< Micah 7 >

1 Ègbé ni fún mi! Nítorí èmi sì dàbí ẹni tí ń kó èso ẹ̀ẹ̀rùn jọ, ìpèsè ọgbà àjàrà; kò sì ṣí odidi àjàrà kankan láti jẹ, kò sì ṣí àkọ́so ọ̀pọ̀tọ́ nítorí tí ebi ń pa mí.
I'm totally miserable! I've become like someone trying to glean summer fruit after the grape harvest is over. I can't find any grapes to eat, and there are no early figs that I love.
2 Àwọn olódodo sì ti kúrò ní ilẹ̀ náà, kò sì ṣí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù tí ó jọ olóòtítọ́; gbogbo wọn sì ń purọ́ ní dídúró nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀, olúkúlùkù wọ́n sì ń fi àwọ̀n de arákùnrin rẹ̀.
All the good people in the country are gone, there's no one who does right left anywhere. Everyone is looking to murder others; they try to trap even their own brothers.
3 Ọwọ́ wọn méjèèjì ti múra tán láti ṣe búburú; àwọn alákòóso ń béèrè fún ẹ̀bùn, àwọn onídàájọ́ sì ń gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ alágbára sì ń pàṣẹ ohun tí wọ́n fẹ́, gbogbo wọn sì jùmọ̀ ń dìtẹ̀.
They are experts at evil; both officials and judges ask for bribes; the powerful demand their evil desires; and they scheme together to get what they want.
4 Ẹni tí ó sàn jùlọ nínú wọn sì dàbí ẹ̀gún, ẹni tí ó jẹ́ olódodo jùlọ burú ju ẹ̀gún ọgbà lọ. Ọjọ́ àwọn olùṣọ́ rẹ̀ ti dé, àti ọjọ́ tí Ọlọ́run bẹ̀ ọ́ wò. Nísinsin yìí ní àkókò ìdààmú wọn.
Even the best of them is like a thorny bush, the most honest like a thorn hedge. Your day of judgment that was announced by the prophets, your time of punishment, has arrived. You'rethrown into complete confusion.
5 Ẹ má ṣe gba ọ̀rẹ́ kan gbọ́; ẹ má sì ṣe gbẹ́kẹ̀lé amọ̀nà kankan. Pa ìlẹ̀kùn ẹnu rẹ fún ẹni tí ó sùn ní oókan àyà rẹ.
Don't trust a neighbor, don't rely on a friend. Watch what you say even to the one who lies in your arms.
6 Nítorí tí ọmọkùnrin kò bọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọbìnrin sì dìde sí ìyá rẹ̀, aya ọmọ sí ìyá ọkọ rẹ̀, ọ̀tá olúkúlùkù ni àwọn ará ilé rẹ̀.
For a son treats his father with contempt; a daughter opposes her mother, and a daughter-in-law her mother-in-law. Your enemies are members of your own family.
7 Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi ní ìwòye ní ìrètí sí Olúwa, èmi dúró de Ọlọ́run olùgbàlà mi; Ọlọ́run mi yóò sì tẹ́tí sí mi.
But as for me, I look to the Lord. I will wait for the God who saves me. My God will hear me.
8 Má ṣe yọ̀ mí, ìwọ ọ̀tá mi. Bí mó bá ṣubú, èmi yóò dìde. Nígbà tí mo bá jókòó sínú òkùnkùn Olúwa yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ fún mi.
Don't gloat over me, my enemies! Even though I fall, I will rise again. Though I sit in darkness, the Lord is my light.
9 Nítorí èmi ti dẹ́ṣẹ̀ sí i, èmi yóò faradà ìbínú Olúwa, títí òun yóò ṣe gba ẹjọ́ mi rò, tí yóò sì ṣe ìdájọ́ mi. Òun yóò sì mú mi wá sínú ìmọ́lẹ̀; èmi yóò sì rí òdodo rẹ̀.
I will endure the Lord's anger because I have sinned against him. But after that he will argue my case and give me justice. He will bring me into the light and I will see his integrity.
10 Nígbà náà ni ọ̀tá mi yóò rí i ìtìjú yóò sì bo ẹni tí ó wí fún mi pé, “Níbo ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wà?” Ojú mi yóò rí ìṣubú rẹ̀; nísinsin yìí ni yóò di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ òpópó.
Then my enemies will see it and cover their faces in shame for taunting me, asking, “Where is the Lord your God?” With my own eyes I will see what happens to them; they will be trodden down like mud in the streets.
11 Ọjọ́ tí a ó mọ odi rẹ yóò dé, ọjọ́ náà ni àṣẹ yóò jìnnà réré.
On that day it will be time to build your walls. On that day your boundaries will be extended.
12 Ní ọjọ́ náà àwọn ènìyàn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ láti Asiria àti ìlú ńlá Ejibiti àní láti Ejibiti dé Eufurate láti Òkun dé Òkun àti láti òkè ńlá dé òkè ńlá.
On that day people will come from Assyria and the cities of Egypt, from Egypt to the Euphrates River, from sea to sea, from mountain to mountain.
13 Ilẹ̀ náà yóò di ahoro fún àwọn olùgbé inú rẹ̀, nítorí èso ìwà wọn.
But the rest of the earth will become desolate because of what those who live there have done.
14 Fi ọ̀pá rẹ bọ́ àwọn ènìyàn, agbo ẹran ìní rẹ, èyí tí ó ń dágbé nínú igbó ní àárín Karmeli. Jẹ́ kí wọn jẹun ní Baṣani àti Gileadi bí ọjọ́ ìgbàanì.
Protect your people with your shepherd's rod. Take care of your flock, your special people, who live alone in the wilderness and in cultivated land. Let them feed in Basham and Gilead as they did long ago.
15 “Bí i ọjọ́ tí ó jáde kúrò ní Ejibiti wá, ni èmi yóò fi ohun ìyanu hàn án.”
Like the time when you left the land of Egypt, I will do miracles for you.
16 Orílẹ̀-èdè yóò rí i, ojú yóò sì tì wọ́n, nínú gbogbo agbára wọn. Wọn yóò fi ọwọ́ lé ẹnu wọn, etí wọn yóò sì di.
The nations will see, and they will be humiliated despite their strength. They will cover their mouths with their hands, and their ears shall become deaf.
17 Wọn yóò lá erùpẹ̀ bí ejò, wọn yóò sì jáde kúrò nínú ihò wọn bí ekòló. Wọn yóò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, wọn yóò sì bẹ̀rù nítorí rẹ̀.
They will lick the dust like snakes; they will be like the creepy-crawlies of the earth. They will come trembling from their fortresses to meet the Lord our God, fearful and afraid before him.
18 Ta ni Ọlọ́run bí rẹ̀, ẹni tí ó dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì, tí ó sì fojú fo ìrékọjá èyí tókù ìní rẹ̀? Kì í dúró nínú ìbínú rẹ̀ láéláé nítorí òun ní inú dídùn sí àánú.
Who is a God like you who forgives sin and passes over the rebellion of those who are left of his special people? You do not remain angry forever because you delight in showing faithful love.
19 Òun yóò tún padà yọ́nú sí wa; òun yóò tẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa mọ́lẹ̀, yóò sì fa gbogbo àìṣedéédéé wa sínú ibú Òkun.
You will have compassion on us again. You will tread our sins under your feet, and you will throw our sins into the depths of the sea.
20 Ìwọ yóò fi òtítọ́ hàn sí Jakọbu ìwọ yóò sì fi àánú hàn sí Abrahamu, bí ìwọ ṣe búra fún àwọn baba wa láti ọjọ́ ìgbàanì.
You will give your trustworthy truth to the people of Jacob, your faithful love to the people of Abraham, as you promised our forefathers long ago.

< Micah 7 >