< Micah 7 >

1 Ègbé ni fún mi! Nítorí èmi sì dàbí ẹni tí ń kó èso ẹ̀ẹ̀rùn jọ, ìpèsè ọgbà àjàrà; kò sì ṣí odidi àjàrà kankan láti jẹ, kò sì ṣí àkọ́so ọ̀pọ̀tọ́ nítorí tí ebi ń pa mí.
Wanginla finsrak luk! Nga oana sie mwet masrinsral su tia ku in konauk fokinsak ulun sak uh, ac wangin pac grape ke oa in grape uh. Grape nukewa ac fig emwem nukewa kinkinla tari.
2 Àwọn olódodo sì ti kúrò ní ilẹ̀ náà, kò sì ṣí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù tí ó jọ olóòtítọ́; gbogbo wọn sì ń purọ́ ní dídúró nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀, olúkúlùkù wọ́n sì ń fi àwọ̀n de arákùnrin rẹ̀.
Wanginna sie mwet suwohs lula fin acn uh, wangin sie su inse pwaye nu sin God. Mwet nukewa suk pacl fal in orek akmas. Elos suk na in oru koluk nu sin mwet Israel wialos.
3 Ọwọ́ wọn méjèèjì ti múra tán láti ṣe búburú; àwọn alákòóso ń béèrè fún ẹ̀bùn, àwọn onídàájọ́ sì ń gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ alágbára sì ń pàṣẹ ohun tí wọ́n fẹ́, gbogbo wọn sì jùmọ̀ ń dìtẹ̀.
Elos nukewa mwet na pisrla in oru ma koluk. Mwet fulat ac mwet nununku soano in oasr mol nu selos meet liki elos fah oru ma kunalos. Mwet pweyen uh elos fahk ma elos kena kac, na mwet kol ingan insese nu kac ac tukeni orek pwapa lukma.
4 Ẹni tí ó sàn jùlọ nínú wọn sì dàbí ẹ̀gún, ẹni tí ó jẹ́ olódodo jùlọ burú ju ẹ̀gún ọgbà lọ. Ọjọ́ àwọn olùṣọ́ rẹ̀ ti dé, àti ọjọ́ tí Ọlọ́run bẹ̀ ọ́ wò. Nísinsin yìí ní àkókò ìdààmú wọn.
Finne mwet su srulun wo ac lulalfongiyuk inmasrlolos, a elos mwet lusrongten oana mah uh. Len sac summa tari ke God El ac kalyei mwet uh, oana ke El tuh sensenkakinulos meet ke pusren mwet palu. Inge elos arulana fohsak.
5 Ẹ má ṣe gba ọ̀rẹ́ kan gbọ́; ẹ má sì ṣe gbẹ́kẹ̀lé amọ̀nà kankan. Pa ìlẹ̀kùn ẹnu rẹ fún ẹni tí ó sùn ní oókan àyà rẹ.
Nimet lulalfongi mwet tulan lom ku mwet kawuk lom. Liyaung ma kom fahk, finne nu sin mutan kiom.
6 Nítorí tí ọmọkùnrin kò bọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọbìnrin sì dìde sí ìyá rẹ̀, aya ọmọ sí ìyá ọkọ rẹ̀, ọ̀tá olúkúlùkù ni àwọn ará ilé rẹ̀.
In pacl inge tulik mukul nutin papa uh oru papa uh oana mwet lalfon, ac tulik mutan uh supangkas nu sin nina kialos uh, ac mutan fusr akukuin nu sin nina talupalos. Mwet lokoalok lun sie mwet pa mwet na in sou lal sifacna.
7 Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi ní ìwòye ní ìrètí sí Olúwa, èmi dúró de Ọlọ́run olùgbàlà mi; Ọlọ́run mi yóò sì tẹ́tí sí mi.
Tusruktu nga fah tawi na LEUM GOD; nga fah tupan God, mweyen nga lulalfongi lah El ac moliyula. God luk El fah porongeyu.
8 Má ṣe yọ̀ mí, ìwọ ọ̀tá mi. Bí mó bá ṣubú, èmi yóò dìde. Nígbà tí mo bá jókòó sínú òkùnkùn Olúwa yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ fún mi.
Wangin sripa mwet lokoalok lasr in niankusri kut. Kut ne ikori, tuh kut ac fah sifilpa tuyak. Kut ne oasr in lohsr in pacl inge, tuh LEUM GOD El kalem lasr.
9 Nítorí èmi ti dẹ́ṣẹ̀ sí i, èmi yóò faradà ìbínú Olúwa, títí òun yóò ṣe gba ẹjọ́ mi rò, tí yóò sì ṣe ìdájọ́ mi. Òun yóò sì mú mi wá sínú ìmọ́lẹ̀; èmi yóò sì rí òdodo rẹ̀.
Kut tuh oru ma Koluk lain LEUM GOD, na pa inge kut enenu in muteng kasrkusrak lal ke kitin pacl. Tusruktu ke saflaiya El ac fah loangekut ac akwoyela ma koluk su tuh orek nu sesr. El ac fah uskutme nu ke kalem. Kut fah moul ac liye ke El ac molikutla.
10 Nígbà náà ni ọ̀tá mi yóò rí i ìtìjú yóò sì bo ẹni tí ó wí fún mi pé, “Níbo ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wà?” Ojú mi yóò rí ìṣubú rẹ̀; nísinsin yìí ni yóò di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ òpópó.
Na mwet lokoalok lasr fah liye ma inge ac mwekinla — nuna mwet lokoalok pacna su tuh isrun kut ac fahk, “Pia sruk LEUM GOD se lowos an?” Kut ac fah liye ke kutangyukla elos, ac lolongyuki oana fohk furarrar inkanek uh.
11 Ọjọ́ tí a ó mọ odi rẹ yóò dé, ọjọ́ náà ni àṣẹ yóò jìnnà réré.
Mwet Jerusalem, pacl in sifilpa musai pot in siti uh summa. In pacl sac acn lowos ac fah akyokyeyukelik.
12 Ní ọjọ́ náà àwọn ènìyàn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ láti Asiria àti ìlú ńlá Ejibiti àní láti Ejibiti dé Eufurate láti Òkun dé Òkun àti láti òkè ńlá dé òkè ńlá.
Mwet lowos fah folokeni nu yuruwos liki acn nukewa — liki acn Assyria layen kutulap, liki Egypt layen eir, liki acn nukewa apunla Infacl Euphrates, liki meoa ac fineol yen loessula uh.
13 Ilẹ̀ náà yóò di ahoro fún àwọn olùgbé inú rẹ̀, nítorí èso ìwà wọn.
Tusruktu faclu ac fah ekla sie acn mwesis ke sripen ma koluk lalos su muta fac.
14 Fi ọ̀pá rẹ bọ́ àwọn ènìyàn, agbo ẹran ìní rẹ, èyí tí ó ń dágbé nínú igbó ní àárín Karmeli. Jẹ́ kí wọn jẹun ní Baṣani àti Gileadi bí ọjọ́ ìgbàanì.
LEUM GOD, kom in oana sie shepherd nu sin mwet lom, mwet su kom sulela. Elos finne muta mukaimtal insak uh, oasr na ima wowo raunelosla. Lela elos in som mongo in ima wowo lun Bashan ac Gilead, oana ke elos tuh oru in pacl meet ah.
15 “Bí i ọjọ́ tí ó jáde kúrò ní Ejibiti wá, ni èmi yóò fi ohun ìyanu hàn án.”
Orek mwenmen nu sesr, LEUM GOD, in oana ke kom tuh oru in len ingo ke kom uskutme liki acn Egypt.
16 Orílẹ̀-èdè yóò rí i, ojú yóò sì tì wọ́n, nínú gbogbo agbára wọn. Wọn yóò fi ọwọ́ lé ẹnu wọn, etí wọn yóò sì di.
Mutanfahl puspis ac fah liye ma inge ac arulana mwekinla kac, finne yohk ku lalos. Elos fah kaliya oallos ac fonosya insraclos ke sripen elos toasrla.
17 Wọn yóò lá erùpẹ̀ bí ejò, wọn yóò sì jáde kúrò nínú ihò wọn bí ekòló. Wọn yóò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, wọn yóò sì bẹ̀rù nítorí rẹ̀.
Elos fah orak infohk uh oana wet uh. Ke sripen sangeng lalos elos ac rarrar ac tuku liki pot ku lalos, ac forla nu sin LEUM GOD lasr.
18 Ta ni Ọlọ́run bí rẹ̀, ẹni tí ó dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì, tí ó sì fojú fo ìrékọjá èyí tókù ìní rẹ̀? Kì í dúró nínú ìbínú rẹ̀ láéláé nítorí òun ní inú dídùn sí àánú.
Wangin sie pac god oana kom, O LEUM GOD. Kom nunak munas ke ma koluk lun mwet lom su painmoulla. Kom tia sruokya kasrkusrak lom nwe tok, ac kom insewowo in fahkak nu sesr lungse kawil lom.
19 Òun yóò tún padà yọ́nú sí wa; òun yóò tẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa mọ́lẹ̀, yóò sì fa gbogbo àìṣedéédéé wa sínú ibú Òkun.
Kom ac fah sifilpa pakoten nu sesr. Kom fah futungya ma koluk lasr nu ye niom, ac supweya nu yen loallana in meoa uh!
20 Ìwọ yóò fi òtítọ́ hàn sí Jakọbu ìwọ yóò sì fi àánú hàn sí Abrahamu, bí ìwọ ṣe búra fún àwọn baba wa láti ọjọ́ ìgbàanì.
Kom fah akkalemye oaru ac lungse kawil lom nu sin mwet lom, mwet in fwil natul Abraham ac Jacob, oana ke kom wuleang nu sin mwet matu lasr pacl loes somla ah.

< Micah 7 >