< Nehemiah 11 >

1 Nísinsin yìí àwọn olórí àwọn ènìyàn tẹ̀dó sí Jerusalẹmu, àwọn ènìyàn tókù sì dìbò láti mú ẹnìkọ̀ọ̀kan jáde nínú àwọn mẹ́wàá mẹ́wàá láti máa gbé ní Jerusalẹmu, ìlú mímọ́, nígbà tí àwọn mẹ́sàn-án tókù yóò dúró sí àwọn ìlú u wọn.
And the rulers of the people dwelt at Jerusalem: and the rest of the people cast lots, to bring one of every ten to dwell in Jerusalem the holy city, and the nine parts to [remain] in the [other] cities.
2 Àwọn ènìyàn súre fún gbogbo àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ̀wọ́ ara wọn láti gbé ní Jerusalẹmu.
And the people blessed all the men, that offered themselves voluntarily to dwell at Jerusalem.
3 Wọ̀nyí ni àwọn olórí agbègbè ìjọba tí wọ́n tẹ̀dó sí Jerusalẹmu (díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ìran àwọn ìránṣẹ́ Solomoni ń gbé àwọn ìlú Juda, olúkúlùkù ń gbé lórí ilẹ̀ ìní rẹ̀ ní àwọn ìlú náà.
Now these are the chiefs of the province that dwelt in Jerusalem; but in the cities of Judah dwelt every one in his possession in their cities, [to wit, ] Israel, the priests, and the Levites, and the temple-servants, and the children of Solomon's servants.
4 Nígbà tí àwọn ènìyàn tókù nínú àwọn Juda àti Benjamini ń gbé ní Jerusalẹmu). Nínú àwọn ọmọ Juda: Ataiah ọmọ Ussiah ọmọ Sekariah, ọmọ Amariah, ọmọ Ṣefatia, ọmọ Mahalaleli, ìran Peresi;
And at Jerusalem dwelt certain of the children of Judah, and of the children of Benjamin. Of the children of Judah: 'Athayah the son of 'Uzziyah, the son of Zechariah, the son of Amaryah, the son of Shephatyah, the son of Mahalalel, of the children of Perez:
5 àti Maaseiah ọmọ Baruku, ọmọ Koli-Hose, ọmọ Hasaiah, ọmọ Adaiah, ọmọ Joiaribu, ọmọ Sekariah, ọmọ Ṣilo.
And Ma'asseyah the son of Baruch, the son of Kol-chozeh, the son of Chazayah, the son of 'Adayah, the son of Joyarib, the son of Zechariah, the son of Hashiloni;
6 Àwọn ìran Peresi tó gbé ní Jerusalẹmu jẹ́ àádọ́rinlénírinwó ó dín méjì alágbára ọkùnrin.
All the sons of Perez that dwelt at Jerusalem were four hundred sixty and eight valiant men.
7 Nínú àwọn ìran Benjamini: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Joẹdi, ọmọ Pedaiah, ọmọ Kolaiah, ọmọ Maaseiah, ọmọ Itieli, ọmọ Jeṣaiah,
And these are the sons of Benjamin: Sallu the son of Meshullam, the son of Jo'ed, the son of Pedayah, the son of Kolayah, the son of Ma'asseyah, the son of Ithiel, the son of Jessha'yah;
8 àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Gabbai àti Sallai jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rún ó lé mẹ́jọ ọkùnrin.
And next to him Gabbai, Sallai; nine hundred twenty and eight.
9 Joẹli ọmọ Sikri ni olórí òṣìṣẹ́ wọn, Juda ọmọ Hasenuah sì ni olórí agbègbè kejì ní ìlú náà.
And Joel the son of Zichri was overseer over them; and Judah the son of Hassenuah was second over the city.
10 Nínú àwọn àlùfáà: Jedaiah; ọmọ Joiaribu; Jakini;
Of the priests: Jedayah the son of Joyarib, Jachin:
11 Seraiah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, àwọn ni olórí tó ń bojútó ilé Ọlọ́run,
Serayah the son of Chilkiyah, the son of Meshullam, the son of Zadok, the son of Merayoth, the son of Achitub, the superintendent of the house of God;
12 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, ẹni tí ó ń ṣe iṣẹ́ ní tẹmpili jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó lé mẹ́rìnlélógún ọkùnrin: Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Pelaiah, ọmọ Amisi, ọmọ Sekariah, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah,
And their brethren who did the work of the house, eight hundred twenty and two; and 'Adayah the son of Jerocham, the son of Pelalyah, the son of Amzi, the son of Zechariah, the son of Pashchur, the son of Malkiyah;
13 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ olórí ìdílé jẹ́ òjìlúgba ó lé méjì ọkùnrin: Amaṣai ọmọ Asareeli, ọmọ Ahsai, ọmọ Meṣilemoti, ọmọ Immeri,
And his brethren, chiefs of the divisions, two hundred forty and two; and 'Amashsai the son of 'Azarel, the son of Achsai, the son of Meshillemoth, the son of Immer;
14 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin jẹ́ méjìdínláàádóje. Olórí òṣìṣẹ́ ẹ wọn ni Sabdieli ọmọ Hagedolimu.
And their brethren, mighty men of valor, one hundred twenty and eight; and the overseer over them was Zabdiel, the son of Haggedolim.
15 Láti inú àwọn ọmọ Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ọmọ Bunni;
Also of the Levites: Shema'yah the son of Chasshub, the son of 'Azrikam, the son of Chashabyah, the son of Bunni;
16 Ṣabbetai àti Josabadi, olórí méjì nínú àwọn ọmọ Lefi, àwọn tí ó jẹ́ alábojútó iṣẹ́ tí ó wà ní ẹ̀yìn àgbàlá ilé Ọlọ́run;
And Shabbethai and Jozabad, of the chiefs of the Levites, had the oversight of the outward business of the house of God;
17 Mattaniah ọmọ Mika, ọmọ Sabdi, ọmọ Asafu, adarí tí ó ń ṣáájú ìdúpẹ́ àti àdúrà; Bakbukiah ẹnìkejì láàrín àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀; àti Abida ọmọ Ṣammua, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni.
And Matthaniah the son of Micha, the son of Zabdi, the son of Assaph, the principal to begin the thanksgiving at prayer; and Bakbukyah the second among his brethren and 'Abda the son of Shammua', the son of Galal, the son of Jeduthun.
18 Àwọn ọmọ Lefi nínú ìlú mímọ́ jẹ́ ọ̀rìnlélúgba ó lé mẹ́rin.
All the Levites in the holy city were two hundred eighty and four.
19 Àwọn aṣọ́nà: Akkubu, Talmoni, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, tí wọ́n máa ń ṣọ́nà jẹ́ méjìléláàádọ́sàn-án ọkùnrin.
And the gatekeepers, Akkub, Talmon and their brethren that watched at the gates, were one hundred seventy and two.
20 Àwọn tókù nínú àwọn ọmọ Israẹli, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, wà ní gbogbo ìlú u Juda, olúkúlùkù lórí ilẹ̀ ìní tirẹ̀.
And the residue of Israel, of the priests, and the Levites, were in all the cities of Judah, every one in his inheritance.
21 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili ń gbé lórí òkè Ofeli, Siha àti Giṣpa sì ni alábojútó wọn.
But the temple-servants dwelt in the hill-fort; and Zicha and Gishpa were over the temple-servants.
22 Olórí òṣìṣẹ́ àwọn ọmọ Lefi ní Jerusalẹmu ní Ussi ọmọ Bani, ọmọ Haṣabiah, ọmọ Mattaniah ọmọ Mika. Ussi jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ìran Asafu tí wọ́n jẹ́ akọrin ojúṣe nínú ìjọ́sìn ní ilé Ọlọ́run.
And the overseer of the Levites at Jerusalem was 'Uzzi the son of Bani, the son of Chashabyah, the son of Matthanyah, the son of Micha, one of the sons of Assaph, the singers, over the business of the house of God.
23 Àwọn akọrin wà ní abẹ́ àṣẹ ọba, èyí tí ó n díwọ̀n iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn.
For the king's command was obligatory on them; and there was a fixed rate for the singers, the requirement of every day on its day.
24 Petahiah ọmọ Meṣesabeli, ọ̀kan nínú àwọn Sera ọmọ Juda ní aṣojú ọba nínú ohun gbogbo tí ó jẹ mọ́ ti àwọn ènìyàn náà.
And Pethachyah the son of Meshezabel, of the children of Zerach the son of Judah, was at the king's hand in every thing concerning the people.
25 Fún ìletò pẹ̀lú oko wọn, díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn Juda tí ń gbé Kiriati-Arba, àti àwọn ìletò agbègbè e rẹ̀, ní Diboni àti ìletò rẹ̀, ní Jekabseeli.
And respecting the villages with their fields, some of the children of Judah dwelt at Kiryath-arba' and in its villages, and at Dibon and in its villages, and at Jekabzeel and in its villages.
26 Ní Jeṣua, ní Molada, ní Beti-Peleti
And at Jeshua', and at Moladah, and at Beth-phelet,
27 ní Hasari-Ṣuali, ní Beerṣeba àti àwọn agbègbè rẹ̀.
And at Chazar-shu'al, and at Beer-sheba' and in its villages,
28 Ní Siklagi, ní Mekona àti àwọn ìletò rẹ̀,
And at Ziklag, and at Mechonah and in its villages,
29 ní Ẹni-Rimoni, ní Sora, ní Jarmatu,
And at 'En-rimmon, and at Zor'ah, and at Yarmuth,
30 Sanoa, Adullamu àti àwọn ìletò o wọn, ní Lakiṣi àti àwọn oko rẹ̀, àti ní Aseka àti àwọn ìletò rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé láti Beerṣeba títí dé àfonífojì Hinnomu.
Zanoach, 'Adullam, and in their villages, at Lachish and its fields, at 'Azekah and in its villages. And they dwelt from Beer-sheba' as far as the valley of Hinnom.
31 Àwọn ọmọ Benjamini láti Geba ń gbé ní Mikmasi, Aija, Beteli àti àwọn ìletò rẹ̀.
And the children of Benjamin [dwelt], beginning from Geba', at Michmash, and 'Ay-ya, and Beth-el, and in their villages,
32 Ní Anatoti, Nobu àti Ananiah,
'Anathoth, Nob, 'Ananyah,
33 ní Hasori Rama àti Gittaimu,
Chazor, Ramah, Gittayim.
34 ní Hadidi, Seboimu àti Neballati,
Chadid, Zebo'im, Neballat,
35 ní Lodi àti Ono, àti ní àfonífojì àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà.
Lod, and Ono, the valley of the carpenters.
36 Nínú ìpín àwọn ọmọ Lefi ni Juda tẹ̀dó sí Benjamini.
And of the Levites dwelt certain divisions in Judah, and in Benjamin.

< Nehemiah 11 >