< Nehemiah 10 >

1 Àwọn tí ó fi èdìdì dì í ni: Nehemiah baálẹ̀, ọmọ Hakaliah. Sedekiah
Or [ceux qui] apposèrent leurs seings, [furent], Néhémie, qui est Attirsatha, fils de Hachalia, et Sédécias.
2 Seraiah, Asariah, Jeremiah,
Séraja, Hazaria, Jérémie,
3 Paṣuri, Amariah, Malkiah,
Pashur, Hamaria, Malkija,
4 Hattusi, Ṣebaniah, Malluki,
Hattus, Sébania, Malluc,
5 Harimu, Meremoti, Obadiah,
Harim, Mérémoth, Hobadia,
6 Daniẹli, Ginetoni, Baruku,
Daniel, Guinnethon, Baruc,
7 Meṣullamu, Abijah, Mijamini,
Mésullam, Abija, Mijamin,
8 Maasiah, Bilgai àti Ṣemaiah. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà.
Mahazia, Bilgaï et Sémahia. Ce [furent]-là les Sacrificateurs.
9 Àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua ọmọ Asaniah, Binnui ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Henadadi, Kadmieli,
Des Lévites: Jésuah fils d'Azania, Binnui d'entre les enfants de Hénadad, et Kadmiel.
10 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn: Ṣebaniah, Hodiah, Kelita, Pelaiah, Hanani,
Et leurs frères, Sébania, Hodija, Kélita, Pélaja, Hanan,
11 Mika, Rehobu, Haṣabiah,
Micaï, Réhob, Asabja.
12 Sakkuri, Ṣerebiah, Ṣebaniah,
Zaccur, Sérebia, Sébania,
13 Hodiah, Bani àti Beninu.
Hodija, Bani et Béninu.
14 Àwọn olórí àwọn ènìyàn: Paroṣi, Pahati-Moabu, Elamu, Sattu, Bani,
Des Chefs du peuple, Parhos, Pahath-Moab, Hélam, Zattu, Bani,
15 Bunni, Asgadi, Bebai.
Bunni, Hazgad, Bébaï,
16 Adonijah, Bigfai, Adini,
Adonija, Bigvaï, Hadin,
17 Ateri, Hesekiah, Assuri,
Ater, Ezéchias, Hazur,
18 Hodiah, Haṣumu, Besai,
Hodija, Hasum, Betsaï,
19 Harifu, Anatoti, Nebai,
Hariph, Hanathoth, Nébaï,
20 Magpiaṣi, Meṣullamu, Hesiri
Magpihas, Mésullam, Hézir,
21 Meṣesabeli, Sadoku, Jaddua
Mésézabéel, Tsadok, Jadduah,
22 Pelatiah, Hanani, Anaiah,
Pélatia, Hanan, Hanaja,
23 Hosea, Hananiah, Haṣubu,
Osée, Hanania, Hasub,
24 Halloheṣi, Pileha, Ṣobeki,
Lohès, Pilha, Sobek,
25 Rehumu, Haṣabna, Maaseiah,
Réhum, Hasabna, Mahaséja,
26 Ahijah, Hanani, Anani,
Ahija, Hanan, Hunan,
27 Malluki, Harimu, àti Baanah.
Malluc, Harim et Bahana.
28 “Àwọn ènìyàn tókù—àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn aṣọ́nà, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn àjèjì nítorí òfin Ọlọ́run, papọ̀ pẹ̀lú ìyàwó wọn, gbogbo ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, tí òye yé
Quant au reste du peuple les Sacrificateurs, les Lévites, les portiers, les chantres, les Néthiniens, et tous ceux qui s'étaient séparés des peuples des pays pour [faire] la Loi de Dieu, leurs femmes, leurs fils, et leurs filles, tous ceux qui étaient capables de connaissance et d'intelligence,
29 gbogbo wọn fi ara mọ́ àwọn arákùnrin wọn, àwọn ọlọ́lá, wọ́n sì fi ègún àti ìbúra dé ara wọn láti máa tẹ̀lé òfin Ọlọ́run tí a fi fún wọn ní ipasẹ̀ Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run àti láti pa gbogbo àṣẹ, ìlànà àti òfin Olúwa, wa mọ́ dáradára.
Adhérèrent entièrement à leurs frères, les plus considérables d'entre eux, et prêtèrent serment avec exécration et jurèrent de marcher dans la Loi de Dieu, qui avait été donnée par le moyen de Moïse serviteur de Dieu, et de garder et de faire tous les commandements de l'Eternel notre Seigneur, ses jugements et ses ordonnances;
30 “A ti ṣe ìlérí pé, a kò ní fi àwọn ọmọbìnrin wa fún àwọn tí wọ́n wà ní àyíká wa bí ìyàwó, tàbí fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin wa.
Et de ne donner point de nos filles aux peuples du pays, et de ne prendre point leurs filles pour nos fils;
31 “Nígbà tí àwọn ènìyàn àdúgbò bá mú ọjà tàbí oúnjẹ wá ní ọjọ́ ìsinmi láti tà, àwa kò ní rà á ní ọwọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi tàbí ní ọjọ́ mímọ́ kankan. Ní gbogbo ọdún keje àwa kò ní ro ilẹ̀ náà, a ó sì pa gbogbo àwọn gbèsè rẹ́.
Et de ne prendre rien le jour du Sabbat, ou tel autre jour sanctifié, des peuples du pays, qui apportent des marchandises, et toutes sortes de denrées le jour du Sabbat, pour les vendre; et d'abandonner la septième année, avec tout le droit d'exiger ce qui est dû.
32 “Àwa gbà ojúṣe láti máa pa àṣẹ mọ́ pé, a ó máa san ìdámẹ́ta ṣékélì ní ọdọọdún fún iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa:
Nous fîmes aussi des ordonnances, nous chargeant de donner chaque année la troisième partie d'un sicle, pour le service de la maison de notre Dieu;
33 nítorí oúnjẹ tí ó wà lórí tábìlì; nítorí ọrẹ ohun jíjẹ àti ẹbọ sísun ìgbà gbogbo; nítorí ọrẹ ọjọ́ ìsinmi, ti àyajọ́ oṣù tuntun àti àjọ̀dún tí a yàn; nítorí ọrẹ mímọ́; nítorí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún Israẹli; àti fún gbogbo iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa.
Pour les pains de proposition, pour le gâteau continuel, et pour l'holocauste continuel; et pour ceux des Sabbats, des nouvelles lunes, et des fêtes solennelles; pour les choses saintes, et pour les offrandes pour le péché, afin de réconcilier Israël; enfin, pour tout ce qui se faisait dans la maison de notre Dieu.
34 “Àwa, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ènìyàn náà ti dìbò láti pinnu ìgbà tí olúkúlùkù àwọn ìdílé yóò mú ọrẹ igi wá láti sun lọ́ríi pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa sí ilé Ọlọ́run wa, ní àkókò tí a yàn ní ọdọọdún. Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin.
Nous jetâmes aussi le sort touchant le bois des oblations, tant les sacrificateurs et les Lévites, que le peuple; afin de l'amener dans la maison de notre Dieu, selon les maisons de nos pères, et dans les temps déterminés, d'année en année, pour brûler sur l'autel de notre Dieu, ainsi qu'il est écrit dans la Loi.
35 “Àwa tún gbà ojúṣe láti mú àkọ́so àwọn èso wa wá àti gbogbo èso igi wá ní ilé Olúwa.
[Nous ordonnâmes] aussi que nous apporterions dans la maison de l'Eternel, d'année en année, les premiers fruits de notre terre, et les prémices de tous les fruits de tous les arbres;
36 “Gẹ́gẹ́ bí a sì ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin, àwa yóò mú àkọ́bí àwọn ọmọkùnrin wa, ti ohun ọ̀sìn wa, ti àwọn abo màlúù àti ti àwọn àgùntàn wa, wá sí ilé Ọlọ́run wa, fún àwọn àlùfáà tí ń ṣiṣẹ́ níbẹ̀.
Et [que nous rachèterions] les premiers-nés de nos fils, et de nos bêtes, comme il est écrit dans la Loi; et que nous amènerions en la maison de notre Dieu, aux Sacrificateurs qui font le service dans la maison de notre Dieu, les premiers-nés de nos bœufs et de notre menu bétail.
37 “Síwájú sí i, àwa yóò mú àkọ́so oúnjẹ ilẹ̀ wa ti ọrẹ oúnjẹ, ti gbogbo èso àwọn igi àti ti wáìnì tuntun wa àti ti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ilé Ọlọ́run wa àti fún àwọn àlùfáà. Àwa yóò sì mú ìdámẹ́wàá ohun ọ̀gbìn wá fún àwọn ọmọ Lefi, nítorí àwọn ọmọ Lefi ni ó ń gba ìdámẹ́wàá ní gbogbo àwọn ìlú tí a ti ń ṣiṣẹ́.
Et que nous apporterions les prémices de notre pâte, nos oblations, les fruits de tous les arbres, le vin, et l'huile aux Sacrificateurs, dans les chambres de la maison de notre Dieu, et la dîme de notre terre aux Lévites, et que les Lévites prendraient les dîmes par toutes les villes de notre labourage;
38 Àlùfáà tí o ti ìdílé Aaroni wá ni yóò wá pẹ̀lú àwọn ọmọ Lefi nígbà tí wọ́n bá ń gba ìdámẹ́wàá, àwọn ọmọ Lefi yóò sì mú ìdámẹ́wàá ti ìdámẹ́wàá náà wá sí ilé Ọlọ́run, sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí inú ilé ìṣúra.
Et qu'il y aurait un Sacrificateur, fils d'Aaron, avec les Lévites pour dîmer les Lévites, et que les Lévites apporteraient la dîme de la dîme en la maison de notre Dieu, dans les chambres, au lieu où étaient les greniers.
39 Àwọn ènìyàn Israẹli, àti àwọn ọmọ Lefi gbọdọ̀ mú ọrẹ oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí níbi tí a pa ohun èlò ibi mímọ́ mọ́ sí àti ibi tí àwọn àlùfáà tí ń ṣe ìránṣẹ́ lọ́wọ́, àwọn aṣọ́nà àti àwọn akọrin máa ń dúró sí. “Àwa kì yóò gbàgbé tàbí ṣe àìbìkítà nípa ilé Ọlọ́run wa.”
(car les enfants d'Israël? et les enfants de Lévi devaient apporter dans les chambres l'oblation du froment, du vin? et de l'huile; et là étaient les ustensiles du Sanctuaire, et les Sacrificateurs qui font le service, et les portiers, et les chantres ) et que nous n'abandonnerions point la maison de notre Dieu.

< Nehemiah 10 >