< Micah 5 >

1 Nísinsin yìí, kó àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ jọ, ìwọ ìlú ti o ni ọmọ-ogun, nítorí ó ti fi gbógun dó tì wá. Wọn yóò fi ọ̀pá lu àwọn alákòóso Israẹli ní ẹ̀rẹ̀kẹ́.
І згрома́джуйсь тепер, дочко то́впищ! Обло́гу вчинили на нас, трости́ною б'ють по щоці Ізраїлевого суддю́...
2 “Ṣùgbọ́n ìwọ, Bẹtilẹhẹmu Efrata, bí ìwọ ti jẹ́ kékeré láàrín àwọn ẹ̀yà Juda, nínú rẹ ni ẹni tí yóò jẹ́ olórí ní Israẹli yóò ti jáde tọ̀ mí wá, ìjáde lọ rẹ̀ sì jẹ́ láti ìgbà àtijọ́, láti ìgbà láéláé.”
А ти, Віфлеєме-Єфра́те, хоч малий ти у тисячах Юди, — із тебе Мені ви́йде Той, що бу́де Владика в Ізраїлі, і відда́вна поста́ння Його, від днів вікові́чних.
3 Nítorí náà Israẹli yóò di kíkọ̀sílẹ̀ pátápátá títí di àkókò tí ẹni tí ń rọbí yóò fi bí, àti àwọn ìyókù arákùnrin rẹ̀ yóò fi padà láti darapọ̀ mọ́ àwọn Israẹli.
Тому́ Він їх видасть до ча́су, аж поки ота не породить, що має родити, а останок братів Його ве́рнеться до Ізраїлевих синів.
4 Òun yóò sì dúró, yóò sì máa ṣe olùṣọ́-àgùntàn àwọn agbo ẹran rẹ̀ ní agbára Olúwa, ní ọláńlá orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀. Wọn yóò sì wà láìléwu, nítorí nísinsin yìí ni títóbi rẹ yóò sì dé òpin ayé.
І стане, і буде Він па́сти Господньою силою, вели́чністю Йме́ння Господа Бога Свого́. І осядуть вони, бо Він стане великий тепер аж до кі́нців землі!
5 Òun yóò sì jẹ́ àlàáfíà wọn. Nígbà tí àwọn Asiria bá gbógun sí ilẹ̀ wa tí wọ́n sì ń yan lórí odi alágbára wa, nígbà náà ni a ó gbé olùṣọ́-àgùntàn méje dìde sí i, àti olórí ènìyàn mẹ́jọ.
І Він буде миром. Як при́йде до нашого краю Ашшу́р, і буде топта́тись по наших пала́тах, то поставимо на нього сім па́стирів та во́сьмеро лю́дських княжа́т.
6 Wọn yóò sì fi idà pa ilẹ̀ Asiria run, àti ilẹ̀ Nimrodu pẹ̀lú idà tí a fà. Òun yóò sì gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Asiria nígbà tí wọn bá gbógun ti ilẹ̀ wa tí wọ́n sì tún yan wọ ẹnu-bodè wa.
І вони будуть па́сти мечем край Ашшу́ра, край же Німро́да — у воро́тях його. Та Він від Ашшу́ра врятує, як той при́йде в наш край, і коли буде топтатись по наших грани́цях.
7 Ìyókù Jakọbu yóò sì wà láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn bí ìrì láti ọ̀dọ̀ Olúwa wa, bí ọ̀wààrà òjò lórí koríko, tí kò gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn tàbí kò dúró de àwọn ọmọ ènìyàn.
І Яковів за́лишок буде посе́ред числе́нних наро́дів, як роса та від Господа, як той дощ на траві, і він наді́ї не кла́стиме на чоловіка, і не буде наді́ї склада́ти на лю́дських синів.
8 Ìyókù Jakọbu yóò sì wà láàrín àwọn aláìkọlà ní àárín àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn, bí i kìnnìún láàrín àwọn ẹranko inú igbó, bí i ọmọ kìnnìún láàrín agbo àgùntàn, èyí tí ó máa ń fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, tí ó sì máa ń tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀, tí kò sì ṣí ẹnìkan tí ó lè gbà á là.
І Яковів за́лишок буде між лю́дами, серед числе́нних наро́дів, як лев між лісно́ю худо́бою, як левчу́к між ота́рами ове́ць, — що як він перехо́дить, то то́пче й шматує, і немає ніко́го, хто б зміг урятувати.
9 A ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀, gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sì ni a ó parun.
Хай зведе́ться рука твоя на твоїх ненави́сників, і хай всі вороги твої ви́тяті бу́дуть!
10 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò pa àwọn ẹṣin rẹ̀ run kúrò láàrín rẹ èmi yóò sì pa àwọn kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ run.
І станеться в день той, говорить Госпо́дь, — і ви́тну Я ко́ні твої з-серед тебе, і колесни́ці твої повигу́люю.
11 Èmi yóò sì pa ilẹ̀ ìlú ńlá rẹ̀ run, èmi ó sì fa gbogbo ibi gíga rẹ̀ ya.
І пони́щу міста́ твого кра́ю, і всі тверди́ні твої порозвалюю.
12 Èmi yóò gé ìwà àjẹ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ̀, ìwọ kì yóò sì ní aláfọ̀ṣẹ mọ́.
І повипо́люю ча́ри з твоєї руки, і ворожби́тів у тебе не бу́де.
13 Èmi yóò pa àwọn ère fínfín rẹ̀ run, àti ọwọ̀n rẹ̀ kúrò láàrín rẹ̀; ìwọ kì yóò sì le è foríbalẹ̀ fún iṣẹ́ ọwọ́ rẹ mọ́.
І понищу бовва́ни твої та жерто́вні стовпи́ твої з-посеред тебе, і ти чи́нові рук своїх більше не бу́деш вклоня́тися.
14 Èmi yóò fa ère Aṣerah tu kúrò láàrín rẹ̀, èmi yóò sì pa ìlú ńlá rẹ̀ run.
І повитина́ю дере́ва жерто́вні твої з-серед тебе, і міста́ твої вигублю.
15 Èmi yóò gbẹ̀san ní ìbínú àti ìrunú lórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò ti tẹríba fún mi.”
І в гніві та в лютості по́мсту вчиню́ над наро́дами, що Мене не послу́хались!

< Micah 5 >