< Nehemiah 12 >
1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tí ó bá Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti Jeṣua padà: Seraiah, Jeremiah, Esra,
Aya nĩo athĩnjĩri-Ngai na Alawii arĩa maacookire hamwe na Zerubabeli mũrũ wa Shealitieli, na Jeshua: Seraia, na Jeremia, na Ezara,
2 Amariah, Malluki, Hattusi,
na Amaria, na Maluku, na Hatushu,
3 Ṣekaniah, Rehumu, Meremoti,
na Shekania, na Rehumu, na Meremothu,
4 Iddo, Ginetoni, Abijah,
na Ido, na Ginethoni, na Abija,
5 Mijamini, Moadiah, Bilgah,
na Mijamini, na Maadia, na Biliga,
6 Ṣemaiah, Joiaribu, Jedaiah,
na Shemaia, na Joiaribu, na Jedaia,
7 Sallu, Amoki, Hilkiah, àti Jedaiah. Wọ̀nyí ni olórí àwọn àlùfáà àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn ní ìgbà ayé e Jeṣua.
na Salu, na Amoku, na Hilikia, na Jedaia. Acio nĩo maarĩ atongoria a athĩnjĩri-Ngai na athiritũ ao, matukũ-inĩ macio ma Jeshua.
8 Àwọn ọmọ Lefi ni Jeṣua, Binnui, Kadmieli, Ṣerebiah, Juda àti Mattaniah ẹni tí òun pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, ni wọn ṣe àkóso orin ìdúpẹ́.
Nao Alawii maarĩ Jeshua, na Binui, na Kadimieli, na Sherebia, na Juda, o na Matania, ũrĩa, marĩ hamwe na athiritũ ake, nĩwe warũgamĩrĩire arĩa maainaga nyĩmbo cia gũcookia ngaatho.
9 Bakbukiah àti Unni, àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn dúró sí òdìkejì wọn nínú ìsìn.
Bakabukia na Uni, athiritũ ao, maarũgamaga mangʼethanĩire nao magĩtungata.
10 Jeṣua ni baba Joiakimu, Joiakimu ni baba Eliaṣibu, Eliaṣibu ni baba Joiada,
Jeshua nĩwe warĩ ithe wa Joiakimu, nake Joiakimu aarĩ ithe wa Eliashibu, nake Eliashibu aarĩ ithe wa Joiada,
11 Joiada ni baba Jonatani, Jonatani sì ni baba Jaddua.
nake Joiada aarĩ ithe wa Jonathani, nake Jonathani aarĩ ithe wa Jadua.
12 Ní ìgbé ayé Joiakimu, wọ̀nyí ni àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn àlùfáà: ti ìdílé Seraiah, Meraiah; ti ìdílé Jeremiah, Hananiah;
Matukũ-inĩ ma Joiakimu, aya nĩo maarĩ atongoria a nyũmba cia athĩnjĩri-Ngai: ya Seraia, aarĩ Meraia; ya Jeremia, aarĩ Hanania;
13 ti ìdílé Esra, Meṣullamu; ti ìdílé Amariah, Jehohanani;
ya Ezara, aarĩ Meshulamu; ya Amaria, aarĩ Jehohanani;
14 ti ìdílé Malluki, Jonatani; ti ìdílé Ṣekaniah, Josẹfu;
ya Maluki, aarĩ Jonathani; ya Shebania, aarĩ Jusufu;
15 ti ìdílé Harimu, Adna; ti ìdílé Meraioti Helikai;
ya Harimu, aarĩ Adina; ya Meraiothu, aarĩ Helikai;
16 ti ìdílé Iddo, Sekariah; ti ìdílé Ginetoni, Meṣullamu;
ya Ido, aarĩ Zekaria; ya Ginethoni, aarĩ Meshulamu;
17 ti ìdílé Abijah, Sikri; ti ìdílé Miniamini àti ti ìdílé Moadiah, Piltai;
ya Abija, aarĩ Zikiri; ya Miniamini na Moadia, aarĩ Pilitai;
18 ti ìdílé Bilgah, Ṣammua; ti ìdílé Ṣemaiah, Jehonatani;
ya Biliga, aarĩ Shamua; ya Shemaia, aarĩ Jehonathani;
19 ti ìdílé Joiaribu, Mattenai; ti ìdílé Jedaiah, Ussi;
ya Joiaribu, aarĩ Matenai; ya Jedaia, aarĩ Uzi;
20 ti ìdílé Sallu, Kallai; ti ìdílé Amoki, Eberi;
ya Salai, aarĩ Kalai; ya Amoku, aarĩ Eberi;
21 ti ìdílé Hilkiah, Haṣabiah; ti ìdílé Jedaiah, Netaneli.
ya Hilikia, aarĩ Hashabia; na ya Jedaia, aarĩ Nethaneli.
22 Àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi ní ìgbà ayé Eliaṣibu, Joiada, Johanani àti Jaddua, àti pẹ̀lú ti àwọn àlùfáà ni a kọ sílẹ̀ ní ìgbà ìjọba Dariusi ará Persia.
Nao atongoria a nyũmba cia Alawii matukũ-inĩ ma Eliashibu, na Joiada, na Johanani, na Jadua, o ũndũ ũmwe na atongoria a athinjĩri-Ngai, nĩmandĩkirwo marĩĩtwa mao hĩndĩ ya wathani wa Dario ũrĩa Mũperisia.
23 Àwọn olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Lefi títí di àkókò Johanani ọmọ Eliaṣibu ni a kọ sílẹ̀ nínú ìwé ìtàn.
Atongoria a nyũmba cia njiaro cia Lawi nginya hĩndĩ ya Johanani mũrũ wa Eliashibu o nao nĩmandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa matukũ macio.
24 Àti àwọn olórí àwọn ọmọ Lefi ni Haṣabiah, Ṣerebiah, Jeṣua ọmọ Kadmieli, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n dúró ní ìdojúkojú wọn láti fi ìyìn àti láti dúpẹ́, apá kan ń dá èkejì lóhùn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run.
Nao atongoria a Alawii maarĩ Hashabia, na Sherebia, na Jeshua mũrũ wa Kadimieli, na athiritũ ao, arĩa maarũgamaga mamangʼetheire makĩina nyĩmbo cia kũgooca na cia gũcookia ngaatho, gĩkundi kĩmwe gĩkaamũkagĩria kĩrĩa kĩngĩ, kũringana na ũrĩa gwathanĩtwo nĩ Daudi mũndũ wa Ngai.
25 Mattaniah, Bakbukiah, Obadiah, Meṣullamu, Talmoni àti Akkubu ni aṣọ́nà tí wọ́n ń sọ yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ní ẹnu-ọ̀nà.
Matania, na Bakabukia, na Obadia, na Meshulamu, na Talimoni, na Akubu maarĩ aikaria a ihingo arĩa maarangagĩra makũmbĩ marĩa maarĩ ihingo-inĩ.
26 Wọ́n ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ìgbà ayé e Joiakimu ọmọ Jeṣua, ọmọ Josadaki, àti ní ọjọ́ ọ Nehemiah baálẹ̀ àti ní ọjọ́ Esra àlùfáà àti akọ̀wé.
Maatungataga hĩndĩ ya Joiakimu mũrũ wa Jeshua, mũrũ wa Jozadaku, na hĩndĩ ya Nehemia ũrĩa warĩ barũthi, na hĩndĩ ya Ezara ũrĩa warĩ mũthĩnjĩri-Ngai na mwandĩki-marũa.
27 Nígbà ìyàsímímọ́ odi Jerusalẹmu a mú àwọn ọmọ Lefi jáde wá láti ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú wọn wá sí Jerusalẹmu láti fi ayọ̀ ṣe ayẹyẹ ìyàsímímọ́ pẹ̀lú orin ìdúpẹ́ àti pẹ̀lú ohun èlò orin kimbali, haapu àti ohun èlò orin olókùn.
Hĩndĩ ya kwamũrwo kwa rũthingo rwa Jerusalemu, Alawii nĩmacaririo kuuma kũrĩa guothe maarĩ nĩguo moke Jerusalemu makũngũĩre kwamũrwo kũu marĩ na gĩkeno, na makĩinaga nyĩmbo cia gũcookia ngaatho, makĩinaga na thaani iria ihũũrithanagio, na inanda cia kĩnũbi, na cia mũgeeto.
28 A kó àwọn akọrin náà jọ papọ̀ láti àwọn ìletò tí ó yí Jerusalẹmu náà ká—láti àwọn abúlé Netofa,
Aini o nao nĩmacookanĩrĩirio hamwe kuuma ngʼongo iria ciathiũrũrũkĩirie Jerusalemu, magĩcookanĩrĩrio kuuma tũtũũra-inĩ twa Anetofathi,
29 láti Beti-Gilgali, àti láti àwọn agbègbè Geba àti Asmafeti, nítorí àwọn akọrin ti kọ́ àwọn ìletò fúnra wọn ní agbègbè Jerusalẹmu.
na kuuma Bethi-Giligali, na kuuma mwena wa Geba na Azimavethu, nĩgũkorwo aini nĩmeyakĩire matũũra gũthiũrũrũkĩria Jerusalemu.
30 Nígbà tí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n ya àwọn ènìyàn sí mímọ́, àti ẹnu ibodè àti odi pẹ̀lú.
Nao athĩnjĩri-Ngai na Alawii marĩkia gwĩtheria, magĩtheria andũ, na ihingo, o na rũthingo.
31 Mo sì tún yan àwọn olórí Juda láti gun orí odi náà. Mo sì tún yan àwọn ẹgbẹ́ akọrin ńlá méjì láti dúpẹ́. Àwọn kan yóò gòkè odi lọ sí apá ọ̀tún sí ọ̀nà ibodè Ààtàn.
Atongoria a Juda nĩndameerire mahaice rũthingo-igũrũ. Ningĩ ngĩhe ikundi igĩrĩ nene cia aini wĩra wa gũcookia ngaatho. Gĩkundi kĩmwe gĩgĩthiĩ mwena wa ũrĩo kĩrĩ rũthingo-igũrũ, kĩerekeire Kĩhingo gĩa Kĩara-inĩ.
32 Hoṣaiah àti ìdajì àwọn olórí Juda tẹ̀lé wọn,
Hoshaia hamwe na nuthu ya atongoria a Juda makĩmarũmĩrĩra,
33 àwọn wọ̀nyí náà sì lọ pẹ̀lú wọn, Asariah, Esra, Meṣullamu,
hamwe na Azaria, na Ezara, na Meshulamu,
34 Juda, Benjamini, Ṣemaiah, Jeremiah,
na Juda, na Benjamini, na Shemaia, na Jeremia,
35 pẹ̀lú àwọn àlùfáà díẹ̀ pẹ̀lú ìpè, pẹ̀lú u Sekariah ọmọ Jonatani, ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Mattaniah, ọmọ Mikaiah, ọmọ Sakkuri, ọmọ Asafu,
o ũndũ ũmwe na athĩnjĩri-Ngai amwe me na tũrumbeta, o na Zekaria mũrũ wa Jonathani, mũrũ wa Shemaia, mũrũ wa Matania, mũrũ wa Mikaia, mũrũ wa Zakuri, mũrũ wa Asafu,
36 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, Ṣemaiah, Asareeli, Milalai, Gilalai, Maai, Netaneli, Juda àti Hanani—pẹ̀lú ohun èlò orin bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run. Esra akọ̀wé ni ó ṣáájú wọn bí wọ́n ti ń tò lọ lọ́wọ̀ọ̀wọ́.
na athiritũ ake, nĩo Shemaia, na Azareli, na Milalai, na Gilalai, na Maai, na Nethaneli, na Juda, na Hanani, marĩ na indo cia kũina nacio o ta ũrĩa gwathanĩtwo nĩ Daudi, mũndũ wa Ngai. Ezara ũrĩa mwandĩki-marũa nĩwe wamatongoretie.
37 Ní ẹnu ibodè orísun wọ́n ti ń lọ tààrà sí ọ̀nà ní orí àtẹ̀gùn ìlú Dafidi ní orí òkè tí ó kángun sí odi, wọ́n sì gba ẹ̀gbẹ́ ilé Dafidi kọjá títí dé ẹnu ibodè omi ní ìhà ìlà-oòrùn.
Na rĩrĩ, kuuma Kĩhingo gĩa Gĩthima maathiire marũngĩrĩirie, makĩhaica rũthingo igũrũ na ngathĩ cia Itũũra rĩa Daudi, makĩhĩtũkĩra igũrũ rĩa nyũmba ya Daudi, o nginya Kĩhingo kĩa Maaĩ mwena wa irathĩro.
38 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin kejì gba ọ̀nà òdìkejì lọ. Mo tẹ̀lé wọn ní orí odi, pẹ̀lú ìdajì àwọn ènìyàn, kọjá ilé ìṣọ́ ìléru lọ sí odi fífẹ̀,
Gĩkundi gĩa keerĩ kĩa aini gĩgĩthiĩ kĩerekeire mwena wa ũmotho. Na niĩ ngĩmarũmĩrĩra kũu rũthingo igũrũ hamwe na nuthu ya andũ, tũkĩhĩtũkĩra Mũthiringo wa Mariiko ma Mwaki o nginya Rũthingo-inĩ Rwariĩ,
39 kọjá ẹnu ibodè Efraimu ibodè Jeṣana, ẹnu ibodè ẹja, ilé ìṣọ́ Hananeli àti ilé ìṣọ́ ọgọ́rùn-ún, títí dé ẹnu ibodè àgùntàn. Wọ́n sì dúró ní ibodè ìṣọ́.
igũrũ rĩa Kĩhingo kĩa Efiraimu, na Kĩhingo kĩa Jeshana, na Kĩhingo gĩa Thamaki, na Mũthiringo wa Hananeli, na Mũthiringo wa Igana, nginya Kĩhingo-inĩ kĩa Ngʼondu. Makĩrũgama Kĩhingo-inĩ kĩa Mũrangĩri.
40 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin méjèèjì tí wọ́n dúpẹ́ wà ní ààyè nínú ilé Ọlọ́run, èmi náà sì dúró ní ààyè mi pẹ̀lú ìdajì àwọn ìjòyè,
Ikundi icio cierĩ cia aini cia gũcookia ngaatho igĩikara handũ ha cio thĩinĩ wa nyũmba ya Ngai, o na niĩ ngĩĩka o ũguo, hamwe na nuthu ya anene,
41 àti àwọn àlùfáà Eliakimu, Maaseiah, Miniamini, Mikaiah, Elioenai, Sekariah àti Hananiah pẹ̀lú àwọn ìpè wọn.
o ũndũ ũmwe na athĩnjĩri-Ngai, nĩo Eliakimu, na Maaseia, na Miniamini, na Mikaia, na Elioenai, na Zekaria, na Hanania marĩ na tũrumbeta twao,
42 Àti pẹ̀lú Maaseiah, Ṣemaiah, Eleasari àti Ussi, àti Jehohanani, àti Malkiah, àti Elamu, àti Eseri. Àwọn akọrin kọrin sókè ní abẹ́ alábojútó Jesrahiah.
o hamwe na Maaseia, na Shemaia, na Eleazaru, na Uzi, na Jehohanani, na Malikija, na Elamu, na Ezeri. Nao aini maatongoragio nĩ Jezerahia.
43 Ní ọjọ́ náà wọ́n rú ẹbọ ńlá, wọ́n ṣe àjọyọ̀ nítorí Ọlọ́run ti fún wọn ní ayọ̀ ńlá. Àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé sì yọ̀ pẹ̀lú. A lè gbọ́ ariwo ayọ̀ tí ó jáde láti Jerusalẹmu ní jìnnà réré.
Na mũthenya ũcio nĩmarutire magongona manene, makĩrũũhagia tondũ Ngai nĩamaheete gĩkeno kĩnene. O nao andũ-a-nja na ciana magĩkena. Mbugĩrĩrio ya gĩkeno kũu Jerusalemu nĩyaiguĩkaga kũndũ kũraya.
44 Ní àkókò náà, a yan àwọn ènìyàn láti jẹ́ alábojútó yàrá ìṣúra fún àwọn ọrẹ àkọ́so èso àti àwọn ìdámẹ́wàá. Láti inú àwọn oko tí ó wà ní àyíká ìlú ni wọ́n ti ní láti mú wá sínú yàrá ìṣúra, ìpín tí òfin sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, nítorí inú àwọn ará a Juda yọ́ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tó ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́.
Mahinda-inĩ macio nĩ gwathuurirwo andũ marũgamĩrĩre makũmbĩ ma indo iria ciarutagwo, na maciaro ma mbere, na gĩcunjĩ gĩa ikũmi. Kuuma mĩgũnda-inĩ ĩrĩa yathiũrũrũkĩirie matũũra magĩrĩirwo kurehe makũmbĩ-inĩ icunjĩ iria ciatuĩtwo nĩ watho irĩ cia athĩnjĩri-Ngai na Alawii, tondũ andũ a Juda nĩmakenagĩra athĩnjĩri-Ngai na Alawii arĩa maatungataga.
45 Wọ́n ń ṣiṣẹ́ Ọlọ́run wọn àti iṣẹ́ ìyàsímímọ́, bẹ́ẹ̀ náà ni fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà, wọ́n ń ṣe gẹ́gẹ́ bí Dafidi àti Solomoni ọmọ rẹ̀ ti pàṣẹ fún wọn.
Nĩmarutaga wĩra wa gũtungatĩra Ngai wao, na wĩra wa gwĩtheria, o ta ũrĩa aini na aikaria a ihingo meekaga, kũringana na ũrĩa gwathanĩtwo nĩ Daudi na mũriũ Solomoni.
46 Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn ní ìgbà Dafidi àti Asafu, ni àwọn atọ́nisọ́nà ti wà fún àwọn akọrin àti fún orin ìyìn àti orin ọpẹ́ sí Ọlọ́run.
Nĩgũkorwo tene mũno, matukũ-inĩ ma Daudi na ma Asafu, nĩ kwarĩ na atongoria a aini na a nyĩmbo cia kũgooca na gũcookeria Ngai ngaatho.
47 Nítorí náà ní ìgbà ayé Serubbabeli àti Nehemiah, gbogbo Israẹli ni ó ń dá ìpín lójoojúmọ́ fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà. Wọ́n sì tún yan ìpín mìíràn sọ́tọ̀ fún àwọn ọmọ Lefi tókù, àwọn ọmọ Lefi náà tún ya ìpín ti àwọn ọmọ Aaroni sọ́tọ̀ fún wọn.
Nĩ ũndũ ũcio matukũ-inĩ ma Zerubabeli na ma Nehemia, andũ a Isiraeli othe nĩmarutaga icunjĩ cia o mũthenya nĩ ũndũ wa aini na aikaria a ihingo. Ningĩ nĩmamũraga icunjĩ nĩ ũndũ wa Alawii arĩa angĩ, nao Alawii makaamũra icunjĩ nĩ ũndũ wa njiaro cia Harũni.