< Nehemiah 11 >

1 Nísinsin yìí àwọn olórí àwọn ènìyàn tẹ̀dó sí Jerusalẹmu, àwọn ènìyàn tókù sì dìbò láti mú ẹnìkọ̀ọ̀kan jáde nínú àwọn mẹ́wàá mẹ́wàá láti máa gbé ní Jerusalẹmu, ìlú mímọ́, nígbà tí àwọn mẹ́sàn-án tókù yóò dúró sí àwọn ìlú u wọn.
Les notables parmi le peuple s’établirent à Jérusalem; le reste du peuple désigna, par la voie du sort, un sur dix pour habiter Jérusalem, la ville sainte, neuf dixièmes restant dans les autres villes.
2 Àwọn ènìyàn súre fún gbogbo àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ̀wọ́ ara wọn láti gbé ní Jerusalẹmu.
Le peuple bénit tous les hommes qui s’offraient d’eux-mêmes à habiter Jérusalem.
3 Wọ̀nyí ni àwọn olórí agbègbè ìjọba tí wọ́n tẹ̀dó sí Jerusalẹmu (díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ìran àwọn ìránṣẹ́ Solomoni ń gbé àwọn ìlú Juda, olúkúlùkù ń gbé lórí ilẹ̀ ìní rẹ̀ ní àwọn ìlú náà.
Voici les chefs de la province qui se fixèrent à Jérusalem; quant aux villes de Juda, chacun s’était établi dans sa propriété, dans sa ville respective, Israélites, prêtres, Lévites, serviteurs du temple et descendants des esclaves de Salomon.
4 Nígbà tí àwọn ènìyàn tókù nínú àwọn Juda àti Benjamini ń gbé ní Jerusalẹmu). Nínú àwọn ọmọ Juda: Ataiah ọmọ Ussiah ọmọ Sekariah, ọmọ Amariah, ọmọ Ṣefatia, ọmọ Mahalaleli, ìran Peresi;
A Jérusalem s’établirent donc une partie des enfants de Juda et des enfants de Benjamin des enfants de Juda: Ataïa, fils d’Ouzzia, fils de Zacharie, fils d’Amaria, fils de Chefatia, fils de Mahalalel, descendants de Péreç;
5 àti Maaseiah ọmọ Baruku, ọmọ Koli-Hose, ọmọ Hasaiah, ọmọ Adaiah, ọmọ Joiaribu, ọmọ Sekariah, ọmọ Ṣilo.
Maassèya, fils de Baruch, fils de Kol-Hozé, fils de Hazaïa, fils d’Adaïa, fils de Yoyarib, fils de Zacharie, fils de Chiloni.
6 Àwọn ìran Peresi tó gbé ní Jerusalẹmu jẹ́ àádọ́rinlénírinwó ó dín méjì alágbára ọkùnrin.
Tous les descendants de Péreç, établis à Jérusalem, étaient au nombre de quatre-cent soixante-huit, tous hommes vaillants.
7 Nínú àwọn ìran Benjamini: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Joẹdi, ọmọ Pedaiah, ọmọ Kolaiah, ọmọ Maaseiah, ọmọ Itieli, ọmọ Jeṣaiah,
Voici les enfants de Benjamin: Sallou, fils de Mechoullam, fils de Joëd, fils de Pedaïa, fils de Kolaïa, fils de Maassèya, fils d’Itiël, fils d’Isaïe;
8 àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Gabbai àti Sallai jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rún ó lé mẹ́jọ ọkùnrin.
après lui, Gabbaï, Sallaï, au nombre de neuf cent vingt-huit;
9 Joẹli ọmọ Sikri ni olórí òṣìṣẹ́ wọn, Juda ọmọ Hasenuah sì ni olórí agbègbè kejì ní ìlú náà.
Joël, fils de Zikhri, était leur chef, et Juda, fils de Hassenoua, commandait la ville en second.
10 Nínú àwọn àlùfáà: Jedaiah; ọmọ Joiaribu; Jakini;
Parmi les prêtres: Yedaïa, fils de Joyarib, Yakhîn;
11 Seraiah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, àwọn ni olórí tó ń bojútó ilé Ọlọ́run,
Seraïa, fils de Hilkia, fils de Mechoullam, fils de Çadok, fils de Meraïot, fils d’Ahitoub préposé au temple de Dieu;
12 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, ẹni tí ó ń ṣe iṣẹ́ ní tẹmpili jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó lé mẹ́rìnlélógún ọkùnrin: Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Pelaiah, ọmọ Amisi, ọmọ Sekariah, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah,
leurs frères, chargés de la besogne du temple, au nombre de huit cent vingt-deux; Adaïa, fils de Yeroham, fils de Pelalia, fils d’Amci, fils de Zacharie, fils de Pachhour, fils de Malkia;
13 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ olórí ìdílé jẹ́ òjìlúgba ó lé méjì ọkùnrin: Amaṣai ọmọ Asareeli, ọmọ Ahsai, ọmọ Meṣilemoti, ọmọ Immeri,
ses frères, chefs de famille, au nombre de deux cent quarante-deux; Amachsaï, fils d’Azarel, fils d’Ahzaï, fils de Mechillêmot, fils d’Immêr;
14 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin jẹ́ méjìdínláàádóje. Olórí òṣìṣẹ́ ẹ wọn ni Sabdieli ọmọ Hagedolimu.
leurs frères, tous hommes vaillants, au nombre de cent vingt-huit. Le chef qui les dirigeait était Zabdiêl, fils de Haggedolîm.
15 Láti inú àwọn ọmọ Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ọmọ Bunni;
Parmi les Lévites: Chemaïa, fils de Hachoub, fils d’Azrikâm, fils de Hachabia, fils de Bounni;
16 Ṣabbetai àti Josabadi, olórí méjì nínú àwọn ọmọ Lefi, àwọn tí ó jẹ́ alábojútó iṣẹ́ tí ó wà ní ẹ̀yìn àgbàlá ilé Ọlọ́run;
Chabbetaï, Yozabad, préposés aux travaux extérieurs de la maison de Dieu, comme faisant partie des chefs des Lévites;
17 Mattaniah ọmọ Mika, ọmọ Sabdi, ọmọ Asafu, adarí tí ó ń ṣáájú ìdúpẹ́ àti àdúrà; Bakbukiah ẹnìkejì láàrín àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀; àti Abida ọmọ Ṣammua, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni.
Mattania, fils de Mikha, fils de Zabdi, fils d’Assaph qui était le coryphée entonnant les eulogies pendant la prière Bakboukia, son second parmi ses frères, Abda, fils de Chammoua, fils de Galal, fils de Yedouthoun.
18 Àwọn ọmọ Lefi nínú ìlú mímọ́ jẹ́ ọ̀rìnlélúgba ó lé mẹ́rin.
Tous les Lévites, dans la ville sainte, étaient au nombre de deux cent quatre-vingt-quatre.
19 Àwọn aṣọ́nà: Akkubu, Talmoni, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, tí wọ́n máa ń ṣọ́nà jẹ́ méjìléláàádọ́sàn-án ọkùnrin.
Les portiers, Akkoub, Talmôn et leurs frères, qui étaient de garde aux portes, atteignaient le nombre de cent soixante-douze.
20 Àwọn tókù nínú àwọn ọmọ Israẹli, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, wà ní gbogbo ìlú u Juda, olúkúlùkù lórí ilẹ̀ ìní tirẹ̀.
Le reste des Israélites, les prêtres, les Lévites demeuraient dans toutes les villes de Juda, chacun dans sa propriété.
21 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili ń gbé lórí òkè Ofeli, Siha àti Giṣpa sì ni alábojútó wọn.
Les serviteurs du temple étaient établis sur la colline fortifiée, leurs chefs étant Ciha et Ghichpa.
22 Olórí òṣìṣẹ́ àwọn ọmọ Lefi ní Jerusalẹmu ní Ussi ọmọ Bani, ọmọ Haṣabiah, ọmọ Mattaniah ọmọ Mika. Ussi jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ìran Asafu tí wọ́n jẹ́ akọrin ojúṣe nínú ìjọ́sìn ní ilé Ọlọ́run.
Le chef des Lévites à Jérusalem était Ouzzi, fils de Bâni, fils de Hachabia, fils de Mattania, fils de Mikha, faisant partie des descendants d’Assaph, les chanteurs, chargés du service intérieur de la maison de Dieu;
23 Àwọn akọrin wà ní abẹ́ àṣẹ ọba, èyí tí ó n díwọ̀n iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn.
car il existait un règlement royal à leur égard et un contrat assurant aux chanteurs l’entretien de chaque jour.
24 Petahiah ọmọ Meṣesabeli, ọ̀kan nínú àwọn Sera ọmọ Juda ní aṣojú ọba nínú ohun gbogbo tí ó jẹ mọ́ ti àwọn ènìyàn náà.
Petahia, fils de Mechêzabel, des descendants de Zérah, fils de Juda, était le mandataire du roi en tout ce qui concernait le peuple.
25 Fún ìletò pẹ̀lú oko wọn, díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn Juda tí ń gbé Kiriati-Arba, àti àwọn ìletò agbègbè e rẹ̀, ní Diboni àti ìletò rẹ̀, ní Jekabseeli.
Quant aux bourgades avec leur banlieue, des descendants de Juda occupaient Kiryath-Arba et ses dépendances, Dibôn et ses dépendances, Yekabceêl et ses villages;
26 Ní Jeṣua, ní Molada, ní Beti-Peleti
Yêchoua, Molada et Beth-Pélet;
27 ní Hasari-Ṣuali, ní Beerṣeba àti àwọn agbègbè rẹ̀.
Haçar-Choual, Bersabée et ses dépendances;
28 Ní Siklagi, ní Mekona àti àwọn ìletò rẹ̀,
Ciklag, Mekhona et ses dépendances;
29 ní Ẹni-Rimoni, ní Sora, ní Jarmatu,
En-Rimmôn, Çorea et Yarmout:
30 Sanoa, Adullamu àti àwọn ìletò o wọn, ní Lakiṣi àti àwọn oko rẹ̀, àti ní Aseka àti àwọn ìletò rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé láti Beerṣeba títí dé àfonífojì Hinnomu.
Zanoah, Adoullam et leurs villages, Lakhich avec sa banlieue, Azêka avec ses dépendances; ils occupaient donc le pays depuis Beer Sheva jusqu’à la vallée de Hinnom.
31 Àwọn ọmọ Benjamini láti Geba ń gbé ní Mikmasi, Aija, Beteli àti àwọn ìletò rẹ̀.
Les descendants de Benjamin occupaient, en partant de Ghéba, Mikhmach, Aïa, Béthel et ses dépendances;
32 Ní Anatoti, Nobu àti Ananiah,
Anatot, Nob, Anania;
33 ní Hasori Rama àti Gittaimu,
Haçor, Rama, Ghittaïm;
34 ní Hadidi, Seboimu àti Neballati,
Hadid, Ceboïm, Neballat;
35 ní Lodi àti Ono, àti ní àfonífojì àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà.
Lod, Ono, la vallée des artisans.
36 Nínú ìpín àwọn ọmọ Lefi ni Juda tẹ̀dó sí Benjamini.
Quelques-uns des Lévites demeuraient dans des parties de Juda rattachées à Benjamin.

< Nehemiah 11 >