< Nehemiah 10 >

1 Àwọn tí ó fi èdìdì dì í ni: Nehemiah baálẹ̀, ọmọ Hakaliah. Sedekiah
Or, les signataires furent Néhémias Athersatha, fils d’Hachélaï, et Sédécias,
2 Seraiah, Asariah, Jeremiah,
Saraïas, Azarias, Jérémie,
3 Paṣuri, Amariah, Malkiah,
Pheshur, Amarias, Melchias,
4 Hattusi, Ṣebaniah, Malluki,
Hattus, Sébénia, Melluch,
5 Harimu, Meremoti, Obadiah,
Harem, Mérimuth, Obdias,
6 Daniẹli, Ginetoni, Baruku,
Daniel, Genthon, Baruch,
7 Meṣullamu, Abijah, Mijamini,
Mosollam, Abia, Miamin,
8 Maasiah, Bilgai àti Ṣemaiah. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà.
Maazia, Belgaï, Séméia: ceux-là furent les prêtres.
9 Àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua ọmọ Asaniah, Binnui ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Henadadi, Kadmieli,
Mais les Lévites: Josué, fils d’Azanias; Bennuï, des fils de Hénadad, Cedmihel,
10 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn: Ṣebaniah, Hodiah, Kelita, Pelaiah, Hanani,
Et leurs frères, Sébénia, Odaïa, Célita, Phalaïa, Hanan,
11 Mika, Rehobu, Haṣabiah,
Micha, Rohob, Hasébia,
12 Sakkuri, Ṣerebiah, Ṣebaniah,
Zachur, Sérébia. Sabania,
13 Hodiah, Bani àti Beninu.
Odaïa, Bani, Baninu.
14 Àwọn olórí àwọn ènìyàn: Paroṣi, Pahati-Moabu, Elamu, Sattu, Bani,
Les chefs du peuple: Pharos, Phahathmoab, Elam, Zéthu, Bani,
15 Bunni, Asgadi, Bebai.
Bonni, Azgad, Bébaï,
16 Adonijah, Bigfai, Adini,
Adonia, Bégoaï, Adin,
17 Ateri, Hesekiah, Assuri,
Ater, Hézécia, Azur,
18 Hodiah, Haṣumu, Besai,
Odaïa, Hasum, Bésaï,
19 Harifu, Anatoti, Nebai,
Hareph, Anathoth, Nébaï,
20 Magpiaṣi, Meṣullamu, Hesiri
Megphias, Mosollam, Hazir,
21 Meṣesabeli, Sadoku, Jaddua
Mésizabel, Sadoc, Jeddua,
22 Pelatiah, Hanani, Anaiah,
Pheltia, Hanan, Anaïa,
23 Hosea, Hananiah, Haṣubu,
Osée, Hanania, Hasub,
24 Halloheṣi, Pileha, Ṣobeki,
Alohès, Phaléa, Sobec,
25 Rehumu, Haṣabna, Maaseiah,
Réhum, Hasebna, Maasia,
26 Ahijah, Hanani, Anani,
Echaïa, Hanan, Anan,
27 Malluki, Harimu, àti Baanah.
Melluch, Haran, Baana.
28 “Àwọn ènìyàn tókù—àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn aṣọ́nà, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn àjèjì nítorí òfin Ọlọ́run, papọ̀ pẹ̀lú ìyàwó wọn, gbogbo ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, tí òye yé
Et le reste du peuple, les prêtres, les Lévites, les portiers et les chantres, les Nathinéens, et tous ceux qui s’étaient séparés des peuples de la terre pour la loi de Dieu, leurs femmes, leurs fils et leurs filles,
29 gbogbo wọn fi ara mọ́ àwọn arákùnrin wọn, àwọn ọlọ́lá, wọ́n sì fi ègún àti ìbúra dé ara wọn láti máa tẹ̀lé òfin Ọlọ́run tí a fi fún wọn ní ipasẹ̀ Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run àti láti pa gbogbo àṣẹ, ìlànà àti òfin Olúwa, wa mọ́ dáradára.
Tous ceux qui pouvaient être éclairés, répondant pour leurs frères; les grands aussi; enfin tous ceux qui venaient pour promettre et jurer qu’ils marcheraient dans la loi de Dieu, qu’il avait donnée par l’entremise de Moïse, serviteur de Dieu, qu’ils accompliraient et garderaient tous les commandements du Seigneur notre Dieu, et ses ordonnances et ses cérémonies,
30 “A ti ṣe ìlérí pé, a kò ní fi àwọn ọmọbìnrin wa fún àwọn tí wọ́n wà ní àyíká wa bí ìyàwó, tàbí fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin wa.
Que nous ne donnerions point nos filles au peuple du pays, et que nous ne prendrions point leurs filles pour nos fils.
31 “Nígbà tí àwọn ènìyàn àdúgbò bá mú ọjà tàbí oúnjẹ wá ní ọjọ́ ìsinmi láti tà, àwa kò ní rà á ní ọwọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi tàbí ní ọjọ́ mímọ́ kankan. Ní gbogbo ọdún keje àwa kò ní ro ilẹ̀ náà, a ó sì pa gbogbo àwọn gbèsè rẹ́.
De plus, quant aux peuples du pays qui importent des objets de vente de toute sorte de choses de consommation, au jour du Sabbat, pour les vendre, nous ne les accepterons pas d’eux pendant le Sabbat, et en un jour sanctifié. Nous abandonnerons aussi la septième année et l’exaction de toute main.
32 “Àwa gbà ojúṣe láti máa pa àṣẹ mọ́ pé, a ó máa san ìdámẹ́ta ṣékélì ní ọdọọdún fún iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa:
Et nous établirons pour nous comme préceptes de donner par an la troisième partie d’un sicle, pour l’œuvre de la maison de notre Dieu.
33 nítorí oúnjẹ tí ó wà lórí tábìlì; nítorí ọrẹ ohun jíjẹ àti ẹbọ sísun ìgbà gbogbo; nítorí ọrẹ ọjọ́ ìsinmi, ti àyajọ́ oṣù tuntun àti àjọ̀dún tí a yàn; nítorí ọrẹ mímọ́; nítorí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún Israẹli; àti fún gbogbo iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa.
Pour les pains de proposition, et pour le sacrifice perpétuel, pour l’holocauste perpétuel dans les sabbats, dans les calendes, dans les solennités, et dans les choses sanctifiées et pour le péché, afin que l’on prie pour Israël, et pour le service de la maison de notre Dieu.
34 “Àwa, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ènìyàn náà ti dìbò láti pinnu ìgbà tí olúkúlùkù àwọn ìdílé yóò mú ọrẹ igi wá láti sun lọ́ríi pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa sí ilé Ọlọ́run wa, ní àkókò tí a yàn ní ọdọọdún. Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin.
Nous jetâmes donc les sorts, pour l’offrande des bois, entre les prêtres, les Lévites et le peuple, afin qu’ils fussent apportés dans la maison de notre Dieu, selon les maisons de nos pères, à des temps marqués, depuis les temps d’une année jusqu’à une autre année, afin qu’ils brûlassent sur l’autel du Seigneur notre Dieu, comme il est écrit dans la loi de Moïse.
35 “Àwa tún gbà ojúṣe láti mú àkọ́so àwọn èso wa wá àti gbogbo èso igi wá ní ilé Olúwa.
Nous promîmes aussi et nous jurâmes, que nous apporterions les prémices de notre terre et les prémices de tous les fruits de tout arbre, d’année en année, dans la maison du Seigneur,
36 “Gẹ́gẹ́ bí a sì ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin, àwa yóò mú àkọ́bí àwọn ọmọkùnrin wa, ti ohun ọ̀sìn wa, ti àwọn abo màlúù àti ti àwọn àgùntàn wa, wá sí ilé Ọlọ́run wa, fún àwọn àlùfáà tí ń ṣiṣẹ́ níbẹ̀.
Et les premiers-nés de nos fils et de nos troupeaux, comme il est écrit dans la loi, et les prémices de nos bœufs et de nos brebis, pour être offerts dans la maison de notre Dieu, aux prêtres qui servent dans la maison de notre Dieu;
37 “Síwájú sí i, àwa yóò mú àkọ́so oúnjẹ ilẹ̀ wa ti ọrẹ oúnjẹ, ti gbogbo èso àwọn igi àti ti wáìnì tuntun wa àti ti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ilé Ọlọ́run wa àti fún àwọn àlùfáà. Àwa yóò sì mú ìdámẹ́wàá ohun ọ̀gbìn wá fún àwọn ọmọ Lefi, nítorí àwọn ọmọ Lefi ni ó ń gba ìdámẹ́wàá ní gbogbo àwọn ìlú tí a ti ń ṣiṣẹ́.
Les prémices aussi de nos aliments et de nos libations, et les fruits de tout arbre, de la vigne aussi bien que de l’olivier, nous les apporterons aux prêtres, pour le trésor de notre Dieu, et la dixième partie de notre terre aux Lévites. Eux-mêmes, les Lévites recevront de toutes les villes les dîmes de nos travaux.
38 Àlùfáà tí o ti ìdílé Aaroni wá ni yóò wá pẹ̀lú àwọn ọmọ Lefi nígbà tí wọ́n bá ń gba ìdámẹ́wàá, àwọn ọmọ Lefi yóò sì mú ìdámẹ́wàá ti ìdámẹ́wàá náà wá sí ilé Ọlọ́run, sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí inú ilé ìṣúra.
Et le prêtre, fils d’Aaron, sera avec les Lévites dans les dîmes des Lévites; et les Lévites offriront la dixième partie de leur dîme dans la maison de notre Dieu, au lieu où on garde le trésor, dans la maison du trésor.
39 Àwọn ènìyàn Israẹli, àti àwọn ọmọ Lefi gbọdọ̀ mú ọrẹ oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí níbi tí a pa ohun èlò ibi mímọ́ mọ́ sí àti ibi tí àwọn àlùfáà tí ń ṣe ìránṣẹ́ lọ́wọ́, àwọn aṣọ́nà àti àwọn akọrin máa ń dúró sí. “Àwa kì yóò gbàgbé tàbí ṣe àìbìkítà nípa ilé Ọlọ́run wa.”
Car c’est au lieu où on garde le trésor que les enfants d’Israël et les enfants de Lévi apporteront les prémices du froment, du vin et de l’huile; et là seront les vases sanctifiés, les prêtres, les chantres, les portiers et les ministres, et nous n’abandonnerons pas la maison de notre Dieu.

< Nehemiah 10 >