< Nehemiah 10 >

1 Àwọn tí ó fi èdìdì dì í ni: Nehemiah baálẹ̀, ọmọ Hakaliah. Sedekiah
Arĩa meekĩrire kĩrĩkanĩro kĩu mũhũũri maarĩ: Nehemia ũrĩa warĩ barũthi wa kũu, mũrũ wa Hakalia, na Zedekia,
2 Seraiah, Asariah, Jeremiah,
na Seraia, na Azaria, na Jeremia,
3 Paṣuri, Amariah, Malkiah,
na Pashuru, na Amaria, na Malikija,
4 Hattusi, Ṣebaniah, Malluki,
na Hatushu, na Shebania, na Maluku,
5 Harimu, Meremoti, Obadiah,
na Harimu, na Meremothu, na Obadia,
6 Daniẹli, Ginetoni, Baruku,
na Danieli, na Ginethoni, na Baruku,
7 Meṣullamu, Abijah, Mijamini,
na Meshulamu, na Abija, na Mijamini,
8 Maasiah, Bilgai àti Ṣemaiah. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà.
na Maazia, na Biligai, na Shemaia. Acio nĩo maarĩ athĩnjĩri-Ngai.
9 Àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua ọmọ Asaniah, Binnui ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Henadadi, Kadmieli,
Nao Alawii maarĩ: Jeshua mũrũ wa Azania, na Binui wa ariũ a Henadadi, na Kadimieli,
10 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn: Ṣebaniah, Hodiah, Kelita, Pelaiah, Hanani,
nao athiritũ ao maarĩ: Shebania, na Hodia, na Kelita, na Pelaia, na Hanani,
11 Mika, Rehobu, Haṣabiah,
na Mika, na Rehobu, na Hashabia,
12 Sakkuri, Ṣerebiah, Ṣebaniah,
na Zakuri, na Sherebia, na Shebania,
13 Hodiah, Bani àti Beninu.
na Hodia, na Bani, na Beninu.
14 Àwọn olórí àwọn ènìyàn: Paroṣi, Pahati-Moabu, Elamu, Sattu, Bani,
Nao atongoria a andũ maarĩ: Paroshu, na Pahathu-Moabi, na Elamu, na Zatu, na Bani,
15 Bunni, Asgadi, Bebai.
na Buni, na Azigadi, na Bebai,
16 Adonijah, Bigfai, Adini,
na Adonija, na Bigivai, na Adini,
17 Ateri, Hesekiah, Assuri,
na Ateri, na Hezekia, na Azuri,
18 Hodiah, Haṣumu, Besai,
na Hodia, na Hashumu, na Bezai,
19 Harifu, Anatoti, Nebai,
na Harifu, na Anathothu, na Nebai,
20 Magpiaṣi, Meṣullamu, Hesiri
na Magipiashu, na Meshulamu, na Heziri,
21 Meṣesabeli, Sadoku, Jaddua
na Meshezabeli, na Zadoku, na Jadua,
22 Pelatiah, Hanani, Anaiah,
na Pelatia, na Hanani, na Anaia,
23 Hosea, Hananiah, Haṣubu,
na Hoshea, na Hanania, na Hashubu,
24 Halloheṣi, Pileha, Ṣobeki,
na Haloheshu, na Piliha, na Shobeku,
25 Rehumu, Haṣabna, Maaseiah,
na Rehumu, na Hashabina, na Maaseia,
26 Ahijah, Hanani, Anani,
na Ahia, na Hanani, na Anani,
27 Malluki, Harimu, àti Baanah.
na Maluku, na Harimu, na Baana.
28 “Àwọn ènìyàn tókù—àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn aṣọ́nà, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn àjèjì nítorí òfin Ọlọ́run, papọ̀ pẹ̀lú ìyàwó wọn, gbogbo ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, tí òye yé
“Andũ arĩa angĩ, nĩo athĩnjĩri-Ngai, na Alawii, na aikaria a ihingo, na aini, o na ndungata cia hekarũ na arĩa othe meyamũranĩtie na andũ arĩa maariganĩtie nao nĩguo maathĩkĩre Watho wa Ngai, marĩ hamwe na atumia ao, na aanake, na airĩtu ao othe arĩa mangĩhota gũtaũkĩrwo nĩ maũndũ,
29 gbogbo wọn fi ara mọ́ àwọn arákùnrin wọn, àwọn ọlọ́lá, wọ́n sì fi ègún àti ìbúra dé ara wọn láti máa tẹ̀lé òfin Ọlọ́run tí a fi fún wọn ní ipasẹ̀ Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run àti láti pa gbogbo àṣẹ, ìlànà àti òfin Olúwa, wa mọ́ dáradára.
andũ aya othe maanyiitana na ariũ a ithe wao arĩa marĩ igweta, na meeohe na kĩrumi na mwĩhĩtwa atĩ nĩmarĩrũmagĩrĩra Watho wa Ngai ũrĩa waheirwo Musa ndungata ya Ngai, na mamenyagĩrĩre gwathĩkĩra maathani mothe, na mawatho, na kĩrĩra gĩa kũrũmĩrĩrwo kĩa Jehova Mwathani witũ.
30 “A ti ṣe ìlérí pé, a kò ní fi àwọn ọmọbìnrin wa fún àwọn tí wọ́n wà ní àyíká wa bí ìyàwó, tàbí fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin wa.
“Tweranĩra atĩ tũtikaheana airĩtu aitũ mahikio nĩ andũ arĩa matũrigiicĩirie o na kana aanake aitũ mahikie airĩtu ao.
31 “Nígbà tí àwọn ènìyàn àdúgbò bá mú ọjà tàbí oúnjẹ wá ní ọjọ́ ìsinmi láti tà, àwa kò ní rà á ní ọwọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi tàbí ní ọjọ́ mímọ́ kankan. Ní gbogbo ọdún keje àwa kò ní ro ilẹ̀ náà, a ó sì pa gbogbo àwọn gbèsè rẹ́.
“Rĩrĩa andũ a mabũrũri marĩa tũriganĩtie marĩrehaga indo na ngano ya kwendia mũthenya wa Thabatũ, tũtikamagũrĩra mũthenya ũcio wa Thabatũ o na kana mũthenya ũngĩ o wothe mwamũre. O mwaka wa mũgwanja wakinya tũtirĩrĩmaga mĩgũnda iitũ, na nĩtũrĩĩrekanagĩra mathiirĩ mothe.
32 “Àwa gbà ojúṣe láti máa pa àṣẹ mọ́ pé, a ó máa san ìdámẹ́ta ṣékélì ní ọdọọdún fún iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa:
“Nĩtuoya mũrigo wa kũhingia mawatho ma kũheanaga gĩcunjĩ gĩa gatatũ gĩa cekeri o mwaka nĩ ũndũ wa wĩra wa nyũmba ya Ngai witũ:
33 nítorí oúnjẹ tí ó wà lórí tábìlì; nítorí ọrẹ ohun jíjẹ àti ẹbọ sísun ìgbà gbogbo; nítorí ọrẹ ọjọ́ ìsinmi, ti àyajọ́ oṣù tuntun àti àjọ̀dún tí a yàn; nítorí ọrẹ mímọ́; nítorí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún Israẹli; àti fún gbogbo iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa.
nĩ ũndũ wa mĩgate ĩrĩa ĩigagwo metha-inĩ; nĩ ũndũ wa mahinda ma maruta ma mũtu na ma njino; na nĩ ũndũ wa maruta marĩa marutagwo mũthenya wa Thabatũ, na wa ciathĩ cia Karũgamo ka Mweri, na wa ciathĩ iria ciathanĩtwo; nĩ ũndũ wa maruta marĩa maamũre; nĩ ũndũ wa maruta ma kũhoroheria mehia ma Isiraeli; o na nĩ ũndũ wa mawĩra mothe ma nyũmba ya Ngai witũ.
34 “Àwa, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ènìyàn náà ti dìbò láti pinnu ìgbà tí olúkúlùkù àwọn ìdílé yóò mú ọrẹ igi wá láti sun lọ́ríi pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa sí ilé Ọlọ́run wa, ní àkókò tí a yàn ní ọdọọdún. Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin.
“Ithuĩ athĩnjĩri-Ngai, na Alawii o na andũ aya angĩ nĩtũcuukĩte mĩtĩ tũgatuanĩra rĩrĩa o nyũmba iitũ ĩrĩĩrehaga ngũ nyũmba-inĩ ya Ngai witũ, cia gũikaragia mwaki wakanĩte kĩgongona-inĩ kĩa Jehova Ngai witũ mahinda marĩa matuanĩirwo o mwaka, o ta ũrĩa kwandĩkĩtwo Watho-inĩ.
35 “Àwa tún gbà ojúṣe láti mú àkọ́so àwọn èso wa wá àti gbogbo èso igi wá ní ilé Olúwa.
“O na nĩtuoya mũrigo wa kũrehaga maciaro ma mbere ma mĩgũnda iitũ na ma mũtĩ o wothe wa matunda nyũmba-inĩ ya Jehova o mwaka.
36 “Gẹ́gẹ́ bí a sì ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin, àwa yóò mú àkọ́bí àwọn ọmọkùnrin wa, ti ohun ọ̀sìn wa, ti àwọn abo màlúù àti ti àwọn àgùntàn wa, wá sí ilé Ọlọ́run wa, fún àwọn àlùfáà tí ń ṣiṣẹ́ níbẹ̀.
“O ta ũrĩa kwandĩkĩtwo Watho-inĩ, nĩtũrĩĩrehaga marigithathi maitũ ma aanake, na ma ngʼombe, na ma ndũũru cia ngʼombe na cia mbũri ciitũ gũkũ nyũmba-inĩ ya Ngai witũ kũrĩ athĩnjĩri-Ngai arĩa matungataga kuo.
37 “Síwájú sí i, àwa yóò mú àkọ́so oúnjẹ ilẹ̀ wa ti ọrẹ oúnjẹ, ti gbogbo èso àwọn igi àti ti wáìnì tuntun wa àti ti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ilé Ọlọ́run wa àti fún àwọn àlùfáà. Àwa yóò sì mú ìdámẹ́wàá ohun ọ̀gbìn wá fún àwọn ọmọ Lefi, nítorí àwọn ọmọ Lefi ni ó ń gba ìdámẹ́wàá ní gbogbo àwọn ìlú tí a ti ń ṣiṣẹ́.
“O na ningĩ nĩtũrĩĩrehaga thĩinĩ wa makũmbĩ ma nyũmba ya Ngai, tũnengere athĩnjĩri-Ngai mũtu wa mbere, na magongona maitũ ma ngano ma mbere, na maruta ma matunda ma mĩtĩ iitũ yothe ma mbere, na ma ndibei iitũ ya mũhihano o na ma maguta. O na nĩtũrĩĩrehaga gĩcunjĩ gĩa ikũmi kĩa maciaro ma mĩgũnda iitũ, tũkanengera Alawii, nĩgũkorwo nĩ Alawii maamũkagĩra icunjĩ cia ikũmi kuuma matũũra mothe kũrĩa tũrutaga wĩra.
38 Àlùfáà tí o ti ìdílé Aaroni wá ni yóò wá pẹ̀lú àwọn ọmọ Lefi nígbà tí wọ́n bá ń gba ìdámẹ́wàá, àwọn ọmọ Lefi yóò sì mú ìdámẹ́wàá ti ìdámẹ́wàá náà wá sí ilé Ọlọ́run, sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí inú ilé ìṣúra.
Mũthĩnjĩri-Ngai wa rũciaro rwa Harũni nĩarĩkoragwo ho Alawii makĩamũkĩra gĩcunjĩ kĩu gĩa ikũmi, nao Alawii nĩmarĩĩrehaga gĩcunjĩ gĩa ikũmi kĩa indo ciothe makũmbĩ-inĩ ma kĩgĩĩna kĩa nyũmba ya Ngai witũ.
39 Àwọn ènìyàn Israẹli, àti àwọn ọmọ Lefi gbọdọ̀ mú ọrẹ oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí níbi tí a pa ohun èlò ibi mímọ́ mọ́ sí àti ibi tí àwọn àlùfáà tí ń ṣe ìránṣẹ́ lọ́wọ́, àwọn aṣọ́nà àti àwọn akọrin máa ń dúró sí. “Àwa kì yóò gbàgbé tàbí ṣe àìbìkítà nípa ilé Ọlọ́run wa.”
Andũ a Isiraeli, hamwe na Alawii, nĩmarĩĩrehaga maruta mao ma ngano, na ndibei ya mũhihano, na maguta thĩinĩ wa makũmbĩ marĩa indo cia handũ-harĩa-haamũre ciigagwo, na kũrĩa athĩnjĩri-Ngai, arĩa maratungata, na aikaria a ihingo, na aini maikaraga. “Tũtirĩrekagĩrĩria nyũmba ya Ngai witũ.”

< Nehemiah 10 >