< Nehemiah 12 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tí ó bá Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti Jeṣua padà: Seraiah, Jeremiah, Esra,
Now, these, are the priests and the Levites, who came up with Zerubbabel son of Shealtiel, and Jeshua, —Seraiah, Jeremiah, Ezra;
2 Amariah, Malluki, Hattusi,
Amariah, Malluch, Hattush;
3 Ṣekaniah, Rehumu, Meremoti,
Shecaniah, Rehum, Meremoth;
4 Iddo, Ginetoni, Abijah,
Iddo, Ginnethoi, Abijah;
5 Mijamini, Moadiah, Bilgah,
Mijamin, Maadiah, Bilgah;
6 Ṣemaiah, Joiaribu, Jedaiah,
Shemaiah, and Joiarib, Jedaiah;
7 Sallu, Amoki, Hilkiah, àti Jedaiah. Wọ̀nyí ni olórí àwọn àlùfáà àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn ní ìgbà ayé e Jeṣua.
Sallu, Amok, Hilkiah, Jedaiah, —these, were the chiefs of the priests and their brethren, in the days of Jeshua.
8 Àwọn ọmọ Lefi ni Jeṣua, Binnui, Kadmieli, Ṣerebiah, Juda àti Mattaniah ẹni tí òun pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, ni wọn ṣe àkóso orin ìdúpẹ́.
And, the Levites, Jeshua, Binnui, Kadmiel, Sherebiah, Judah, Mattaniah, —over the choirs, he and his brethren;
9 Bakbukiah àti Unni, àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn dúró sí òdìkejì wọn nínú ìsìn.
and Bakbukiah and Unno their brethren, were over against them, in wards.
10 Jeṣua ni baba Joiakimu, Joiakimu ni baba Eliaṣibu, Eliaṣibu ni baba Joiada,
And Jeshua, begat Joiakim, —and Joiakim, begat Eliashib, and, Eliashib, [begat] Joiada;
11 Joiada ni baba Jonatani, Jonatani sì ni baba Jaddua.
and, Joiada, begat Jonathan, —and, Jonathan, begat Jaddua.
12 Ní ìgbé ayé Joiakimu, wọ̀nyí ni àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn àlùfáà: ti ìdílé Seraiah, Meraiah; ti ìdílé Jeremiah, Hananiah;
And, in the days of Joiakim, were priests, ancestral chiefs, —of Seraiah, Meraiah, of Jeremiah, Hananiah;
13 ti ìdílé Esra, Meṣullamu; ti ìdílé Amariah, Jehohanani;
of Ezra, Meshullam, —of Amariah, Jehohanan;
14 ti ìdílé Malluki, Jonatani; ti ìdílé Ṣekaniah, Josẹfu;
of Malluchi, Jonathan, —of Shebaniah, Joseph;
15 ti ìdílé Harimu, Adna; ti ìdílé Meraioti Helikai;
of Harim, Adna, —of Meraioth, Helkai;
16 ti ìdílé Iddo, Sekariah; ti ìdílé Ginetoni, Meṣullamu;
of Iddo, Zechariah, —of Ginnethon, Meshullam;
17 ti ìdílé Abijah, Sikri; ti ìdílé Miniamini àti ti ìdílé Moadiah, Piltai;
of Abijah, Zichri, —of Miniamin, of Moadiah, Piltai;
18 ti ìdílé Bilgah, Ṣammua; ti ìdílé Ṣemaiah, Jehonatani;
of Bilgah, Shammua, —of Shemaiah, Jehonathan;
19 ti ìdílé Joiaribu, Mattenai; ti ìdílé Jedaiah, Ussi;
and, of Joiarib, Mattenai, —of Jedaiah, Uzzi;
20 ti ìdílé Sallu, Kallai; ti ìdílé Amoki, Eberi;
of Sallai, Kallai, —of Amok, Eber;
21 ti ìdílé Hilkiah, Haṣabiah; ti ìdílé Jedaiah, Netaneli.
of Hilkiah, Hashabiah, —of Jedaiah, Nethanel.
22 Àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi ní ìgbà ayé Eliaṣibu, Joiada, Johanani àti Jaddua, àti pẹ̀lú ti àwọn àlùfáà ni a kọ sílẹ̀ ní ìgbà ìjọba Dariusi ará Persia.
The Levites—in the days of Eliashib, Joiada, and Johanan, and Jaddua, were recorded as ancestral chiefs, —also the priests, unto the reign of Darius the Persian.
23 Àwọn olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Lefi títí di àkókò Johanani ọmọ Eliaṣibu ni a kọ sílẹ̀ nínú ìwé ìtàn.
the sons of Levi, ancestral heads, were written in the book of Chronicles, —even until the days of Johanan, son of Eliashib.
24 Àti àwọn olórí àwọn ọmọ Lefi ni Haṣabiah, Ṣerebiah, Jeṣua ọmọ Kadmieli, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n dúró ní ìdojúkojú wọn láti fi ìyìn àti láti dúpẹ́, apá kan ń dá èkejì lóhùn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run.
And, the chiefs of the Levites, Hashabiah, Sherebiah, and Jeshua son of Kadmiel, with their brethren over against them, to praise—to give thanks, by the commandment of David the man of God, —ward joined to ward.
25 Mattaniah, Bakbukiah, Obadiah, Meṣullamu, Talmoni àti Akkubu ni aṣọ́nà tí wọ́n ń sọ yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ní ẹnu-ọ̀nà.
Mattaniah and Bakbukiah, Obadiah, Meshullam, Talmon, Akkub, were watchers, doorkeepers of the ward, in the storehouses of the gates.
26 Wọ́n ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ìgbà ayé e Joiakimu ọmọ Jeṣua, ọmọ Josadaki, àti ní ọjọ́ ọ Nehemiah baálẹ̀ àti ní ọjọ́ Esra àlùfáà àti akọ̀wé.
These, were in the days of Joiakim, son of Jeshua, son of Jozadak, —and in the days of Nehemiah the pasha, and Ezra the priest the scribe.
27 Nígbà ìyàsímímọ́ odi Jerusalẹmu a mú àwọn ọmọ Lefi jáde wá láti ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú wọn wá sí Jerusalẹmu láti fi ayọ̀ ṣe ayẹyẹ ìyàsímímọ́ pẹ̀lú orin ìdúpẹ́ àti pẹ̀lú ohun èlò orin kimbali, haapu àti ohun èlò orin olókùn.
And, at the dedication of the wall of Jerusalem, they sought the Levites, out of all their places, to bring them to Jerusalem, —to keep the dedication and the rejoicing, both with thanksgiving and with music, cymbals, harps, and with lyres.
28 A kó àwọn akọrin náà jọ papọ̀ láti àwọn ìletò tí ó yí Jerusalẹmu náà ká—láti àwọn abúlé Netofa,
So the sons of the singers gathered themselves together, —both out of the circuit round about Jerusalem, and out of the villages of the Netophathites;
29 láti Beti-Gilgali, àti láti àwọn agbègbè Geba àti Asmafeti, nítorí àwọn akọrin ti kọ́ àwọn ìletò fúnra wọn ní agbègbè Jerusalẹmu.
also out of Beth-gilgal, and out of the fields of Geba, and Azmaveth, —for, villages, had the singers builded for themselves, round about Jerusalem.
30 Nígbà tí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n ya àwọn ènìyàn sí mímọ́, àti ẹnu ibodè àti odi pẹ̀lú.
And the priests and the Levites purified themselves, —and purified the people, and the gates, and the wall.
31 Mo sì tún yan àwọn olórí Juda láti gun orí odi náà. Mo sì tún yan àwọn ẹgbẹ́ akọrin ńlá méjì láti dúpẹ́. Àwọn kan yóò gòkè odi lọ sí apá ọ̀tún sí ọ̀nà ibodè Ààtàn.
Then brought I up the rulers of Judah upon the wall, —and I appointed two large choirs, even to go in procession to the right, upon the wall, towards the dung-gate;
32 Hoṣaiah àti ìdajì àwọn olórí Juda tẹ̀lé wọn,
and after them went Hoshaiah, and half the rulers of Judah;
33 àwọn wọ̀nyí náà sì lọ pẹ̀lú wọn, Asariah, Esra, Meṣullamu,
then Azariah, Ezra, and Meshullam;
34 Juda, Benjamini, Ṣemaiah, Jeremiah,
Judah, and Benjamin, and Shemaiah, and Jeremiah;
35 pẹ̀lú àwọn àlùfáà díẹ̀ pẹ̀lú ìpè, pẹ̀lú u Sekariah ọmọ Jonatani, ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Mattaniah, ọmọ Mikaiah, ọmọ Sakkuri, ọmọ Asafu,
and, of the sons of the priests, with trumpets, Zechariah—son of Jonathan—son of Shemaiah—son of Mattaniah, son of Micaiah, son of Zaccur, son of Asaph;
36 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, Ṣemaiah, Asareeli, Milalai, Gilalai, Maai, Netaneli, Juda àti Hanani—pẹ̀lú ohun èlò orin bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run. Esra akọ̀wé ni ó ṣáájú wọn bí wọ́n ti ń tò lọ lọ́wọ̀ọ̀wọ́.
and his brethren—Shemaiah and Azarel, Milalai, Gilalai, Maai, Nethanel, and Judah, Hanani, with the instruments of music of David, the man of God, —with Ezra the scribe before them;
37 Ní ẹnu ibodè orísun wọ́n ti ń lọ tààrà sí ọ̀nà ní orí àtẹ̀gùn ìlú Dafidi ní orí òkè tí ó kángun sí odi, wọ́n sì gba ẹ̀gbẹ́ ilé Dafidi kọjá títí dé ẹnu ibodè omi ní ìhà ìlà-oòrùn.
and, over they fountain gate and straight before them, they went up by the stairs of the city of David, at the going up of the wall, —above the house of David, even as far as the water-gate, eastward.
38 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin kejì gba ọ̀nà òdìkejì lọ. Mo tẹ̀lé wọn ní orí odi, pẹ̀lú ìdajì àwọn ènìyàn, kọjá ilé ìṣọ́ ìléru lọ sí odi fífẹ̀,
And, the second choir, was going over against them, I, following it, —with the half of the people upon the wall, above the tower of the ovens, even as far as the broad wall;
39 kọjá ẹnu ibodè Efraimu ibodè Jeṣana, ẹnu ibodè ẹja, ilé ìṣọ́ Hananeli àti ilé ìṣọ́ ọgọ́rùn-ún, títí dé ẹnu ibodè àgùntàn. Wọ́n sì dúró ní ibodè ìṣọ́.
and above the gate of Ephraim, and upon the old gate, and upon the fish-gate, and the tower of Hananel, and the tower of Hammeah, even as far as the sheep-gate, —and they came to a stand, at the gate of the guard.
40 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin méjèèjì tí wọ́n dúpẹ́ wà ní ààyè nínú ilé Ọlọ́run, èmi náà sì dúró ní ààyè mi pẹ̀lú ìdajì àwọn ìjòyè,
So the two choirs, came to a stand, at the house of God, —and I, and half the deputies with me;
41 àti àwọn àlùfáà Eliakimu, Maaseiah, Miniamini, Mikaiah, Elioenai, Sekariah àti Hananiah pẹ̀lú àwọn ìpè wọn.
and, the priests—Eliakim, Maaseiah, Miniamin, Micaiah, Elioenai, Zechariah, and Hananiah, with trumpets;
42 Àti pẹ̀lú Maaseiah, Ṣemaiah, Eleasari àti Ussi, àti Jehohanani, àti Malkiah, àti Elamu, àti Eseri. Àwọn akọrin kọrin sókè ní abẹ́ alábojútó Jesrahiah.
and Maaseiah and Shemaiah and Eleazar and Uzzi and Jehohanan and Malchijah and Elam and Ezer, —and the musicians sounded, aloud with Jezrahiah who was over them.
43 Ní ọjọ́ náà wọ́n rú ẹbọ ńlá, wọ́n ṣe àjọyọ̀ nítorí Ọlọ́run ti fún wọn ní ayọ̀ ńlá. Àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé sì yọ̀ pẹ̀lú. A lè gbọ́ ariwo ayọ̀ tí ó jáde láti Jerusalẹmu ní jìnnà réré.
And they sacrificed, on that day, great sacrifices, and rejoiced, for, God, had caused them to rejoice with great joy, moreover also, the women and children, rejoiced, —so that the rejoicing of Jerusalem was heard afar off.
44 Ní àkókò náà, a yan àwọn ènìyàn láti jẹ́ alábojútó yàrá ìṣúra fún àwọn ọrẹ àkọ́so èso àti àwọn ìdámẹ́wàá. Láti inú àwọn oko tí ó wà ní àyíká ìlú ni wọ́n ti ní láti mú wá sínú yàrá ìṣúra, ìpín tí òfin sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, nítorí inú àwọn ará a Juda yọ́ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tó ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́.
And there were set in charge, on that day, certain men, over the chambers for the treasures, for the heave-offerings, for the firstfruits, and for the tithes, to gather into them, out of the fields of the cities, the portions appointed by the law, for the priests, and for the Levites, —for, the joy of Judah, was over the priests and over the Levites, who were remaining.
45 Wọ́n ń ṣiṣẹ́ Ọlọ́run wọn àti iṣẹ́ ìyàsímímọ́, bẹ́ẹ̀ náà ni fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà, wọ́n ń ṣe gẹ́gẹ́ bí Dafidi àti Solomoni ọmọ rẹ̀ ti pàṣẹ fún wọn.
So they kept the charge of their God, and the charge of the purification, and [so did] the singers and the doorkeepers, —according to the commandment of David and of Solomon his son.
46 Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn ní ìgbà Dafidi àti Asafu, ni àwọn atọ́nisọ́nà ti wà fún àwọn akọrin àti fún orin ìyìn àti orin ọpẹ́ sí Ọlọ́run.
For, in the days of David and Asaph, of old, there were chiefs of the singers, and songs of praise and thanksgiving, unto God.
47 Nítorí náà ní ìgbà ayé Serubbabeli àti Nehemiah, gbogbo Israẹli ni ó ń dá ìpín lójoojúmọ́ fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà. Wọ́n sì tún yan ìpín mìíràn sọ́tọ̀ fún àwọn ọmọ Lefi tókù, àwọn ọmọ Lefi náà tún ya ìpín ti àwọn ọmọ Aaroni sọ́tọ̀ fún wọn.
Now, all Israel—in the days of Zerubbabel, and in the days of Nehemiah, used to give the portions of the singers and the doorkeepers, the need of a day upon its day, —and they hallowed them unto the Levites, and, the Levites, hallowed them unto the sons of Aaron.

< Nehemiah 12 >