< Nehemiah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah. Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa,
Słowa Nehemiasza, syna Chakaliasza. Oto w miesiącu Kislew, dwudziestego roku, gdy przebywałem w pałacu Suza;
2 Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.
Przyszedł Chanani, jeden z moich braci, a [wraz z nim niektórzy] mężczyźni z Judy. Zapytałem ich o ocalałych Żydów, którzy przeżyli niewolę, i o Jerozolimę.
3 Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”
I odpowiedzieli mi: Ostatki spośród tych, którzy w tamtej prowincji przeżyli niewolę, są w wielkim utrapieniu i pohańbieniu; ponadto mur Jerozolimy jest zburzony i jej bramy zostały spalone ogniem.
4 Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run.
A gdy usłyszałem te słowa, usiadłem, płakałem i smuciłem się przez [kilka] dni, pościłem i modliłem się przed Bogiem niebios.
5 Nígbà náà ni mo wí pé: “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́.
I powiedziałem: Ach PANIE, Boże niebios, Boże wielki i straszny, który zachowujesz przymierze i [okazujesz] miłosierdzie tym, którzy cię miłują i przestrzegają twoich przykazań.
6 Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ.
Niech twoje ucho będzie uważne, a twoje oczy będą otwarte, aby wysłuchać modlitwy twego sługi, którą teraz zanoszę do ciebie dniem i nocą za synów Izraela, twoje sługi, i [w której] wyznaję grzechy synów Izraela, które popełniliśmy przeciwko tobie. Również ja i dom mego ojca zgrzeszyliśmy.
7 Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.
Postąpiliśmy bardzo niegodziwie wobec ciebie i nie przestrzegaliśmy przykazań, ustaw ani praw, które nakazałeś Mojżeszowi, swemu słudze.
8 “Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Wspomnij, proszę, na słowo, które przekazałeś Mojżeszowi, swemu słudze, gdy powiedziałeś: [Jeśli] przekroczycie [moje przykazania], to rozproszę was między narodami;
9 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’
Lecz jeśli nawrócicie się do mnie i będziecie przestrzegać moich przykazań i wypełniać je, to choćby wasi wygnańcy byli na krańcu nieba, zgromadzę ich stamtąd i przyprowadzę na miejsce, które wybrałem, aby tam przebywało moje imię.
10 “Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ.
Oni bowiem są twoimi sługami i twoim ludem, który odkupiłeś swoją wielką mocą i silną ręką.
11 Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì síjú àánú wò ó níwájú ọkùnrin yìí.” Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.
Proszę, Panie, niech twoje ucho będzie uważne na modlitwę twego sługi i na modlitwę twoich sług, którzy pragną bać się twego imienia. Spraw dziś, proszę, aby poszczęściło się twemu słudze, i okaż mu łaskę na oczach tego człowieka. Byłem bowiem podczaszym króla.

< Nehemiah 1 >