< Nahum 1 >

1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ nípa Ninefe. Ìwé ìran Nahumu ará Elkoṣi.
Пророцтво на Ніневію. Книга видіння елкошейця Наума.
2 Ọlọ́run ń jẹ owú, ó sì ń gbẹ̀san, Olúwa ń gbẹ̀san, ó sì kún fún ìbínú. Olúwa ń gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀. Ìbínú rẹ̀ kò sì yí padà lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀.
„Палки́й Бог, і мсти́вий Госпо́дь, Господь мстивий та лютий, — Господь мстивий до тих, хто Його ненавидить, і пам'ятає про кривду Своїх ворогів.
3 Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì tóbi ní agbára; Olúwa kì yóò fi àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sílẹ̀ láìjìyà. Ọ̀nà rẹ̀ wà nínú afẹ́fẹ́ àti nínú ìjì, ìkùùkuu sánmọ̀ sì ni eruku ẹsẹ̀ rẹ̀.
Господь довготерпели́вий і великої поту́ги, та очистити винного — Він не очистить. Господь — у бурі та в ви́хрі доро́га Його, а хмара — від стіп Його ку́рява.
4 Ó bá òkun wí, ó sì mú kí ó gbẹ; Ó sìsọ gbogbo odò di gbígbẹ. Baṣani àti Karmeli sì rọ. Ìtànná Lebanoni sì rẹ̀ sílẹ̀.
Як загні́вається Він на море, то сушить його, і всі рі́ки висушує, в'яне Баша́н та Карме́л, і в'яне та квітка Ліва́ну.
5 Àwọn òkè ńlá wárìrì níwájú rẹ̀, àwọn òkè kéékèèké sì di yíyọ́, ilẹ̀ ayé sì jóná níwájú rẹ̀, àní ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
Гори тремтять перед Ним, а підгі́рки топні́ють, перед обличчям Його трясеться земля та вселе́нна, та всі її ме́шканці.
6 Ta ni ó lé dúró níwájú ìbínú rẹ̀? Ta ni ó lé faradà gbígbóná ìbínú rẹ̀? Ìbínú rẹ̀ tú jáde bí iná; àwọn àpáta sì fọ́ túútúú níwájú rẹ̀.
Хто встоїть перед гнівом Його́, і хто стане у по́лум'ї люті Його? Його шал виливається, мов той огонь, і розпада́ються скелі від Нього!
7 Rere ni Olúwa, òun ni ààbò ní ọjọ́ ìpọ́njú. Òun sì tọ́jú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e,
Добрий Господь, пристано́вище Він у день у́тиску, і знає Він тих, хто на Нього наді́ється!
8 ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìkún omi ńlá ní òun yóò fi ṣe ìparun láti ibẹ̀ dé òpin; òkùnkùn yóò sì máa lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀.
Але в зливі нава́льній Він зробить кінця́ між Його заколо́тниками, і ворогів зажене́ у темно́ту.
9 Kí ni ẹ̀yìn ń gbìmọ̀ lòdì sí Olúwa? Òun yóò fi òpin sí i, ìpọ́njú kì yóò wáyé ní ìgbà kejì.
Що ви ду́маєте проти Господа? Бо Він зробить кінця́, — не поста́не два ра́зи наси́льство.
10 Wọn yóò sì lọ́lù papọ̀ bí ẹ̀gún òṣùṣú wọn yóò sì mu àmupara nínú ọtí wáìnì wọn a ó sì run wọn gẹ́gẹ́ bi àgékù koríko gbígbẹ.
Бо вони переплу́тані, наче той те́рен, і повпива́лись, немов би вином, — вони будуть пожерті зовсі́м, мов солома суха!
11 Láti ọ̀dọ̀ rẹ, ìwọ Ninefe, ni ẹnìkan ti jáde wá tí ó ń gbèrò ibi sí Olúwa ti ó sì ń gbìmọ̀ búburú.
З тебе вийшов заду́муючий проти Господа лихо, радник нікче́мний.
12 Báyìí ni Olúwa wí: “Bí wọ́n tilẹ̀ ni ìfọwọ́sowọ́pọ̀, tí wọ́n sì pọ̀ níye, ṣùgbọ́n, báyìí ní a ó ké wọn lulẹ̀, nígbà tí òun ó bá kọjá. Bí mo tilẹ̀ ti pọ́n ọ lójú ìwọ Juda, èmi kì yóò pọ́n ọ lójúmọ́.
Так говорить Госпо́дь: Хоч були б найсильніші і дуже числе́нні, та пости́нані будуть вони, та й мину́ться! І хоч Я тебе мучив, та мучити більше тебе вже не бу́ду!
13 Nísinsin yìí ni èmi yóò já àjàgà wọn kúrò ní ọrùn rẹ èmi yóò já ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ rẹ dànù.”
А тепер Я злама́ю ярмо́ його, яке на тобі, і пу́та твої позрива́ю.
14 Olúwa ti fi àṣẹ kan lélẹ̀ nítorí tìrẹ Ninefe: “Ìwọ kì yóò ni irú-ọmọ láti máa jẹ́ orúkọ rẹ mọ́, Èmi yóò pa ère fínfín àti ère dídà run tí ó wà nínú tẹmpili àwọn ọlọ́run rẹ. Èmi yóò wa ibojì rẹ, nítorí ẹ̀gbin ni ìwọ.”
І накаже на тебе, Ашшу́ре, Господь: Більш не буде вже сі́ятися з твого йме́ння! З дому бога твого́ Я бовва́на та і́дола ви́тну, зроблю́ тобі гро́ба із них, бо ти став легкова́жений.
15 Wò ó, lórí àwọn òkè, àwọn ẹsẹ̀ ẹni tí ó mú ìròyìn ayọ̀ wá, ẹni tí ó ń kéde àlàáfíà. Ìwọ Juda, pa àṣẹ rẹ tí ó ní ìrònú mọ́, kí ó sì san àwọn ẹ̀jẹ́ rẹ. Àwọn ènìyàn búburú kì yóò sì gbóguntì ọ́ mọ́; wọn yóò sì parun pátápátá.
Ось на горах ноги́ благові́сника, що звіщає про мир: Святкуй, Юдо, свята свої, виконуй прися́ги свої, бо більше не буде нікче́мний ходи́ти по тобі, — він ви́тятий ввесь!

< Nahum 1 >