< Nehemiah 11 >

1 Nísinsin yìí àwọn olórí àwọn ènìyàn tẹ̀dó sí Jerusalẹmu, àwọn ènìyàn tókù sì dìbò láti mú ẹnìkọ̀ọ̀kan jáde nínú àwọn mẹ́wàá mẹ́wàá láti máa gbé ní Jerusalẹmu, ìlú mímọ́, nígbà tí àwọn mẹ́sàn-án tókù yóò dúró sí àwọn ìlú u wọn.
Les princes du peuple habitaient à Jérusalem. Le reste du peuple tirait aussi au sort une part de dix pour habiter à Jérusalem, la ville sainte, et neuf parts dans les autres villes.
2 Àwọn ènìyàn súre fún gbogbo àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ̀wọ́ ara wọn láti gbé ní Jerusalẹmu.
Le peuple bénissait tous les hommes qui s'offraient volontairement pour habiter à Jérusalem.
3 Wọ̀nyí ni àwọn olórí agbègbè ìjọba tí wọ́n tẹ̀dó sí Jerusalẹmu (díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ìran àwọn ìránṣẹ́ Solomoni ń gbé àwọn ìlú Juda, olúkúlùkù ń gbé lórí ilẹ̀ ìní rẹ̀ ní àwọn ìlú náà.
Voici les chefs de la province qui habitaient à Jérusalem; mais dans les villes de Juda, chacun habitait dans sa propriété dans ses villes: Israël, les prêtres, les lévites, les serviteurs du temple et les enfants des serviteurs de Salomon.
4 Nígbà tí àwọn ènìyàn tókù nínú àwọn Juda àti Benjamini ń gbé ní Jerusalẹmu). Nínú àwọn ọmọ Juda: Ataiah ọmọ Ussiah ọmọ Sekariah, ọmọ Amariah, ọmọ Ṣefatia, ọmọ Mahalaleli, ìran Peresi;
Une partie des fils de Juda et des fils de Benjamin habitaient à Jérusalem. Des fils de Juda: Athaja, fils d'Ozias, fils de Zacharie, fils d'Amaria, fils de Shephatia, fils de Mahalalel, des fils de Pérez;
5 àti Maaseiah ọmọ Baruku, ọmọ Koli-Hose, ọmọ Hasaiah, ọmọ Adaiah, ọmọ Joiaribu, ọmọ Sekariah, ọmọ Ṣilo.
Maaséja, fils de Baruch, fils de Colhozeh, fils de Hazaja, fils d'Adaja, fils de Joiarib, fils de Zacharie, fils du Shilonite.
6 Àwọn ìran Peresi tó gbé ní Jerusalẹmu jẹ́ àádọ́rinlénírinwó ó dín méjì alágbára ọkùnrin.
Tous les fils de Pérez qui habitaient à Jérusalem étaient quatre cent soixante-huit hommes vaillants.
7 Nínú àwọn ìran Benjamini: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Joẹdi, ọmọ Pedaiah, ọmọ Kolaiah, ọmọ Maaseiah, ọmọ Itieli, ọmọ Jeṣaiah,
Voici les fils de Benjamin: Sallu, fils de Meshullam, fils de Jœd, fils de Pedaja, fils de Kolaja, fils de Maaséja, fils d'Ithiel, fils de Jeshaiah.
8 àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Gabbai àti Sallai jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rún ó lé mẹ́jọ ọkùnrin.
Après lui, Gabbaï et Sallaï, neuf cent vingt-huit.
9 Joẹli ọmọ Sikri ni olórí òṣìṣẹ́ wọn, Juda ọmọ Hasenuah sì ni olórí agbègbè kejì ní ìlú náà.
Joël, fils de Zicri, était leur surveillant; et Juda, fils de Hassenua, était le second sur la ville.
10 Nínú àwọn àlùfáà: Jedaiah; ọmọ Joiaribu; Jakini;
Parmi les sacrificateurs: Jedaja, fils de Joiarib, Jachin,
11 Seraiah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, àwọn ni olórí tó ń bojútó ilé Ọlọ́run,
Seraja, fils de Hilkija, fils de Meshullam, fils de Tsadok, fils de Meraioth, fils d'Ahitub, chef de la maison de Dieu,
12 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, ẹni tí ó ń ṣe iṣẹ́ ní tẹmpili jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó lé mẹ́rìnlélógún ọkùnrin: Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Pelaiah, ọmọ Amisi, ọmọ Sekariah, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah,
et leurs frères qui faisaient les travaux de la maison, huit cent vingt-deux; Adaja, fils de Jerocham, fils de Pelalia, fils d'Amzi, fils de Zacharie, fils de Pashhur, fils de Malkija,
13 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ olórí ìdílé jẹ́ òjìlúgba ó lé méjì ọkùnrin: Amaṣai ọmọ Asareeli, ọmọ Ahsai, ọmọ Meṣilemoti, ọmọ Immeri,
et ses frères, chefs de famille, deux cent quarante-deux; Amashsaï, fils d'Azarel, fils d'Ahzaï, fils de Meshillemoth, fils d'Immer,
14 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin jẹ́ méjìdínláàádóje. Olórí òṣìṣẹ́ ẹ wọn ni Sabdieli ọmọ Hagedolimu.
et leurs frères, vaillants hommes, cent vingt-huit; et leur chef était Zabdiel, fils de Haggedolim.
15 Láti inú àwọn ọmọ Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ọmọ Bunni;
Parmi les Lévites: Schemaeja, fils de Hasshub, fils d'Azrikam, fils de Haschabia, fils de Bunni;
16 Ṣabbetai àti Josabadi, olórí méjì nínú àwọn ọmọ Lefi, àwọn tí ó jẹ́ alábojútó iṣẹ́ tí ó wà ní ẹ̀yìn àgbàlá ilé Ọlọ́run;
Shabbethaï et Jozabad, des chefs des Lévites, qui avaient la surveillance des affaires extérieures de la maison de Dieu;
17 Mattaniah ọmọ Mika, ọmọ Sabdi, ọmọ Asafu, adarí tí ó ń ṣáájú ìdúpẹ́ àti àdúrà; Bakbukiah ẹnìkejì láàrín àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀; àti Abida ọmọ Ṣammua, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni.
et Mattania, fils de Mica, fils de Zabdi, fils d'Asaph, qui était le chef pour commencer les actions de grâces en prière, et Bakbukiah, le second parmi ses frères; et Abda, fils de Shammua, fils de Galal, fils de Jeduthun.
18 Àwọn ọmọ Lefi nínú ìlú mímọ́ jẹ́ ọ̀rìnlélúgba ó lé mẹ́rin.
Tous les Lévites de la ville sainte étaient au nombre de deux cent quatre-vingt-quatre.
19 Àwọn aṣọ́nà: Akkubu, Talmoni, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, tí wọ́n máa ń ṣọ́nà jẹ́ méjìléláàádọ́sàn-án ọkùnrin.
Les gardiens des portes, Akkub, Talmon et leurs frères, qui surveillaient les portes, étaient au nombre de cent soixante-douze.
20 Àwọn tókù nínú àwọn ọmọ Israẹli, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, wà ní gbogbo ìlú u Juda, olúkúlùkù lórí ilẹ̀ ìní tirẹ̀.
Le reste d'Israël, les prêtres et les lévites étaient dans toutes les villes de Juda, chacun dans son héritage.
21 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili ń gbé lórí òkè Ofeli, Siha àti Giṣpa sì ni alábojútó wọn.
Mais les serviteurs du temple habitaient à Ophel, et Ziha et Gishpa étaient à la tête des serviteurs du temple.
22 Olórí òṣìṣẹ́ àwọn ọmọ Lefi ní Jerusalẹmu ní Ussi ọmọ Bani, ọmọ Haṣabiah, ọmọ Mattaniah ọmọ Mika. Ussi jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ìran Asafu tí wọ́n jẹ́ akọrin ojúṣe nínú ìjọ́sìn ní ilé Ọlọ́run.
Le surveillant des Lévites à Jérusalem était Uzzi, fils de Bani, fils de Haschabia, fils de Matthania, fils de Mica, d'entre les fils d'Asaph, les chantres, qui étaient chargés des affaires de la maison de Dieu.
23 Àwọn akọrin wà ní abẹ́ àṣẹ ọba, èyí tí ó n díwọ̀n iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn.
Car il y avait un ordre du roi à leur sujet, et une provision fixe pour les chantres, selon les besoins de chaque jour.
24 Petahiah ọmọ Meṣesabeli, ọ̀kan nínú àwọn Sera ọmọ Juda ní aṣojú ọba nínú ohun gbogbo tí ó jẹ mọ́ ti àwọn ènìyàn náà.
Pethahia, fils de Meshezabel, des fils de Zérach, fils de Juda, était auprès du roi pour tout ce qui concernait le peuple.
25 Fún ìletò pẹ̀lú oko wọn, díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn Juda tí ń gbé Kiriati-Arba, àti àwọn ìletò agbègbè e rẹ̀, ní Diboni àti ìletò rẹ̀, ní Jekabseeli.
Quant aux villages avec leurs champs, des fils de Juda habitèrent à Kiriath Arba et dans ses villes, à Dibon et dans ses villes, à Jekabzeel et dans ses villages,
26 Ní Jeṣua, ní Molada, ní Beti-Peleti
à Jeshua, à Molada, à Beth Pelet,
27 ní Hasari-Ṣuali, ní Beerṣeba àti àwọn agbègbè rẹ̀.
à Hazar Shual, à Beersheba et ses villes,
28 Ní Siklagi, ní Mekona àti àwọn ìletò rẹ̀,
à Ziklag, à la Mecque et ses villes,
29 ní Ẹni-Rimoni, ní Sora, ní Jarmatu,
à En Rimmon, à Zorah, à Jarmuth,
30 Sanoa, Adullamu àti àwọn ìletò o wọn, ní Lakiṣi àti àwọn oko rẹ̀, àti ní Aseka àti àwọn ìletò rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé láti Beerṣeba títí dé àfonífojì Hinnomu.
à Zanoa, à Adullam et leurs villages, à Lakis et ses champs, à Azéka et ses villes. Ils campèrent ainsi depuis Beer Schéba jusqu'à la vallée de Hinnom.
31 Àwọn ọmọ Benjamini láti Geba ń gbé ní Mikmasi, Aija, Beteli àti àwọn ìletò rẹ̀.
Les fils de Benjamin habitaient aussi depuis Guéba, à Micmasch et à Aija, à Béthel et aux villes de son ressort,
32 Ní Anatoti, Nobu àti Ananiah,
à Anathoth, à Nob, à Anania,
33 ní Hasori Rama àti Gittaimu,
à Hatsor, à Rama, à Gittaïm,
34 ní Hadidi, Seboimu àti Neballati,
à Hadid, à Zeboïm, à Neballat,
35 ní Lodi àti Ono, àti ní àfonífojì àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà.
à Lod, et à Ono, la vallée des artisans.
36 Nínú ìpín àwọn ọmọ Lefi ni Juda tẹ̀dó sí Benjamini.
Parmi les Lévites, certaines divisions de Juda s'établirent dans le territoire de Benjamin.

< Nehemiah 11 >