< Nehemiah 10 >

1 Àwọn tí ó fi èdìdì dì í ni: Nehemiah baálẹ̀, ọmọ Hakaliah. Sedekiah
וְעַ֖ל הַחֲתוּמִ֑ים נְחֶמְיָ֧ה הַתִּרְשָׁ֛תָא בֶּן־חֲכַלְיָ֖ה וְצִדְקִיָּֽה׃
2 Seraiah, Asariah, Jeremiah,
שְׂרָיָ֥ה עֲזַרְיָ֖ה יִרְמְיָֽה׃
3 Paṣuri, Amariah, Malkiah,
פַּשְׁח֥וּר אֲמַרְיָ֖ה מַלְכִּיָּֽה׃
4 Hattusi, Ṣebaniah, Malluki,
חַטּ֥וּשׁ שְׁבַנְיָ֖ה מַלּֽוּךְ׃
5 Harimu, Meremoti, Obadiah,
חָרִ֥ם מְרֵמֹ֖ות עֹֽבַדְיָֽה׃
6 Daniẹli, Ginetoni, Baruku,
דָּנִיֵּ֥אל גִּנְּתֹ֖ון בָּרֽוּךְ׃
7 Meṣullamu, Abijah, Mijamini,
מְשֻׁלָּ֥ם אֲבִיָּ֖ה מִיָּמִֽן׃
8 Maasiah, Bilgai àti Ṣemaiah. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà.
מַֽעַזְיָ֥ה בִלְגַּ֖י שְׁמַֽעְיָ֑ה אֵ֖לֶּה הַכֹּהֲנִֽים׃ ס
9 Àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua ọmọ Asaniah, Binnui ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Henadadi, Kadmieli,
וְֽהַלְוִיִּ֑ם וְיֵשׁ֙וּעַ֙ בֶּן־אֲזַנְיָ֔ה בִּנּ֕וּי מִבְּנֵ֥י חֵנָדָ֖ד קַדְמִיאֵֽל׃
10 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn: Ṣebaniah, Hodiah, Kelita, Pelaiah, Hanani,
וַאֲחֵיהֶ֑ם שְׁבַנְיָ֧ה הֹֽודִיָּ֛ה קְלִיטָ֖א פְּלָאיָ֥ה חָנָֽן׃
11 Mika, Rehobu, Haṣabiah,
מִיכָ֥א רְחֹ֖וב חֲשַׁבְיָֽה׃
12 Sakkuri, Ṣerebiah, Ṣebaniah,
זַכּ֥וּר שֵׁרֵֽבְיָ֖ה שְׁבַנְיָֽה׃
13 Hodiah, Bani àti Beninu.
הֹודִיָּ֥ה בָנִ֖י בְּנִֽינוּ׃ ס
14 Àwọn olórí àwọn ènìyàn: Paroṣi, Pahati-Moabu, Elamu, Sattu, Bani,
רָאשֵׁ֖י הָעָ֑ם פַּרְעֹשׁ֙ פַּחַ֣ת מֹואָ֔ב עֵילָ֥ם זַתּ֖וּא בָּנִֽי׃
15 Bunni, Asgadi, Bebai.
בֻּנִּ֥י עַזְגָּ֖ד בֵּבָֽי׃
16 Adonijah, Bigfai, Adini,
אֲדֹנִיָּ֥ה בִגְוַ֖י עָדִֽין׃
17 Ateri, Hesekiah, Assuri,
אָטֵ֥ר חִזְקִיָּ֖ה עַזּֽוּר׃
18 Hodiah, Haṣumu, Besai,
הֹודִיָּ֥ה חָשֻׁ֖ם בֵּצָֽי׃
19 Harifu, Anatoti, Nebai,
חָרִ֥יף עֲנָתֹ֖ות נֹובָי (נֵיבָֽי)׃
20 Magpiaṣi, Meṣullamu, Hesiri
מַגְפִּיעָ֥שׁ מְשֻׁלָּ֖ם חֵזִֽיר׃
21 Meṣesabeli, Sadoku, Jaddua
מְשֵׁיזַבְאֵ֥ל צָדֹ֖וק יַדּֽוּעַ׃
22 Pelatiah, Hanani, Anaiah,
פְּלַטְיָ֥ה חָנָ֖ן עֲנָיָֽה׃
23 Hosea, Hananiah, Haṣubu,
הֹושֵׁ֥עַ חֲנַנְיָ֖ה חַשּֽׁוּב׃
24 Halloheṣi, Pileha, Ṣobeki,
הַלֹּוחֵ֥שׁ פִּלְחָ֖א שֹׁובֵֽק׃
25 Rehumu, Haṣabna, Maaseiah,
רְח֥וּם חֲשַׁבְנָ֖ה מַעֲשֵׂיָֽה׃
26 Ahijah, Hanani, Anani,
וַאֲחִיָּ֥ה חָנָ֖ן עָנָֽן׃
27 Malluki, Harimu, àti Baanah.
מַלּ֥וּךְ חָרִ֖ם בַּעֲנָֽה׃
28 “Àwọn ènìyàn tókù—àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn aṣọ́nà, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn àjèjì nítorí òfin Ọlọ́run, papọ̀ pẹ̀lú ìyàwó wọn, gbogbo ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, tí òye yé
וּשְׁאָ֣ר הָעָ֡ם הַכֹּהֲנִ֣ים הַ֠לְוִיִּם הַשֹּׁועֲרִ֨ים הַמְשֹׁרְרִ֜ים הַנְּתִינִ֗ים וְֽכָל־הַנִּבְדָּ֞ל מֵעַמֵּ֤י הָאֲרָצֹות֙ אֶל־תֹּורַ֣ת הָאֱלֹהִ֔ים נְשֵׁיהֶ֖ם בְּנֵיהֶ֣ם וּבְנֹתֵיהֶ֑ם כֹּ֖ל יֹודֵ֥עַ מֵבִֽין׃
29 gbogbo wọn fi ara mọ́ àwọn arákùnrin wọn, àwọn ọlọ́lá, wọ́n sì fi ègún àti ìbúra dé ara wọn láti máa tẹ̀lé òfin Ọlọ́run tí a fi fún wọn ní ipasẹ̀ Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run àti láti pa gbogbo àṣẹ, ìlànà àti òfin Olúwa, wa mọ́ dáradára.
מַחֲזִיקִ֣ים עַל־אֲחֵיהֶם֮ אַדִּירֵיהֶם֒ וּבָאִ֞ים בְּאָלָ֣ה וּבִשְׁבוּעָ֗ה לָלֶ֙כֶת֙ בְּתֹורַ֣ת הָאֱלֹהִ֔ים אֲשֶׁ֣ר נִתְּנָ֔ה בְּיַ֖ד מֹשֶׁ֣ה עֶֽבֶד־הֽ͏ָאֱלֹהִ֑ים וְלִשְׁמֹ֣ור וְלַעֲשֹׂ֗ות אֶת־כָּל־מִצְוֹת֙ יְהוָ֣ה אֲדֹנֵ֔ינוּ וּמִשְׁפָּטָ֖יו וְחֻקָּֽיו׃
30 “A ti ṣe ìlérí pé, a kò ní fi àwọn ọmọbìnrin wa fún àwọn tí wọ́n wà ní àyíká wa bí ìyàwó, tàbí fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin wa.
וַאֲשֶׁ֛ר לֹא־נִתֵּ֥ן בְּנֹתֵ֖ינוּ לְעַמֵּ֣י הָאָ֑רֶץ וְאֶת־בְּנֹ֣תֵיהֶ֔ם לֹ֥א נִקַּ֖ח לְבָנֵֽינוּ׃
31 “Nígbà tí àwọn ènìyàn àdúgbò bá mú ọjà tàbí oúnjẹ wá ní ọjọ́ ìsinmi láti tà, àwa kò ní rà á ní ọwọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi tàbí ní ọjọ́ mímọ́ kankan. Ní gbogbo ọdún keje àwa kò ní ro ilẹ̀ náà, a ó sì pa gbogbo àwọn gbèsè rẹ́.
וְעַמֵּ֣י הָאָ֡רֶץ הַֽמְבִיאִים֩ אֶת־הַמַּקָּחֹ֨ות וְכָל־שֶׁ֜בֶר בְּיֹ֤ום הַשַּׁבָּת֙ לִמְכֹּ֔ור לֹא־נִקַּ֥ח מֵהֶ֛ם בַּשַּׁבָּ֖ת וּבְיֹ֣ום קֹ֑דֶשׁ וְנִטֹּ֛שׁ אֶת־הַשָּׁנָ֥ה הַשְּׁבִיעִ֖ית וּמַשָּׁ֥א כָל־יָֽד׃
32 “Àwa gbà ojúṣe láti máa pa àṣẹ mọ́ pé, a ó máa san ìdámẹ́ta ṣékélì ní ọdọọdún fún iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa:
וְהֶעֱמַ֤דְנוּ עָלֵ֙ינוּ֙ מִצְוֹ֔ת לָתֵ֥ת עָלֵ֛ינוּ שְׁלִשִׁ֥ית הַשֶּׁ֖קֶל בַּשָּׁנָ֑ה לַעֲבֹדַ֖ת בֵּ֥ית אֱלֹהֵֽינוּ׃
33 nítorí oúnjẹ tí ó wà lórí tábìlì; nítorí ọrẹ ohun jíjẹ àti ẹbọ sísun ìgbà gbogbo; nítorí ọrẹ ọjọ́ ìsinmi, ti àyajọ́ oṣù tuntun àti àjọ̀dún tí a yàn; nítorí ọrẹ mímọ́; nítorí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún Israẹli; àti fún gbogbo iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa.
לְלֶ֣חֶם הַֽמַּעֲרֶ֡כֶת וּמִנְחַ֣ת הַתָּמִ֣יד וּלְעֹולַ֣ת הַ֠תָּמִיד הַשַּׁבָּתֹ֨ות הֶחֳדָשִׁ֜ים לַמֹּועֲדִ֗ים וְלַקֳּדָשִׁים֙ וְלַ֣חַטָּאֹ֔ות לְכַפֵּ֖ר עַל־יִשְׂרָאֵ֑ל וְכֹ֖ל מְלֶ֥אכֶת בֵּית־אֱלֹהֵֽינוּ׃ ס
34 “Àwa, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ènìyàn náà ti dìbò láti pinnu ìgbà tí olúkúlùkù àwọn ìdílé yóò mú ọrẹ igi wá láti sun lọ́ríi pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa sí ilé Ọlọ́run wa, ní àkókò tí a yàn ní ọdọọdún. Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin.
וְהַגֹּורָלֹ֨ות הִפַּ֜לְנוּ עַל־קֻרְבַּ֣ן הָעֵצִ֗ים הַכֹּהֲנִ֣ים הַלְוִיִּם֮ וְהָעָם֒ לְ֠הָבִיא לְבֵ֨ית אֱלֹהֵ֧ינוּ לְבֵית־אֲבֹתֵ֛ינוּ לְעִתִּ֥ים מְזֻמָּנִ֖ים שָׁנָ֣ה בְשָׁנָ֑ה לְבַעֵ֗ר עַל־מִזְבַּח֙ יְהוָ֣ה אֱלֹהֵ֔ינוּ כַּכָּת֖וּב בַּתֹּורָֽה׃
35 “Àwa tún gbà ojúṣe láti mú àkọ́so àwọn èso wa wá àti gbogbo èso igi wá ní ilé Olúwa.
וּלְהָבִ֞יא אֶת־בִּכּוּרֵ֣י אַדְמָתֵ֗נוּ וּבִכּוּרֵ֛י כָּל־פְּרִ֥י כָל־עֵ֖ץ שָׁנָ֣ה בְשָׁנָ֑ה לְבֵ֖ית יְהוָֽה׃
36 “Gẹ́gẹ́ bí a sì ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin, àwa yóò mú àkọ́bí àwọn ọmọkùnrin wa, ti ohun ọ̀sìn wa, ti àwọn abo màlúù àti ti àwọn àgùntàn wa, wá sí ilé Ọlọ́run wa, fún àwọn àlùfáà tí ń ṣiṣẹ́ níbẹ̀.
וְאֶת־בְּכֹרֹ֤ות בָּנֵ֙ינוּ֙ וּבְהֶמְתֵּ֔ינוּ כַּכָּת֖וּב בַּתֹּורָ֑ה וְאֶת־בְּכֹורֵ֨י בְקָרֵ֜ינוּ וְצֹאנֵ֗ינוּ לְהָבִיא֙ לְבֵ֣ית אֱלֹהֵ֔ינוּ לַכֹּ֣הֲנִ֔ים הַמְשָׁרְתִ֖ים בְּבֵ֥ית אֱלֹהֵֽינוּ׃
37 “Síwájú sí i, àwa yóò mú àkọ́so oúnjẹ ilẹ̀ wa ti ọrẹ oúnjẹ, ti gbogbo èso àwọn igi àti ti wáìnì tuntun wa àti ti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ilé Ọlọ́run wa àti fún àwọn àlùfáà. Àwa yóò sì mú ìdámẹ́wàá ohun ọ̀gbìn wá fún àwọn ọmọ Lefi, nítorí àwọn ọmọ Lefi ni ó ń gba ìdámẹ́wàá ní gbogbo àwọn ìlú tí a ti ń ṣiṣẹ́.
וְאֶת־רֵאשִׁ֣ית עֲרִיסֹתֵ֣ינוּ וּ֠תְרוּמֹתֵינוּ וּפְרִ֨י כָל־עֵ֜ץ תִּירֹ֣ושׁ וְיִצְהָ֗ר נָבִ֤יא לַכֹּהֲנִים֙ אֶל־לִשְׁכֹ֣ות בֵּית־אֱלֹהֵ֔ינוּ וּמַעְשַׂ֥ר אַדְמָתֵ֖נוּ לַלְוִיִּ֑ם וְהֵם֙ הַלְוִיִּ֔ם הַֽמְעַשְּׂרִ֔ים בְּכֹ֖ל עָרֵ֥י עֲבֹדָתֵֽנוּ׃
38 Àlùfáà tí o ti ìdílé Aaroni wá ni yóò wá pẹ̀lú àwọn ọmọ Lefi nígbà tí wọ́n bá ń gba ìdámẹ́wàá, àwọn ọmọ Lefi yóò sì mú ìdámẹ́wàá ti ìdámẹ́wàá náà wá sí ilé Ọlọ́run, sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí inú ilé ìṣúra.
וְהָיָ֨ה הַכֹּהֵ֧ן בֶּֽן־אַהֲרֹ֛ן עִם־הַלְוִיִּ֖ם בַּעְשֵׂ֣ר הַלְוִיִּ֑ם וְהַלְוִיִּ֞ם יַעֲל֨וּ אֶת־מַעֲשַׂ֤ר הַֽמַּעֲשֵׂר֙ לְבֵ֣ית אֱלֹהֵ֔ינוּ אֶל־הַלְּשָׁכֹ֖ות לְבֵ֥ית הָאֹוצָֽר׃
39 Àwọn ènìyàn Israẹli, àti àwọn ọmọ Lefi gbọdọ̀ mú ọrẹ oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí níbi tí a pa ohun èlò ibi mímọ́ mọ́ sí àti ibi tí àwọn àlùfáà tí ń ṣe ìránṣẹ́ lọ́wọ́, àwọn aṣọ́nà àti àwọn akọrin máa ń dúró sí. “Àwa kì yóò gbàgbé tàbí ṣe àìbìkítà nípa ilé Ọlọ́run wa.”
כִּ֣י אֶל־הַ֠לְּשָׁכֹות יָבִ֨יאוּ בְנֵי־יִשְׂרָאֵ֜ל וּבְנֵ֣י הַלֵּוִ֗י אֶת־תְּרוּמַ֣ת הַדָּגָן֮ הַתִּירֹ֣ושׁ וְהַיִּצְהָר֒ וְשָׁם֙ כְּלֵ֣י הַמִּקְדָּ֔שׁ וְהַכֹּהֲנִים֙ הַמְשָׁ֣רְתִ֔ים וְהַשֹּׁועֲרִ֖ים וְהַמְשֹׁרְרִ֑ים וְלֹ֥א נַעֲזֹ֖ב אֶת־בֵּ֥ית אֱלֹהֵֽינוּ׃

< Nehemiah 10 >