< Nahum 1 >

1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ nípa Ninefe. Ìwé ìran Nahumu ará Elkoṣi.
Elkosh Nahum kah mangthui cabu he tah Nineveh kah olrhuh ni.
2 Ọlọ́run ń jẹ owú, ó sì ń gbẹ̀san, Olúwa ń gbẹ̀san, ó sì kún fún ìbínú. Olúwa ń gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀. Ìbínú rẹ̀ kò sì yí padà lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀.
Pathen tah thatlai tih BOEIPA loh phu a loh. BOEIPA loh phu a loh tih kosi boei la om. BOEIPA loh a rhal soah phu a loh tih a thunkha rhoek taengah khaw lunguen.
3 Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì tóbi ní agbára; Olúwa kì yóò fi àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sílẹ̀ láìjìyà. Ọ̀nà rẹ̀ wà nínú afẹ́fẹ́ àti nínú ìjì, ìkùùkuu sánmọ̀ sì ni eruku ẹsẹ̀ rẹ̀.
BOEIPA loh thintoek a ueh. A thadueng tah len khaw len tih hmil rhoe la hmil mahpawh. BOEIPA tah cangpalam khui neh hlithae khuiah khaw a longpuei om tih cingmai te a kho dongah a tangdik nah.
4 Ó bá òkun wí, ó sì mú kí ó gbẹ; Ó sìsọ gbogbo odò di gbígbẹ. Baṣani àti Karmeli sì rọ. Ìtànná Lebanoni sì rẹ̀ sílẹ̀.
Tuitunli te a tluung tih a kak sak phoeiah tuiva khaw boeih a khah. Bashan neh Karmel te a tahah sak tih Lebanon rhaiphuelh khaw a tahah sak.
5 Àwọn òkè ńlá wárìrì níwájú rẹ̀, àwọn òkè kéékèèké sì di yíyọ́, ilẹ̀ ayé sì jóná níwájú rẹ̀, àní ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
Amah taengah tlang rhoek khaw hinghuen uh tih som rhoek khaw paci uh. A mikhmuh ah diklai khaw, lunglai neh a khuikah khosa boeih khaw phoek uh.
6 Ta ni ó lé dúró níwájú ìbínú rẹ̀? Ta ni ó lé faradà gbígbóná ìbínú rẹ̀? Ìbínú rẹ̀ tú jáde bí iná; àwọn àpáta sì fọ́ túútúú níwájú rẹ̀.
A kosi hmai ah unim aka pai? A thintoek thinsa te unim aka oel thai? A kosi he hmai bangla hawk uh tih lungpang khaw amah taengah palet uh coeng.
7 Rere ni Olúwa, òun ni ààbò ní ọjọ́ ìpọ́njú. Òun sì tọ́jú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e,
BOEIPA tah citcai tue vaengkah lunghim la then tih amah ah aka ying rhoek tah a ming.
8 ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìkún omi ńlá ní òun yóò fi ṣe ìparun láti ibẹ̀ dé òpin; òkùnkùn yóò sì máa lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀.
Tedae lungpook neh aka pah rhoek tah amah hmuen ah a bawtnah hil a saii vetih a thunkha rhoek te hmaisuep ah a hloem ni.
9 Kí ni ẹ̀yìn ń gbìmọ̀ lòdì sí Olúwa? Òun yóò fi òpin sí i, ìpọ́njú kì yóò wáyé ní ìgbà kejì.
Balae tih BOEIPA te na taeng. A bawtnah hil a saii sak vetih citcai pabae khaw pai thai mahpawh.
10 Wọn yóò sì lọ́lù papọ̀ bí ẹ̀gún òṣùṣú wọn yóò sì mu àmupara nínú ọtí wáìnì wọn a ó sì run wọn gẹ́gẹ́ bi àgékù koríko gbígbẹ.
Hling lakli ah aka ven uh tih a yuhuem bangla aka yumii rhoek ngawn tah divawt a rhae rhap bangla ung uh ni.
11 Láti ọ̀dọ̀ rẹ, ìwọ Ninefe, ni ẹnìkan ti jáde wá tí ó ń gbèrò ibi sí Olúwa ti ó sì ń gbìmọ̀ búburú.
Nang lamlong ni BOEIPA aka taeng la boethae kah olrhoep hlang muen khaw a thoeng.
12 Báyìí ni Olúwa wí: “Bí wọ́n tilẹ̀ ni ìfọwọ́sowọ́pọ̀, tí wọ́n sì pọ̀ níye, ṣùgbọ́n, báyìí ní a ó ké wọn lulẹ̀, nígbà tí òun ó bá kọjá. Bí mo tilẹ̀ ti pọ́n ọ lójú ìwọ Juda, èmi kì yóò pọ́n ọ lójúmọ́.
BOEIPA loh he ni a. thui. Rhuemtuet la ping uh tangloeng dae a vok uh vetih khum ni. Nang te kan phaep cakhaw nang kan phaep voel mahpawh.
13 Nísinsin yìí ni èmi yóò já àjàgà wọn kúrò ní ọrùn rẹ èmi yóò já ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ rẹ dànù.”
A cunghloeng te nang dong lamloh ka khaem pawn vetih na kuelrhui te khaw ka bawt ni.
14 Olúwa ti fi àṣẹ kan lélẹ̀ nítorí tìrẹ Ninefe: “Ìwọ kì yóò ni irú-ọmọ láti máa jẹ́ orúkọ rẹ mọ́, Èmi yóò pa ère fínfín àti ère dídà run tí ó wà nínú tẹmpili àwọn ọlọ́run rẹ. Èmi yóò wa ibojì rẹ, nítorí ẹ̀gbin ni ìwọ.”
Nang ham te BOEIPA loh a uen coeng. Na ming ham khaw na pathen im ah soem voel mahpawh. Mueithuk neh mueihlawn te ka hnawt ni. Na phuel te thaephoei ham ni ka khueh eh.
15 Wò ó, lórí àwọn òkè, àwọn ẹsẹ̀ ẹni tí ó mú ìròyìn ayọ̀ wá, ẹni tí ó ń kéde àlàáfíà. Ìwọ Juda, pa àṣẹ rẹ tí ó ní ìrònú mọ́, kí ó sì san àwọn ẹ̀jẹ́ rẹ. Àwọn ènìyàn búburú kì yóò sì gbóguntì ọ́ mọ́; wọn yóò sì parun pátápátá.
Tlang soah rhoepnah aka phong tih aka yaak sak kah a kho aih ke. Judah aw, na khotue ah lam laeh. Na olcaeng te thuung laeh. Aka paan ham long khaw na khuila paan ham tah khoep voel ngawn mahpawh. Aka muen tah a pum la a thup ni.

< Nahum 1 >