< Nahum 2 >

1 Àwọn apanirun ti dìde sí ọ, ìwọ Ninefe. Pa ilé ìṣọ́ mọ́, ṣọ́ ọ̀nà náà, di àmùrè, ẹ̀gbẹ́ rẹ kí ó le múra gírí.
Fa nitroatse añ’atrefan-dahara’o eo ty mpandrotsake, tano i kijoliy, jilovo i lalañey, mitokia an-kaozarañe, avorio o hafatrara’oo.
2 Olúwa yóò mú ọláńlá Jakọbu padà sípò gẹ́gẹ́ bí ọláńlá Israẹli bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn apanirun ti pa ibẹ̀ run, tí wọ́n sì ba ẹ̀ka àjàrà wọn jẹ́.
Vaòe’ Iehovà ty enge’ Iakobe naho ty volonahe’ Israele; fa nampikoake iareo o mampikoakeo, vaho jinoi’ iareo o singam-bahe’eo.
3 Asà àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sì di pupa; àwọn ológun wọn sì wọ aṣọ òdòdó. Idẹ tí ó wà lórí kẹ̀kẹ́ ogun ń kọ mọ̀nàmọ́ná ní ọjọ́ tí a bá pèsè wọn sílẹ̀ tán; igi firi ni a ó sì mì tìtì.
Ho mena mañabarà ty fikalan-defo’ o fanalolahio, misikiñe mena iaby o lahin-defo’eo, afo amam-bý miloeloe o sarete’eo amy andro fihentseña’ey, vaho miriñariña iaby o lefon-ambilazoo;
4 Àwọn kẹ̀kẹ́ ogun yóò ya bo àwọn pópónà, wọn yóò sì máa sáré síwá àti sẹ́yìn ní àárín ìgboro. Wọn sì dàbí ètùfù iná; tí ó sì kọ bí i mọ̀nàmọ́ná.
Mitrakotrako amo lalañeo o sareteo, mifaniotsiotse an-diolio eo; manahake ty fañilo ty vinta’ iareo, ie mihelatse mb’etia mb’eroa.
5 Ninefe yóò ṣe àṣàrò àwọn ọlọ́lá rẹ̀; síbẹ̀ wọ́n ń kọsẹ̀ ní ojú ọ̀nà wọn; wọn sáré lọ sí ibi odi rẹ̀, a ó sì pèsè ààbò rẹ̀.
Tiahi’e i mpiaolo rey; mamingañe iereo te miloka; malisa t’ie handrombake i kijoliy, fa nihentseñeñe ty fikala’e,
6 A ó ṣí ìlẹ̀kùn àwọn odò wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀, a ó sì mú ààfin náà di wíwó palẹ̀.
Misokake o lalam-pikalañañe i sakaio vaho rinava’e i anjombay.
7 A pa á láṣẹ pé ìlú náà, èyí tí a ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ ni a ó sì kó ní ìgbèkùn lọ. A ó sì mú un gòkè wá àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ yóò kérora bí ti ẹyẹ àdàbà, wọn a sì máa lu àyà wọn.
Fa nivoloseñe i mpanjaka ampelay, fa nasese añe, miñeoñeoñe hoe feon-deho-fona o anak’ ampata’eo, ie mamofok’ arañañe;
8 Ninefe dàbí adágún omi, tí omi rẹ̀ sì ń gbẹ́ ẹ lọ. “Dúró! Dúró!” ni wọ́n ó máa kígbe, ṣùgbọ́n ẹnìkankan kì yóò wo ẹ̀yìn.
Manahake o antara haehaeo t’i Ninevè, ie mihelañe añe; mijohaña, mitsangana! fe leo raike tsy mitoli-boho.
9 “Ẹ kó ìkógun fàdákà! Ẹ kó ìkógun wúrà! Ìṣúra wọn ti kò lópin náà, àti ọrọ̀ kúrò nínú gbogbo ohun èlò ti a fẹ́!”
Kopaho o volafotio, haofo o volamenao amy te tsy ho revo ty an-driha ao, fanake tsifotofoto ty ao.
10 Òun ti ṣòfò, ó si di asán, ó sì di ahoro: ọkàn pami, eékún ń lu ara wọn, ìrora púpọ̀ sì wà nínú gbogbo ẹgbẹ́ àti ojú gbogbo wọ́n sì rẹ̀wẹ̀sì.
Kapaike re, mangoakoake naho mavo, mitranake ty arofo, mifampigaiñe o ongotseo, mikoritoke iaby ze fisafoa, mikò mainte iaby o vintañeo.
11 Níbo ni ihò àwọn kìnnìún wà àti ibi ìjẹun àwọn ọmọ kìnnìún, níbi tí kìnnìún, àní abo kìnnìún tí ń rìn, àti ọmọ kìnnìún, láìsí ohun ìbẹ̀rù.
Aia i lakaton-dionay, ty famahanañe o liona tora’eo, i fipiapià’ i lionay naho i liona-vavey naho i ana-dionaiy, ie tsy amam-pañembañe?
12 Kìnnìún tipa ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì fún un ẹran ọdẹ ní ọrùn pa fún àwọn abo kìnnìún rẹ̀, ó sì fi ohun pípa kún ibùgbé rẹ̀ àti ihò rẹ̀ fún ohun ọdẹ.
Nahaeneñe o ana’eo ty rinimi’ i lionay, nahatseke o vali’eo o vinono’eo, natsafe’e tsindroke o lava’eo, le nofotse riniatse an-dakato’eo.
13 “Kíyèsi i èmi dojúkọ ọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi yóò sì fi kẹ̀kẹ́ rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì jóná nínú èéfín, idà yóò sì jẹ ọmọ kìnnìún rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì run. Èmi yóò sì ké ohun ọdẹ rẹ kúrò lórí ilẹ̀ ayé. Ohùn àwọn ìránṣẹ́ rẹ ni a kì yóò sì tún gbọ́ mọ́.”
Miatreatre azo iraho, hoe t’Iehovà’ i Màroy Haonjoko an-katòeñe o sarete’eo, habotse’ i fibaray o liona tora’oo; le haitoako ami’ty tane toy o tsindro’oo, vaho tsy ho janjiñeñe ka ty fiarañanaña’ o ira’oo.

< Nahum 2 >