< Nahum 2 >

1 Àwọn apanirun ti dìde sí ọ, ìwọ Ninefe. Pa ilé ìṣọ́ mọ́, ṣọ́ ọ̀nà náà, di àmùrè, ẹ̀gbẹ́ rẹ kí ó le múra gírí.
Kua tae ake te kaiwawahi ki tou aroaro: tiakina te pa, tuteia te ara, kia kaha tou hope, kia u rawa tou kaha.
2 Olúwa yóò mú ọláńlá Jakọbu padà sípò gẹ́gẹ́ bí ọláńlá Israẹli bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn apanirun ti pa ibẹ̀ run, tí wọ́n sì ba ẹ̀ka àjàrà wọn jẹ́.
No te mea ka whakahokia mai e Ihowa te kororia o Hakopa, me te kororia o Iharaira: kua takoto kau hoki ratou i nga kaiwhakatakoto kau, kua he ano a ratou manga waina i a ratou.
3 Asà àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sì di pupa; àwọn ológun wọn sì wọ aṣọ òdòdó. Idẹ tí ó wà lórí kẹ̀kẹ́ ogun ń kọ mọ̀nàmọ́ná ní ọjọ́ tí a bá pèsè wọn sílẹ̀ tán; igi firi ni a ó sì mì tìtì.
Kua oti te whakangungu rakau a ana marohirohi te whakawhero, he ngangana te kakahu o nga maia: kei te rino e kanapa ana te rite o nga hariata i te ra e takatu ai ia, a ko nga tao wiri rawa.
4 Àwọn kẹ̀kẹ́ ogun yóò ya bo àwọn pópónà, wọn yóò sì máa sáré síwá àti sẹ́yìn ní àárín ìgboro. Wọn sì dàbí ètùfù iná; tí ó sì kọ bí i mọ̀nàmọ́ná.
Ngana tonu nga hariata i nga ara, taututetute ana ki a ratou ano i nga waharoa: ko to ratou ahua ano he roherohe, e rere ana me he uira.
5 Ninefe yóò ṣe àṣàrò àwọn ọlọ́lá rẹ̀; síbẹ̀ wọ́n ń kọsẹ̀ ní ojú ọ̀nà wọn; wọn sáré lọ sí ibi odi rẹ̀, a ó sì pèsè ààbò rẹ̀.
Ka mahara ia ki ana metararahi: ka tapatu ratou i a ratou e haere ana; ka hohoro ratou ki to reira taiepa, a ka rite te arai.
6 A ó ṣí ìlẹ̀kùn àwọn odò wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀, a ó sì mú ààfin náà di wíwó palẹ̀.
Ka whakatuwheratia nga kuwaha o nga awa, ka papahoro te whare kingi.
7 A pa á láṣẹ pé ìlú náà, èyí tí a ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ ni a ó sì kó ní ìgbèkùn lọ. A ó sì mú un gòkè wá àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ yóò kérora bí ti ẹyẹ àdàbà, wọn a sì máa lu àyà wọn.
Na kua tu tahanga a Huhapa, kua maua atu ia, a ka tangi ana pononga wahine, ko te reo koia ano kei to te kukupa, ko o ratou uma hei timipera ma ratou.
8 Ninefe dàbí adágún omi, tí omi rẹ̀ sì ń gbẹ́ ẹ lọ. “Dúró! Dúró!” ni wọ́n ó máa kígbe, ṣùgbọ́n ẹnìkankan kì yóò wo ẹ̀yìn.
Ko Ninewe ia, ko tona rite mai onamata, kei te puna wai: heoi ka tahuti ratou; ka karanga, E tu, e tu; heoi e kore tetahi e titiro whakamuri.
9 “Ẹ kó ìkógun fàdákà! Ẹ kó ìkógun wúrà! Ìṣúra wọn ti kò lópin náà, àti ọrọ̀ kúrò nínú gbogbo ohun èlò ti a fẹ́!”
Pahuatia te hiriwa, pahuatia te koura: kahore hoki he mutunga o nga rawa, o te kororia i roto i nga taonga ahuareka katoa.
10 Òun ti ṣòfò, ó si di asán, ó sì di ahoro: ọkàn pami, eékún ń lu ara wọn, ìrora púpọ̀ sì wà nínú gbogbo ẹgbẹ́ àti ojú gbogbo wọ́n sì rẹ̀wẹ̀sì.
Kua takoto kau ia, kahore ana mea, moti rawa; harotu kau te ngakau, kei te aki ano nga turi ki a raua, he nui te mamae kei nga hope katoa, kua koma nga mata o ratou katoa.
11 Níbo ni ihò àwọn kìnnìún wà àti ibi ìjẹun àwọn ọmọ kìnnìún, níbi tí kìnnìún, àní abo kìnnìún tí ń rìn, àti ọmọ kìnnìún, láìsí ohun ìbẹ̀rù.
Kei hea te nohoanga o nga raiona? te wahi kai a nga kuao raiona? te wahi i haereere ai te raiona, me te raiona katua, me te kuao raiona, te ai he kaiwhakawehi?
12 Kìnnìún tipa ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì fún un ẹran ọdẹ ní ọrùn pa fún àwọn abo kìnnìún rẹ̀, ó sì fi ohun pípa kún ibùgbé rẹ̀ àti ihò rẹ̀ fún ohun ọdẹ.
I haehaea mai e te raiona he mea e makona ai ana kuao, notia ana e ia te kaki hei mea ma ana raiona uha, whakakiia ana e ia ona rua ki te kai, ona nohoanga hoki ki te mea i haehaea.
13 “Kíyèsi i èmi dojúkọ ọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi yóò sì fi kẹ̀kẹ́ rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì jóná nínú èéfín, idà yóò sì jẹ ọmọ kìnnìún rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì run. Èmi yóò sì ké ohun ọdẹ rẹ kúrò lórí ilẹ̀ ayé. Ohùn àwọn ìránṣẹ́ rẹ ni a kì yóò sì tún gbọ́ mọ́.”
Nana, hei hoariri tenei ahau mou, e ai ta Ihowa o nga Mano, ka tahuna ano e ahau ana hariata i roto i te paowa, ka pau au kuao raiona i te hoari: ka kore i ahau he haehaenga mau i runga i te whenua, e kore ano te reo o au karere e rangona a muri ake nei.

< Nahum 2 >