< Nehemiah 12 >
1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tí ó bá Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti Jeṣua padà: Seraiah, Jeremiah, Esra,
Et voici les prêtres et les lévites qui étaient revenus avec Zorobabel, fils de Salathiel et Josué: Saraïa, Jérémie, Esdras,
2 Amariah, Malluki, Hattusi,
Amarias, Maluch,
3 Ṣekaniah, Rehumu, Meremoti,
Sechénias;
4 Iddo, Ginetoni, Abijah,
Tels étaient les princes des prêtres, et leurs frères du temps de Josué.
5 Mijamini, Moadiah, Bilgah,
Tels étaient les princes des prêtres, et leurs frères du temps de Josué.
6 Ṣemaiah, Joiaribu, Jedaiah,
Tels étaient les princes des prêtres, et leurs frères du temps de Josué.
7 Sallu, Amoki, Hilkiah, àti Jedaiah. Wọ̀nyí ni olórí àwọn àlùfáà àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn ní ìgbà ayé e Jeṣua.
Tels étaient les princes des prêtres, et leurs frères du temps de Josué.
8 Àwọn ọmọ Lefi ni Jeṣua, Binnui, Kadmieli, Ṣerebiah, Juda àti Mattaniah ẹni tí òun pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, ni wọn ṣe àkóso orin ìdúpẹ́.
Et les lévites étaient Josué, Banuï, Cadmiel, Sarabia, Joad, Matthanias (celui-ci dirigeait les chants, et leurs frères étaient désignés
9 Bakbukiah àti Unni, àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn dúró sí òdìkejì wọn nínú ìsìn.
Pour les services journaliers.
10 Jeṣua ni baba Joiakimu, Joiakimu ni baba Eliaṣibu, Eliaṣibu ni baba Joiada,
Or, Josué engendra Joacim, et Joacim engendra Eliasib, et Eliasib engendra Joad,
11 Joiada ni baba Jonatani, Jonatani sì ni baba Jaddua.
Et Joad engendra Jonathas, et Jonathas engendra Jadu.
12 Ní ìgbé ayé Joiakimu, wọ̀nyí ni àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn àlùfáà: ti ìdílé Seraiah, Meraiah; ti ìdílé Jeremiah, Hananiah;
Et du temps de Joacim, ses frères, les prêtres et les chefs des familles paternelles, étaient, savoir: De la famille de Saraïa, Amarias; de celle de Jérémie, Ananias;
13 ti ìdílé Esra, Meṣullamu; ti ìdílé Amariah, Jehohanani;
De celle d'Esdras, Mesulam; de celle d'Amarias, Johanan;
14 ti ìdílé Malluki, Jonatani; ti ìdílé Ṣekaniah, Josẹfu;
De celle d'Amaluch, Jonathas; de celle de Sechénias, Joseph;
15 ti ìdílé Harimu, Adna; ti ìdílé Meraioti Helikai;
De celle d'Aré, Mannas; de celle de Marioth, Elcaï;
16 ti ìdílé Iddo, Sekariah; ti ìdílé Ginetoni, Meṣullamu;
De celle d'Adadaï, Zacharie; de celle de Ganathoth, Mesolam;
17 ti ìdílé Abijah, Sikri; ti ìdílé Miniamini àti ti ìdílé Moadiah, Piltai;
De celle d'Abias, Zéchri; de celle de Miamin, Maadaï; de celle de Phéléthi;
18 ti ìdílé Bilgah, Ṣammua; ti ìdílé Ṣemaiah, Jehonatani;
De la famille de Balgas, Samué; de celle de Semias, Jonathan;
19 ti ìdílé Joiaribu, Mattenai; ti ìdílé Jedaiah, Ussi;
De celle de Joarib, Matthanaï; de celle d'Edio, Ozi;
20 ti ìdílé Sallu, Kallai; ti ìdílé Amoki, Eberi;
De celle de Salaï, Callaï; de celle d'Amec, Abed;
21 ti ìdílé Hilkiah, Haṣabiah; ti ìdílé Jedaiah, Netaneli.
De celle d'Elcias, Asabias; de celle de Jedeïu, Nathanaël;
22 Àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi ní ìgbà ayé Eliaṣibu, Joiada, Johanani àti Jaddua, àti pẹ̀lú ti àwọn àlùfáà ni a kọ sílẹ̀ ní ìgbà ìjọba Dariusi ará Persia.
Les lévites du temps d'Eliasib étaient Joad, Joas, Johanan et Idua, inscrits comme chefs de familles, ainsi que les prêtres sous le règne de Darius le Perse.
23 Àwọn olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Lefi títí di àkókò Johanani ọmọ Eliaṣibu ni a kọ sílẹ̀ nínú ìwé ìtàn.
Les fils de Lévi, chefs de familles paternelles, ont été inscrits dans le livre du récit de ces temps, jusqu'aux jours de Johanan, fils d'Elisué.
24 Àti àwọn olórí àwọn ọmọ Lefi ni Haṣabiah, Ṣerebiah, Jeṣua ọmọ Kadmieli, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n dúró ní ìdojúkojú wọn láti fi ìyìn àti láti dúpẹ́, apá kan ń dá èkejì lóhùn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run.
Et les chefs des lévites étaient Asabia, et Sarabia, et Josué, et les fils de Cadmiel et leurs frères, se tenaient devant eux lorsqu'ils chantaient les louanges du Seigneur, journellement comme l'avait prescrit David, homme de Dieu.
25 Mattaniah, Bakbukiah, Obadiah, Meṣullamu, Talmoni àti Akkubu ni aṣọ́nà tí wọ́n ń sọ yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ní ẹnu-ọ̀nà.
Je ressemblai aussi les portiers,
26 Wọ́n ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ìgbà ayé e Joiakimu ọmọ Jeṣua, ọmọ Josadaki, àti ní ọjọ́ ọ Nehemiah baálẹ̀ àti ní ọjọ́ Esra àlùfáà àti akọ̀wé.
Du temps de Joacim, fils de Josué, fils de Josédec, et du temps de Néhémias, et alors Esdras était prêtre et scribe.
27 Nígbà ìyàsímímọ́ odi Jerusalẹmu a mú àwọn ọmọ Lefi jáde wá láti ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú wọn wá sí Jerusalẹmu láti fi ayọ̀ ṣe ayẹyẹ ìyàsímímọ́ pẹ̀lú orin ìdúpẹ́ àti pẹ̀lú ohun èlò orin kimbali, haapu àti ohun èlò orin olókùn.
Et lorsque l'on fit la dédicace des murs de Jérusalem, on chercha les lévites en leurs résidences pour les amener à Jérusalem, et faire la fête de la dédicace et les réjouissances, avec des actions de grâces et des chants accompagnés de harpes et de cymbales,
28 A kó àwọn akọrin náà jọ papọ̀ láti àwọn ìletò tí ó yí Jerusalẹmu náà ká—láti àwọn abúlé Netofa,
Et les fils des chantres vinrent de la banlieue de Jérusalem, et de ses villages,
29 láti Beti-Gilgali, àti láti àwọn agbègbè Geba àti Asmafeti, nítorí àwọn akọrin ti kọ́ àwọn ìletò fúnra wọn ní agbègbè Jerusalẹmu.
Et de ses campagnes, car ils s'étaient bâti des demeures autour de Jérusalem.
30 Nígbà tí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n ya àwọn ènìyàn sí mímọ́, àti ẹnu ibodè àti odi pẹ̀lú.
Et les prêtres et les lévites, après s'être purifiés, purifièrent le peuple, et les portiers, et les remparts.
31 Mo sì tún yan àwọn olórí Juda láti gun orí odi náà. Mo sì tún yan àwọn ẹgbẹ́ akọrin ńlá méjì láti dúpẹ́. Àwọn kan yóò gòkè odi lọ sí apá ọ̀tún sí ọ̀nà ibodè Ààtàn.
Et l'on fit monter les princes de Juda sur le rempart avec deux chœurs, pour chanter des actions de grâces à Dieu, et ils tournèrent sur le rempart à droite se dirigeant vers la porte du Fumier.
32 Hoṣaiah àti ìdajì àwọn olórí Juda tẹ̀lé wọn,
Et derrière les chantres marchaient Osaïas et la moitié des princes de Juda,
33 àwọn wọ̀nyí náà sì lọ pẹ̀lú wọn, Asariah, Esra, Meṣullamu,
Et Azarias, Esdras, Mesollam,
34 Juda, Benjamini, Ṣemaiah, Jeremiah,
Juda, Benjamin, Samaïas et Jérémie,
35 pẹ̀lú àwọn àlùfáà díẹ̀ pẹ̀lú ìpè, pẹ̀lú u Sekariah ọmọ Jonatani, ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Mattaniah, ọmọ Mikaiah, ọmọ Sakkuri, ọmọ Asafu,
Et des fils des prêtres avec les trompettes: Zacharie, fils de Jonathas, fils de Samaïas, fils de Matthanias, fils de Michée, fils de Zacchur, fils d'Asaph,
36 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, Ṣemaiah, Asareeli, Milalai, Gilalai, Maai, Netaneli, Juda àti Hanani—pẹ̀lú ohun èlò orin bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run. Esra akọ̀wé ni ó ṣáájú wọn bí wọ́n ti ń tò lọ lọ́wọ̀ọ̀wọ́.
Et ses frères Samaïas, Oziel et Gelod, Jama, Aïas, Nathanaël, Juda et Anani, et ils chantaient les cantiques de David, homme de Dieu; et Esdras, le scribe, les avait devancés
37 Ní ẹnu ibodè orísun wọ́n ti ń lọ tààrà sí ọ̀nà ní orí àtẹ̀gùn ìlú Dafidi ní orí òkè tí ó kángun sí odi, wọ́n sì gba ẹ̀gbẹ́ ilé Dafidi kọjá títí dé ẹnu ibodè omi ní ìhà ìlà-oòrùn.
Sur la porte pour chanter devant eux les louanges du Seigneur. Et ils montèrent par les degrés de la ville de David sur le mur, au-dessus du palais de ce roi, et ils allèrent jusqu'à la porte des Eaux à l'Est [d'Elihrem; ]
38 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin kejì gba ọ̀nà òdìkejì lọ. Mo tẹ̀lé wọn ní orí odi, pẹ̀lú ìdajì àwọn ènìyàn, kọjá ilé ìṣọ́ ìléru lọ sí odi fífẹ̀,
Et le second chœur marcha du côté opposé, et je le suivais, moi et la moitié du peuple, sur la muraille, au-dessus de la tour des Fours, jusqu'à la muraille large.
39 kọjá ẹnu ibodè Efraimu ibodè Jeṣana, ẹnu ibodè ẹja, ilé ìṣọ́ Hananeli àti ilé ìṣọ́ ọgọ́rùn-ún, títí dé ẹnu ibodè àgùntàn. Wọ́n sì dúró ní ibodè ìṣọ́.
Au dessus de la tour d'Ephraïm,
40 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin méjèèjì tí wọ́n dúpẹ́ wà ní ààyè nínú ilé Ọlọ́run, èmi náà sì dúró ní ààyè mi pẹ̀lú ìdajì àwọn ìjòyè,
Et les deux chœurs s'arrêtèrent dans la maison de Dieu, ainsi que moi et la moitié des magistrats, qui m'accompagnait.
41 àti àwọn àlùfáà Eliakimu, Maaseiah, Miniamini, Mikaiah, Elioenai, Sekariah àti Hananiah pẹ̀lú àwọn ìpè wọn.
Et les sacrificateurs Eliakim, Maaséia, Minjamin, Micaïa, Eljoénaï, Zacharie, Hanania avec des trompettes.
42 Àti pẹ̀lú Maaseiah, Ṣemaiah, Eleasari àti Ussi, àti Jehohanani, àti Malkiah, àti Elamu, àti Eseri. Àwọn akọrin kọrin sókè ní abẹ́ alábojútó Jesrahiah.
et Maaséia et Sémaïa et Eléazar et Uzzi et Johanan et Malkija et Elam et Ezer, et les chantres furent entendus et comptés.
43 Ní ọjọ́ náà wọ́n rú ẹbọ ńlá, wọ́n ṣe àjọyọ̀ nítorí Ọlọ́run ti fún wọn ní ayọ̀ ńlá. Àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé sì yọ̀ pẹ̀lú. A lè gbọ́ ariwo ayọ̀ tí ó jáde láti Jerusalẹmu ní jìnnà réré.
Et ce jour-là, on immola de nombreuses victimes et la joie était grande, car Dieu les avait grandement réjouis, et leurs femmes et leurs enfants prenaient part à ces réjouissances, et les cris joyeux de Jérusalem s'entendaient au loin.
44 Ní àkókò náà, a yan àwọn ènìyàn láti jẹ́ alábojútó yàrá ìṣúra fún àwọn ọrẹ àkọ́so èso àti àwọn ìdámẹ́wàá. Láti inú àwọn oko tí ó wà ní àyíká ìlú ni wọ́n ti ní láti mú wá sínú yàrá ìṣúra, ìpín tí òfin sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, nítorí inú àwọn ará a Juda yọ́ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tó ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́.
Et ce jour-là, on institua des gardiens des trésors, des prémices et des dîmes, et des hommes pour les recueillir dans les villes, et on les choisit parmi les prêtres et les lévites; car Juda se réjouissait d'avoir vu les lévites et les prêtres reprendre leurs fonctions.
45 Wọ́n ń ṣiṣẹ́ Ọlọ́run wọn àti iṣẹ́ ìyàsímímọ́, bẹ́ẹ̀ náà ni fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà, wọ́n ń ṣe gẹ́gẹ́ bí Dafidi àti Solomoni ọmọ rẹ̀ ti pàṣẹ fún wọn.
Et l'on remit en vigueur les règlements de David et de Salomon, son fils, concernant les purifications, ainsi que les chantres et les portiers.
46 Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn ní ìgbà Dafidi àti Asafu, ni àwọn atọ́nisọ́nà ti wà fún àwọn akọrin àti fún orin ìyìn àti orin ọpẹ́ sí Ọlọ́run.
Car, du temps de David, Asaph était à la tête des chantres, et de ceux qui célébraient le Seigneur.
47 Nítorí náà ní ìgbà ayé Serubbabeli àti Nehemiah, gbogbo Israẹli ni ó ń dá ìpín lójoojúmọ́ fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà. Wọ́n sì tún yan ìpín mìíràn sọ́tọ̀ fún àwọn ọmọ Lefi tókù, àwọn ọmọ Lefi náà tún ya ìpín ti àwọn ọmọ Aaroni sọ́tọ̀ fún wọn.
Et du temps de Zorobabel et de Néhémias, tout le peuple d'Israël assigna des parts aux chantres et aux portiers; on les leur distribuait chaque jour. On donnait aussi aux lévites ce qui leur était dû de la chair des sacrifices, et les lévites donnaient aux fils d'Aaron la part qui leur en revenait.