< Nahum 2 >

1 Àwọn apanirun ti dìde sí ọ, ìwọ Ninefe. Pa ilé ìṣọ́ mọ́, ṣọ́ ọ̀nà náà, di àmùrè, ẹ̀gbẹ́ rẹ kí ó le múra gírí.
Saldırı altındasın, ey Ninova, surlarını koru, Yolu gözle, belini doğrult, topla bütün gücünü.
2 Olúwa yóò mú ọláńlá Jakọbu padà sípò gẹ́gẹ́ bí ọláńlá Israẹli bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn apanirun ti pa ibẹ̀ run, tí wọ́n sì ba ẹ̀ka àjàrà wọn jẹ́.
Çünkü RAB Yakup'un soyunu İsrail'in eski görkemine kavuşturacak; Düşmanları onları perişan edip asmalarını harap etmiş olsa bile.
3 Asà àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sì di pupa; àwọn ológun wọn sì wọ aṣọ òdòdó. Idẹ tí ó wà lórí kẹ̀kẹ́ ogun ń kọ mọ̀nàmọ́ná ní ọjọ́ tí a bá pèsè wọn sílẹ̀ tán; igi firi ni a ó sì mì tìtì.
Askerlerinin kalkanları kıpkızıl, Yiğitler allar kuşanmış. Savaş arabalarının demirleri hazırlık günü nasıl da parıldıyor! Çam mızraklar sallanıyor havada.
4 Àwọn kẹ̀kẹ́ ogun yóò ya bo àwọn pópónà, wọn yóò sì máa sáré síwá àti sẹ́yìn ní àárín ìgboro. Wọn sì dàbí ètùfù iná; tí ó sì kọ bí i mọ̀nàmọ́ná.
Sokaklardan fırtına gibi geçiyor savaş arabaları, Meydanlardan koşuşuyorlar her yöne, Şimşek gibi seğirtiyorlar. Görünüşleri meşalelerden farksız.
5 Ninefe yóò ṣe àṣàrò àwọn ọlọ́lá rẹ̀; síbẹ̀ wọ́n ń kọsẹ̀ ní ojú ọ̀nà wọn; wọn sáré lọ sí ibi odi rẹ̀, a ó sì pèsè ààbò rẹ̀.
Ninova Kralı topluyor seçkin askerlerini, Ama sendeliyorlar yolda. Saldıranlar kent surlarına doğru seğirtiyor, Siperler kuruluyor.
6 A ó ṣí ìlẹ̀kùn àwọn odò wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀, a ó sì mú ààfin náà di wíwó palẹ̀.
Irmakların kapıları açıldı Ve yerle bir oldu saray.
7 A pa á láṣẹ pé ìlú náà, èyí tí a ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ ni a ó sì kó ní ìgbèkùn lọ. A ó sì mú un gòkè wá àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ yóò kérora bí ti ẹyẹ àdàbà, wọn a sì máa lu àyà wọn.
Tanrı'nın dediği oldu, soyup götürdüler kenti. Güvercinler gibi inliyor kadın köleler, Göğüslerini döverek.
8 Ninefe dàbí adágún omi, tí omi rẹ̀ sì ń gbẹ́ ẹ lọ. “Dúró! Dúró!” ni wọ́n ó máa kígbe, ṣùgbọ́n ẹnìkankan kì yóò wo ẹ̀yìn.
Kaçıp gidiyor Ninova halkı, Boşalan bir havuzun suyu gibi, “Durun, durun!” diye bağırıyorlar, Ama geri dönüp bakan yok.
9 “Ẹ kó ìkógun fàdákà! Ẹ kó ìkógun wúrà! Ìṣúra wọn ti kò lópin náà, àti ọrọ̀ kúrò nínú gbogbo ohun èlò ti a fẹ́!”
Yağmalayın altınını, gümüşünü, Yok servetinin sonu. Her tür değerli eşyayla dolup taşıyor.
10 Òun ti ṣòfò, ó si di asán, ó sì di ahoro: ọkàn pami, eékún ń lu ara wọn, ìrora púpọ̀ sì wà nínú gbogbo ẹgbẹ́ àti ojú gbogbo wọ́n sì rẹ̀wẹ̀sì.
Yıkıldı, yerle bir oldu, viraneye döndü Ninova. Eriyor yürekler, Bükülüyor dizler, titriyor bedenler, Herkesin beti benzi soluyor.
11 Níbo ni ihò àwọn kìnnìún wà àti ibi ìjẹun àwọn ọmọ kìnnìún, níbi tí kìnnìún, àní abo kìnnìún tí ń rìn, àti ọmọ kìnnìún, láìsí ohun ìbẹ̀rù.
Aslanların inine, Yavru aslanların beslendiği yere ne oldu? Aslanla dişisinin ve yavrularının korkusuzca gezindiği yere ne oldu?
12 Kìnnìún tipa ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì fún un ẹran ọdẹ ní ọrùn pa fún àwọn abo kìnnìún rẹ̀, ó sì fi ohun pípa kún ibùgbé rẹ̀ àti ihò rẹ̀ fún ohun ọdẹ.
Aslan, yavrularına yetecek kadarını avladı, Dişileri için avını boğazladı. Mağarasını avladıklarıyla, İnini kurbanlarıyla doldurdu.
13 “Kíyèsi i èmi dojúkọ ọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi yóò sì fi kẹ̀kẹ́ rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì jóná nínú èéfín, idà yóò sì jẹ ọmọ kìnnìún rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì run. Èmi yóò sì ké ohun ọdẹ rẹ kúrò lórí ilẹ̀ ayé. Ohùn àwọn ìránṣẹ́ rẹ ni a kì yóò sì tún gbọ́ mọ́.”
Her Şeye Egemen RAB, “Sana karşıyım” diyor, “Yakacağım savaş arabalarını, Dumanları tütecek. Genç aslanlarını kılıç yiyip tüketecek. Yeryüzünde av bırakmayacağım sana Ulaklarının sesi işitilmeyecek artık.”

< Nahum 2 >