< Micah 4 >

1 Ní ọjọ́ ìkẹyìn a ó fi òkè ilé Olúwa lélẹ̀ lórí àwọn òkè ńlá, a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèké lọ, àwọn ènìyàn yóò sì máa wọ̀ sínú rẹ̀.
Biraq axirqi zamanda, Perwerdigarning öyi jaylashqan tagh taghlarning béshi bolup békitilidu, Hemme döng-égizliktin üstün qilinip kötürülidu; Barliq xelqler uninggha qarap éqip kélishidu.
2 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò wá, wọn yóò sì wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa, àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu. Òun yóò sì kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀, kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.” Òfin yóò jáde láti Sioni wá, àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
Nurghun qowm-milletler chiqip bir-birige: — «kélinglar, biz Perwerdigarning téghigha, Yaqupning Xudasining öyige chiqip kéleyli; U öz yolliridin bizge ögitidu, We biz uning izlirida mangimiz» — déyishidu. Chünki qanun-yolyoruq Ziondin, Perwerdigarning söz-kalami Yérusalémdin chiqidighan bolidu.
3 Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, yóò sì parí aáwọ̀ fún orílẹ̀-èdè alágbára jíjìn réré. Wọn yóò sì fi idà wọn rọ ohun èlò ìtulẹ̀ àti ọ̀kọ̀ wọn di dòjé orílẹ̀-èdè kì yóò gbé idà sókè sí orílẹ̀-èdè mọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
U bolsa köp xelq-milletler arisida höküm chiqiridu, U küchlük eller, yiraqta turghan ellerning heq-naheqlirige késim qilidu; Buning bilen ular öz qilichlirini sapan chishliri, Neyzilirini orghaq qilip soqushidu; Bir el yene bir elge qilich kötürmeydu, Ular hem yene urush qilishni ögenmeydu;
4 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù yóò jókòó lábẹ́ àjàrà rẹ̀ àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀, ẹnìkan kì yóò sì dẹ́rùbà wọ́n, nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ̀rọ̀.
Belki ularning herbiri öz üzüm téli we öz enjür derixi astida olturidu, We héchkim ularni qorqatmaydu; Chünki samawiy qoshunlarning Serdari bolghan Perwerdigar Öz aghzi bilen shundaq éytti.
5 Gbogbo àwọn ènìyàn ń rìn, olúkúlùkù ni orúkọ ọlọ́run tirẹ̀, ṣùgbọ́n àwa yóò máa rìn ní orúkọ Olúwa. Ọlọ́run wa láé àti láéláé.
Barliq xelqler öz «ilah»ining namida mangsimu, Biraq biz Xudayimiz Perwerdigarning namida ebedil’ebedgiche mangimiz.
6 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò kó àwọn arọ jọ; èmi yóò sì ṣà àwọn tí a lé kúrò ní ìlú jọ, àti àwọn ẹni tí èmi ti pọ́n lójú.
Shu künide, — deydu Perwerdigar, — Men méyip bolghuchilarni, Heydiwétilgenlerni we Özüm azar bergenlerni yighimen;
7 Èmi yóò dá àwọn arọ sí fún èyí tókù, èmi yóò sì sọ àwọn tí a lé kúrò ní ìlú di orílẹ̀-èdè alágbára. Olúwa yóò sì jẹ ọba lórí wọn ní òkè ńlá Sioni láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé.
We méyip bolghuchini bir «qaldi», Heydiwétilgenni küchlük bir el qilimen; Shuning bilen Perwerdigar Zion téghida ular üstidin höküm süridu, Shu kündin bashlap menggügiche.
8 Ní ti ìwọ, ilé ìṣọ́ agbo àgùntàn, odi alágbára ọmọbìnrin Sioni, a ó mú ìjọba ìṣáájú padà bọ̀ sípò fún un yín; ìjọba yóò sì wà sí ọ̀dọ̀ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.”
We sen, i padini közetküchi munar, — Zion qizining égizliki, [padishahliq] sanga kélidu: — — Berheq, sanga eslidiki hoquq-hökümranliq kélidu; Padishahliq Yérusalém qizigha kélidu.
9 Kí ni ìwọ ha ń kígbe sókè sí nísinsin yìí? Ǹjẹ́ ìwọ kò ní ọba bí? Àwọn ìgbìmọ̀ rẹ ṣègbé bí? Nítorí ìrora ti dì ọ́ mú bí obìnrin tí ń rọbí.
Emdi sen hazir némishqa nida qilip nale kötürisen? Sende padishah yoqmidi? Séning mushawiringmu halak bolghanmidi, Ayalni tolghaq tutqandek azablar séni tutuwalghanmidi?
10 Máa yí síyìn-ín sọ́hùn-ún nínú ìrora, ìwọ obìnrin Sioni, bí ẹni tí ń rọbí, nítorí nísinsin yìí ìwọ yóò jáde lọ kúrò ní ìlú, ìwọ yóò sì máa gbé inú igbó. Ìwọ yóò lọ sí Babeli; níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì ti rí ìgbàlà. Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ.
Azabqa chüsh, tolghaq tutqan ayaldek tughushqa tolghinip tirishqin, i Zion qizi; Chünki sen hazir sheherdin chiqisen, Hazir dalada turisen, Sen hetta Babilghimu chiqisen. Sen ashu yerde qutquzulisen; Ashu yerde Perwerdigar sanga hemjemet bolup düshmenliringdin qutquzidu.
11 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ọ̀pọ̀lọpọ̀ Orílẹ̀-èdè kó ara wọn jọ sí ọ. Wọ́n sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sọ ọ́ di àìmọ́, ẹ jẹ́ kí ojú wa kí ó wo Sioni!”
We hazir nurghun eller: — «U ayagh asti qilinip bulghansun! Közimiz Zionning [izasini] körsün!» — dep sanga qarshi jeng qilishqa yighilidu;
12 Ṣùgbọ́n wọn kò mọ èrò inú Olúwa; bẹ́ẹ̀ ni òye ìmọ̀ rẹ̀ kò yé wọn, nítorí ó ti kó wọn jọ bí i ìtí sínú ìpakà.
Biraq ular Perwerdigarning oylirini bilmeydu, Uning nishanini chüshenmeydu; Chünki önchilerni xaman’gha yighqandek U ularni yighip qoydi.
13 “Dìde, kí ó sì máa pa ọkà ìwọ ọmọbìnrin Sioni, nítorí èmi yóò sọ ìwo rẹ̀ di irin, èmi yóò sì sọ pátákò rẹ̀ di idẹ ìwọ yóò run ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pátápátá.” Èmi yóò sì ya èrè wọn sọ́tọ̀ fún Olúwa àti ọrọ̀ wọn sí Olúwa gbogbo ayé.
Ornungdin turup xamanni tep, i Zion qizi, Chünki Men münggüzüngni tömür, tuyaqliringni mis qilimen; Nurghun ellerni soqup pare-pare qiliwétisen; Men ularning ghenimitini Perwerdigargha, Ularning mal-dunyalirini pütkül yer-zémin Igisige béghishlaymen.

< Micah 4 >