, uMahaseya, uMiniyamini, uMikhaya, uEliyowenayi, uZekhariya, uHananiya, belezimpondo,
42 Àti pẹ̀lú Maaseiah, Ṣemaiah, Eleasari àti Ussi, àti Jehohanani, àti Malkiah, àti Elamu, àti Eseri. Àwọn akọrin kọrin sókè ní abẹ́ alábojútó Jesrahiah.
loMahaseya, loShemaya, loEleyazare, loUzi, loJehohanani, loMalikiya, loElamu, loEzeri. Abahlabeleli basebezizwakalisa, loJezerahiya umboni.
43 Ní ọjọ́ náà wọ́n rú ẹbọ ńlá, wọ́n ṣe àjọyọ̀ nítorí Ọlọ́run ti fún wọn ní ayọ̀ ńlá. Àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé sì yọ̀ pẹ̀lú. A lè gbọ́ ariwo ayọ̀ tí ó jáde láti Jerusalẹmu ní jìnnà réré.
Basebehlaba mhlalokho imihlatshelo emikhulu, bathokoza, ngoba uNkulunkulu wabenza bathokoza ngentokozo enkulu; labesifazana labantwana labo bathokoza; kwaze kwathi intokozo yeJerusalema yezwakala khatshana.
44 Ní àkókò náà, a yan àwọn ènìyàn láti jẹ́ alábojútó yàrá ìṣúra fún àwọn ọrẹ àkọ́so èso àti àwọn ìdámẹ́wàá. Láti inú àwọn oko tí ó wà ní àyíká ìlú ni wọ́n ti ní láti mú wá sínú yàrá ìṣúra, ìpín tí òfin sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, nítorí inú àwọn ará a Juda yọ́ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tó ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́.
Ngalolosuku kwamiswa-ke amadoda phezu kwamakamelo okuligugu, aweminikelo, awezithelo zokuqala, lawokwetshumi, ukuqoqela kuwo okuvela emasimini emizi izabelo zomlayo zabapristi lezamaLevi. Ngoba uJuda wathokoza ngabapristi lamaLevi ayemile.
45 Wọ́n ń ṣiṣẹ́ Ọlọ́run wọn àti iṣẹ́ ìyàsímímọ́, bẹ́ẹ̀ náà ni fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà, wọ́n ń ṣe gẹ́gẹ́ bí Dafidi àti Solomoni ọmọ rẹ̀ ti pàṣẹ fún wọn.
Abahlabeleli labalindimasango basebegcina imfanelo kaNkulunkulu wabo, lemfanelo yokuhlambulula, njengomlayo kaDavida loSolomoni indodana yakhe.
46 Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn ní ìgbà Dafidi àti Asafu, ni àwọn atọ́nisọ́nà ti wà fún àwọn akọrin àti fún orin ìyìn àti orin ọpẹ́ sí Ọlọ́run.
Ngoba ensukwini zamandulo zikaDavida loAsafi kwakulezinhloko zabahlabeleli lezingoma zokudumisa lokubonga kuNkulunkulu.
47 Nítorí náà ní ìgbà ayé Serubbabeli àti Nehemiah, gbogbo Israẹli ni ó ń dá ìpín lójoojúmọ́ fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà. Wọ́n sì tún yan ìpín mìíràn sọ́tọ̀ fún àwọn ọmọ Lefi tókù, àwọn ọmọ Lefi náà tún ya ìpín ti àwọn ọmọ Aaroni sọ́tọ̀ fún wọn.
LoIsrayeli wonke ensukwini zikaZerubhabheli lensukwini zikaNehemiya banika izabelo zabahlabeleli labalindimasango, udaba losuku ngosuku lwalo; basebekungcwelisela amaLevi, lamaLevi akungcwelisela abantwana bakoAroni.

< Nehemiah 12 >