< Nehemiah 11 >

1 Nísinsin yìí àwọn olórí àwọn ènìyàn tẹ̀dó sí Jerusalẹmu, àwọn ènìyàn tókù sì dìbò láti mú ẹnìkọ̀ọ̀kan jáde nínú àwọn mẹ́wàá mẹ́wàá láti máa gbé ní Jerusalẹmu, ìlú mímọ́, nígbà tí àwọn mẹ́sàn-án tókù yóò dúró sí àwọn ìlú u wọn.
The [Israeli] leaders [and their families] settled in the sacred city, Jerusalem. The other people (cast lots/threw marked stones) to determine which family from each ten families would live in Jerusalem. The other people continued to live in the other towns and cities [in Judea].
2 Àwọn ènìyàn súre fún gbogbo àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ̀wọ́ ara wọn láti gbé ní Jerusalẹmu.
Those people [asked God to] bless those who volunteered to [be among the 10% who] moved to Jerusalem.
3 Wọ̀nyí ni àwọn olórí agbègbè ìjọba tí wọ́n tẹ̀dó sí Jerusalẹmu (díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ìran àwọn ìránṣẹ́ Solomoni ń gbé àwọn ìlú Juda, olúkúlùkù ń gbé lórí ilẹ̀ ìní rẹ̀ ní àwọn ìlú náà.
[Some of] the priests, [some of] the [other] descendants of Levi, [some of] the temple workers, and the descendants of King Solomon’s servants, and many of the other people lived on their own property in the towns [where their ancestors had lived].
4 Nígbà tí àwọn ènìyàn tókù nínú àwọn Juda àti Benjamini ń gbé ní Jerusalẹmu). Nínú àwọn ọmọ Juda: Ataiah ọmọ Ussiah ọmọ Sekariah, ọmọ Amariah, ọmọ Ṣefatia, ọmọ Mahalaleli, ìran Peresi;
But some people from the tribes of Judah and Benjamin [decided to] live in Jerusalem. One of them from the tribe of Judah was Athaiah. He was the son of Uzziah, who was the son of Zechariah, who was the son of Amariah, who was the son of Shephatiah, who was the son of Mahalalel, who was a descendant of [Judah’s son] Perez.
5 àti Maaseiah ọmọ Baruku, ọmọ Koli-Hose, ọmọ Hasaiah, ọmọ Adaiah, ọmọ Joiaribu, ọmọ Sekariah, ọmọ Ṣilo.
[Another one from the tribe of Judah was] Maaseiah, [who was] the son of Baruch, [who was] the son of Colhozeh, [who was] the son of Hazaiah, [who was] the son of Adaiah, [who was] the son of Joiarib, [who was] the son of Zechariah, [who was] a descendant of [Judah’s son] Shelah.
6 Àwọn ìran Peresi tó gbé ní Jerusalẹmu jẹ́ àádọ́rinlénírinwó ó dín méjì alágbára ọkùnrin.
There were 468 men who were descendants of Perez who were valiant/courageous soldiers who lived in Jerusalem.
7 Nínú àwọn ìran Benjamini: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Joẹdi, ọmọ Pedaiah, ọmọ Kolaiah, ọmọ Maaseiah, ọmọ Itieli, ọmọ Jeṣaiah,
[One of the men] of the tribe of Benjamin who decided to live in Jerusalem was Sallu, the son of Meshullam, the son of Joed, the son of Pedaiah, the son of Kolaiah, the son of Maaseiah, the son of Ithiel, the son of Jeshaiah.
8 àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Gabbai àti Sallai jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rún ó lé mẹ́jọ ọkùnrin.
Two of Sallu’s relatives, Gabbai and Sallai, also settled in Jerusalem. Altogether, 928 people from the tribe of Benjamin settled in Jerusalem
9 Joẹli ọmọ Sikri ni olórí òṣìṣẹ́ wọn, Juda ọmọ Hasenuah sì ni olórí agbègbè kejì ní ìlú náà.
Their leader was Joel, son of Zichri. The official who was second in command in Jerusalem was Hassenuah.
10 Nínú àwọn àlùfáà: Jedaiah; ọmọ Joiaribu; Jakini;
The priests [who settled in Jerusalem] were Jedaiah the son of Joiarib, Jakin,
11 Seraiah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, àwọn ni olórí tó ń bojútó ilé Ọlọ́run,
Seraiah, the son of Hilkiah, the son of Meshullam, the son of Zadok, the son of Meraioth, the son of Ahitub [who had previously been] the Supreme Priest.
12 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, ẹni tí ó ń ṣe iṣẹ́ ní tẹmpili jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó lé mẹ́rìnlélógún ọkùnrin: Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Pelaiah, ọmọ Amisi, ọmọ Sekariah, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah,
Altogether, 822 members of that clan worked in the temple. Another [priest who settled in Jerusalem] was Adaiah, the son of Jeroham, the son of Pelaliah, the son of Amzi, the son of Zechariah, the son of Pashhur, the son of Malchijah.
13 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ olórí ìdílé jẹ́ òjìlúgba ó lé méjì ọkùnrin: Amaṣai ọmọ Asareeli, ọmọ Ahsai, ọmọ Meṣilemoti, ọmọ Immeri,
Altogether, there were 242 members of that clan who were leaders of the clan [who settled in Jerusalem]. Another [priest who settled in Jerusalem] was Amashsai the son of Azarel, the son of Ahzai, the son of Meshillemoth, the son of Immer.
14 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin jẹ́ méjìdínláàádóje. Olórí òṣìṣẹ́ ẹ wọn ni Sabdieli ọmọ Hagedolimu.
There were 128 members of that clan who were valiant soldiers [who settled in Jerusalem]. Their leader was Zabdiel the son of Haggedolim.
15 Láti inú àwọn ọmọ Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ọmọ Bunni;
Another descendant of Levi who settled in Jerusalem was Shemaiah the son of Hasshub, the son of Azrikam, the son of Hashabiah, the son of Bunni.
16 Ṣabbetai àti Josabadi, olórí méjì nínú àwọn ọmọ Lefi, àwọn tí ó jẹ́ alábojútó iṣẹ́ tí ó wà ní ẹ̀yìn àgbàlá ilé Ọlọ́run;
Two others were Shabbethai and Jozabad, who were prominent men who supervised the work outside the temple.
17 Mattaniah ọmọ Mika, ọmọ Sabdi, ọmọ Asafu, adarí tí ó ń ṣáájú ìdúpẹ́ àti àdúrà; Bakbukiah ẹnìkejì láàrín àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀; àti Abida ọmọ Ṣammua, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni.
Another one was Mattaniah, the son of Mica, the son of Zabdi, the son of Asaph. Mattaniah directed the temple choir when they sang the prayers to thank [God]. His assistant was Bakbukiah. Another one was Abda, the son of Shammua, the son of Galal, the son of Jeduthun.
18 Àwọn ọmọ Lefi nínú ìlú mímọ́ jẹ́ ọ̀rìnlélúgba ó lé mẹ́rin.
Altogether, there were 284 descendants of Levi who settled in Jerusalem.
19 Àwọn aṣọ́nà: Akkubu, Talmoni, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, tí wọ́n máa ń ṣọ́nà jẹ́ méjìléláàádọ́sàn-án ọkùnrin.
The men who guarded the temple gates were Akkub and Talmon and 172 of their relatives who settled in Jerusalem.
20 Àwọn tókù nínú àwọn ọmọ Israẹli, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, wà ní gbogbo ìlú u Juda, olúkúlùkù lórí ilẹ̀ ìní tirẹ̀.
The other Israeli people including priests and [other] descendants of Levi lived on their own property in other towns and cities in Judea.
21 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili ń gbé lórí òkè Ofeli, Siha àti Giṣpa sì ni alábojútó wọn.
But the temple workers lived on Ophel [Hill in Jerusalem]. They were supervised by Ziha and Gishpa.
22 Olórí òṣìṣẹ́ àwọn ọmọ Lefi ní Jerusalẹmu ní Ussi ọmọ Bani, ọmọ Haṣabiah, ọmọ Mattaniah ọmọ Mika. Ussi jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ìran Asafu tí wọ́n jẹ́ akọrin ojúṣe nínú ìjọ́sìn ní ilé Ọlọ́run.
The man who supervised the [other] descendants of Levi who [helped the priests and] lived in Jerusalem was Uzzi, the son of Bani, the son of Hashabiah, the son of Mattaniah, the son of Mica. Uzzi belonged to the clan of Asaph, the clan that was in charge of the music in the temple.
23 Àwọn akọrin wà ní abẹ́ àṣẹ ọba, èyí tí ó n díwọ̀n iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn.
The king [of Persia] had commanded that the clans should decide what each clan should do to lead the music in the temple each day.
24 Petahiah ọmọ Meṣesabeli, ọ̀kan nínú àwọn Sera ọmọ Juda ní aṣojú ọba nínú ohun gbogbo tí ó jẹ mọ́ ti àwọn ènìyàn náà.
Pethahiah, the son of Meshezabel, [who was] from the clan of Zerah and a descendant of Judah, was the ambassador [of the Israelis] to the king of Persia.
25 Fún ìletò pẹ̀lú oko wọn, díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn Juda tí ń gbé Kiriati-Arba, àti àwọn ìletò agbègbè e rẹ̀, ní Diboni àti ìletò rẹ̀, ní Jekabseeli.
Some of the people [who did not settle in Jerusalem] lived in villages close to their farms. Some from the tribe of Judah lived in villages near Kiriath-Arba, Dibon, and Jekabzeel [cities].
26 Ní Jeṣua, ní Molada, ní Beti-Peleti
Some lived in Jeshua [city], in Moladah [city], in Beth-Pelet [city],
27 ní Hasari-Ṣuali, ní Beerṣeba àti àwọn agbègbè rẹ̀.
in Hazar-Shual [city], and in Beersheba [city] and the villages near it.
28 Ní Siklagi, ní Mekona àti àwọn ìletò rẹ̀,
Others lived in Ziklag [city], in Meconah [city] and the villages near it,
29 ní Ẹni-Rimoni, ní Sora, ní Jarmatu,
in En-Rimmon [city], in Zorah [city], in Jarmuth [city],
30 Sanoa, Adullamu àti àwọn ìletò o wọn, ní Lakiṣi àti àwọn oko rẹ̀, àti ní Aseka àti àwọn ìletò rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé láti Beerṣeba títí dé àfonífojì Hinnomu.
in Zanoah [city], in Adullam [city], and in the villages near those cities. Some lived in Lachish [city] and in the nearby villages, and some lived in Azekah [town] and the villages near it. All of those people lived in Judea, in the area between Beersheba [in the south] and Hinnom Valley [in the north, at the edge of Jerusalem].
31 Àwọn ọmọ Benjamini láti Geba ń gbé ní Mikmasi, Aija, Beteli àti àwọn ìletò rẹ̀.
The people of the tribe of Benjamin lived in Geba [city], Micmash [city], Aija [city which is also known as Ai], Bethel [city] and in nearby villages,
32 Ní Anatoti, Nobu àti Ananiah,
in Anathoth [city], in Nob [city], in Ananiah [town],
33 ní Hasori Rama àti Gittaimu,
in Hazor [city], in Ramah [city], in Gittaim [city],
34 ní Hadidi, Seboimu àti Neballati,
in Hadid [city], in Zeboim [town], in Neballat [town],
35 ní Lodi àti Ono, àti ní àfonífojì àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà.
in Lod [town], in Ono [town], and in Craftsmen’s Valley.
36 Nínú ìpín àwọn ọmọ Lefi ni Juda tẹ̀dó sí Benjamini.
Some of the groups of the descendants of Levi who had lived in Judea were sent to live with [the people of the tribe of] Benjamin.

< Nehemiah 11 >