< Nehemiah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah. Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa,
Besede Nehemija, Hahaljájevega sina. Pripetilo se je v mesecu kislévu, v dvajsetem letu, medtem ko sem bil v palači Suze,
2 Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.
da je prišel Hananí, eden izmed mojih bratov, on in nekateri možje iz Juda. Vprašal sem jih glede Judov, ki so pobegnili, ki so preostali od ujetništva in glede Jeruzalema.
3 Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”
Rekli so mi: »Ostanek, ki je ostal od ujetništva, tam v provinci, je v veliki stiski in graji. Prav tako je porušeno jeruzalemsko obzidje in njegova velika vrata so požgana z ognjem.«
4 Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run.
In pripetilo se je, ko sem slišal te besede, da sem se usedel, jokal in žaloval določene dni in se postil ter molil pred Bogom nebes
5 Nígbà náà ni mo wí pé: “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́.
in rekel: »Rotim te, oh Gospod Bog nebes, veliki in strašni Bog, ki ohranja zavezo in usmiljenje za tiste, ki ga ljubijo in obeležujejo njegove zapovedi.
6 Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ.
Naj bo tvoje uho sedaj pozorno in tvoje oči odprte, da boš lahko slišal molitev svojega služabnika, ki jo sedaj molim pred teboj podnevi in ponoči zaradi tvojih služabnikov, Izraelovih otrok in priznavam grehe Izraelovih otrok, ki smo jih zagrešili zoper tebe. Tako jaz, kakor hiša mojega očeta smo grešili.
7 Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.
Zoper tebe smo postopali zelo izprijeno in se nismo držali zapovedi niti zakonov niti sodb, ki si jih zapovedal svojemu služabniku Mojzesu.
8 “Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Spomni se, rotim te, besede, ki jo zapoveduješ svojemu služabniku Mojzesu, rekoč: › Če grešite, vas bom razkropil na tuje, med narode.
9 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’
Toda če se obrnete k meni in se držite mojih zapovedi in jih izpolnjujete, čeprav bi bili izmed vas vrženi v najbolj oddaljen del neba, jih bom vendar zbral od tam in jih privedel na kraj, ki sem ga izbral, da tam postavim svoje ime.‹
10 “Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ.
Torej ti so tvoji služabniki in tvoje ljudstvo, ki si jih odkupil s svojo veliko oblastjo in s svojo močno roko.
11 Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì síjú àánú wò ó níwájú ọkùnrin yìí.” Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.
Oh Gospod, rotim te, naj bo sedaj tvoje uho pozorno k molitvi tvojega služabnika in k molitvi tvojih služabnikov, ki se želijo bati tvojega imena. Prosim te, naredi svojega služabnika ta dan uspešnega in zagotovi mu usmiljenje pred očmi tega človeka.« Kajti bil sem kraljevi dvorni točaj.

< Nehemiah 1 >