< Nehemiah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah. Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa,
Ⱨaⱪaliyaning oƣli Nǝⱨǝmiya xundaⱪ bayan ⱪildiki: — Yigirminqi yili Kislǝw eyida, mǝn Xuxan ⱪǝl’ǝsidǝ turattim,
2 Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.
Ɵz ⱪerindaxlirimdin biri bolƣan Ⱨanani bilǝn birnǝqqǝ kixi Yǝⱨudiyǝdin qiⱪip kǝldi; mǝn ulardin sürgünlüktin ⱪutulup ⱪalƣan Yǝⱨudalar wǝ Yerusalem toƣrisida soridim.
3 Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”
Ular manga: — Sürgünlüktin ⱪutulƣan hǝlⱪning ⱪaldisi [Yǝⱨudiyǝ] ɵlkisidǝ ⱪattiⱪ japa-muxǝⱪⱪǝt astida wǝ aⱨanǝt iqidǝ ⱪaldi. Yerusalemning sepili bolsa ɵrüwetildi, ⱪowuⱪlirimu kɵydürüwetildi, dǝp eytip bǝrdi.
4 Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run.
Mǝn bu gǝplǝrni anglap olturup yiƣlap kǝttim, birnǝqqǝ küngiqǝ nalǝ-pǝryad kɵtürüp, asmanlardiki Huda aldida roza tutup, dua ⱪilip
5 Nígbà náà ni mo wí pé: “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́.
mundaⱪ dedim: — «I asmandiki Huda Pǝrwǝrdigar, Ɵzini sɵyüp, ǝmrlirini tutⱪanlarƣa ɵzgǝrmǝs meⱨir kɵrsitip ǝⱨdisidǝ turƣuqi uluƣ wǝ dǝⱨxǝtlik Tǝngri,
6 Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ.
ǝmdi Sening aldingda muxu pǝyttǝ ⱪulliring Israillar üqün peⱪir ⱪulungning keqǝ-kündüz ⱪiliwatⱪan bu duasiƣa ⱪuliⱪing selinƣay, kɵzüng oquⱪ bolƣay! Mǝn biz Israillarning Sening aldingda sadir ⱪilƣan gunaⱨlirimizni etirap ⱪilimǝn; mǝnmu, atamning jǝmǝtimu gunaⱨ ⱪilduⱪ!
7 Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.
Biz Sening yolungƣa tǝtür ix ⱪilip, Sǝn ⱪulung Musaƣa tapiliƣan ǝmrliring, bǝlgilimiliring wǝ ⱨɵkümliringni ⱨeq tutmiduⱪ.
8 “Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Sening Ɵz ⱪulung Musaƣa tapilap: «Əgǝr silǝr wapasizliⱪ ⱪilsanglar, silǝrni pütün taipilǝrning arisiƣa tarⱪitiwetimǝn; lekin Manga yenip kelip, Mening ǝmrlirimni tutup ǝmǝl ⱪilsanglar, gǝrqǝ aranglardin ⱨǝtta asmanlarning ǝng qetigǝ ⱪoƣliwetilgǝnlǝr bolsimu, Mǝn ularni xu yǝrdin yiƣip, Mening namimni tiklǝxkǝ talliƣan jayƣa elip kelimǝn» degǝn sɵzüngni yad ⱪilƣaysǝn, dǝp ɵtünimǝn.
9 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’
10 “Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ.
Bularning ⱨǝmmisi Sening ⱪulliring wǝ Sening hǝlⱪing, Ɵzüngning zor ⱪudriting wǝ küqlük ⱪolung bilǝn ⱨɵrlükkǝ ⱪutⱪuzdung.
11 Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì síjú àánú wò ó níwájú ọkùnrin yìí.” Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.
I Rǝbbim, ⱪulungning duasiƣa ⱨǝm Sening namingdin ǝyminixtin sɵyüngǝn ⱪulliringningmu duasini ⱪuliⱪing tingxiƣay; bügün ⱪulungning ixlirini onguxluⱪ ⱪilƣaysǝn, uni xu kixining aldida iltipatⱪa erixtürgǝysǝn». Xu waⱪitta mǝn padixaⱨning saⱪiysi idim.

< Nehemiah 1 >