< Micah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.
Slovo Hospodinovo, kteréž se stalo k Micheášovi Moraštickému za dnů Jotama, Achasa a Ezechiáše králů Judských, kteréž u vidění slyšel o Samaří a Jeruzalému.
2 Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn, fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, kí Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.
Slyšte všickni lidé napořád, pozoruj země, i což na ní jest, a nechť jest Panovník Hospodin proti vám svědkem, Panovník z chrámu svatosti své.
3 Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀; yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.
Nebo aj, Hospodin vyjde z místa svého, a sstoupě, šlapati bude po vysokostech země.
4 Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀, àwọn àfonífojì yóò sì pínyà, bí idà níwájú iná, bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.
I budou se rozplývati hory pod ním, a údolé se roztrhovati, tak jako vosk od ohně, a jako vody mající spád dolů,
5 Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí, àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli. Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu? Ǹjẹ́ Samaria ha kọ? Kí ni àwọn ibi gíga Juda? Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?
A to všecko pro Jákobovo zpronevěření, a pro hříchy domu Izraelského. Kdo jest příčina zpronevěření Jákobova? Zdali ne Samaří? A kdo výsostí Judských: Zdali ne Jeruzalém?
6 “Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá, bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà. Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì. Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.
Protož obrátím Samaří v hromadu rumu, k štípení vinic, a svalím do údolí kamení její, i základy její odkryji.
7 Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run. Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà, gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”
A všecky rytiny její ztlučeny budou, i všickni darové její ohněm spáleni, a všecky modly její obrátím v pustinu. Nebo ze mzdy nevěstčí toho nashromáždila, protož se zase ke mzdě nevěstčí to navrátí.
8 Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún, èmi yóò sì pohùnréré ẹkún: èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò. Èmi yóò ké bí akátá, èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.
Nad čímž kvíliti a naříkati budu, chodě svlečený a nahý, vydám se v naříkání jako drakové, a v kvílení jako mladé sovy,
9 Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán; ó sì ti wá sí Juda. Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi, àní sí Jerusalẹmu.
Proto že zneduživěla od ran svých, a že přišlo to až k Judovi, dosáhlo až k bráně lidu mého, až do Jeruzaléma.
10 Ẹ má ṣe sọ ní Gati ẹ má ṣe sọkún rárá. Ní ilẹ̀ Beti-Ofra mo yí ara mi nínú eruku.
Neoznamujtež v Gát, aniž hned plačte; v domě Ofra v prachu se válej.
11 Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú, ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri. Àwọn tí ó ń gbé ni Saanani kì yóò sì jáde wá. Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀; a ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.
Ty, kteráž bydlíš v Safir, zajdi, obnaženou majíc hanbu. Nevyjdeť ta, kteráž bydlí v Zaanan pro kvílení v Betezel, od vás maje živnost svou.
12 Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre, ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
Bude, pravím, bolestiti pro dobré věci obyvatelkyně Marót, proto že sstoupí zlé od Hospodina až do brány Jeruzalémské.
13 Ìwọ olùgbé Lakiṣi, dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára. Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀ sí àwọn ọmọbìnrin Sioni, nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.
Zapřáhni do vozu rychlé koně, obyvatelkyně Lachis, kteráž jsi původ hřícha dceři Sionské; nebo v tobě nalezena jsou přestoupení Izraelova.
14 Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún Moreṣeti Gati. Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.
Protož pošleš dary své s Morešet v Gát; domové Achzib zklamají krále Izraelské.
15 Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa. Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli yóò sì wá sí Adullamu.
Ó obyvatelkyně Maresa, i toběť tudíž přivedu dědice; až do Adulam přijde, k slávě Izraelské.
16 Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára, sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún, nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.
Učiniž sobě lysinu, a ohol se pro syny rozkoší svých; rozšiř lysinu svou jako orlice, nebo stěhují se od tebe.

< Micah 1 >