< Nehemiah 10 >

1 Àwọn tí ó fi èdìdì dì í ni: Nehemiah baálẹ̀, ọmọ Hakaliah. Sedekiah
Forsothe the seeleris weren Neemye, Athersata, the sone of Achilai,
2 Seraiah, Asariah, Jeremiah,
and Sedechie, Saraie, Azarie, Jeremye, Phasur,
3 Paṣuri, Amariah, Malkiah,
Amarie, Melchie,
4 Hattusi, Ṣebaniah, Malluki,
Accus, Sebenye,
5 Harimu, Meremoti, Obadiah,
Mellucarem, Nerymuth, Oddie, Danyel,
6 Daniẹli, Ginetoni, Baruku,
Genton, Baruc, Mosollam, Abia,
7 Meṣullamu, Abijah, Mijamini,
Mianymy, Mazie, Belga, and Semeie;
8 Maasiah, Bilgai àti Ṣemaiah. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà.
these weren prestis.
9 Àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua ọmọ Asaniah, Binnui ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Henadadi, Kadmieli,
Forsothe dekenes weren Josue, the sone of Azarie, Bennuy, of the sones of Ennadab,
10 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn: Ṣebaniah, Hodiah, Kelita, Pelaiah, Hanani,
Cedinyel, and hise britheren, Sethenye, Odenmye, Telita, Phalaie, Anam,
11 Mika, Rehobu, Haṣabiah,
Myca, Roob, Asebie
12 Sakkuri, Ṣerebiah, Ṣebaniah,
Zaccur, Serebie, Sabanye,
13 Hodiah, Bani àti Beninu.
Odias, Bany, Hamyn.
14 Àwọn olórí àwọn ènìyàn: Paroṣi, Pahati-Moabu, Elamu, Sattu, Bani,
The heedis of the puple, Phetos, Moab, Elam,
15 Bunni, Asgadi, Bebai.
Zecu, Banny, Bonny, Azgad, Bebay,
16 Adonijah, Bigfai, Adini,
Donai, Bogoia, Adyn,
17 Ateri, Hesekiah, Assuri,
Ather, Azochie, Azur,
18 Hodiah, Haṣumu, Besai,
Odenye, Assuyn, Bessaie,
19 Harifu, Anatoti, Nebai,
Ares, Anatoth, Nebai,
20 Magpiaṣi, Meṣullamu, Hesiri
Methpie, Mosollam, Azir,
21 Meṣesabeli, Sadoku, Jaddua
Meizabel, Sadoch, Reddua,
22 Pelatiah, Hanani, Anaiah,
Pheltie, Ananye, Osee,
23 Hosea, Hananiah, Haṣubu,
Anaie, Azub, Aloes,
24 Halloheṣi, Pileha, Ṣobeki,
Phaleam, Sobeth,
25 Rehumu, Haṣabna, Maaseiah,
Reu, Asebyne, Mathsie,
26 Ahijah, Hanani, Anani,
Ethaie, Anam,
27 Malluki, Harimu, àti Baanah.
Mellucarem, Baana;
28 “Àwọn ènìyàn tókù—àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn aṣọ́nà, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn àjèjì nítorí òfin Ọlọ́run, papọ̀ pẹ̀lú ìyàwó wọn, gbogbo ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, tí òye yé
and othere of the puple, prestis, dekenes, porteris, and syngeris, Natynneis, and alle men that departiden hem silf fro the puplis of londis to the lawe of God, the wyues of hem, and `the sones of hem, and the douytris of hem;
29 gbogbo wọn fi ara mọ́ àwọn arákùnrin wọn, àwọn ọlọ́lá, wọ́n sì fi ègún àti ìbúra dé ara wọn láti máa tẹ̀lé òfin Ọlọ́run tí a fi fún wọn ní ipasẹ̀ Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run àti láti pa gbogbo àṣẹ, ìlànà àti òfin Olúwa, wa mọ́ dáradára.
alle that myyten vndurstonde, bihetynge for her britheren, the principal men of hem, `and thei that camen to biheete, and to swere, that thei schulden go in the lawe of the Lord, which he `hadde youe bi the hond of Moyses, his seruaunt, that thei schulden do and kepe alle the heestis of `oure Lord God, and hise domes, and hise cerymonyes; and that we schulden not yyue
30 “A ti ṣe ìlérí pé, a kò ní fi àwọn ọmọbìnrin wa fún àwọn tí wọ́n wà ní àyíká wa bí ìyàwó, tàbí fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin wa.
oure douytris to the puple of the lond, and that we schulden not take her douytris to oure sones.
31 “Nígbà tí àwọn ènìyàn àdúgbò bá mú ọjà tàbí oúnjẹ wá ní ọjọ́ ìsinmi láti tà, àwa kò ní rà á ní ọwọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi tàbí ní ọjọ́ mímọ́ kankan. Ní gbogbo ọdún keje àwa kò ní ro ilẹ̀ náà, a ó sì pa gbogbo àwọn gbèsè rẹ́.
Also the puplis of the lond, `that bryngen in thingis set to sale, and alle thingis to vss, bi the dai of sabat, for to sille, we schulen not take of hem in the sabat, and in a dai halewid; and we schulen leeue the seuenthe yeer, and the axynge of al hond.
32 “Àwa gbà ojúṣe láti máa pa àṣẹ mọ́ pé, a ó máa san ìdámẹ́ta ṣékélì ní ọdọọdún fún iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa:
And we schulen ordeyne comaundementis `on vs, that we yyue the thridde part of a sicle `bi the yeer to the werk of `oure Lord God,
33 nítorí oúnjẹ tí ó wà lórí tábìlì; nítorí ọrẹ ohun jíjẹ àti ẹbọ sísun ìgbà gbogbo; nítorí ọrẹ ọjọ́ ìsinmi, ti àyajọ́ oṣù tuntun àti àjọ̀dún tí a yàn; nítorí ọrẹ mímọ́; nítorí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún Israẹli; àti fún gbogbo iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa.
to the looues of settyngforth, and to the euerlastynge sacrifice, `and in to brent sacrifice euerlastynge, in sabatis, in calendis, `that is, bigynnyngis of monethis, in solempnytees, in halewid daies, and for synne, that `me preie for Israel, and in to al the vss of the hows of oure God.
34 “Àwa, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ènìyàn náà ti dìbò láti pinnu ìgbà tí olúkúlùkù àwọn ìdílé yóò mú ọrẹ igi wá láti sun lọ́ríi pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa sí ilé Ọlọ́run wa, ní àkókò tí a yàn ní ọdọọdún. Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin.
`Therfor we senten `lottis on the offryng of trees, bitwixe prestis and dekenes and the puple, that tho schulden be brouyt in to the hows of oure God, bi the housis of oure fadris bi tymes, fro the tymes of a yeer `til to a yeer, that `tho schulden brenne on the auter of `oure Lord God, as it is writun in the lawe of Moyses;
35 “Àwa tún gbà ojúṣe láti mú àkọ́so àwọn èso wa wá àti gbogbo èso igi wá ní ilé Olúwa.
and that we bringe the firste gendrid thingis of oure lond, and the firste fruytis of al fruyt of ech tree, fro yeer in to yeer,
36 “Gẹ́gẹ́ bí a sì ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin, àwa yóò mú àkọ́bí àwọn ọmọkùnrin wa, ti ohun ọ̀sìn wa, ti àwọn abo màlúù àti ti àwọn àgùntàn wa, wá sí ilé Ọlọ́run wa, fún àwọn àlùfáà tí ń ṣiṣẹ́ níbẹ̀.
in to the hows of the Lord, and the firste gendrid thingis of oure sones, and of oure beestis, as it is writun in the lawe, and the firste gendrid thingis of oure oxis, and of oure scheep, that tho be offrid in the hows of oure God, to prestis that mynystren in the hows of oure God;
37 “Síwájú sí i, àwa yóò mú àkọ́so oúnjẹ ilẹ̀ wa ti ọrẹ oúnjẹ, ti gbogbo èso àwọn igi àti ti wáìnì tuntun wa àti ti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ilé Ọlọ́run wa àti fún àwọn àlùfáà. Àwa yóò sì mú ìdámẹ́wàá ohun ọ̀gbìn wá fún àwọn ọmọ Lefi, nítorí àwọn ọmọ Lefi ni ó ń gba ìdámẹ́wàá ní gbogbo àwọn ìlú tí a ti ń ṣiṣẹ́.
and we schulen brynge the firste fruytis of oure metis, and of oure moiste sacrifices, and the applis of ech tre, and of vendage, and of oile, to `prestis, at the treserie of the Lord, and the tenthe part of oure lond to dekenes; thilke dekenes schulen take tithis of alle the citees of oure werkis.
38 Àlùfáà tí o ti ìdílé Aaroni wá ni yóò wá pẹ̀lú àwọn ọmọ Lefi nígbà tí wọ́n bá ń gba ìdámẹ́wàá, àwọn ọmọ Lefi yóò sì mú ìdámẹ́wàá ti ìdámẹ́wàá náà wá sí ilé Ọlọ́run, sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí inú ilé ìṣúra.
Sotheli a prest, the sone of Aaron, schal be with the dekenes in the tithis of dekenes; and the dekenes schulen offre the tenthe part of her tithe in the hows of oure God, `at the tresorie, in the hows of tresour.
39 Àwọn ènìyàn Israẹli, àti àwọn ọmọ Lefi gbọdọ̀ mú ọrẹ oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí níbi tí a pa ohun èlò ibi mímọ́ mọ́ sí àti ibi tí àwọn àlùfáà tí ń ṣe ìránṣẹ́ lọ́wọ́, àwọn aṣọ́nà àti àwọn akọrin máa ń dúró sí. “Àwa kì yóò gbàgbé tàbí ṣe àìbìkítà nípa ilé Ọlọ́run wa.”
For the sones of Israel and the sones of Leuy schulen brynge the firste fruytis of wheete, of wiyn, and of oile; and halewid vessels schulen be there, and prestis, and syngeris, and porteris, and mynystris; and we schulen not forsake the hows of `oure God.

< Nehemiah 10 >