< Nehemiah 10 >
1 Àwọn tí ó fi èdìdì dì í ni: Nehemiah baálẹ̀, ọmọ Hakaliah. Sedekiah
Acum, cei care l-au sigilat au fost: Neemia Tirșata, fiul lui Hacalia, și Zedechia,
2 Seraiah, Asariah, Jeremiah,
Seraia, Azaria, Ieremia,
3 Paṣuri, Amariah, Malkiah,
Pașhur, Amaria, Malchiia,
4 Hattusi, Ṣebaniah, Malluki,
Hatuș, Șebania, Maluc,
5 Harimu, Meremoti, Obadiah,
Harim, Meremot, Obadia,
6 Daniẹli, Ginetoni, Baruku,
Daniel, Ghineton, Baruc,
7 Meṣullamu, Abijah, Mijamini,
Meșulam, Abiia, Miiamin,
8 Maasiah, Bilgai àti Ṣemaiah. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà.
Maazia, Bilgai, Șemaia: aceștia au fost preoții.
9 Àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua ọmọ Asaniah, Binnui ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Henadadi, Kadmieli,
Și leviții: deopotrivă Ieșua, fiul lui Azania, Binui dintre copiii lui Henadad, Cadmiel;
10 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn: Ṣebaniah, Hodiah, Kelita, Pelaiah, Hanani,
Și frații lor: Șebania, Hodiia, Chelita, Pelaia, Hanan,
11 Mika, Rehobu, Haṣabiah,
Mica, Rehob, Hașabia,
12 Sakkuri, Ṣerebiah, Ṣebaniah,
Zacur, Șerebia, Șebania,
13 Hodiah, Bani àti Beninu.
Hodiia, Bani, Beninu.
14 Àwọn olórí àwọn ènìyàn: Paroṣi, Pahati-Moabu, Elamu, Sattu, Bani,
Mai marii poporului: Pareoș, Pahat-Moab, Elam, Zatu, Bani,
16 Adonijah, Bigfai, Adini,
Adoniia, Bigvai, Adin,
17 Ateri, Hesekiah, Assuri,
Ater, Ezchiia, Azur,
18 Hodiah, Haṣumu, Besai,
Hodiia, Hașum, Bețai,
19 Harifu, Anatoti, Nebai,
Harif, Anatot, Nebai,
20 Magpiaṣi, Meṣullamu, Hesiri
Magpiaș, Meșulam, Hezir,
21 Meṣesabeli, Sadoku, Jaddua
Meșezabeel, Țadoc, Iadua,
22 Pelatiah, Hanani, Anaiah,
Pelatia, Hanan, Anaia,
23 Hosea, Hananiah, Haṣubu,
Hoșea, Hanania, Hașub,
24 Halloheṣi, Pileha, Ṣobeki,
Haloheș, Pilha, Șobec,
25 Rehumu, Haṣabna, Maaseiah,
Rehum, Hașabna, Maaseia,
26 Ahijah, Hanani, Anani,
Și Ahiia, Hanan, Anan,
27 Malluki, Harimu, àti Baanah.
Maluc, Harim, Baana.
28 “Àwọn ènìyàn tókù—àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn aṣọ́nà, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn àjèjì nítorí òfin Ọlọ́run, papọ̀ pẹ̀lú ìyàwó wọn, gbogbo ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, tí òye yé
Și restul poporului, preoții, leviții, portarii, cântăreții, netinimii și toți cei care se separaseră de popoarele țărilor pentru legea lui Dumnezeu, soțiile lor, fiii lor și fiicele lor, oricine avea cunoștință și avea înțelegere;
29 gbogbo wọn fi ara mọ́ àwọn arákùnrin wọn, àwọn ọlọ́lá, wọ́n sì fi ègún àti ìbúra dé ara wọn láti máa tẹ̀lé òfin Ọlọ́run tí a fi fún wọn ní ipasẹ̀ Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run àti láti pa gbogbo àṣẹ, ìlànà àti òfin Olúwa, wa mọ́ dáradára.
S-au alipit de frații lor, nobilii lor și au intrat într-un blestem și într-un jurământ, pentru a umbla în legea lui Dumnezeu, care a fost dată prin Moise servitorul lui Dumnezeu și pentru a ține și a împlini toate poruncile DOMNULUI Domnul nostru și judecățile lui și statutele lui;
30 “A ti ṣe ìlérí pé, a kò ní fi àwọn ọmọbìnrin wa fún àwọn tí wọ́n wà ní àyíká wa bí ìyàwó, tàbí fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin wa.
Și că noi nu vom da pe fiicele noastre popoarelor țării, nici nu vom lua pe fiicele lor pentru fiii noștri;
31 “Nígbà tí àwọn ènìyàn àdúgbò bá mú ọjà tàbí oúnjẹ wá ní ọjọ́ ìsinmi láti tà, àwa kò ní rà á ní ọwọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi tàbí ní ọjọ́ mímọ́ kankan. Ní gbogbo ọdún keje àwa kò ní ro ilẹ̀ náà, a ó sì pa gbogbo àwọn gbèsè rẹ́.
Și dacă popoarele țării vor aduce mărfuri sau orice fel de alimente în ziua sabatului pentru a vinde, că noi nu vom cumpăra de la ei în sabat, sau în ziua sfântă; și că vom lăsa al șaptelea an și luarea oricărei datorii.
32 “Àwa gbà ojúṣe láti máa pa àṣẹ mọ́ pé, a ó máa san ìdámẹ́ta ṣékélì ní ọdọọdún fún iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa:
De asemenea am făcut rânduieli pentru noi, pentru a da anual a treia parte dintr-un șekel pentru serviciul casei Dumnezeului nostru;
33 nítorí oúnjẹ tí ó wà lórí tábìlì; nítorí ọrẹ ohun jíjẹ àti ẹbọ sísun ìgbà gbogbo; nítorí ọrẹ ọjọ́ ìsinmi, ti àyajọ́ oṣù tuntun àti àjọ̀dún tí a yàn; nítorí ọrẹ mímọ́; nítorí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún Israẹli; àti fún gbogbo iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa.
Pentru pâinile punerii înainte și pentru darul de mâncare neîncetat și pentru ofranda arsă neîncetat a sabatelor, a lunilor noi, pentru sărbătorile rânduite și pentru lucrurile sfinte și pentru ofrandele pentru păcat pentru a face ispășire pentru Israel și pentru toată lucrarea casei Dumnezeului nostru.
34 “Àwa, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ènìyàn náà ti dìbò láti pinnu ìgbà tí olúkúlùkù àwọn ìdílé yóò mú ọrẹ igi wá láti sun lọ́ríi pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa sí ilé Ọlọ́run wa, ní àkókò tí a yàn ní ọdọọdún. Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin.
Și am aruncat sorții între preoți, leviți și popor, pentru darul lemnelor, de a-l aduce la casa Dumnezeului nostru, după casele părinților noștri, la timpuri rânduite an de an, ca să ardă pe altarul DOMNULUI Dumnezeului nostru, precum este scris în lege;
35 “Àwa tún gbà ojúṣe láti mú àkọ́so àwọn èso wa wá àti gbogbo èso igi wá ní ilé Olúwa.
Și să aducem cele dintâi roade ale pământului nostru și cele dintâi roade ale tuturor fructelor din toți pomii an de an la casa DOMNULUI;
36 “Gẹ́gẹ́ bí a sì ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin, àwa yóò mú àkọ́bí àwọn ọmọkùnrin wa, ti ohun ọ̀sìn wa, ti àwọn abo màlúù àti ti àwọn àgùntàn wa, wá sí ilé Ọlọ́run wa, fún àwọn àlùfáà tí ń ṣiṣẹ́ níbẹ̀.
De asemenea pe întâii născuți ai fiilor noștri și ai vitelor noastre, precum este scris în lege și pe întâii născuți ai cirezilor noastre și ai turmelor noastre, pentru a-i aduce la casa Dumnezeului nostru, la preoții care servesc în casa Dumnezeului nostru;
37 “Síwájú sí i, àwa yóò mú àkọ́so oúnjẹ ilẹ̀ wa ti ọrẹ oúnjẹ, ti gbogbo èso àwọn igi àti ti wáìnì tuntun wa àti ti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ilé Ọlọ́run wa àti fún àwọn àlùfáà. Àwa yóò sì mú ìdámẹ́wàá ohun ọ̀gbìn wá fún àwọn ọmọ Lefi, nítorí àwọn ọmọ Lefi ni ó ń gba ìdámẹ́wàá ní gbogbo àwọn ìlú tí a ti ń ṣiṣẹ́.
Și ca să aducem cele dintâi roade ale aluatului nostru și ofrandele noastre și rodul a tot felul de pomi, din vin și din untdelemn, la preoți, în camerele casei Dumnezeului nostru; și zeciuielile pământului nostru leviților, ca ei, leviții, să poată avea zeciuielile în toate cetățile aratului nostru.
38 Àlùfáà tí o ti ìdílé Aaroni wá ni yóò wá pẹ̀lú àwọn ọmọ Lefi nígbà tí wọ́n bá ń gba ìdámẹ́wàá, àwọn ọmọ Lefi yóò sì mú ìdámẹ́wàá ti ìdámẹ́wàá náà wá sí ilé Ọlọ́run, sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí inú ilé ìṣúra.
Și preotul, fiul lui Aaron, să fie cu leviții când leviții iau zeciuieli; și leviții să aducă zeciuiala zeciuielilor la casa Dumnezeului nostru, în camere, la casa tezaurului.
39 Àwọn ènìyàn Israẹli, àti àwọn ọmọ Lefi gbọdọ̀ mú ọrẹ oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí níbi tí a pa ohun èlò ibi mímọ́ mọ́ sí àti ibi tí àwọn àlùfáà tí ń ṣe ìránṣẹ́ lọ́wọ́, àwọn aṣọ́nà àti àwọn akọrin máa ń dúró sí. “Àwa kì yóò gbàgbé tàbí ṣe àìbìkítà nípa ilé Ọlọ́run wa.”
Căci copiii lui Israel și copiii lui Levi vor aduce darul din grâne, din vin nou și din untdelemn, în camere, unde sunt vasele sanctuarului și preoții care servesc și portarii și cântăreții; și nu vom părăsi casa Dumnezeului nostru.