< Nahum 1 >

1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ nípa Ninefe. Ìwé ìran Nahumu ará Elkoṣi.
القوشی.۱
2 Ọlọ́run ń jẹ owú, ó sì ń gbẹ̀san, Olúwa ń gbẹ̀san, ó sì kún fún ìbínú. Olúwa ń gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀. Ìbínú rẹ̀ kò sì yí padà lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀.
یهوه خدای غیور و انتقام گیرنده است. خداوند انتقام گیرنده و صاحب غضب است. خداوند از دشمنان خویش انتقام می‌گیرد و برای خصمان خود خشم را نگاه می‌دارد.۲
3 Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì tóbi ní agbára; Olúwa kì yóò fi àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sílẹ̀ láìjìyà. Ọ̀nà rẹ̀ wà nínú afẹ́fẹ́ àti nínú ìjì, ìkùùkuu sánmọ̀ sì ni eruku ẹsẹ̀ rẹ̀.
خداونددیرغضب و عظیم القوت است و گناه را هرگزبی سزا نمی گذارد. راه خداوند در تند باد و طوفان است و ابرها خاک پای او می‌باشد.۳
4 Ó bá òkun wí, ó sì mú kí ó gbẹ; Ó sìsọ gbogbo odò di gbígbẹ. Baṣani àti Karmeli sì rọ. Ìtànná Lebanoni sì rẹ̀ sílẹ̀.
دریا را عتاب می‌کند و آن را می‌خشکاند و جمیع نهرها راخشک می‌سازد. باشان و کرمل کاهیده می‌شوند وگل لبنان پژمرده می‌گردد.۴
5 Àwọn òkè ńlá wárìrì níwájú rẹ̀, àwọn òkè kéékèèké sì di yíyọ́, ilẹ̀ ayé sì jóná níwájú rẹ̀, àní ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
کوهها از او متزلزل وتلها گداخته می‌شوند و جهان از حضور وی متحرک می‌گردد و ربع مسکون و جمیع ساکنانش.۵
6 Ta ni ó lé dúró níwájú ìbínú rẹ̀? Ta ni ó lé faradà gbígbóná ìbínú rẹ̀? Ìbínú rẹ̀ tú jáde bí iná; àwọn àpáta sì fọ́ túútúú níwájú rẹ̀.
پیش خشم وی که تواند ایستاد؟ و درحدت غضب او که تواند برخاست؟ غضب او مثل آتش ریخته می‌شود و صخره‌ها از او خردمی گردد.۶
7 Rere ni Olúwa, òun ni ààbò ní ọjọ́ ìpọ́njú. Òun sì tọ́jú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e,
خداوند نیکو است و در روز تنگی ملجا می‌باشد و متوکلان خود را می‌شناسد.۷
8 ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìkún omi ńlá ní òun yóò fi ṣe ìparun láti ibẹ̀ dé òpin; òkùnkùn yóò sì máa lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀.
و به سیل سرشار، مکان آن را بالکل خراب خواهدساخت و تاریکی دشمنان او را تعاقب خواهدنمود.۸
9 Kí ni ẹ̀yìn ń gbìmọ̀ lòdì sí Olúwa? Òun yóò fi òpin sí i, ìpọ́njú kì yóò wáyé ní ìgbà kejì.
کدام تدبیر را به ضد خداوند توانید نمود؟ او دفعه هلاک خواهد کرد و مصیبت دفعه دیگر برپا نخواهد شد.۹
10 Wọn yóò sì lọ́lù papọ̀ bí ẹ̀gún òṣùṣú wọn yóò sì mu àmupara nínú ọtí wáìnì wọn a ó sì run wọn gẹ́gẹ́ bi àgékù koríko gbígbẹ.
زیرا اگرچه مثل خارها بهم پیچیده و مانند می‌گساران مست بشوند، لیکن چون کاه خشک بالکل سوخته خواهند شد.۱۰
11 Láti ọ̀dọ̀ rẹ, ìwọ Ninefe, ni ẹnìkan ti jáde wá tí ó ń gbèrò ibi sí Olúwa ti ó sì ń gbìmọ̀ búburú.
مشیر بلیعال که به ضد خداوند بد می‌اندیشد، از تو بیرون آمده است.۱۱
12 Báyìí ni Olúwa wí: “Bí wọ́n tilẹ̀ ni ìfọwọ́sowọ́pọ̀, tí wọ́n sì pọ̀ níye, ṣùgbọ́n, báyìí ní a ó ké wọn lulẹ̀, nígbà tí òun ó bá kọjá. Bí mo tilẹ̀ ti pọ́n ọ lójú ìwọ Juda, èmi kì yóò pọ́n ọ lójúmọ́.
خداوند چنین می‌گوید: «اگرچه ایشان درقوت سالم و در شماره نیز بسیار باشند لیکن منقطع شده، در خواهند گذشت. و اگر‌چه تو راذلیل ساختم، لیکن بار دیگر تو را ذلیل نخواهم نمود.۱۲
13 Nísinsin yìí ni èmi yóò já àjàgà wọn kúrò ní ọrùn rẹ èmi yóò já ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ rẹ dànù.”
و الان یوغ او را از گردن تو خواهم شکست و بندهای تو را خواهم گسیخت.»۱۳
14 Olúwa ti fi àṣẹ kan lélẹ̀ nítorí tìrẹ Ninefe: “Ìwọ kì yóò ni irú-ọmọ láti máa jẹ́ orúkọ rẹ mọ́, Èmi yóò pa ère fínfín àti ère dídà run tí ó wà nínú tẹmpili àwọn ọlọ́run rẹ. Èmi yóò wa ibojì rẹ, nítorí ẹ̀gbin ni ìwọ.”
وخداوند درباره تو امر فرموده است که بار دیگرذریتی به نام تو نخواهد بود و از خانه خدایانت بتهای تراشیده و اصنام ریخته شده را منقطع خواهم نمود و قبر تو را خواهم ساخت زیرا خوارشده‌ای.۱۴
15 Wò ó, lórí àwọn òkè, àwọn ẹsẹ̀ ẹni tí ó mú ìròyìn ayọ̀ wá, ẹni tí ó ń kéde àlàáfíà. Ìwọ Juda, pa àṣẹ rẹ tí ó ní ìrònú mọ́, kí ó sì san àwọn ẹ̀jẹ́ rẹ. Àwọn ènìyàn búburú kì yóò sì gbóguntì ọ́ mọ́; wọn yóò sì parun pátápátá.
اینک بر کوهها پایهای مبشر که سلامتی را ندا می‌کند! ای یهودا عیدهای خود رانگاه دار و نذرهای خود را وفا کن زیرا که مردبلیعال بار دیگر از تو نخواهد گذشت بلکه بالکل منقطع خواهد شد.۱۵

< Nahum 1 >