< Micah 4 >

1 Ní ọjọ́ ìkẹyìn a ó fi òkè ilé Olúwa lélẹ̀ lórí àwọn òkè ńlá, a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèké lọ, àwọn ènìyàn yóò sì máa wọ̀ sínú rẹ̀.
Ale w ostatecznych dniach stanie się, że góra domu PANA będzie utwierdzona na szczycie gór i wywyższona ponad pagórki, a narody do niej popłyną.
2 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò wá, wọn yóò sì wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa, àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu. Òun yóò sì kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀, kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.” Òfin yóò jáde láti Sioni wá, àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
I wiele narodów przybędzie, mówiąc: Chodźcie, wstąpmy na górę PANA, do domu Boga Jakuba, i będzie nas nauczał swoich dróg, a my będziemy chodzili jego ścieżkami. Z Syjonu bowiem wyjdzie prawo i słowo PANA z Jerozolimy.
3 Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, yóò sì parí aáwọ̀ fún orílẹ̀-èdè alágbára jíjìn réré. Wọn yóò sì fi idà wọn rọ ohun èlò ìtulẹ̀ àti ọ̀kọ̀ wọn di dòjé orílẹ̀-èdè kì yóò gbé idà sókè sí orílẹ̀-èdè mọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
On będzie sądzić wśród wielu narodów i będzie karać narody potężne i odległe. I przekują swoje miecze na lemiesze, a swoje oszczepy na sierpy. Naród przeciwko narodowi nie podniesie miecza i już nie będą się uczyć sztuki wojennej.
4 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù yóò jókòó lábẹ́ àjàrà rẹ̀ àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀, ẹnìkan kì yóò sì dẹ́rùbà wọ́n, nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ̀rọ̀.
Ale każdy będzie siedział pod swoją winoroślą i pod swoim drzewem figowym i nikt nie będzie ich straszył, bo to usta PANA zastępów powiedziały.
5 Gbogbo àwọn ènìyàn ń rìn, olúkúlùkù ni orúkọ ọlọ́run tirẹ̀, ṣùgbọ́n àwa yóò máa rìn ní orúkọ Olúwa. Ọlọ́run wa láé àti láéláé.
Wszystkie narody bowiem będą chodzić, każdy w imię swego boga, ale my będziemy chodzić w imię PANA, naszego Boga, na wieki wieków.
6 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò kó àwọn arọ jọ; èmi yóò sì ṣà àwọn tí a lé kúrò ní ìlú jọ, àti àwọn ẹni tí èmi ti pọ́n lójú.
W tym dniu, mówi PAN, zgromadzę chromą, zbiorę wygnaną oraz tę, którą trapiłem;
7 Èmi yóò dá àwọn arọ sí fún èyí tókù, èmi yóò sì sọ àwọn tí a lé kúrò ní ìlú di orílẹ̀-èdè alágbára. Olúwa yóò sì jẹ ọba lórí wọn ní òkè ńlá Sioni láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé.
A z tej chromej uczynię resztkę, a z wygnanej – potężny naród. I PAN będzie królował nad nimi na górze Syjon odtąd aż na wieki.
8 Ní ti ìwọ, ilé ìṣọ́ agbo àgùntàn, odi alágbára ọmọbìnrin Sioni, a ó mú ìjọba ìṣáájú padà bọ̀ sípò fún un yín; ìjọba yóò sì wà sí ọ̀dọ̀ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.”
A ty, wieżo trzody, twierdzo córki Syjonu, [wiedz, że] do ciebie przyjdzie, przyjdzie pierwsze panowanie, królestwo córki Jerozolimy.
9 Kí ni ìwọ ha ń kígbe sókè sí nísinsin yìí? Ǹjẹ́ ìwọ kò ní ọba bí? Àwọn ìgbìmọ̀ rẹ ṣègbé bí? Nítorí ìrora ti dì ọ́ mú bí obìnrin tí ń rọbí.
Czemu teraz tak bardzo krzyczysz? Czy nie ma króla u ciebie? Czy twój doradca zginął, że cię ból ogarnął jak rodzącą?
10 Máa yí síyìn-ín sọ́hùn-ún nínú ìrora, ìwọ obìnrin Sioni, bí ẹni tí ń rọbí, nítorí nísinsin yìí ìwọ yóò jáde lọ kúrò ní ìlú, ìwọ yóò sì máa gbé inú igbó. Ìwọ yóò lọ sí Babeli; níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì ti rí ìgbàlà. Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ.
Odczuwaj ból i jęcz, córko Syjonu, jak rodząca, bo już wyjdziesz z miasta i zamieszkasz w polu, i pójdziesz aż do Babilonu. Tam będziesz wybawiona, tam cię PAN odkupi z rąk twoich wrogów.
11 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ọ̀pọ̀lọpọ̀ Orílẹ̀-èdè kó ara wọn jọ sí ọ. Wọ́n sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sọ ọ́ di àìmọ́, ẹ jẹ́ kí ojú wa kí ó wo Sioni!”
Teraz zebrało się przeciwko tobie wiele narodów, które mówią: Niech będzie zbezczeszczona, niech nasze oko patrzy na Syjon.
12 Ṣùgbọ́n wọn kò mọ èrò inú Olúwa; bẹ́ẹ̀ ni òye ìmọ̀ rẹ̀ kò yé wọn, nítorí ó ti kó wọn jọ bí i ìtí sínú ìpakà.
One jednak nie znają myśli PANA ani nie rozumieją jego rady. On bowiem je zgromadzi jak snopy na klepisku.
13 “Dìde, kí ó sì máa pa ọkà ìwọ ọmọbìnrin Sioni, nítorí èmi yóò sọ ìwo rẹ̀ di irin, èmi yóò sì sọ pátákò rẹ̀ di idẹ ìwọ yóò run ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pátápátá.” Èmi yóò sì ya èrè wọn sọ́tọ̀ fún Olúwa àti ọrọ̀ wọn sí Olúwa gbogbo ayé.
Wstań i młóć, córko Syjonu, bo twój róg uczynię z żelaza i twoje kopyta uczynię ze spiżu, i zmiażdżysz wiele narodów. Poświęcę PANU ich łupy i ich bogactwo Panu całej ziemi.

< Micah 4 >