< Nehemiah 12 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tí ó bá Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti Jeṣua padà: Seraiah, Jeremiah, Esra,
Voici les sacrificateurs et les Lévites qui montèrent avec Zorobabel, fils de Shealthiel, et avec Josué: Seraia, Jérémie, Esdras,
2 Amariah, Malluki, Hattusi,
Amaria, Malluch, Hattush,
3 Ṣekaniah, Rehumu, Meremoti,
Shecania, Rehum, Meremoth,
4 Iddo, Ginetoni, Abijah,
Iddo, Ginnethoi, Abija,
5 Mijamini, Moadiah, Bilgah,
Mijamin, Maadia, Bilga,
6 Ṣemaiah, Joiaribu, Jedaiah,
Shemaia, Joiarib, Jedaiah,
7 Sallu, Amoki, Hilkiah, àti Jedaiah. Wọ̀nyí ni olórí àwọn àlùfáà àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn ní ìgbà ayé e Jeṣua.
Sallu, Amok, Hilkiah et Jedaiah. Tels étaient les chefs des prêtres et de leurs frères, du temps de Josué.
8 Àwọn ọmọ Lefi ni Jeṣua, Binnui, Kadmieli, Ṣerebiah, Juda àti Mattaniah ẹni tí òun pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, ni wọn ṣe àkóso orin ìdúpẹ́.
Les Lévites étaient: Josué, Binnui, Kadmiel, Shérébia, Juda, et Matthania, qui était chargé des chants d'action de grâces, lui et ses frères.
9 Bakbukiah àti Unni, àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn dúró sí òdìkejì wọn nínú ìsìn.
Bakbukiah et Unno, leurs frères, étaient également près d'eux, selon leurs fonctions.
10 Jeṣua ni baba Joiakimu, Joiakimu ni baba Eliaṣibu, Eliaṣibu ni baba Joiada,
Jeshua engendra Joiakim; Joiakim engendra Eliashib; Eliashib engendra Joiada;
11 Joiada ni baba Jonatani, Jonatani sì ni baba Jaddua.
Joiada engendra Jonathan; Jonathan engendra Jaddua.
12 Ní ìgbé ayé Joiakimu, wọ̀nyí ni àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn àlùfáà: ti ìdílé Seraiah, Meraiah; ti ìdílé Jeremiah, Hananiah;
Du temps de Jojakim, il y eut des prêtres, chefs de famille de leurs pères: de Seraja, Meraja; de Jérémie, Hanania;
13 ti ìdílé Esra, Meṣullamu; ti ìdílé Amariah, Jehohanani;
d'Esdras, Meshullam; d'Amaria, Jehohanan;
14 ti ìdílé Malluki, Jonatani; ti ìdílé Ṣekaniah, Josẹfu;
de Malluchi, Jonathan; de Shebania, Joseph;
15 ti ìdílé Harimu, Adna; ti ìdílé Meraioti Helikai;
de Harim, Adna; de Meraioth, Helkaï;
16 ti ìdílé Iddo, Sekariah; ti ìdílé Ginetoni, Meṣullamu;
d'Iddo, Zacharie; de Ginnethon, Meshullam;
17 ti ìdílé Abijah, Sikri; ti ìdílé Miniamini àti ti ìdílé Moadiah, Piltai;
d'Abija, Zichri; de Miniamin, de Moadia, Piltai;
18 ti ìdílé Bilgah, Ṣammua; ti ìdílé Ṣemaiah, Jehonatani;
de Bilga, Shammua; de Shemaia, Jehonathan;
19 ti ìdílé Joiaribu, Mattenai; ti ìdílé Jedaiah, Ussi;
de Jojarib, Mattenai; de Jedaia, Uzzi;
20 ti ìdílé Sallu, Kallai; ti ìdílé Amoki, Eberi;
de Sallai, Kallai; d'Amok, Eber;
21 ti ìdílé Hilkiah, Haṣabiah; ti ìdílé Jedaiah, Netaneli.
de Hilkiah, Hashabiah; de Jedaiah, Nethanel.
22 Àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi ní ìgbà ayé Eliaṣibu, Joiada, Johanani àti Jaddua, àti pẹ̀lú ti àwọn àlùfáà ni a kọ sílẹ̀ ní ìgbà ìjọba Dariusi ará Persia.
Quant aux Lévites, aux jours d'Eliaschib, de Jojada, de Jochanan et de Jaddua, on enregistra les chefs de famille; les prêtres aussi, sous le règne de Darius le Perse.
23 Àwọn olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Lefi títí di àkókò Johanani ọmọ Eliaṣibu ni a kọ sílẹ̀ nínú ìwé ìtàn.
Les fils de Lévi, chefs de famille, furent inscrits dans le livre des chroniques, jusqu'à l'époque de Johanan, fils d'Eliashib.
24 Àti àwọn olórí àwọn ọmọ Lefi ni Haṣabiah, Ṣerebiah, Jeṣua ọmọ Kadmieli, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n dúró ní ìdojúkojú wọn láti fi ìyìn àti láti dúpẹ́, apá kan ń dá èkejì lóhùn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run.
Les chefs des Lévites: Haschabia, Shérébia et Josué, fils de Kadmiel, avec leurs frères près d'eux, pour louer et remercier selon le commandement de David, homme de Dieu, section par section.
25 Mattaniah, Bakbukiah, Obadiah, Meṣullamu, Talmoni àti Akkubu ni aṣọ́nà tí wọ́n ń sọ yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ní ẹnu-ọ̀nà.
Mattania, Bakbukiah, Abdias, Meshullam, Talmon et Akkub étaient des gardiens de portes qui surveillaient les entrepôts des portes.
26 Wọ́n ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ìgbà ayé e Joiakimu ọmọ Jeṣua, ọmọ Josadaki, àti ní ọjọ́ ọ Nehemiah baálẹ̀ àti ní ọjọ́ Esra àlùfáà àti akọ̀wé.
C'était du temps de Jojakim, fils de Josué, fils de Jotsadak, du temps de Néhémie, le gouverneur, et d'Esdras, le prêtre et le scribe.
27 Nígbà ìyàsímímọ́ odi Jerusalẹmu a mú àwọn ọmọ Lefi jáde wá láti ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú wọn wá sí Jerusalẹmu láti fi ayọ̀ ṣe ayẹyẹ ìyàsímímọ́ pẹ̀lú orin ìdúpẹ́ àti pẹ̀lú ohun èlò orin kimbali, haapu àti ohun èlò orin olókùn.
Lors de la dédicace de la muraille de Jérusalem, on chercha les Lévites de tous les lieux où ils se trouvaient, pour les faire venir à Jérusalem afin de célébrer la dédicace dans la joie, tant par des actions de grâces que par des chants, avec des cymbales, des instruments à cordes et des harpes.
28 A kó àwọn akọrin náà jọ papọ̀ láti àwọn ìletò tí ó yí Jerusalẹmu náà ká—láti àwọn abúlé Netofa,
Les fils des chantres se rassemblèrent, tant de la plaine qui entoure Jérusalem que des villages des Netophathites;
29 láti Beti-Gilgali, àti láti àwọn agbègbè Geba àti Asmafeti, nítorí àwọn akọrin ti kọ́ àwọn ìletò fúnra wọn ní agbègbè Jerusalẹmu.
aussi de Beth Gilgal et des champs de Guéba et d'Azmaveth, car les chantres s'étaient construit des villages autour de Jérusalem.
30 Nígbà tí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n ya àwọn ènìyàn sí mímọ́, àti ẹnu ibodè àti odi pẹ̀lú.
Les prêtres et les lévites se purifièrent; ils purifièrent le peuple, les portes et la muraille.
31 Mo sì tún yan àwọn olórí Juda láti gun orí odi náà. Mo sì tún yan àwọn ẹgbẹ́ akọrin ńlá méjì láti dúpẹ́. Àwọn kan yóò gòkè odi lọ sí apá ọ̀tún sí ọ̀nà ibodè Ààtàn.
Puis je fis monter les princes de Juda sur la muraille, et je désignai deux grandes compagnies qui rendirent grâces et allèrent en procession. L'une marchait à droite sur la muraille, vers la porte des fumiers;
32 Hoṣaiah àti ìdajì àwọn olórí Juda tẹ̀lé wọn,
et après elle, Hoshaiah, avec la moitié des princes de Juda,
33 àwọn wọ̀nyí náà sì lọ pẹ̀lú wọn, Asariah, Esra, Meṣullamu,
Azaria, Esdras, Meshullam,
34 Juda, Benjamini, Ṣemaiah, Jeremiah,
Juda, Benjamin, Shemaiah, Jérémie,
35 pẹ̀lú àwọn àlùfáà díẹ̀ pẹ̀lú ìpè, pẹ̀lú u Sekariah ọmọ Jonatani, ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Mattaniah, ọmọ Mikaiah, ọmọ Sakkuri, ọmọ Asafu,
et quelques fils de prêtres avec des trompettes: Zacharie, fils de Jonathan, fils de Schemaeja, fils de Matthania, fils de Michée, fils de Zaccur, fils d'Asaph,
36 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, Ṣemaiah, Asareeli, Milalai, Gilalai, Maai, Netaneli, Juda àti Hanani—pẹ̀lú ohun èlò orin bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run. Esra akọ̀wé ni ó ṣáájú wọn bí wọ́n ti ń tò lọ lọ́wọ̀ọ̀wọ́.
et ses frères, Schemaeja, Azarel, Milalaï, Gilalaï, Maaï, Nethaneel, Juda et Hanani, avec les instruments de musique de David, homme de Dieu; et Esdras, le scribe, était devant eux.
37 Ní ẹnu ibodè orísun wọ́n ti ń lọ tààrà sí ọ̀nà ní orí àtẹ̀gùn ìlú Dafidi ní orí òkè tí ó kángun sí odi, wọ́n sì gba ẹ̀gbẹ́ ilé Dafidi kọjá títí dé ẹnu ibodè omi ní ìhà ìlà-oòrùn.
Par la porte de la source, et droit devant eux, ils montèrent par les escaliers de la ville de David, sur la montée de la muraille, au-dessus de la maison de David, jusqu'à la porte des eaux, à l'orient.
38 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin kejì gba ọ̀nà òdìkejì lọ. Mo tẹ̀lé wọn ní orí odi, pẹ̀lú ìdajì àwọn ènìyàn, kọjá ilé ìṣọ́ ìléru lọ sí odi fífẹ̀,
L'autre troupe de ceux qui rendaient grâces alla à leur rencontre, et moi après eux, avec la moitié du peuple, sur le mur au-dessus de la tour des fourneaux, jusqu'à la grande muraille,
39 kọjá ẹnu ibodè Efraimu ibodè Jeṣana, ẹnu ibodè ẹja, ilé ìṣọ́ Hananeli àti ilé ìṣọ́ ọgọ́rùn-ún, títí dé ẹnu ibodè àgùntàn. Wọ́n sì dúró ní ibodè ìṣọ́.
et au-dessus de la porte d'Ephraïm, et par la vieille porte, et par la porte des poissons, la tour de Hananel, et la tour de Hamméa, jusqu'à la porte des brebis; et ils s'arrêtèrent à la porte de la garde.
40 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin méjèèjì tí wọ́n dúpẹ́ wà ní ààyè nínú ilé Ọlọ́run, èmi náà sì dúró ní ààyè mi pẹ̀lú ìdajì àwọn ìjòyè,
Les deux compagnies de ceux qui rendaient grâces dans la maison de Dieu se tinrent debout, moi et la moitié des chefs avec moi,
41 àti àwọn àlùfáà Eliakimu, Maaseiah, Miniamini, Mikaiah, Elioenai, Sekariah àti Hananiah pẹ̀lú àwọn ìpè wọn.
et les prêtres, Eliakim, Maaséja, Miniamin, Micaeja, Elioénaï, Zacharie et Hanania, avec des trompettes,
42 Àti pẹ̀lú Maaseiah, Ṣemaiah, Eleasari àti Ussi, àti Jehohanani, àti Malkiah, àti Elamu, àti Eseri. Àwọn akọrin kọrin sókè ní abẹ́ alábojútó Jesrahiah.
et Maaséja, Schemaeja, Éléazar, Uzzi, Johanan, Malkija, Élam et Ézer. Les chantres chantaient à haute voix, avec Jizrachia, leur chef.
43 Ní ọjọ́ náà wọ́n rú ẹbọ ńlá, wọ́n ṣe àjọyọ̀ nítorí Ọlọ́run ti fún wọn ní ayọ̀ ńlá. Àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé sì yọ̀ pẹ̀lú. A lè gbọ́ ariwo ayọ̀ tí ó jáde láti Jerusalẹmu ní jìnnà réré.
Ils offrirent ce jour-là de grands sacrifices, et ils se réjouirent, car Dieu les avait comblés d'une grande joie; les femmes et les enfants se réjouirent aussi, de sorte que la joie de Jérusalem se fit entendre jusqu'au loin.
44 Ní àkókò náà, a yan àwọn ènìyàn láti jẹ́ alábojútó yàrá ìṣúra fún àwọn ọrẹ àkọ́so èso àti àwọn ìdámẹ́wàá. Láti inú àwọn oko tí ó wà ní àyíká ìlú ni wọ́n ti ní láti mú wá sínú yàrá ìṣúra, ìpín tí òfin sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, nítorí inú àwọn ará a Juda yọ́ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tó ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́.
Ce jour-là, des hommes furent désignés pour surveiller les salles destinées aux trésors, aux offrandes ondulées, aux prémices et aux dîmes, afin d'y recueillir, selon les champs des villes, les portions fixées par la loi pour les prêtres et les lévites; car Juda se réjouissait pour les prêtres et pour les lévites qui faisaient le service.
45 Wọ́n ń ṣiṣẹ́ Ọlọ́run wọn àti iṣẹ́ ìyàsímímọ́, bẹ́ẹ̀ náà ni fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà, wọ́n ń ṣe gẹ́gẹ́ bí Dafidi àti Solomoni ọmọ rẹ̀ ti pàṣẹ fún wọn.
Ils accomplissaient le devoir de leur Dieu et le devoir de la purification, de même que les chantres et les portiers, selon le commandement de David et de Salomon, son fils.
46 Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn ní ìgbà Dafidi àti Asafu, ni àwọn atọ́nisọ́nà ti wà fún àwọn akọrin àti fún orin ìyìn àti orin ọpẹ́ sí Ọlọ́run.
Car du temps de David et d'Asaph, il y avait un chef des chantres, et des chants de louange et d'action de grâce à Dieu.
47 Nítorí náà ní ìgbà ayé Serubbabeli àti Nehemiah, gbogbo Israẹli ni ó ń dá ìpín lójoojúmọ́ fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà. Wọ́n sì tún yan ìpín mìíràn sọ́tọ̀ fún àwọn ọmọ Lefi tókù, àwọn ọmọ Lefi náà tún ya ìpín ti àwọn ọmọ Aaroni sọ́tọ̀ fún wọn.
Tout Israël, du temps de Zorobabel et du temps de Néhémie, donna les portions des chantres et des portiers, selon les besoins de chaque jour; on mit à part ce qui était pour les Lévites, et les Lévites mirent à part ce qui était pour les fils d'Aaron.

< Nehemiah 12 >