< Nehemiah 12 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tí ó bá Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti Jeṣua padà: Seraiah, Jeremiah, Esra,
Voici les prêtres et les Lévites qui revinrent avec Zorobabel, fils de Chealtiêl, et Yêchoua: Seraïa, Jérémie, Ezra;
2 Amariah, Malluki, Hattusi,
Amaria, Mallouc, Hattouch;
3 Ṣekaniah, Rehumu, Meremoti,
Chekhania, Rehoum, Merêmot;
4 Iddo, Ginetoni, Abijah,
Iddo, Ghinnetoï, Abia;
5 Mijamini, Moadiah, Bilgah,
Miyamin, Maadia, Bilga;
6 Ṣemaiah, Joiaribu, Jedaiah,
Chemaïa, Yoyarib, Yedaïa;
7 Sallu, Amoki, Hilkiah, àti Jedaiah. Wọ̀nyí ni olórí àwọn àlùfáà àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn ní ìgbà ayé e Jeṣua.
Sallou, Amok, Hilkia, Yedaïa. Voilà quels étaient les chefs des prêtres et de leurs frères au temps de Yêchoua.
8 Àwọn ọmọ Lefi ni Jeṣua, Binnui, Kadmieli, Ṣerebiah, Juda àti Mattaniah ẹni tí òun pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, ni wọn ṣe àkóso orin ìdúpẹ́.
Les Lévites étaient: Yêchoua, Binnoui, Kadmiêl, Chèrèbia, Juda, Mattania, préposé aux cantiques, lui et ses frères;
9 Bakbukiah àti Unni, àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn dúró sí òdìkejì wọn nínú ìsìn.
Bakboukia et Ounni, leurs frères, les assistaient selon l’ordre des sections.
10 Jeṣua ni baba Joiakimu, Joiakimu ni baba Eliaṣibu, Eliaṣibu ni baba Joiada,
Yêchoua engendra Joïakim, Joïakim engendra Elyachib, Elyachib engendra Joïada;
11 Joiada ni baba Jonatani, Jonatani sì ni baba Jaddua.
Joïada engendra Jonathan, Jonathan engendra Yaddoua.
12 Ní ìgbé ayé Joiakimu, wọ̀nyí ni àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn àlùfáà: ti ìdílé Seraiah, Meraiah; ti ìdílé Jeremiah, Hananiah;
Voici les prêtres qui furent, au temps de Joïakim, chefs des familles: pour Seraïa, Meraïa; pour Jérémie, Hanania;
13 ti ìdílé Esra, Meṣullamu; ti ìdílé Amariah, Jehohanani;
pour Ezra, Mechoullam; pour Amaria, Johanan;
14 ti ìdílé Malluki, Jonatani; ti ìdílé Ṣekaniah, Josẹfu;
pour Melikhou, Jonathan; pour Chebania, Joseph;
15 ti ìdílé Harimu, Adna; ti ìdílé Meraioti Helikai;
pour Harim, Adna; pour Meraïot, Helkaï;
16 ti ìdílé Iddo, Sekariah; ti ìdílé Ginetoni, Meṣullamu;
pour Iddo, Zacharie; pour Ghinnetôn, Mechoullam;
17 ti ìdílé Abijah, Sikri; ti ìdílé Miniamini àti ti ìdílé Moadiah, Piltai;
pour Abia, Zikhri; pour Miniamin, pour Moadia, Piltaï;
18 ti ìdílé Bilgah, Ṣammua; ti ìdílé Ṣemaiah, Jehonatani;
pour Bilga, Chammoua; pour Chemaïa, Jonathan;
19 ti ìdílé Joiaribu, Mattenai; ti ìdílé Jedaiah, Ussi;
pour Yoyarib, Mattenaï; pour Yedaïa, Ouzzi;
20 ti ìdílé Sallu, Kallai; ti ìdílé Amoki, Eberi;
pour Sallaï, Kaliaï, pour Amok, Eber;
21 ti ìdílé Hilkiah, Haṣabiah; ti ìdílé Jedaiah, Netaneli.
pour Hilkia, Hachabia; pour Yedaïa, Nethanel.
22 Àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi ní ìgbà ayé Eliaṣibu, Joiada, Johanani àti Jaddua, àti pẹ̀lú ti àwọn àlùfáà ni a kọ sílẹ̀ ní ìgbà ìjọba Dariusi ará Persia.
En ce qui concerne les Lévites, leurs chefs de famille furent inscrits au temps d’Elyachib, de Joïada, de Johanan et de Yaddoua; de même pour les prêtres, jusqu’au règne de Darius le Perse.
23 Àwọn olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Lefi títí di àkókò Johanani ọmọ Eliaṣibu ni a kọ sílẹ̀ nínú ìwé ìtàn.
Fils de Lévi, chefs des familles, inscrits dans le livre des chroniques jusqu’aux jours de Johanan, fils d’Elyachib;
24 Àti àwọn olórí àwọn ọmọ Lefi ni Haṣabiah, Ṣerebiah, Jeṣua ọmọ Kadmieli, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n dúró ní ìdojúkojú wọn láti fi ìyìn àti láti dúpẹ́, apá kan ń dá èkejì lóhùn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run.
ces chefs de Lévites étaient: Hachabia, Chèrèbia, Yêchoua, fils de Kadmiel, qu’assistaient leurs frères dans la récitation des louanges et actions de grâces, suivant le règlement de David, homme de Dieu, section par section;
25 Mattaniah, Bakbukiah, Obadiah, Meṣullamu, Talmoni àti Akkubu ni aṣọ́nà tí wọ́n ń sọ yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ní ẹnu-ọ̀nà.
Mattania, Bakboukia, Obadia, Mechoullam, Talmôn, Akkoub, surveillants, portiers préposés à la garde des magasins près des portes.
26 Wọ́n ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ìgbà ayé e Joiakimu ọmọ Jeṣua, ọmọ Josadaki, àti ní ọjọ́ ọ Nehemiah baálẹ̀ àti ní ọjọ́ Esra àlùfáà àti akọ̀wé.
Voilà ceux qui fonctionnaient au temps de Joïakim, fils de Yêchoua, fils de Joçadak, et au temps de Néhémie, le gouverneur, et du prêtre Ezra, le scribe.
27 Nígbà ìyàsímímọ́ odi Jerusalẹmu a mú àwọn ọmọ Lefi jáde wá láti ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú wọn wá sí Jerusalẹmu láti fi ayọ̀ ṣe ayẹyẹ ìyàsímímọ́ pẹ̀lú orin ìdúpẹ́ àti pẹ̀lú ohun èlò orin kimbali, haapu àti ohun èlò orin olókùn.
Lors de l’inauguration du mur de Jérusalem, on se mit en quête des Lévites dans tous leurs lieux d’habitation pour les amener à Jérusalem, afin de célébrer l’inauguration en une fête joyeuse, avec des actions de grâces et des chants, des cymbales, des lyres et des harpes.
28 A kó àwọn akọrin náà jọ papọ̀ láti àwọn ìletò tí ó yí Jerusalẹmu náà ká—láti àwọn abúlé Netofa,
Les membres des chœurs de chanteurs s’assemblèrent tant du district qui avoisine Jérusalem que des villages de Netofa,
29 láti Beti-Gilgali, àti láti àwọn agbègbè Geba àti Asmafeti, nítorí àwọn akọrin ti kọ́ àwọn ìletò fúnra wọn ní agbègbè Jerusalẹmu.
de Beth-Ghilgal et des campagnes de Ghéba et d’Azmaveth, car les chanteurs s’étaient bâti des villages autour de Jérusalem.
30 Nígbà tí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n ya àwọn ènìyàn sí mímọ́, àti ẹnu ibodè àti odi pẹ̀lú.
Les prêtres et les Lévites se purifièrent, puis ils purifièrent le peuple, ainsi que les portes et les murs.
31 Mo sì tún yan àwọn olórí Juda láti gun orí odi náà. Mo sì tún yan àwọn ẹgbẹ́ akọrin ńlá méjì láti dúpẹ́. Àwọn kan yóò gòkè odi lọ sí apá ọ̀tún sí ọ̀nà ibodè Ààtàn.
Je fis monter les chefs de Juda sur la muraille et j’y plaçai deux grands chœurs avec des cortèges, dont l’un s’avança à droite sur la muraille vers la porte des ordures;
32 Hoṣaiah àti ìdajì àwọn olórí Juda tẹ̀lé wọn,
à sa suite marchaient Hochaïa et la moitié des chefs de Juda,
33 àwọn wọ̀nyí náà sì lọ pẹ̀lú wọn, Asariah, Esra, Meṣullamu,
Azaria, Ezra, Mechoullam,
34 Juda, Benjamini, Ṣemaiah, Jeremiah,
Juda, Benjamin, Chemaïa et Jérémie.
35 pẹ̀lú àwọn àlùfáà díẹ̀ pẹ̀lú ìpè, pẹ̀lú u Sekariah ọmọ Jonatani, ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Mattaniah, ọmọ Mikaiah, ọmọ Sakkuri, ọmọ Asafu,
Puis une partie des prêtres avec des trompettes: Zacharie, fils de Jonathan, fils de Chemaïa, fils de Mattania, fils de Mikhaïa, fils de Zaccour, fils d’Assaph;
36 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, Ṣemaiah, Asareeli, Milalai, Gilalai, Maai, Netaneli, Juda àti Hanani—pẹ̀lú ohun èlò orin bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run. Esra akọ̀wé ni ó ṣáájú wọn bí wọ́n ti ń tò lọ lọ́wọ̀ọ̀wọ́.
ses frères: Chemaïa, Azarel, Milalaï, Ghilalaï, Maaï, Nethanel, Juda, Hanâni, munis des instruments de musique de David, homme de Dieu. A leur tête marchait Ezra le scribe.
37 Ní ẹnu ibodè orísun wọ́n ti ń lọ tààrà sí ọ̀nà ní orí àtẹ̀gùn ìlú Dafidi ní orí òkè tí ó kángun sí odi, wọ́n sì gba ẹ̀gbẹ́ ilé Dafidi kọjá títí dé ẹnu ibodè omi ní ìhà ìlà-oòrùn.
Ils arrivèrent à la porte de la source et gravirent droit devant eux, par les degrés de la ville de David, la montée du mur s’élevant au-dessus du palais du roi et jusqu’à la porte de l’eau à l’est.
38 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin kejì gba ọ̀nà òdìkejì lọ. Mo tẹ̀lé wọn ní orí odi, pẹ̀lú ìdajì àwọn ènìyàn, kọjá ilé ìṣọ́ ìléru lọ sí odi fífẹ̀,
Le deuxième chœur, qui se dirigeait à l’opposite, et que je suivais avec la moitié du peuple, s’avança sur le mur au-dessus de la tour des fours, et jusqu’au rempart large;
39 kọjá ẹnu ibodè Efraimu ibodè Jeṣana, ẹnu ibodè ẹja, ilé ìṣọ́ Hananeli àti ilé ìṣọ́ ọgọ́rùn-ún, títí dé ẹnu ibodè àgùntàn. Wọ́n sì dúró ní ibodè ìṣọ́.
puis au-dessus de la porte d’Ephraïm, de la porte vieille, de la porte des poissons, de la tour de Hananel, de la tour des cent jusqu’à la porte des brebis; on s’arrêta à la porte de la prison.
40 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin méjèèjì tí wọ́n dúpẹ́ wà ní ààyè nínú ilé Ọlọ́run, èmi náà sì dúró ní ààyè mi pẹ̀lú ìdajì àwọn ìjòyè,
Les deux chœurs prirent place près de la maison de Dieu, moi présent et accompagné de la moitié des chefs,
41 àti àwọn àlùfáà Eliakimu, Maaseiah, Miniamini, Mikaiah, Elioenai, Sekariah àti Hananiah pẹ̀lú àwọn ìpè wọn.
ainsi que des prêtres Elyakim, Maassèya, Miniamim, Mikhaïa, Elyoènaï, Zacharie, Hanania, munis de trompettes,
42 Àti pẹ̀lú Maaseiah, Ṣemaiah, Eleasari àti Ussi, àti Jehohanani, àti Malkiah, àti Elamu, àti Eseri. Àwọn akọrin kọrin sókè ní abẹ́ alábojútó Jesrahiah.
et de Maassèya, Chemaïa, Eléazar, Ouzzi, Johanan, Malkia, Elam et Ezer. Les chanteurs se firent entendre, ayant Israhia pour chef.
43 Ní ọjọ́ náà wọ́n rú ẹbọ ńlá, wọ́n ṣe àjọyọ̀ nítorí Ọlọ́run ti fún wọn ní ayọ̀ ńlá. Àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé sì yọ̀ pẹ̀lú. A lè gbọ́ ariwo ayọ̀ tí ó jáde láti Jerusalẹmu ní jìnnà réré.
Ils immolèrent en ce jour de nombreux sacrifices et se livrèrent à des réjouissances, car Dieu leur avait donné une grande joie; les femmes et les enfants se réjouirent également, et les démonstrations de joie de Jérusalem furent entendues au loin.
44 Ní àkókò náà, a yan àwọn ènìyàn láti jẹ́ alábojútó yàrá ìṣúra fún àwọn ọrẹ àkọ́so èso àti àwọn ìdámẹ́wàá. Láti inú àwọn oko tí ó wà ní àyíká ìlú ni wọ́n ti ní láti mú wá sínú yàrá ìṣúra, ìpín tí òfin sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, nítorí inú àwọn ará a Juda yọ́ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tó ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́.
En ce même temps, des hommes furent préposés aux salles servant de dépôt pour les prélèvements, les prémices et les dîmes, et où affluèrent, des banlieues des villes, les parts attribuées par la Thora aux prêtres et aux Lévites; car Juda était ravi des prêtres et des Lévites, qui étaient à leur poste,
45 Wọ́n ń ṣiṣẹ́ Ọlọ́run wọn àti iṣẹ́ ìyàsímímọ́, bẹ́ẹ̀ náà ni fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà, wọ́n ń ṣe gẹ́gẹ́ bí Dafidi àti Solomoni ọmọ rẹ̀ ti pàṣẹ fún wọn.
veillant aux observances de leur Dieu et au maintien de la pureté; quant aux chanteurs et aux portiers, ils fonctionnaient selon les prescriptions de David et de son fils Salomon.
46 Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn ní ìgbà Dafidi àti Asafu, ni àwọn atọ́nisọ́nà ti wà fún àwọn akọrin àti fún orin ìyìn àti orin ọpẹ́ sí Ọlọ́run.
En effet, dès les jours de David et d’Assaph, dans les temps antiques, il y avait des chefs de chanteurs et des chants de louanges et d’actions de grâces à Dieu.
47 Nítorí náà ní ìgbà ayé Serubbabeli àti Nehemiah, gbogbo Israẹli ni ó ń dá ìpín lójoojúmọ́ fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà. Wọ́n sì tún yan ìpín mìíràn sọ́tọ̀ fún àwọn ọmọ Lefi tókù, àwọn ọmọ Lefi náà tún ya ìpín ti àwọn ọmọ Aaroni sọ́tọ̀ fún wọn.
Et au temps de Zorobabel comme au temps de Néhémie, tous les Israélites donnaient les parts des chanteurs et des portiers, suivant les besoins de chaque jour, et consacraient aux Lévites leur dû et les Lévites consacraient leur dû aux fils d’Aaron.

< Nehemiah 12 >