< Nehemiah 11 >

1 Nísinsin yìí àwọn olórí àwọn ènìyàn tẹ̀dó sí Jerusalẹmu, àwọn ènìyàn tókù sì dìbò láti mú ẹnìkọ̀ọ̀kan jáde nínú àwọn mẹ́wàá mẹ́wàá láti máa gbé ní Jerusalẹmu, ìlú mímọ́, nígbà tí àwọn mẹ́sàn-án tókù yóò dúró sí àwọn ìlú u wọn.
And the rulers of the people dwelt in Jerusalem, —and, the rest of the people, cast lots, to bring in one out of ten to dwell in Jerusalem, the holy city, and nine parts in [other] cities.
2 Àwọn ènìyàn súre fún gbogbo àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ̀wọ́ ara wọn láti gbé ní Jerusalẹmu.
And the people bestowed a blessing on all the men, who willingly offered themselves to dwell in Jerusalem.
3 Wọ̀nyí ni àwọn olórí agbègbè ìjọba tí wọ́n tẹ̀dó sí Jerusalẹmu (díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ìran àwọn ìránṣẹ́ Solomoni ń gbé àwọn ìlú Juda, olúkúlùkù ń gbé lórí ilẹ̀ ìní rẹ̀ ní àwọn ìlú náà.
Now, these, are the chiefs of the province, who dwelt in Jerusalem, but, in the cities of Judah, dwelt every man in his possession throughout their cities, Israel, the priests, and the Levites and the Nethinim, and the Sons of the Servants of Solomon.
4 Nígbà tí àwọn ènìyàn tókù nínú àwọn Juda àti Benjamini ń gbé ní Jerusalẹmu). Nínú àwọn ọmọ Juda: Ataiah ọmọ Ussiah ọmọ Sekariah, ọmọ Amariah, ọmọ Ṣefatia, ọmọ Mahalaleli, ìran Peresi;
And, in Jerusalem, dwelt certain of the sons of Judah and of the sons of Benjamin, —Of the sons of Judah, Athaiah son of Uzziah, son of Zechariah, son of Amariah, son of Shephatiah, son of Mahalalel, of the sons of Perez;
5 àti Maaseiah ọmọ Baruku, ọmọ Koli-Hose, ọmọ Hasaiah, ọmọ Adaiah, ọmọ Joiaribu, ọmọ Sekariah, ọmọ Ṣilo.
and Maaseiah son of Baruch, son of Col-hozeh, son of Hazaiah, son of Adaiah, son of Joiarib, son of Zechariah, son of the Shilonite.
6 Àwọn ìran Peresi tó gbé ní Jerusalẹmu jẹ́ àádọ́rinlénírinwó ó dín méjì alágbára ọkùnrin.
All the sons of Perez who were dwelling in Jerusalem, four hundred and sixty-eight, men of ability.
7 Nínú àwọn ìran Benjamini: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Joẹdi, ọmọ Pedaiah, ọmọ Kolaiah, ọmọ Maaseiah, ọmọ Itieli, ọmọ Jeṣaiah,
And, these, are the sons of Benjamin, —Sallu son of Meshullam, son of Joed, son of Pedaiah, son of Kolaiah, son of Maaseiah, son of Ithiel, son of Jeshaiah;
8 àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Gabbai àti Sallai jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rún ó lé mẹ́jọ ọkùnrin.
and, after him, Gabbai, Sallai, —nine hundred and twenty-eight.
9 Joẹli ọmọ Sikri ni olórí òṣìṣẹ́ wọn, Juda ọmọ Hasenuah sì ni olórí agbègbè kejì ní ìlú náà.
And, Joel son of Zichri, was in charge over them, —and, Judah son of Hassenuah, was over the city, as second.
10 Nínú àwọn àlùfáà: Jedaiah; ọmọ Joiaribu; Jakini;
Of the priests, Jedaiah son of Joiarib, Jachin;
11 Seraiah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, àwọn ni olórí tó ń bojútó ilé Ọlọ́run,
Seraiah son of Hilkiah, son of Meshullam, son of Zadok, son of Meraioth, son of Ahitub, chief ruler of the house of God;
12 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, ẹni tí ó ń ṣe iṣẹ́ ní tẹmpili jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó lé mẹ́rìnlélógún ọkùnrin: Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Pelaiah, ọmọ Amisi, ọmọ Sekariah, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah,
and their brethren who were doing the work of the house, eight hundred and twenty-two, —and Adaiah son of Jeroham, son of Pelaliah, son of Amzi, son of Zechariah, son of Pashhur, son of Malchijah;
13 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ olórí ìdílé jẹ́ òjìlúgba ó lé méjì ọkùnrin: Amaṣai ọmọ Asareeli, ọmọ Ahsai, ọmọ Meṣilemoti, ọmọ Immeri,
and his brethren, ancestral chiefs, two hundred and forty-two, —and Amashsai son of Azarel, son of Ahzai, son of Meshillemoth, son of Immer;
14 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin jẹ́ méjìdínláàádóje. Olórí òṣìṣẹ́ ẹ wọn ni Sabdieli ọmọ Hagedolimu.
and their brethren, strong men of ability, a hundred and twenty-eight, —and, he who was in charge of them, was Zabdiel, son of Haggedolim.
15 Láti inú àwọn ọmọ Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ọmọ Bunni;
And, of the Levites, Shemaiah son of Hasshub, son of Azrikam, son of Hashabiah, son of Bunni;
16 Ṣabbetai àti Josabadi, olórí méjì nínú àwọn ọmọ Lefi, àwọn tí ó jẹ́ alábojútó iṣẹ́ tí ó wà ní ẹ̀yìn àgbàlá ilé Ọlọ́run;
and Shabbethai and Jozabad, over the outside business of the house of God, of the chiefs of the Levites;
17 Mattaniah ọmọ Mika, ọmọ Sabdi, ọmọ Asafu, adarí tí ó ń ṣáájú ìdúpẹ́ àti àdúrà; Bakbukiah ẹnìkejì láàrín àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀; àti Abida ọmọ Ṣammua, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni.
and Mattaniah son of Mica, son of Zabdi, son of Asaph, leader of the praise who giveth thanks, in prayer, and Bakbukiah the second among his brethren, —and Obadiah son of Shemaiah, son of Galal, son of Jeduthun.
18 Àwọn ọmọ Lefi nínú ìlú mímọ́ jẹ́ ọ̀rìnlélúgba ó lé mẹ́rin.
All the Levites in the holy city, were two hundred and eighty-four.
19 Àwọn aṣọ́nà: Akkubu, Talmoni, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, tí wọ́n máa ń ṣọ́nà jẹ́ méjìléláàádọ́sàn-án ọkùnrin.
And, the door-keepers—Akkub, Talmon, and their brethren who were keeping watch in the gates, were a hundred and seventy-two.
20 Àwọn tókù nínú àwọn ọmọ Israẹli, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, wà ní gbogbo ìlú u Juda, olúkúlùkù lórí ilẹ̀ ìní tirẹ̀.
But, the residue of Israel, the priests, the Levites, were in all the cities of Judah, every one in his inheritance.
21 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili ń gbé lórí òkè Ofeli, Siha àti Giṣpa sì ni alábojútó wọn.
Howbeit, the Nethinim, were dwelling in Ophel, —and, Ziha and Gishpa, were over the Nethinim.
22 Olórí òṣìṣẹ́ àwọn ọmọ Lefi ní Jerusalẹmu ní Ussi ọmọ Bani, ọmọ Haṣabiah, ọmọ Mattaniah ọmọ Mika. Ussi jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ìran Asafu tí wọ́n jẹ́ akọrin ojúṣe nínú ìjọ́sìn ní ilé Ọlọ́run.
And, the overseer of the Levites in Jerusalem, was Uzzi son of Bani, son of Hashabiah, son of Mattaniah, son of Mica, —of the sons of Asaph the singers, to take lead in the business of the house of God.
23 Àwọn akọrin wà ní abẹ́ àṣẹ ọba, èyí tí ó n díwọ̀n iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn.
For, the commandment of the king, was upon them, —as to a fixed provision for the singers, the need of a day upon its day.
24 Petahiah ọmọ Meṣesabeli, ọ̀kan nínú àwọn Sera ọmọ Juda ní aṣojú ọba nínú ohun gbogbo tí ó jẹ mọ́ ti àwọn ènìyàn náà.
And, Pethahiah son of Meshezabel, of the sons of Zerah, son of Judah, was at the hand of the king, in every matter pertaining to the people.
25 Fún ìletò pẹ̀lú oko wọn, díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn Juda tí ń gbé Kiriati-Arba, àti àwọn ìletò agbègbè e rẹ̀, ní Diboni àti ìletò rẹ̀, ní Jekabseeli.
And, as for the villages in their fields, some of the sons of Judah, dwelt in Kiriath-arba, and the hamlets thereof, and in Dibon, and the hamlets thereof, and in Jekabzeel, and the villages thereof;
26 Ní Jeṣua, ní Molada, ní Beti-Peleti
and in Jeshua, and in Moladah, and in Beth-pelet;
27 ní Hasari-Ṣuali, ní Beerṣeba àti àwọn agbègbè rẹ̀.
and in Hazar-shual, and in Beer-sheba, and the hamlets thereof;
28 Ní Siklagi, ní Mekona àti àwọn ìletò rẹ̀,
and in Ziklag, and in Meconah, and in the hamlets thereof,
29 ní Ẹni-Rimoni, ní Sora, ní Jarmatu,
and in En-rimmmon, and in Zorah, and in Jarmuth;
30 Sanoa, Adullamu àti àwọn ìletò o wọn, ní Lakiṣi àti àwọn oko rẹ̀, àti ní Aseka àti àwọn ìletò rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé láti Beerṣeba títí dé àfonífojì Hinnomu.
Zanoah, Adullam and their villages, Lachish, and the fields thereof, Azekah, and the hamlets thereof, —so they encamped from Beer-sheba, unto the valley of Hinnom.
31 Àwọn ọmọ Benjamini láti Geba ń gbé ní Mikmasi, Aija, Beteli àti àwọn ìletò rẹ̀.
And, the sons of Benjamin, [dwelt] from Geba, to Michmas and Aija, and Bethel, and the hamlets thereof:
32 Ní Anatoti, Nobu àti Ananiah,
Anathoth, Nob, Ananiah;
33 ní Hasori Rama àti Gittaimu,
Hazor, Ramah, Gittaim;
34 ní Hadidi, Seboimu àti Neballati,
Hadid, Zeboim, Neballat;
35 ní Lodi àti Ono, àti ní àfonífojì àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà.
Lod and Ono, the valley of craftsmen.
36 Nínú ìpín àwọn ọmọ Lefi ni Juda tẹ̀dó sí Benjamini.
Howbeit, of the Levites, certain courses of Judah, pertained unto Benjamin.

< Nehemiah 11 >