< Micah 4 >

1 Ní ọjọ́ ìkẹyìn a ó fi òkè ilé Olúwa lélẹ̀ lórí àwọn òkè ńlá, a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèké lọ, àwọn ènìyàn yóò sì máa wọ̀ sínú rẹ̀.
Dar în zilele de pe urmă se va întâmpla că muntele casei DOMNULUI va fi întemeiat în vârful munților, și va fi înălțat deasupra dealurilor; și vor curge oameni spre el.
2 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò wá, wọn yóò sì wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa, àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu. Òun yóò sì kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀, kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.” Òfin yóò jáde láti Sioni wá, àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
Și multe națiuni vor veni și vor spune: Veniți și să urcăm pe muntele DOMNULUI și la casa Dumnezeului lui Iacob; și el ne va învăța despre căile lui, și noi vom merge pe cărările lui, fiindcă legea va ieși din Sion și cuvântul DOMNULUI din Ierusalim.
3 Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, yóò sì parí aáwọ̀ fún orílẹ̀-èdè alágbára jíjìn réré. Wọn yóò sì fi idà wọn rọ ohun èlò ìtulẹ̀ àti ọ̀kọ̀ wọn di dòjé orílẹ̀-èdè kì yóò gbé idà sókè sí orílẹ̀-èdè mọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
Și el va judeca între mulți oameni și va mustra națiuni puternice de departe; și ei își vor bate din săbii fiare de plug, și din sulițele lor prăjini de curățat pomi; nu va ridica națiune sabie împotriva altei națiuni, nici nu vor mai învăța războiul.
4 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù yóò jókòó lábẹ́ àjàrà rẹ̀ àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀, ẹnìkan kì yóò sì dẹ́rùbà wọ́n, nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ̀rọ̀.
Dar ei vor ședea, fiecare om sub via sa și sub smochinul său; și nimeni nu-i va înspăimânta; fiindcă gura DOMNULUI oștirilor a vorbit.
5 Gbogbo àwọn ènìyàn ń rìn, olúkúlùkù ni orúkọ ọlọ́run tirẹ̀, ṣùgbọ́n àwa yóò máa rìn ní orúkọ Olúwa. Ọlọ́run wa láé àti láéláé.
Fiindcă toți oamenii vor merge, fiecare în numele dumnezeului său, și noi vom merge în numele DOMNULUI Dumnezeul nostru pentru totdeauna și întotdeauna.
6 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò kó àwọn arọ jọ; èmi yóò sì ṣà àwọn tí a lé kúrò ní ìlú jọ, àti àwọn ẹni tí èmi ti pọ́n lójú.
În acea zi, spune DOMNUL, eu o voi aduna pe cea care șchiopătează și o voi strânge pe cea alungată și pe cea pe care am chinuit-o.
7 Èmi yóò dá àwọn arọ sí fún èyí tókù, èmi yóò sì sọ àwọn tí a lé kúrò ní ìlú di orílẹ̀-èdè alágbára. Olúwa yóò sì jẹ ọba lórí wọn ní òkè ńlá Sioni láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé.
Și pe cea care șchiopăta, o voi face o rămășiță; și pe cea lepădată departe, o națiune puternică; și DOMNUL va domni peste ei în muntele Sion de acum înainte, chiar pentru totdeauna.
8 Ní ti ìwọ, ilé ìṣọ́ agbo àgùntàn, odi alágbára ọmọbìnrin Sioni, a ó mú ìjọba ìṣáájú padà bọ̀ sípò fún un yín; ìjọba yóò sì wà sí ọ̀dọ̀ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.”
Și tu, turn al turmei, locul întărit al fiicei Sionului, la tine va veni, la cea dintâi domnie; împărăția va veni la fiica Ierusalimului.
9 Kí ni ìwọ ha ń kígbe sókè sí nísinsin yìí? Ǹjẹ́ ìwọ kò ní ọba bí? Àwọn ìgbìmọ̀ rẹ ṣègbé bí? Nítorí ìrora ti dì ọ́ mú bí obìnrin tí ń rọbí.
Acum, de ce strigi tare? Nu este împărat în tine? A pierit sfătuitorul tău? Fiindcă te-au luat junghiuri precum o femeie în durerile nașterii.
10 Máa yí síyìn-ín sọ́hùn-ún nínú ìrora, ìwọ obìnrin Sioni, bí ẹni tí ń rọbí, nítorí nísinsin yìí ìwọ yóò jáde lọ kúrò ní ìlú, ìwọ yóò sì máa gbé inú igbó. Ìwọ yóò lọ sí Babeli; níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì ti rí ìgbàlà. Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ.
Fii în durere și chinuiește-te să naști, tu, fiică a Sionului, ca o femeie în durerile nașterii; căci acum vei ieși din cetate și vei locui pe câmp și vei merge la Babilon; acolo tu vei fi eliberată; acolo DOMNUL te va răscumpăra din mâna dușmanilor tăi.
11 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ọ̀pọ̀lọpọ̀ Orílẹ̀-èdè kó ara wọn jọ sí ọ. Wọ́n sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sọ ọ́ di àìmọ́, ẹ jẹ́ kí ojú wa kí ó wo Sioni!”
Acum, de asemenea multe națiuni se adună împotriva ta, care spun: Să fie întinată și ochiul nostru să privească asupra Sionului.
12 Ṣùgbọ́n wọn kò mọ èrò inú Olúwa; bẹ́ẹ̀ ni òye ìmọ̀ rẹ̀ kò yé wọn, nítorí ó ti kó wọn jọ bí i ìtí sínú ìpakà.
Dar ei nu cunosc gândurile DOMNULUI, nici nu înțeleg sfatul lui; fiindcă el îi va aduna ca pe niște snopi în arie.
13 “Dìde, kí ó sì máa pa ọkà ìwọ ọmọbìnrin Sioni, nítorí èmi yóò sọ ìwo rẹ̀ di irin, èmi yóò sì sọ pátákò rẹ̀ di idẹ ìwọ yóò run ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pátápátá.” Èmi yóò sì ya èrè wọn sọ́tọ̀ fún Olúwa àti ọrọ̀ wọn sí Olúwa gbogbo ayé.
Ridică-te și treieră, tu, fiică a Sionului; fiindcă voi face cornul tău, fier și voi face copitele tale, aramă; și tu vei zdrobi în bucăți multe popoare, iar eu voi consacra DOMNULUI câștigul lor, și averea lor Domnului întregului pământ.

< Micah 4 >