< Micah 7 >

1 Ègbé ni fún mi! Nítorí èmi sì dàbí ẹni tí ń kó èso ẹ̀ẹ̀rùn jọ, ìpèsè ọgbà àjàrà; kò sì ṣí odidi àjàrà kankan láti jẹ, kò sì ṣí àkọ́so ọ̀pọ̀tọ́ nítorí tí ebi ń pa mí.
Mening ⱨalimƣa way! Qünki mǝn huddi yazdiki mewilǝr yiƣilip, Üzüm ⱨosulidin keyinki wasangdin keyin aq ⱪalƣan birsigǝ ohxaymǝn, Yegüdǝk sapaⱪ yoⱪtur; Jenim tǝxna bolƣan tunji ǝnjür yoⱪtur!
2 Àwọn olódodo sì ti kúrò ní ilẹ̀ náà, kò sì ṣí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù tí ó jọ olóòtítọ́; gbogbo wọn sì ń purọ́ ní dídúró nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀, olúkúlùkù wọ́n sì ń fi àwọ̀n de arákùnrin rẹ̀.
Ihlasmǝn kixi zemindin yoⱪap kǝtti, Adǝmlǝr arisida durus birsimu yoⱪtur; Ularning ⱨǝmmisi ⱪan tɵküxkǝ paylimaⱪta, Ⱨǝrbiri ɵz ⱪerindixini tor bilǝn owlaydu.
3 Ọwọ́ wọn méjèèjì ti múra tán láti ṣe búburú; àwọn alákòóso ń béèrè fún ẹ̀bùn, àwọn onídàájọ́ sì ń gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ alágbára sì ń pàṣẹ ohun tí wọ́n fẹ́, gbogbo wọn sì jùmọ̀ ń dìtẹ̀.
Rǝzillikni puhta ⱪilix üqün, Ikki ⱪoli uningƣa tǝyyarlanƣan; Əmir «inam»ni soraydu, Soraⱪqimu xundaⱪ; Mɵtiwǝr janab bolsa ɵz jenining nǝpsini axkara eytip beridu; Ular jǝm bolup rǝzillikni toⱪuxmaⱪta.
4 Ẹni tí ó sàn jùlọ nínú wọn sì dàbí ẹ̀gún, ẹni tí ó jẹ́ olódodo jùlọ burú ju ẹ̀gún ọgbà lọ. Ọjọ́ àwọn olùṣọ́ rẹ̀ ti dé, àti ọjọ́ tí Ọlọ́run bẹ̀ ọ́ wò. Nísinsin yìí ní àkókò ìdààmú wọn.
Ularning ǝng esili huddi jiƣandǝk, Əng durusi bolsa, xohiliⱪ tosuⱪtin bǝttǝrdur. Əmdi kɵzǝtqiliring [ⱪorⱪup] kütkǝn kün, Yǝni [Huda] sanga yeⱪinlap jazalaydiƣan küni yetip kǝldi; Ularning alaⱪzadǝ bolup ketidiƣan waⱪti ⱨazir kǝldi.
5 Ẹ má ṣe gba ọ̀rẹ́ kan gbọ́; ẹ má sì ṣe gbẹ́kẹ̀lé amọ̀nà kankan. Pa ìlẹ̀kùn ẹnu rẹ fún ẹni tí ó sùn ní oókan àyà rẹ.
Ülpitinggǝ ixǝnmǝ, Jan dostungƣa tayanma; Aƣzingning ixikini ⱪuqiⱪingda yatⱪuqidin yepip yür.
6 Nítorí tí ọmọkùnrin kò bọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọbìnrin sì dìde sí ìyá rẹ̀, aya ọmọ sí ìyá ọkọ rẹ̀, ọ̀tá olúkúlùkù ni àwọn ará ilé rẹ̀.
Qünki oƣul atisiƣa biⱨɵrmǝtlik ⱪilidu, Ⱪiz anisiƣa, Kelin ⱪeyn anisiƣa ⱪarxi ⱪozƣilidu; Kixining düxmǝnliri ɵz ɵyidiki adǝmliridin ibarǝt bolidu.
7 Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi ní ìwòye ní ìrètí sí Olúwa, èmi dúró de Ọlọ́run olùgbàlà mi; Ọlọ́run mi yóò sì tẹ́tí sí mi.
Biraⱪ mǝn bolsam, Pǝrwǝrdigarƣa ⱪarap ümid baƣlaymǝn; Nijatimni bǝrgüqi Hudani kütimǝn; Mening Hudayim manga ⱪulaⱪ salidu.
8 Má ṣe yọ̀ mí, ìwọ ọ̀tá mi. Bí mó bá ṣubú, èmi yóò dìde. Nígbà tí mo bá jókòó sínú òkùnkùn Olúwa yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ fún mi.
Manga ⱪarap hux bolup kǝtmǝ, i düxminim; Gǝrqǝ mǝn yiⱪilip kǝtsǝmmu, yǝnǝ ⱪopimǝn; Ⱪarangƣuluⱪta oltursam, Pǝrwǝrdigar manga yoruⱪluⱪ bolidu.
9 Nítorí èmi ti dẹ́ṣẹ̀ sí i, èmi yóò faradà ìbínú Olúwa, títí òun yóò ṣe gba ẹjọ́ mi rò, tí yóò sì ṣe ìdájọ́ mi. Òun yóò sì mú mi wá sínú ìmọ́lẹ̀; èmi yóò sì rí òdodo rẹ̀.
Mǝn Pǝrwǝrdigarning ƣǝzipigǝ qidap turimǝn — Qünki mǝn Uning aldida gunaⱨ sadir ⱪildim — U mening dǝwayimni sorap, mǝn üqün ⱨɵküm qiⱪirip yürgüzgüqǝ kütimǝn; U meni yoruⱪluⱪⱪa qiⱪiridu; Mǝn Uning ⱨǝⱪⱪaniyliⱪini kɵrimǝn.
10 Nígbà náà ni ọ̀tá mi yóò rí i ìtìjú yóò sì bo ẹni tí ó wí fún mi pé, “Níbo ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wà?” Ojú mi yóò rí ìṣubú rẹ̀; nísinsin yìí ni yóò di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ òpópó.
Wǝ mening düxminim buni kɵridu, Xuning bilǝn manga: «Pǝrwǝrdigar Hudaying ⱪeni» degǝn ayalni xǝrmǝndilik basidu; Mening kɵzüm uning [mǝƣlubiyitini] kɵridu; U koqidiki patⱪaⱪtǝk dǝssǝp qǝylinidu.
11 Ọjọ́ tí a ó mọ odi rẹ yóò dé, ọjọ́ náà ni àṣẹ yóò jìnnà réré.
— Sening tam-sepilliring ⱪurulidiƣan künidǝ, Xu künidǝ sanga bekitilgǝn pasiling yiraⱪlarƣa yɵtkilidu.
12 Ní ọjọ́ náà àwọn ènìyàn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ láti Asiria àti ìlú ńlá Ejibiti àní láti Ejibiti dé Eufurate láti Òkun dé Òkun àti láti òkè ńlá dé òkè ńlá.
Xu künidǝ ular yeningƣa kelidu; — Asuriyǝdin, Misir xǝⱨǝrliridin, Misirdin [Əfrat] dǝryasiƣiqǝ, dengizdin dengizƣiqǝ wǝ taƣdin taƣƣiqǝ ular yeningƣa kelidu.
13 Ilẹ̀ náà yóò di ahoro fún àwọn olùgbé inú rẹ̀, nítorí èso ìwà wọn.
Biraⱪ yǝr yüzi bolsa ɵzining üstidǝ turuwatⱪanlar tüpǝylidin, Yǝni ularning ⱪilmixlirining mewisi tüpǝylidin harabǝ bolidu.
14 Fi ọ̀pá rẹ bọ́ àwọn ènìyàn, agbo ẹran ìní rẹ, èyí tí ó ń dágbé nínú igbó ní àárín Karmeli. Jẹ́ kí wọn jẹun ní Baṣani àti Gileadi bí ọjọ́ ìgbàanì.
— Ɵz hǝlⱪingni, yǝni ormanda, Karmǝl otturisida yalƣuz turuwatⱪan Ɵz mirasing bolƣan padini, Tayaⱪ-ⱨasang bilǝn ozuⱪlandurƣaysǝn; Ⱪǝdimki künlǝrdikidǝk, Ular Baxan ⱨǝm Gilead qimǝnzarlirida ⱪaytidin ozuⱪlansun!
15 “Bí i ọjọ́ tí ó jáde kúrò ní Ejibiti wá, ni èmi yóò fi ohun ìyanu hàn án.”
— Sǝn Misir zeminidin qiⱪⱪan künlǝrdǝ bolƣandǝk, Mǝn ularƣa karamǝt ixlarni kɵrsitip berimǝn.
16 Orílẹ̀-èdè yóò rí i, ojú yóò sì tì wọ́n, nínú gbogbo agbára wọn. Wọn yóò fi ọwọ́ lé ẹnu wọn, etí wọn yóò sì di.
Əllǝr buni kɵrüp barliⱪ ⱨǝywisidin hijil bolidu; Ⱪolini aƣzi üstigǝ yapidu, Ⱪulaⱪliri gas bolidu;
17 Wọn yóò lá erùpẹ̀ bí ejò, wọn yóò sì jáde kúrò nínú ihò wọn bí ekòló. Wọn yóò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, wọn yóò sì bẹ̀rù nítorí rẹ̀.
Ular yilandǝk topa-qangni yalaydu; Yǝr yüzidiki ɵmiligüqilǝrdǝk ɵz tɵxükliridin titrigǝn peti qiⱪidu; Ular ⱪorⱪup Pǝrwǝrdigar Hudayimizning yeniƣa kelidu, Wǝ sening tüpǝylingdinmu ⱪorⱪidu.
18 Ta ni Ọlọ́run bí rẹ̀, ẹni tí ó dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì, tí ó sì fojú fo ìrékọjá èyí tókù ìní rẹ̀? Kì í dúró nínú ìbínú rẹ̀ láéláé nítorí òun ní inú dídùn sí àánú.
Ⱪǝbiⱨlikni kǝqüridiƣan, Ɵz mirasi bolƣanlarning ⱪaldisining itaǝtsizlikidin ɵtidiƣan Tǝngridursǝn, U aqqiⱪini mǝnggügǝ saⱪlawǝrmǝydu, Qünki U meⱨir-muⱨǝbbǝtni huxalliⱪ dǝp bilidu. Kim sanga tǝngdax ilaⱨdur?
19 Òun yóò tún padà yọ́nú sí wa; òun yóò tẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa mọ́lẹ̀, yóò sì fa gbogbo àìṣedéédéé wa sínú ibú Òkun.
— U yǝnǝ bizgǝ ⱪarap iqini aƣritidu; Ⱪǝbiⱨliklirimizni U dǝssǝp qǝylǝydu; Sǝn ularning barliⱪ gunaⱨlirini dengiz tǝglirigǝ taxlaysǝn.
20 Ìwọ yóò fi òtítọ́ hàn sí Jakọbu ìwọ yóò sì fi àánú hàn sí Abrahamu, bí ìwọ ṣe búra fún àwọn baba wa láti ọjọ́ ìgbàanì.
— Sǝn ⱪǝdimki künlǝrdin beri ata-bowilirimizƣa ⱪǝsǝm ⱪilƣan ⱨǝⱪiⱪǝt-sadaⱪǝtni Yaⱪupⱪa, Ɵzgǝrmǝs muⱨǝbbǝtni Ibraⱨimƣa yǝtküzüp kɵrsitisǝn.

< Micah 7 >