< Micah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.
Parole de Yahweh qui fut adressée à Michée de Moréseth, dans les jours de Joathan, d’Achaz et d’Ezéchias, rois de Juda, dont il eut la vision touchant Samarie et Jérusalem.
2 Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn, fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, kí Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.
Ecoutez, vous tous, peuples! Sois attentive, terre, avec ce qui te remplit! Le Seigneur Yahweh va témoigner contre vous, le Seigneur, du palais de sa sainteté!
3 Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀; yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.
Car voici que Yahweh va sortir de sa demeure; il descendra, il marchera sur les hauteurs de la terre.
4 Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀, àwọn àfonífojì yóò sì pínyà, bí idà níwájú iná, bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.
Les montagnes se fondront sous ses pas, les vallées se fendront, comme la cire devant le feu, comme l’eau versée sur une pente.
5 Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí, àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli. Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu? Ǹjẹ́ Samaria ha kọ? Kí ni àwọn ibi gíga Juda? Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?
Tout cela, à cause du crime de Jacob, et à cause des péchés de la maison d’Israël. Quel est le crime de Jacob? n’est-ce pas Samarie? Et quels sont les hauts lieux de Juda? n’est-ce pas Jérusalem?
6 “Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá, bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà. Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì. Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.
Je ferai de Samarie un tas de pierres dans un champ, un lieu à planter la vigne; je ferai rouler ses pierres dans la vallée, et je mettrai à nu ses fondements.
7 Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run. Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà, gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”
Toutes ses statues seront brisées; et tous ses salaires consumés par le feu; de toutes ses idoles je ferai une ruine, car elle les a amassées avec le salaire de la prostitution, et elles redeviendront un salaire de prostitution.
8 Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún, èmi yóò sì pohùnréré ẹkún: èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò. Èmi yóò ké bí akátá, èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.
A cause de cela, je me lamenterai et je hurlerai, je marcherai dépouillé et nu; je répandrai une lamentation comme le chacal, et une plainte comme l’autruche.
9 Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán; ó sì ti wá sí Juda. Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi, àní sí Jerusalẹmu.
Car sa plaie est mortelle; car elle vient jusqu’à Juda, elle arrive jusqu’à la porte de mon peuple, jusqu’à Jérusalem.
10 Ẹ má ṣe sọ ní Gati ẹ má ṣe sọkún rárá. Ní ilẹ̀ Beti-Ofra mo yí ara mi nínú eruku.
Ne l’annoncez pas dans Geth; ne pleurez pas dans Acco! A Beth-Aphra je me roule dans la poussière.
11 Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú, ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri. Àwọn tí ó ń gbé ni Saanani kì yóò sì jáde wá. Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀; a ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.
Passe, habitante de Saphir, dans une honteuse nudité! L’habitante de Tsoanan n’est pas sortie; le deuil de Beth-Haetsel vous prive de son abri.
12 Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre, ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
L’habitante de Maroth est en détresse à cause de ses biens; car le malheur est descendu d’auprès de Yahweh, sur la porte de Jérusalem.
13 Ìwọ olùgbé Lakiṣi, dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára. Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀ sí àwọn ọmọbìnrin Sioni, nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.
Attelle le char au coursier, habitante de Lachis; ce fut le commencement du péché pour la fille de Sion, qu’on ait trouvé chez toi les crimes d’Israël.
14 Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún Moreṣeti Gati. Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.
C’est pourquoi tu renonceras à posséder Moréseth de Geth; les maisons d’Aczib seront une déception pour les rois d’Israël.
15 Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa. Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli yóò sì wá sí Adullamu.
Je t’amènerai un conquérant, habitante de Marésa; la noblesse d’Israël s’en ira jusqu’à Odollam.
16 Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára, sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún, nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.
Arrache tes cheveux, rase-les, à cause de tes enfants bien-aimés; fais-toi chauve comme le vautour, car ils s’en vont en captivité loin de toi!

< Micah 1 >