< Nehemiah 12 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tí ó bá Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti Jeṣua padà: Seraiah, Jeremiah, Esra,
Tito pak jsou kněží a Levítové, kteříž se byli navrátili s Zorobábelem synem Salatielovým, a s Jesua: Saraiáš, Jeremiáš, Ezdráš,
2 Amariah, Malluki, Hattusi,
Amariáš, Malluch, Chattus,
3 Ṣekaniah, Rehumu, Meremoti,
Sechaniáš, Rechum, Meremot,
4 Iddo, Ginetoni, Abijah,
Iddo, Ginnetoi, Abiáš,
5 Mijamini, Moadiah, Bilgah,
Miamin, Maadiáš, Bilga,
6 Ṣemaiah, Joiaribu, Jedaiah,
Semaiáš, Joiarib, Jedaiáš,
7 Sallu, Amoki, Hilkiah, àti Jedaiah. Wọ̀nyí ni olórí àwọn àlùfáà àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn ní ìgbà ayé e Jeṣua.
Sallu, Amok, Helkiáš, Jedaiáš. Ti byli přednější z kněží a bratří svých za času Jesua.
8 Àwọn ọmọ Lefi ni Jeṣua, Binnui, Kadmieli, Ṣerebiah, Juda àti Mattaniah ẹni tí òun pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, ni wọn ṣe àkóso orin ìdúpẹ́.
Levítové pak: Jesua, Binnui, Kadmiel, Serebiáš, Juda; Mattaniáš, postavený nad zpěvy chvalitebnými s bratřími svými.
9 Bakbukiah àti Unni, àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn dúró sí òdìkejì wọn nínú ìsìn.
A Bakbukiáš a Unni, bratří jejich, byli naproti nim v pořádcích svých.
10 Jeṣua ni baba Joiakimu, Joiakimu ni baba Eliaṣibu, Eliaṣibu ni baba Joiada,
Jesua pak zplodil Joiakima, a Joiakim zplodil Eliasiba, Eliasib pak zplodil Joiadu.
11 Joiada ni baba Jonatani, Jonatani sì ni baba Jaddua.
A Joiada zplodil Jonatana, Jonatan pak zplodil Jaddua.
12 Ní ìgbé ayé Joiakimu, wọ̀nyí ni àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn àlùfáà: ti ìdílé Seraiah, Meraiah; ti ìdílé Jeremiah, Hananiah;
Za času pak Joiakima byli přední kněží z čeledí otcovských: Z Saraiášovy Meraiáš, z Jeremiášovy Chananiáš,
13 ti ìdílé Esra, Meṣullamu; ti ìdílé Amariah, Jehohanani;
Z Ezdrášovy Mesullam, z Amariášovy Jochanan,
14 ti ìdílé Malluki, Jonatani; ti ìdílé Ṣekaniah, Josẹfu;
Z Melichovy Jonatan, z Sebaniášovy Jozef,
15 ti ìdílé Harimu, Adna; ti ìdílé Meraioti Helikai;
Z Charimovy Adna, z Meraiotovy Chelkai,
16 ti ìdílé Iddo, Sekariah; ti ìdílé Ginetoni, Meṣullamu;
Z Iddovy Zachariáš, z Ginnetonovy Mesullam,
17 ti ìdílé Abijah, Sikri; ti ìdílé Miniamini àti ti ìdílé Moadiah, Piltai;
Z Abiášovy Zichri, z Miniaminovy a z Moadiášovy Piltai,
18 ti ìdílé Bilgah, Ṣammua; ti ìdílé Ṣemaiah, Jehonatani;
Z Bilgovy Sammua, z Semaiášovy Jonatan,
19 ti ìdílé Joiaribu, Mattenai; ti ìdílé Jedaiah, Ussi;
Z Joiaribovy Mattenai, z Jedaiášovy Uzi,
20 ti ìdílé Sallu, Kallai; ti ìdílé Amoki, Eberi;
Z Sallaiovy Kallai, z Amokovy Heber,
21 ti ìdílé Hilkiah, Haṣabiah; ti ìdílé Jedaiah, Netaneli.
Z Helkiášovy Chasabiáš, z Jedaiášovy Natanael.
22 Àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi ní ìgbà ayé Eliaṣibu, Joiada, Johanani àti Jaddua, àti pẹ̀lú ti àwọn àlùfáà ni a kọ sílẹ̀ ní ìgbà ìjọba Dariusi ará Persia.
Levítové pak přednější z čeledí otcovských za dnů Eliasiba, Joiady, Jochanana a Jaddua, zapsáni jsou až do kralování Daria Perského.
23 Àwọn olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Lefi títí di àkókò Johanani ọmọ Eliaṣibu ni a kọ sílẹ̀ nínú ìwé ìtàn.
Synové, pravím, Léví, přední v čeledech otcovských, zapsáni jsou v knize Paralipomenon, až do času Jochanana syna Eliasibova.
24 Àti àwọn olórí àwọn ọmọ Lefi ni Haṣabiah, Ṣerebiah, Jeṣua ọmọ Kadmieli, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n dúró ní ìdojúkojú wọn láti fi ìyìn àti láti dúpẹ́, apá kan ń dá èkejì lóhùn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run.
Potom přední Levítové: Chasabiáš, Serebiáš, a Jesua syn Kadmielův, a bratří jejich naproti nim k chválení a oslavování Boha, podlé nařízení Davida muže Božího, třída proti třídě.
25 Mattaniah, Bakbukiah, Obadiah, Meṣullamu, Talmoni àti Akkubu ni aṣọ́nà tí wọ́n ń sọ yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ní ẹnu-ọ̀nà.
Mataniáš, Bakbukiáš, Abdiáš, Mesullam, Talmon, Akkub, držící stráž vrátných při domu pokladů u bran.
26 Wọ́n ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ìgbà ayé e Joiakimu ọmọ Jeṣua, ọmọ Josadaki, àti ní ọjọ́ ọ Nehemiah baálẹ̀ àti ní ọjọ́ Esra àlùfáà àti akọ̀wé.
Ti byli za času Joiakima, syna Jesua, syna Jozadakova, a za času Nehemiáše vůdce, a Ezdráše kněze a učitele.
27 Nígbà ìyàsímímọ́ odi Jerusalẹmu a mú àwọn ọmọ Lefi jáde wá láti ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú wọn wá sí Jerusalẹmu láti fi ayọ̀ ṣe ayẹyẹ ìyàsímímọ́ pẹ̀lú orin ìdúpẹ́ àti pẹ̀lú ohun èlò orin kimbali, haapu àti ohun èlò orin olókùn.
Ku posvěcování pak zdí Jeruzalémských shlédávali Levíty ze všech míst jejich, aby je přivedli do Jeruzaléma, aby vykonali posvěcení a veselí, a to s oslavováním a zpěvy, cymbály, loutnami a harfami.
28 A kó àwọn akọrin náà jọ papọ̀ láti àwọn ìletò tí ó yí Jerusalẹmu náà ká—láti àwọn abúlé Netofa,
Protož shromážděni jsou synové zpěváků, i z rovin okolo Jeruzaléma, i ze vsí Netofatských,
29 láti Beti-Gilgali, àti láti àwọn agbègbè Geba àti Asmafeti, nítorí àwọn akọrin ti kọ́ àwọn ìletò fúnra wọn ní agbègbè Jerusalẹmu.
Též z domu Galgal, a z polí Gaba i Azmavet; nebo vsi stavěli sobě zpěváci okolo Jeruzaléma.
30 Nígbà tí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n ya àwọn ènìyàn sí mímọ́, àti ẹnu ibodè àti odi pẹ̀lú.
A očistivše se kněží a Levítové, očistili také lid, brány i zed.
31 Mo sì tún yan àwọn olórí Juda láti gun orí odi náà. Mo sì tún yan àwọn ẹgbẹ́ akọrin ńlá méjì láti dúpẹ́. Àwọn kan yóò gòkè odi lọ sí apá ọ̀tún sí ọ̀nà ibodè Ààtàn.
Za tím rozkázal jsem vstoupiti knížatům Judským na zed, a postavil jsem dva houfy veliké oslavujících, z nichž jedni šli na pravo, od horní strany zdi k bráně hnojné.
32 Hoṣaiah àti ìdajì àwọn olórí Juda tẹ̀lé wọn,
A za těmi šel Hosaiáš a polovice knížat Judských,
33 àwọn wọ̀nyí náà sì lọ pẹ̀lú wọn, Asariah, Esra, Meṣullamu,
Též Azariáš, Ezdráš, a Mesullam,
34 Juda, Benjamini, Ṣemaiah, Jeremiah,
Juda, Beniamin, Semaiáš a Jeremiáš.
35 pẹ̀lú àwọn àlùfáà díẹ̀ pẹ̀lú ìpè, pẹ̀lú u Sekariah ọmọ Jonatani, ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Mattaniah, ọmọ Mikaiah, ọmọ Sakkuri, ọmọ Asafu,
Potom za syny kněžskými s trubami Zachariáš syn Jonatana, syna Semaiášova, syna Mattaniášova, syna Michaiášova, syna Zakurova, syna Azafova.
36 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, Ṣemaiah, Asareeli, Milalai, Gilalai, Maai, Netaneli, Juda àti Hanani—pẹ̀lú ohun èlò orin bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run. Esra akọ̀wé ni ó ṣáájú wọn bí wọ́n ti ń tò lọ lọ́wọ̀ọ̀wọ́.
A bratří jeho: Semaiáš, Azarel, Milalai, Gilalai, Maai, Natanael a Juda, Chanani s nástroji hudebnými Davida muže Božího, Ezdráš pak učitel před nimi.
37 Ní ẹnu ibodè orísun wọ́n ti ń lọ tààrà sí ọ̀nà ní orí àtẹ̀gùn ìlú Dafidi ní orí òkè tí ó kángun sí odi, wọ́n sì gba ẹ̀gbẹ́ ilé Dafidi kọjá títí dé ẹnu ibodè omi ní ìhà ìlà-oòrùn.
Potom k bráně u studnice, kteráž naproti nim byla, vstupovali po stupních města Davidova, kudy se chodí na zed, a ode zdi při domě Davidově, až k bráně vodné k východu.
38 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin kejì gba ọ̀nà òdìkejì lọ. Mo tẹ̀lé wọn ní orí odi, pẹ̀lú ìdajì àwọn ènìyàn, kọjá ilé ìṣọ́ ìléru lọ sí odi fífẹ̀,
Houf pak druhý oslavujících bral se naproti oněmno, a já za nimi, a polovice lidu po zdi od věže Tannurim až ke zdi široké,
39 kọjá ẹnu ibodè Efraimu ibodè Jeṣana, ẹnu ibodè ẹja, ilé ìṣọ́ Hananeli àti ilé ìṣọ́ ọgọ́rùn-ún, títí dé ẹnu ibodè àgùntàn. Wọ́n sì dúró ní ibodè ìṣọ́.
A od brány Efraim k bráně staré, a k bráně rybné, a věži Chananeel, a věži Mea, až k bráně bravné. I zastavili se v bráně stráže.
40 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin méjèèjì tí wọ́n dúpẹ́ wà ní ààyè nínú ilé Ọlọ́run, èmi náà sì dúró ní ààyè mi pẹ̀lú ìdajì àwọn ìjòyè,
Potom zastavili se oba houfové oslavujících v domě Božím, i já, a polovice knížat se mnou.
41 àti àwọn àlùfáà Eliakimu, Maaseiah, Miniamini, Mikaiah, Elioenai, Sekariah àti Hananiah pẹ̀lú àwọn ìpè wọn.
Ano i kněží: Eliakim, Maaseiáš, Miniamin, Michaiáš, Elioenai, Zachariáš, Chananiáš, s trubami,
42 Àti pẹ̀lú Maaseiah, Ṣemaiah, Eleasari àti Ussi, àti Jehohanani, àti Malkiah, àti Elamu, àti Eseri. Àwọn akọrin kọrin sókè ní abẹ́ alábojútó Jesrahiah.
A Maaseiáš, Semaiáš, Eleazar, Uzi, Jochanan, Malkiáš, Elam a Ezer. Zpěváci pak zvučně zpívali s Izrachiášem představeným svým.
43 Ní ọjọ́ náà wọ́n rú ẹbọ ńlá, wọ́n ṣe àjọyọ̀ nítorí Ọlọ́run ti fún wọn ní ayọ̀ ńlá. Àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé sì yọ̀ pẹ̀lú. A lè gbọ́ ariwo ayọ̀ tí ó jáde láti Jerusalẹmu ní jìnnà réré.
Obětovali také v ten den oběti veliké, a veselili se; nebo Bůh obveselil je veselím velikým. Ano i ženy a děti veselily se, tak že bylo slyšáno veselí Jeruzaléma opodál.
44 Ní àkókò náà, a yan àwọn ènìyàn láti jẹ́ alábojútó yàrá ìṣúra fún àwọn ọrẹ àkọ́so èso àti àwọn ìdámẹ́wàá. Láti inú àwọn oko tí ó wà ní àyíká ìlú ni wọ́n ti ní láti mú wá sínú yàrá ìṣúra, ìpín tí òfin sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, nítorí inú àwọn ará a Juda yọ́ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tó ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́.
Mezi tím zřízeni jsou v ten den muži nad komorami k pokladům a k obětem, i k prvotinám a k desátkům, aby shromažďovali do nich s polí městských díly, zákonem vyměřené kněžím a Levítům; nebo veselil se Juda z kněží a Levítů přístojících,
45 Wọ́n ń ṣiṣẹ́ Ọlọ́run wọn àti iṣẹ́ ìyàsímímọ́, bẹ́ẹ̀ náà ni fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà, wọ́n ń ṣe gẹ́gẹ́ bí Dafidi àti Solomoni ọmọ rẹ̀ ti pàṣẹ fún wọn.
Kteříž držeti měli stráž Boha svého, a stráž očišťování, a zpěváků i vrátných, podlé nařízení Davidova a Šalomouna syna jeho.
46 Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn ní ìgbà Dafidi àti Asafu, ni àwọn atọ́nisọ́nà ti wà fún àwọn akọrin àti fún orin ìyìn àti orin ọpẹ́ sí Ọlọ́run.
Nebo za času Davidova a Azafova od starodávna přední zpěváci k zpívání, chválení a oslavování Boha stáli před ním.
47 Nítorí náà ní ìgbà ayé Serubbabeli àti Nehemiah, gbogbo Israẹli ni ó ń dá ìpín lójoojúmọ́ fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà. Wọ́n sì tún yan ìpín mìíràn sọ́tọ̀ fún àwọn ọmọ Lefi tókù, àwọn ọmọ Lefi náà tún ya ìpín ti àwọn ọmọ Aaroni sọ́tọ̀ fún wọn.
Pročež všecken Izrael za dnů Zorobábele a za času Nehemiáše dávali díly pro zpěváky a vrátné, na každý den stálé odměření, a odvodili je Levítům, Levítové pak dávali synům Aronovým.

< Nehemiah 12 >